< II Królewska 5 >

1 A Naaman, hetman wojska króla Syryjskiego, był mąż wielki u pana swego, i osoba zacna. Albowiem przezeń dał był Pan wybawienie Syryjczykom; a ten mąż był duży w sile, ale trędowaty.
Naamani jẹ́ olórí ogun ọba Aramu. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ ni Olúwa ti fi ìṣẹ́gun fún Aramu. Òun jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
2 A z Syryi wyszła była swawolna kupa, która pojmała z ziemi Izraelskiej dzieweczkę nie wielką, a ta służyła żonie Naamanowej.
Nísinsin yìí ẹgbẹgbẹ́ láti Aramu ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Israẹli, ó sì sin ìyàwó Naamani.
3 Która rzekła do pani swej: O gdyby się pan mój dostał do proroka, który jest w Samaryi! pewnieby go uzdrowił od trądu jego.
Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samaria! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
4 Wszedł tedy Naaman, i oznajmił to panu swemu, mówiąc: Tak a tak mówiła dzieweczka, która jest z ziemi Izraelskiej.
Naamani lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Israẹli ti sọ.
5 Na co odpowiedział król Syryjski: Idź, wypraw się, a poślę list do króla Izraelskiego. A tak jechał, wziąwszy z sobą dziesięć talentów srebra, i sześć tysięcy złotych, i dziesięcioro szat odmiennych.
“Ní gbogbo ọ̀nà, lọ,” ọba Aramu dá a lóhùn pé, “Èmi yóò fi ìwé ránṣẹ́ sí ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni Naamani lọ, ó sì mú pẹ̀lú rẹ̀ tálẹ́ǹtì fàdákà mẹ́wàá, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìwọ̀n wúrà àti ìpààrọ̀ aṣọ mẹ́wàá.
6 I przyniósł list do króla Izraelskiego w te słowa: Jako cię prędko dojdzie ten list, wiedz, żem posłał do ciebie Naamana, sługę mego, abyś go uzdrowił od trądu jego.
Ìwé tí ó mú lọ sọ́dọ̀ ọba Israẹli kà pé, “Pẹ̀lú ìwé yìí èmi ń rán ìránṣẹ́ mi Naamani sí ọ pé o lè wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
7 A gdy przeczytał król Izraelski list, rozdarł odzienie swoje, mówiąc: Azażem ja jest Bóg, żebym mógł umorzyć i ożywić, iż ten do mnie śle, abym uzdrowił męża tego od trądu jego? Uważcie proszę, a obaczcie, że szuka przyczyny na mię.
Bí ọba Israẹli ti ka ìwé náà ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wí pé, “Èmi ha jẹ́ Ọlọ́run? Ǹjẹ́ èmi le pa kí n sì mú wá sí ààyè padà? Kí ni ó dé tí eléyìí rán ènìyàn sí mi láti wo ààrùn ẹ̀tẹ̀ rẹ sàn, kí ẹ wo bí ó ti ń wá ọ̀nà láti wá ìjà pẹ̀lú mi!”
8 Co gdy usłyszał Elizeusz, mąż Boży, iż rozdarł król Izraelski szaty swe, posłał do króla, mówiąc: Przeczżeś rozdarł szaty swe? Niech przyjdzie do mnie, a dowie się, że jest prorok w Izraelu.
Nígbà tí Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run gbọ́ pé ọba Israẹli ti ya aṣọ rẹ̀, ó sì rán iṣẹ́ yìí sí i pé, “Kí ni ó dé tí o fi fa aṣọ rẹ ya? Jẹ́ kí ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi. Òun yóò sì mọ̀ pé wòlíì wà ní Israẹli.”
9 A tak przyjechał Naaman z końmi swemi, i z wozem swym, i stanął u drzwi domu Elizeuszowego.
Bẹ́ẹ̀ ni Naamani sì lọ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀ àti kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Eliṣa.
10 I wysłał do niego Elizeusz posła, mówiąc: Idź, a omyj się siedm kroć w Jordanie, a przywrócić się zdrowie ciała twego, i będziesz oczyszczony.
Eliṣa rán ìránṣẹ́ láti lọ sọ fún un pé, “Lọ, wẹ̀ ara rẹ ní ìgbà méje ní odò Jordani, ẹran-ara rẹ yóò sì tún padà bọ̀ sípò, ìwọ yóò sì mọ́.”
11 Tedy rozgniewawszy się Naaman, brał się w drogę, mówiąc: Otom myślał sam u siebie, iż pewnie wynijdzie, a stanąwszy przy mnie, wzywać będzie imienia Pana, Boga swego, podniósłszy rękę swoję nad miejscem trądu, uzdrowi trędowatego.
Ṣùgbọ́n Naamani lọ pẹ̀lú ìbínú ó sì wí pé, “Mo lérò pé yóò sì dìde jáde wá nítòótọ́ sí mi, yóò sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run, fi ọwọ́ rẹ̀ lórí ibẹ̀ kí ó sì wo ẹ̀tẹ̀ mi sàn.
12 Azaż nie lepsze są rzeki Abana i Farfar w Damaszku nad wszystkie wody Izraelskie? izalibym się niemógł w nich omyć, abym się oczyścił! A tak obróciwszy się, odjeżdżał z gniewem.
Abana àti Fapari, odò Damasku kò ha dára ju gbogbo omi Israẹli lọ? Ṣé èmi kò le wẹ̀ nínú wọn kí n sì mọ́?” Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà, ó sì lọ pẹ̀lú ìrunú.
13 Ale przystąpiwszy słudzy jego, mówili do niego, i rzekli: Ojcze mój, gdybyć był co wielkiego ten prorok rozkazał, azażbyś nie miał tego uczynić? Jako daleko więcej, gdy rzekł: Omyj się, a będziesz czystym?
Ìránṣẹ́ Naamani lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi, tí wòlíì bá ti sọ fún ọ láti ṣe ohun ńlá kan, ṣé ìwọ kì bá ti ṣe, mélòó mélòó nígbà náà, nígbà tí ó sọ fún ọ pé, ‘Wẹ̀ kí o sì mọ́’!”
14 Przetoż szedłszy omył się w Jordanie siedm kroć według słowa męża Bożego; i stało się ciało jego, jako ciało dziecięcia małego, i oczyszczony jest.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ ó sì tẹ ara rẹ̀ bọ inú odò Jordani ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún un, ẹran-ara rẹ̀ sì tún padà sí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọkùnrin kékeré.
15 Potem się wrócił do męża Bożego, on i wszystek poczet jego, a przyszedłszy stanął przed nim, i rzekł: Otom teraz poznał, że nie masz Boga na wszystkiej ziemi, tylko w Izraelu; przetoż weźmij proszę te upominki od sługi twego.
Nígbà náà Naamani àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ padà lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Ó sì dúró níwájú rẹ̀ ó sì wí pé, “Nísinsin yìí èmi mọ̀ pé kò sí Ọlọ́run ní gbogbo àgbáyé àyàfi ní Israẹli nìkan. Jọ̀wọ́ gba ẹ̀bùn láti ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”
16 A on rzekł: Jako żywy Pan, przed którego obliczem stoję, że nic nie wezmę; a choć go przymuszał, aby wziął, przecię nie chciał.
Wòlíì náà dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ẹni tí mo ń sìn, èmi kò nígbà ohun kan,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Naamani rọ̀ ọ́ láti gbà á, ó kọ̀.
17 I rzekł Naaman: A nie chcesz? niechże będzie dane proszę słudze twemu brzemię ziemi na dwa muły; boć nie będzie więcej sprawował sługa twój całopalenia i innych ofiar bogom cudzym, jedno Panu.
Naamani wí pé, “Tí o kò bá nígbà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fi fún èmi ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹrù erùpẹ̀ tí ìbáaka méjì le rù, nítorí láti òní lọ ìránṣẹ́ rẹ kì yóò rú ẹbọ sísun àti rú ẹbọ sí ọ̀kan lára àwọn ọlọ́run mìíràn mọ́ bí kò ṣe sí Olúwa.
18 Wszakże w tej mierze niech odpuści Pan słudze swemu, gdy wchodzi pan mój do kościoła Remmon, aby się tam kłaniał, a wesprze się na ręce mojej, że się i ja kłaniam w kościele Remmon. Takowe moje kłanianie w kościele Remmon proszę niech odpuści Pan słudze twemu w tej mierze.
Ṣùgbọ́n kí Olúwa kí ó dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún nǹkan yìí. Nígbà tí ọ̀gá mi wọ inú ilé Rimoni láti fi orí balẹ̀ tí ó sì fi ara ti ọwọ́ mi tí mo sì tẹ ara mi ba pẹ̀lú níbẹ̀. Nígbà tí èmi tẹ ara mi ba ní ilé Rimoni, kí Olúwa dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún èyí.”
19 I rzekł mu: Idź w pokoju. A gdy odjechał od niego, jakoby na milę drogi,
Eliṣa wí pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Lẹ́yìn ìgbà tí Naamani tí rin ìrìnàjò tí ó jìnnà,
20 Rzekł Giezy, sługa Elizeusza, męża Bożego: Oto nie dopuścił pan mój temu Naamanowi Syryjskiemu, aby dał z ręki swej, co był przywiózł; jako żywy Pan, że pobieżę za nim, a wezmę co od niego.
Gehasi, ìránṣẹ́ Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run, ó wí fún ara rẹ̀ pé, “Ọ̀gá mi jẹ́ ẹni tí ó rọ́nú lórí Naamani, ará Aramu, nípa pé kò gba ohunkóhun ní ọwọ́ rẹ̀ ohun tí ó mú wá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, èmi yóò sá tẹ̀lé e èmi yóò sì gba ohun kan ní ọwọ́ rẹ̀.”
21 A tak bieżał Giezy za Naamanem. Którego ujrzawszy Naaman bieżącego za sobą, skoczył z wozu przeciw niemu, i rzekł: Dobrzeż się wszystko dzieje?
Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi sáré tẹ̀lé Naamani. Nígbà tí Naamani rí i tí ó ń sáré tẹ̀lé e, ó sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ̀. “Ṣé gbogbo nǹkan wà dáradára?” ó béèrè.
22 Któremu odpowiedział: Dobrze. Pan mój posłał mię, abym ci powiedział: Oto dopiero teraz przyszli do mnie dwaj młodzieńcy z góry Efraim z synów prorockich; dajże im proszę talent srebra, i dwie odmienne szaty.
“Gbogbo nǹkan wà dáradára,” Gehasi dá a lóhùn. “Ọ̀gá mi rán mi láti sọ wí pé, ‘Àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin méjì láti ọ̀dọ̀ ọmọ wòlíì wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi láti orí òkè ìlú ti Efraimu. Jọ̀wọ́ fún wọn ní ẹ̀bùn fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ méjì.’”
23 Tedy rzekł Naaman; Radniej weźmij dwa talenty. I przymusił go, i zawiązał dwa talenty srebra we dwa worki, i dwie odmienne szaty, i włożył na dwóch sług swoich, którzy nieśli przed nim.
Naamani wí pé, “Ní gbogbo ọ̀nà, mú ẹ̀bùn méjì.” Ó sì rọ Gehasi láti gbà wọ́n, ó sì di ẹ̀bùn méjì náà ti fàdákà ní inú àpò méjì, pẹ̀lú ìpààrọ̀ aṣọ méjì, ó sì fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì, wọ́n sì kó wọn lọ sọ́dọ̀ Gehasi.
24 A przyszedłszy na pagórek, wziął to z ręki ich, i złożył w niektórym domu, a męże one odprawił, i odeszli.
Nígbà tí Gehasi sì dé ibi ilé ìṣọ́, ó gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn, ó sì tó wọ́n sínú ilé, ó sì jọ̀wọ́ àwọn ọkùnrin náà lọ́wọ́ lọ, wọ́n sì jáde lọ.
25 Potem przyszedłszy stanął przed panem swym. I rzekł do niego Elizeusz: Skądże Giezy? A on odpowiedział: Nie chodził nigdzie sługa twój.
Nígbà náà ó sì wọlé wá ó sì dúró níwájú ọ̀gá rẹ̀ Eliṣa. “Níbo ni o ti wà Gehasi?” Eliṣa béèrè. “Ìránṣẹ́ rẹ kò lọ sí ibìkan kan.” Gehasi dá a lóhùn.
26 Ale mu on rzekł: Azaż serce moje nie chodziło z tobą, kiedy się obrócił on mąż z wozu swego przeciwko tobie? azaż czas był do brania srebra, i do brania szat, i oliwnic, i winnic, i bydła, i wołów, i sług, i służebnic?
Ṣùgbọ́n Eliṣa wí fún un pé, “Ẹ̀mí mi kò ha wà pẹ̀lú rẹ nígbà tí ọkùnrin náà sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ? Ṣé àsìkò tí ó yẹ láti gba owó nìyìí, tàbí láti gba aṣọ, ọgbà olifi, ọgbà àjàrà, àgùntàn, màlúù tàbí ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin?
27 Przetoż trąd Naamanowy przylgnie do ciebie, i do nasienia twego na wieki. I wyszedł od twarzy jego trędowaty, jako śnieg.
Ẹ̀tẹ̀ Naamani yóò lẹ̀ mọ́ ọ àti sí irú-ọmọ rẹ títí láé.” Nígbà náà Gehasi kúrò níwájú Eliṣa, ó sì di adẹ́tẹ̀, ó sì funfun gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.

< II Królewska 5 >