< II Królewska 7 >

1 Tedy rzekł Elizeusz: Słuchajcie słowa Pańskiego. Tak mówi Pan: O tym czasie jutro miara mąki pszennej będzie za sykiel, a dwie miary jęczmienia za sykiel, w bramie Samaryjskiej.
Eliṣa wí pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Ní àsìkò yìí ní ọ̀la, a ó ta òsùwọ̀n ìyẹ̀fun barle kíkúnná kan ní ṣékélì kan àti méjì òsùwọ̀n ọkà barle fún ṣékélì kan ní ẹnu-bodè Samaria.’”
2 I odpowiedział książe, na którego się ręce król wspierał, mężowi Bożemu i rzekł: By też Pan poczynił okna w niebie, izaliby to mogło być? Który mu rzekł: Oto ty ujrzysz oczyma twemi; ale tego jeść nie będziesz.
Ìjòyè kan ẹni tí ọwọ́ ọba ń fi ara tì dáhùn wí fún ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ẹ wò ó, tí Olúwa bá tilẹ̀ ṣí fèrèsé ọ̀run sílẹ̀, ṣé èyí lè rí bẹ́ẹ̀?” Eliṣa dáhùn pé, “Ìwọ yóò rí i pẹ̀lú ojú rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní jẹ nǹkan kan lára rẹ̀!”
3 A byli czterej mężowie trędowaci u wyjścia bramy, którzy rzekli jeden do drugiego: Pocóż tu mieszkamy, ażbyśmy pomarli?
Nísinsin yìí àwọn ọkùnrin mẹ́rin kan wà pẹ̀lú ẹ̀tẹ̀ ní ẹnu àbáwọlé ibodè ìlú. Wọ́n wí fún olúkúlùkù pé, “Kí ni ó dé tí àwa yóò fi jókòó síbí títí àwa yóò fi kú?
4 Jeźli wnijdziemy do miasta, głód w mieście, i pomrzemy tam, a jeźli tu zostaniemy, przecię pomrzemy. Teraz tedy pójdźcie, a zbieżmy do obozu Syryjskiego; jeźli nas żywo zostawią, będziemy żywi; jeźli nas też zabiją, pomrzemy.
Tí àwa bá wí pé, ‘Àwa lọ sí ìlú, ìyàn wà níbẹ̀,’ àwa yóò sì kú. Tí àwa bá dúró níbí, a máa kú, ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ jẹ́ kí a lọ sí ibùdó ti àwọn ará Siria kí àwa kí ó sì tẹríba. Bí wọ́n bá dá wa sí, àwa yóò yè, tí wọ́n bá sì pa wá, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò kú.”
5 Wstali tedy, gdy się zmierzchać poczęło, aby szli do obozu Syryjskiego; a przyszedłszy na koniec obozu Syryjskiego, oto tam nie było nikogo.
Ní àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n dìde wọ́n sì lọ sí ibùdó àwọn ará Siria. Nígbà tí wọ́n dé ẹ̀gbẹ́ ibùdó náà, kò sí ọkùnrin kan níbẹ̀,
6 Albowiem sprawił Pan, że słychać było w obozie Syryjskim grzmot wozów i tenten koni, i huk wojska wielkiego, i rzekli jeden do drugiego: Oto najął za pieniądze przeciwko nam król Izraelski króle Hetejskie, i króle Egipskie, aby przypadli na nas.
nítorí tí Olúwa jẹ́ kí àwọn ará Siria gbọ́ ìró kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin àti ogun ńlá, wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wò ó, ọba Israẹli ti bẹ ogun àwọn Hiti àti àwọn ọba Ejibiti láti dojúkọ wá!”
7 A tak wstawszy uciekli w zmierzch, zostawiwszy namioty swe, i konie swe i osły swe, i obóz jaki był, a uciekli, chcąc zachować duszę swoję.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì dìde wọ́n sì sálọ ní àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n sì fi àgọ́ wọn sílẹ̀ àti ẹṣin wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n sì fi ibùdó sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti wà, wọ́n sì sálọ fún ẹ̀mí wọn.
8 A gdy przyszli oni trędowaci aż na przodek obozu, weszli do jednego namiotu, i jedli i pili, a nabrawszy stamtąd srebra i złota, i szat, szli i skryli. Potem się wrócili, i weszli do drugiego namiotu, a nabrawszy także stamtąd, odeszli i pokryli.
Nígbà tí àwọn ọkùnrin tí ó ní ààrùn ẹ̀tẹ̀ dé ẹ̀gbẹ́ ibùdó wọ́n sì wọ inú ọ̀kan nínú àgọ́ náà. Wọ́n jẹ wọ́n sì mu, wọ́n sì kó fàdákà, wúrà àti ẹ̀wù, wọ́n sì lọ. Wọ́n sì wọ àgọ́ mìíràn lọ, wọ́n kó àwọn nǹkan láti ibẹ̀ wọ́n sì kó wọn pamọ́ pẹ̀lú.
9 Zatem rzekł jeden do drugiego: Nie dobrze czynimy. Dzień ten jest dzień dobrej nowiny, a my milczymy? Jeźli będziemy czekali aż do zaranku, będziemy winni grzechu. Przetoż teraz pójdźcie, wnijdźmy, a opowiedzmy to domowi królewskiemu.
Nígbà náà wọ́n wí fún ara wọn pé, “Àwa kò ṣe ohun rere. Òní yìí jẹ́ ọjọ́ ìròyìn rere àwa sì pa á mọ́ ara wa. Tí àwa bá dúró títí di àfẹ̀mọ́júmọ́, ìjìyà yóò jẹ́ ti wa. Ẹ jẹ́ kí a lọ ní ẹ̀ẹ̀kan kí a lọ ròyìn èyí fún àwọn ilé ọba.”
10 A tak przyszedłszy zawołali na wrotnego miejskiego, i powiedzieli im mówiąc: Przyszliśmy do obozu Syryjskiego, a oto nie było tam nikogo, ani głosu ludzkiego, oprócz koni uwiązanych, i osłów uwiązanych, i namiotów, jako przedtem były.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì lọ wọ́n sì pe àwọn asọ́bodè ìlú, wọ́n sì wí fún wọn pé, “Àwa lọ sí ibùdó àwọn ará Siria kò sì sí ọkùnrin kankan níbẹ̀ tàbí ohùn ènìyàn kan àyàfi ẹṣin tí a so àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn àgọ́ náà sì wà gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti wà.”
11 Tedy on zawołał na inne wrotne, a ci opowiedzieli to w domu królewskim.
Àwọn aṣọ́bodè náà pariwo ìròyìn náà, wọ́n sì sọ nínú ààfin ọba.
12 Wstawszy tedy król w nocy, rzekł do sług swoich: Powiem ja wam, co nam uczynili Syryjczycy; wiedzą, żeśmy zgłodniali, przetoż wyszli z obozu, a pokryli się w polu, mówiąc: Gdy wynijdą z miasta, pojmiemy je żywo, i miasto ubieżemy.
Ọba sì dìde ní òru ó sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Èmi yóò sọ fún yín ohun tí àwọn ará Siria tí ṣe fún wa. Wọ́n mọ̀ wí pé ebi ń pa wá; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ti kúrò ni ibùdó láti sá pamọ́ sí ẹ̀gbẹ́ ilé, wọ́n rò wí pé, ‘Wọn yóò jáde lóòtítọ́, nígbà náà àwa yóò mú wọn ní ààyè, àwa yóò sì wọ inú ìlú lọ.’”
13 Tedy odpowiedział jeden z sług jego, i rzekł: Proszę niech wezmą pięć koni pozostałych, które zostały w mieście; (oto one są jako wszystko mnóstwo Izraelskie, które zostało w niem; oto one są mówię jako wszystko mnóstwo Izraelskie, które ginie, ) te wyślijmy a wywiedzmy się.
Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ dáhùn pé, “Èmí o bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí àwa kí ó mú márùn-ún nínú àwọn ẹṣin tí ó kù, nínú àwọn tí ó kù ní ìlú—kíyèsí i, wọ́n sá dàbí gbogbo àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ Israẹli tí ó kù nínú rẹ̀, kíyèsí i, àní bí gbogbo ènìyàn Israẹli tí a run, sí jẹ́ kí a rán wọn lọ láti lọ wo ohun tí ó ṣẹlẹ̀.”
14 A tak wziąwszy dwa wozy z końmi, posłał król do obozu Syryjskiego, mówiąc: Idźcie a obaczcie.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan kẹ̀kẹ́ méjì pẹ̀lú ẹṣin wọn, ọba sì ránṣẹ́ tọ ogun àwọn ará Siria lẹ́yìn ó pàṣẹ fún àwọn awakọ̀ pé, “Ẹ lọ kí ẹ lọ wo ohun tí ó ṣẹlẹ̀.”
15 I szli za nimi aż do Jordanu, a oto po wszystkiej drodze pełno było szat i naczynia, które porzucili Syryjczycy, kwapiąc się. Tedy wróciwszy się oni posłowie, oznajmili to królowi.
Wọ́n sì tẹ̀lé wọn títí dé Jordani, wọ́n sì rí gbogbo ọ̀nà kún fún agbádá pẹ̀lú ohun èlò tí ará àwọn Siria gbé sọnù ní yàrá wọn. Ìránṣẹ́ náà padà ó sì wá sọ fún ọba.
16 Przeto wyszedłszy lud, rozchwycił obóz Syryjski; a była miara pszennej mąki za sykiel, a dwie miary jęczmienia za sykiel, według słowa Pańskiego.
Nígbà náà àwọn ènìyàn jáde lọ ìkógun ní ibùdó àwọn ará Siria. Bẹ́ẹ̀ ni òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kan ni wọ́n tà fún ṣékélì kan, àti òsùwọ̀n barle méjì ní ṣékélì kan, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
17 A król postanowił był onego książęcia, na którego się ręce wspierał, w bramie, którego lud podeptał w bramie, aż umarł, jako mu był powiedział mąż Boży, który o tem mówił, gdy był król przyszedł do niego.
Nísinsin yìí ọba sì mú ìjòyè náà lórí ẹni tí ó fi ọwọ́ ara rẹ̀ tì ní ìkáwọ́ ẹnu ibodè, àwọn ènìyàn sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ẹnu ibodè. Ó sì kú, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọtẹ́lẹ̀ nígbà tí ọba sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
18 I stało się według słowa, które był rzekł mąż Boży królowi, mówiąc: Dwie miary jęczmienia za sykiel, a miara pszennej mąki będzie za sykiel, jutro o tym czasie w bramie Samaryjskiej.
Ó sì ti ṣẹlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún ọba: “Ní àsìkò yìí ní ọ̀la, òsùwọ̀n ìyẹ̀fun ni a ó ta nì ṣékélì kan àti òsùwọ̀n méjì barle ní ṣékélì kan ní ẹnu-ọ̀nà ibodè Samaria.”
19 Na co był odpowiedział on książe mężowi Bożemu, mówiąc: By też Pan uczynił okna w niebie, izali to będzie według słowa tego? A on mu rzekł: Oto ty ujrzysz oczyma twemi, ale tego jeść nie będziesz.
Ìjòyè náà ti wí fún ènìyàn Ọlọ́run pé, “Wò ó, kódà ti Olúwa bá ṣí fèrèsé ní ọ̀run, ṣé èyí lè ṣẹlẹ̀?” Ènìyàn Ọlọ́run sì ti dáhùn pé, “Kìkì ojú rẹ ni ìwọ yóò fi rí i, ṣùgbọ́n ìwọ kò ní jẹ ọ̀kankan lára rẹ̀.”
20 I stało mu się tak; bo go podeptał lud w bramie, aż umarł.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí fún un gẹ́lẹ́, nítorí tí àwọn ènìyàn tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ẹnu ibodè, ó sì kú.

< II Królewska 7 >