< II Królewska 6 >

1 I rzekli synowie proroccy do Elizeusza: Oto miejsce, na którem mieszkamy przed tobą, ciasne jest dla nas.
Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Eliṣa pé, “Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa.
2 Niech idziemy proszę aż do Jordanu, a weźmiemy stamtąd każdy po jednem drzewie, i zbudujemy tam sobie miejsce ku mieszkaniu. Którym on rzekł: Idźcie.
Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jordani, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.” Ó sì wí pé, “Lọ.”
3 I rzekł jeden z nich: Pójdź proszę i ty z sługami twoimi. A on rzekł: I ja pójdę; i szedł z nimi.
Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Kí ó wù ọ́, èmí bẹ̀ ọ́, láti bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ?” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ,”
4 A przyszedłszy do Jordanu, rąbali drzewo.
Ó sì lọ pẹ̀lú wọn. Wọ́n sì lọ sí Jordani wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi.
5 I stało się, gdy jeden z nich obalał drzewo, że mu siekiera wpadła w wodę; i zawołał, mówiąc: Ach, ach, panie mój! i tać była pożyczona.
Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kígbe sókè pé, “O! Olúwa mi, mo yá a ni!”
6 Rzekł tedy mąż Boży: Gdzież upadła? i ukazał mu miejsce. A on uciąwszy drewno, wrzucił tam, i sprawił, że wypłynęła ona siekiera.
Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Eliṣa gé igi kan ó sì jù ú síbẹ̀, ó sì mú irin náà fò lójú omi.
7 I rzekł: Weźmij ją sobie; który ściągnąwszy rękę swą, wziął ją.
Ó wí pé, “Gbé e jáde.” Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.
8 A gdy król Syryjski walczył z Izraelem, i naradzał się z sługami swoimi, mówiąc: Na tem a na tem miejscu położy się wojsko moje;
Nísinsin yìí ọba Aramu wà ní ogun pẹ̀lú Israẹli ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbèrò, ó wí pé, “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”
9 Tedy posłał mąż Boży do króla Izraelskiego, mówiąc: Strzeż się, abyś nie przechodził przez ono miejsce; bo tam Syryjczycy są na zasadzce.
Ènìyàn Ọlọ́run rán iṣẹ́ sí ọba Israẹli pé, “Kíyèsi ara láti kọjá ní ibẹ̀ yẹn, nítorí pé ará Aramu wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ síbẹ̀.”
10 Przetoż posłał król Izraelski na ono miejsce, o którem mu był powiedział mąż Boży, i przestrzegł go, aby się go chronił, nie raz ani dwa.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli wo ibi tí ènìyàn Ọlọ́run náà fihàn, ní ẹ̀ẹ̀kan sí i Eliṣa kìlọ̀ fún ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó wà lórí sísọ ní ibẹ̀.
11 A tak zatrwożyło się serce króla Syryjskiego, dla tego. Przetoż zwoławszy sług swoich, rzekł do nich: Czemuż mi nie powiecie, kto wżdy z was donosi to królowi Izraelskiemu?
Èyí mú ọba Aramu bínú. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé ìwọ kò ní sọ fún mi èwo nínú wa ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọba Israẹli?”
12 I rzekł jeden z sług jego: Nie tak, królu, panie mój; ale Elizeusz prorok, który jest w Izraelu, oznajmuje królowi Izraelskiemu słowa, które mówisz w tajemnym pokoju twoim.
Ọ̀kan lára ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí pé, “Kò sí ọ̀kan nínú wa, olúwa ọba mi, ṣùgbọ́n Eliṣa, wòlíì tí ó wà ní Israẹli, sọ fún ọba Israẹli ọ̀rọ̀ gangan tí ó sọ nínú yàrá rẹ̀.”
13 A on rzekł: Idźcie, a dowiedzcie się, gdzie jest, abym posłał i pojmał go. I powiedziano mu, mówiąc: Oto jest w Dotanie.
Ọba pa á láṣẹ, “Lọ, kí ẹ lọ wo ibi tí ó wà, kí èmi kí ó lè rán ènìyàn láti lọ mú un wá.” Ìròyìn padà wá wí pé, “Ó wà ní Dotani.”
14 Przetoż posłał tam konie i wozy z wielkiem wojskiem, którzy przyciągnąwszy w nocy, oblegli miasto.
Nígbà náà ni ó rán àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ àti ogun ńlá tí ó le síbẹ̀. Wọ́n sì lọ ní alẹ́ wọ́n sì yí ìlú náà ká.
15 Tedy wstawszy rano sługa męża Bożego, wyszedł, a oto wojsko otoczyło miasto, i konie, i wozy. I rzekł sługa jego do niego: Ach panie mój! Cóż mamy czynić?
Nígbà tí ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run dìde ó sì jáde lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, ogun pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ wọn ti yí ìlú náà ká. “Yé è, olúwa mi! Kí ni kí àwa kí ó ṣe?” ìránṣẹ́ náà béèrè.
16 A on odpowiedział: Nie bój się; bo więcej ich z nami, niż z nimi.
“Má ṣe bẹ̀rù,” wòlíì náà dáhùn, “Àwọn tí ó wà pẹ̀lú wa, wọ́n pọ̀ ju àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn lọ.”
17 Modlił się tedy Elizeusz, i rzekł: O Panie, otwórz proszę oczy jego, żeby widział. I otworzył Pan oczy sługi onego, i ujrzał, a oto góra pełna koni, i wozy ogniste około Elizeusza.
Eliṣa sì gbàdúrà, “Olúwa, la ojú rẹ̀ kí ó ba à lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú ìránṣẹ́ náà, ó sì wò, ó sì rí òkè ńlá tí ó kún fún ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ iná gbogbo yí Eliṣa ká.
18 A gdy Syryjczycy szli do niego, modlił się Elizeusz Panu, mówiąc: Proszę, zaraź ten lud ślepotą. I zaraził je Pan ślepotą według słowa Elizeuszowego.
Bí àwọn ọ̀tá ṣe ń sọ̀kalẹ̀ wá níwájú rẹ, Eliṣa gbàdúrà sí Olúwa pé. “Bu ìfọ́jú lu àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti béèrè.
19 Wtem rzekł do nich Elizeusz: Nie tać to droga, ani to miasto. Pójdźcie za mną, a zawiodę was do męża, którego szukacie. I przywiódł je do Samaryi,
Eliṣa sọ fún wọn pé, “Èyí kì í ṣe ọ̀nà bẹ́ẹ̀ ni èyí kì í ṣe ìlú náà. Tẹ̀lé mi, èmi yóò mú u yín lọ sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin tí ẹ̀yin ń wá.” Ó sì sìn wọ́n lọ sí Samaria.
20 A gdy weszli do Samaryi, rzekł Elizeusz: O Panie, otwórz oczy tych, aby przejrzeli. I otworzył Pan oczy ich, i widzieli, że byli w pośród Samaryi.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n wọ ìlú náà, Eliṣa wí pé, “Olúwa, la ojú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kí wọn kí ó lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú wọn, wọ́n sì ríran, wọ́n sì wà níbẹ̀, nínú Samaria.
21 I rzekł król Izraelski do Elizeusza, gdy je ujrzał;
Nígbà tí ọba Israẹli rí wọn, ó béèrè lọ́wọ́ Eliṣa pé, “Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n, baba mi? Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n?”
22 Mamże je pobić, ojcze mój? Ale on rzekł: Nie bij. Azażeś je wziął przez miecz twój, albo przez łuk twój, żebyś je miał pobić? Połóż chleb i wodę przed nie, aby jedli i pili, i wrócili się do pana swego.
“Má ṣe pa wọ́n,” ó dáhùn. “Ṣé ìwọ yóò pa àwọn ọkùnrin tí ìwọ mú pẹ̀lú idà rẹ tàbí ọrun rẹ? Gbé oúnjẹ àti omi síwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ kí wọn sì mu, nígbà náà kí wọn padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn.”
23 A tak przygotował dla nich dostatek wielki, i jedli i pili; i puścił je, i odeszli do pana swego. I nie ważyły się więcej wojska Syryjskie wpadać do ziemi Izraelskiej.
Bẹ́ẹ̀ ni ó pèsè àsè ńlá fún wọn, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ tí wọ́n mu, ó sì rán wọn lọ, wọ́n sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ẹgbẹ́ láti Aramu dáwọ́ ìgbógunti ilẹ̀ Israẹli dúró.
24 Stało się potem, że zebrał Benadad, król Syryjski, wszystkie wojska swe, a przyciągnął i obległ Samaryję.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ni Beni-Hadadi ọba Aramu kó gbogbo àwọn ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì yan sókè wọ́n sì dúró ti Samaria.
25 Przetoż był głód wielki w Samaryi; albowiem ją było oblężono, tak, iż głowę oślą sprzedawano za ośmdziesiąt srebrników, a czwartą część miary gnoju gołębiego za pięć srebrników.
Ìyàn ńlá sì mú ní ìlú Samaria; wọ́n dúró tí ì tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń ta orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ní ọgọ́rùn-ún ìwọ̀n fàdákà àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n kábù imí ẹyẹlé, fún ìwọ̀n fàdákà márùn-ún.
26 I przydało się, gdy król Izraelski przechadzał się po murze, że jedna niewiasta zawołała nań mówiąc: Ratuj mię królu, panie mój!
Gẹ́gẹ́ bí ọba Israẹli ti ń kọjá lọ lórí odi, obìnrin kan sọkún sí i pé, “Ràn mí lọ́wọ́, olúwa ọba mi!”
27 Który rzekł: nie ratujeli cię Pan, skądże ja ciebie poratuję? izali z gumna, czyli z prasy?
Ọba sì dá a lóhùn pé, “Bí Olúwa kò bá gbà ọ́, níbo ni èmi yóò gbé ti gbà ọ́? Láti inú ilẹ̀ ìpakà, tàbí láti inú ibi ìfúntí?”
28 Nadto rzekł jej król: Cóż ci? A ona rzekła: Ta niewiasta rzekła do mnie: Daj syna twego, żebyśmy go zjadły dzisiaj, a jutro zjemy syna mego.
Nígbà náà ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Obìnrin yìí wí fún mi pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ ẹ́ lónìí, ní ọ̀la àwa yóò jẹ ọmọkùnrin tèmi.’
29 I uwarzyłyśmy syna mego, i zjadłyśmy go. Potem rzekłam jej dnia drugiego: Daj syna twego, abyśmy go zjadły; ale ona skryła syna swego.
Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe ọmọkùnrin mi a sì jẹ ẹ́. Ní ọjọ́ kejì mo wí fún un pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ,’ ṣùgbọ́n ó ti gbé e pamọ́.”
30 A gdy król usłyszał słowa onej niewiasty, rozdarł odzienie swe; a gdy się przechodził po murze, widział lud, że wór był na ciele jego od spodku.
Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ obìnrin náà, ó fa aṣọ rẹ̀ ya. Gẹ́gẹ́ bí ó sì ti ń kọjá lọ sí orí odi, àwọn ènìyàn wò ó níbẹ̀ ní abẹ́, ó ní aṣọ ọ̀fọ̀ ní ara rẹ̀.
31 Tedy rzekł król: To niechaj mi uczyni Bóg, i to przyczyni, jeźli się głowa Elizeusza, syna Safatowego, na nim dzisiaj ostoi.
Ó sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó fi ìyà jẹ mí, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ dájúdájú, pé orí ọmọkùnrin Eliṣa ọmọ Ṣafati kì ó wà ní ọrùn rẹ̀ ní òní!”
32 (A Elizeusz siedział w domu swoim, i starcy siedzieli z nim.) I posłał męża z tych, którzy przed nim stali; a pierwej, niż on poseł przyszedł do niego, rzekł był do starszych: Nie wiecież, iż posłał syn tego mężobójcę, aby ścięto głowę moję? Patrzcież, gdy przyjdzie ten poseł, a zamknijcież drzwi, a zahamujcie go przede drzwiami; boć tenten nóg pana jego jest już za nim.
Nísinsin yìí Eliṣa jókòó ní ilé rẹ̀ àwọn àgbàgbà náà jókòó pẹ̀lú rẹ̀. Ọba sì rán oníṣẹ́ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó tó dé ibẹ̀, Eliṣa sọ fún àwọn àgbàgbà pé, “Ṣé ẹ̀yin kò rí bí apànìyàn ti ń rán ẹnìkan láti gé orí mi kúrò? Ẹ wò ó, nígbà tí ìránṣẹ́ náà bá dé, ẹ ti ìlẹ̀kùn kí ẹ sì dìímú ṣinṣin ní ẹnu-ọ̀nà, ìró ẹsẹ̀ olúwa rẹ̀ kò ha wà lẹ́yìn rẹ?”
33 A gdy to jeszcze mówił z nimi, oto poseł przychodził ku niemu, i rzekł: Oto to złe jest od Pana; czegóż mam więcej oczekiwać od Pana?
Nígbà tí ó sì ń sọ̀rọ̀ sí wọn, ìránṣẹ́ náà sọ̀kalẹ̀ wá bá a. Ọba náà sì wí pé, “Ibi yìí láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni. Kí ni ó dé tí èmi yóò fi dúró de Olúwa sí i?”

< II Królewska 6 >