< II Królewska 8 >

1 Potem Elizeusz rzekł do onej niewiasty, której był syna wskrzesił, mówiąc: Wstań a idź, ty i dom twój, a bądź gościem, kędy będziesz mogła być; bo zawołał Pan głodu, i przyjdzie na ziemię przez siedm lat.
Nísinsin yìí, Eliṣa wí fún obìnrin náà tí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin jí padà sáyé pé, “Jáde lọ pẹ̀lú ìdílé rẹ kí o sì lọ dúró fún ìgbà díẹ̀ ní ibikíbi tí o bá le dúró sí, nítorí Olúwa ti pàṣẹ ìyàn ní ìlú tí yóò lò tó ọdún méje.”
2 Wstała tedy ona niewiasta, i uczyniła według słowa męża Bożego; a poszła ona i dom jej, i była gościem w ziemi Filistyńskiej przez siedm lat.
Obìnrin náà tẹ̀síwájú gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ti sọ. Òun àti ìdílé rẹ̀ sí lọ, wọ́n sì ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àwọn ará Filistini fún ọdún méje.
3 I stało się po wyjściu siedmiu lat, że się wróciła ona niewiasta z ziemi Filistyńskiej, i poszła, aby wołała na króla o dom swój, i o rolę swoję.
Ní ẹ̀yìn ọdún méje ó sì padà wá láti ilẹ̀ àwọn ará Filistini ó sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba láti lọ bẹ̀ ẹ́ fún ilé àti ilẹ̀ rẹ̀.
4 A na ten czas król rozmawiał z Giezym, sługą męża Bożego, mówiąc: Powiedz mi proszę wszystkie zacne sprawy, które czynił Elizeusz.
Ọba sì ń sọ̀rọ̀ sí Gehasi, ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run pé, “Sọ fún mi nípa gbogbo ohun ńlá tí Eliṣa ti ṣe.”
5 A gdy on powiadał królowi, jako wskrzesił umarłego, oto niewiasta, której był wskrzesił syna, zawołała na króla o dom swój i o rolę swoję. I rzekł Giezy: Królu panie mój, tać to jest niewiasta, i ten syn jej, którego wskrzesił Elizeusz.
Bí Gehasi ti ń sọ bí tí Eliṣa ṣe jí òkú di alààyè, obìnrin náà tí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tí Eliṣa ti dá padà sí ayé wá láti bẹ ọba fún ilé àti ilẹ̀ rẹ̀. Gehasi sì wí pé, “Obìnrin náà nìyìí olúwa mi ọba, ọmọkùnrin rẹ náà nìyí tí Eliṣa ti jí dìde sí ayé.”
6 I pytał król niewiasty, a ona mu powiedziała. I przydał jej król komornika jednego, mówiąc: Przywróć jej wszystko, co jej było, i wszystkie dochody z pola od onego dnia, którego opuściła ziemię, aż dotąd.
Ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà nípa rẹ̀, ó sì sọ fún un. Ó sì yan ìjòyè kan fún ún fún ọ̀rọ̀ rẹ̀ ó sì wí fún un pé, “Ẹ fún un padà gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tirẹ̀, àti pẹ̀lú gbogbo èrè ilé rẹ̀ fún ún láti ọjọ́ tí ó ti kúrò ní ìlú títí di àsìkò yìí.”
7 Potem przyszedł Elizeusz do Damaszku, a Benadad, król Syryjski, chorował. I powiedziano mu, mówiąc: Przyszedł tu mąż Boży.
Eliṣa lọ sí Damasku, Beni-Hadadi ọba Siria ń ṣe àìsàn. Nígbà tí wọ́n sọ fún ọba pé, “Ènìyàn Ọlọ́run ti wá láti gbogbo ọ̀nà òkè síbí,”
8 I rzekł król do Hazaela: Weźmij w rękę swą upominek, a idź przeciwko mężowi Bożemu, i pytaj się Pana przezeń, mówiąc: Wstanęli z tej choroby?
ọba sì wí fún Hasaeli pé, “Mú ọrẹ lọ́wọ́ rẹ, sì lọ pàdé ènìyàn Ọlọ́run. Kí o sì béèrè Olúwa láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé ṣé èmi yóò sàn nínú àìsàn yìí?”
9 Przetoż szedł Hazael przeciwko niemu, a wziąwszy upominek w rękę swą, i ze wszystkich dóbr Damaskich brzemion na czterdzieści wielbłądów. I przyszedł, a stanął przed nim, mówiąc: Syn twój Benadad, król Syryjski, posłał mię do ciebie, mówiąc: Wstanęli z tej choroby?
Hasaeli lọ láti pàdé Eliṣa, ó mú lọ pẹ̀lú rẹ̀ ẹ̀bùn gẹ́gẹ́ bí ogójì ẹrù ìbákasẹ tí gbogbo ìní tí ó dára jù fún wíwò ti Damasku, ó sì wọlé lọ ó sì dúró níwájú rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọ rẹ Beni-Hadadi ọba Siria rán mi láti béèrè pé, ‘Ṣé èmi yóò sàn nínú àìsàn mi yìí?’”
10 I odpowiedział mu Elizeusz: Idź, powiedz mu: Wprawdziebyści mógł żyć; wszakże okazał mi Pan, że pewnie umrzesz.
Eliṣa da á lóhùn pé, “Lọ kí o lọ sọ fún un pé, ‘Ìwo ìbá sàn nítòótọ́’; ṣùgbọ́n Olúwa ti fihàn mí pé nítòótọ́ òun yóò kùú.”
11 Wtem pokazał mu, i stawił twarz swoję smutną, i płakał mąż Boży.
Ó sì ranjú mọ́ ọn pẹ̀lú àtẹjúmọ́ gidigidi títí tí ojú fi ti Hasaeli. Nígbà náà ènìyàn Ọlọ́run bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún.
12 Któremu rzekł Hazael: Czemuż pan mój płacze? I odpowiedział: Iż wiem, co uczynisz złego synom Izraelskim. Twierdze ich popalisz ogniem, a młodzieńce ich mieczem pomordujesz, i dzieci ich poroztrącasz, i brzemienne ich porozcinasz.
“Kí ni ó dé tí olúwa mi fi ń sọkún?” Hasaeli béèrè. “Nítorí pé èmi mọ ibi tí ìwọ yóò ṣe sí Israẹli,” ó sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò fi iná si odi agbára wọn, ìwọ yóò, pa àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin wọn pẹ̀lú idà, ìwọ yóò kọlù àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ wọn, ìwọ ó sì fọ́ wọn túútúú, ìwọ o sì la inú àwọn aboyún wọn.”
13 Tedy rzekł Hazael: Co? Izali sługa twój pies, żeby miał czynić tak wielką rzecz? I odpowiedział Elizeusz: Okazał mi Pan, że ty będziesz królem nad Syrią.
Hasaeli sì wí pé. “Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ, ajá lásán làsàn yóò ṣe ṣe irú nǹkan ńlá bẹ́ẹ̀?” “Olúwa ti fihàn mí pé ìwọ ni yóò jẹ ọba Siria,” Eliṣa dá a lóhùn.
14 I odszedł od Elizeusza, a przyszedł do pana swego, który rzekł do niego: Cóż ci powiedział Elizeusz? A on rzekł: Powiedział mi, żebyś pewnie mógł żyć.
Nígbà náà Hasaeli fi Eliṣa sílẹ̀ ó sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀. Nígbà tí Beni-Hadadi béèrè, “Kí ni ohun tí Eliṣa sọ fún ọ?” Hasaeli dá a lóhùn, “Ó sọ fún mi wí pé ìwọ yóò sàn nítòótọ́.”
15 A nazajutrz wziął Hazael kołdrę i zamaczał ją w wodzie, i rozciągnął na twarzy jego. I umarł (Benadad), a Hazael królował miasto niego.
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì ó mú aṣọ tí ó nípọn, ó sì kì í bọ inú omi ó sì tẹ̀ ẹ́ sí ojú ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó sì kú. Nígbà náà Hasaeli sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
16 A roku piątego Jorama, syna Achaba, króla Izraelskiego, i Jozafata króla Judzkiego, począł królować Joram, syn Jozafata, król Judzki.
Ní ọdún karùn-ún ti Joramu ọmọ Ahabu ọba Israẹli, nígbà tí Jehoṣafati jẹ́ ọba Juda, Jehoramu ọmọ Jehoṣafati bẹ̀rẹ̀ ìjọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba Juda.
17 Trzydzieści i dwa lata miał, gdy królować począł, a ośm lat królował w Jeruzalemie.
Ó jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
18 Ale chodził drogami królów Izraelskich, sprawując się jako dom Achabowy; bo córkę Achabową miał za żonę, i czynił złe przed oczyma Pańskiemi.
Ó sì rìn ní ọ̀nà ọba Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti lọ, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu ó sì ṣe ohun búburú níwájú Olúwa.
19 Wszakże nie chciał Pan wytracić Judy, dla Dawida, sługi swego, jako mu był powiedział, iż mu miał dać pochodnię między synami jego, po wszystkie dni.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, nítorí ti ìránṣẹ́ rẹ̀ Dafidi. Olúwa kò fẹ́ pa Juda run, ó ti ṣèlérí láti ṣètọ́jú ìmọ́lẹ̀ fún Dafidi àti àwọn ilé rẹ̀ títí láéláé.
20 Za dni jego odstąpił Edom, aby nie był pod mocą Judy; i postanowili nad sobą króla.
Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
21 Przetoż przyciągnął Joram do Seiru, i wszystkie wozy z nim; a wstawszy w nocy poraził Edomczyki, którzy go byli otoczyli, i hetmany wozów, tak iż lud uciekał do namiotów swoich.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehoramu lọ sí Sairi pẹ̀lú gbogbo kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Àwọn ará Edomu sì yí i ká àti kẹ̀kẹ́ àwọn olórí wọn, ṣùgbọ́n ó dìde dúró ní òru; àwọn ogun rẹ̀ síbẹ̀síbẹ̀, sá padà lọ ilé.
22 Wszakże odstąpił Edom, aby nie był pod mocą Judy, aż do dnia tego. Odstąpiło także i Lobne onegoż czasu.
Títí ó fi di òní, Edomu wà nínú ọ̀tẹ̀ lórí Juda, Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkókò kan náà.
23 A inne sprawy Joramowe, i wszystko co czynił, izali nie jest napisane w kronikach o królach Judzkich?
Gẹ́gẹ́ bí fún iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Jehoramu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
24 I zasnął Joram z ojcami swymi, a pogrzebiony jest z ojcami swymi w mieście Dawidowem; i królował Ochozyjasz, syn jego, miasto niego.
Jehoramu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi, Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
25 Roku dwunastego Jorama, syna Achaba, króla Izraelskiego, począł królować Ochozyjasz, syn Jorama, króla Judzkiego.
Ní ọdún méjìlá Joramu ọmọkùnrin Ahabu ọba Israẹli, Ahasiah ọmọkùnrin Jehoramu ọba Juda bẹ̀rẹ̀ ìjọba rẹ̀.
26 We dwudziestu i dwóch latach był Ochozyjasz, gdy królować począł, a rok jeden królował w Jeruzalemie; a imię matki jego było Atalija, córka Amrego, króla Izraelskiego.
Ahasiah jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní ọdún kan ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ a sì máa jẹ́ Ataliah, ọmọbìnrin Omri ọba Israẹli.
27 Ten chodził drogą domu Achabowego, i czynił złe przed oczyma Pańskiemi, jako i dom Achabowy; bo był zięciem domu Achabowego.
Nígbà tí ó rin ọ̀nà ilé Ahabu ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe, nítorí ó tan nípa ìgbéyàwó sí ìdílé Ahabu.
28 Przetoż wychadzał z Joramem, synem Achabowym, na wojnę przeciw Hazaelowi, królowi Syryjskiemu, do Ramot Galaadskiego; ale porazili Syryjczycy Jorama.
Ahasiah sì lọ pẹ̀lú Joramu ọmọ Ahabu lọ sí ogun lórí Hasaeli ọba Aramu ní Ramoti Gileadi. Àwọn ará Siria ṣẹ́ Joramu lẹ́sẹ̀.
29 A tak wrócił się król Joram, aby się leczył w Jezreelu na rany, które mu byli zadali Syryjczycy w Ramacie, gdy walczył z Hazaelem, królem Syryjskim. A Ochozyjasz, syn Jorama, króla Judzkiego, przyjechał nawiedzać Jorama, syna Achabowego, do Jezreela; bo tam chorował.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Joramu padà sí Jesreeli láti wo ọgbẹ́ rẹ̀ sàn tí ará Siria ti jẹ ní yà lórí rẹ̀ ní Ramoti ní ojú ogun rẹ̀ pẹ̀lú Hasaeli ọba Aramu. Nígbà náà Ahasiah ọmọ Jehoramu ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jesreeli láti lọ wo Joramu ọmọ Ahabu nítorí tí ó fi ara pa.

< II Królewska 8 >