< Deuteronomy 4 >

1 Gbọ́ Israẹli, gbọ́ òfin àti ìlànà tí èmi yóò kọ́ ọ yín. Ẹ tẹ̀lé wọn kí ẹ ba à lè yè, kí ẹ ba à lè lọ láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín yóò fi fún un yín.
Och nu, Israel, hör de stadgar och rätter som jag vill lära eder, för att I mån göra efter dem, på det att I mån leva och komma in i och taga i besittning det land som HERREN, edra fäders Gud, vill giva eder.
2 Ẹ má ṣe fi kún àwọn ohun tí mo pàṣẹ fún un yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ yọ kúrò nínú wọn, ṣùgbọ́n ẹ pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín tí mo fún un yín mọ́.
I skolen icke lägga något till det som jag bjuder eder, och I skolen icke taga något därifrån; I skolen hålla HERRENS, eder Guds, bud, som jag giver eder.
3 Ẹ ti fi ojú ara yín rí ohun tí Olúwa ṣe ní Baali-Peori. Olúwa Ọlọ́run yín run gbogbo àwọn tí ó tẹ̀lé òrìṣà Baali-Peori kúrò ní àárín yín.
I haven med egna ögon sett vad HERREN har gjort i fråga om Baal-Peor, huru HERREN, din Gud, utrotade ur ditt folk var man som följde efter Baal-Peor.
4 Ṣùgbọ́n gbogbo ẹ̀yin tí ẹ gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run láìyẹsẹ̀ ni ẹ wà láààyè lónìí.
Men I som höllen eder till HERREN, eder Gud, I leven alla ännu i dag.
5 Ẹ kíyèsi i, mo ti kọ́ ọ yín ní àwọn òfin àti àṣẹ bí Olúwa Ọlọ́run mi ti pàṣẹ fún mi, kí ẹ ba à le tẹ̀lé wọn ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń lọ láti ní ní ìní.
Se, jag har lärt eder stadgar och rätter såsom HERREN, min Gud, har bjudit mig, på det att I mån göra efter dem i det land dit I nu kommen, för att taga det i besittning.
6 Ẹ máa kíyèsi wọn dáradára. Èyí ni yóò fi ọgbọ́n àti òye yín han àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn tí wọn yóò gbọ́ nípa àwọn ìlànà wọ̀nyí, tí wọn yóò sì máa wí pé, “Dájúdájú, orílẹ̀-èdè ńlá yìí kún fún ọgbọ́n àti òye.”
I skolen hålla dem och göra efter dem, ty det skall tillräknas eder såsom vishet och förstånd av andra folk. När de få höra alla dessa stadgar, skola säga: »I sanning, ett vist och förståndigt folk är detta stora folk.»
7 Orílẹ̀-èdè olókìkí wo ni ọlọ́run wọn tún súnmọ́ wọn, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti súnmọ́ wa nígbàkígbà tí a bá ń ké pè é?
Ty vilket annat stort folk finnes, vars gudar äro det så nära som HERREN, vår Gud, är oss, så ofta vi åkalla honom?
8 Orílẹ̀-èdè wo ló tún le lókìkí láti ní àwọn ìlànà òdodo, àti òfin gẹ́gẹ́ bí àwọn òfin wọ̀nyí tí mo ń gbé kalẹ̀ fún un yín lónìí.
Och vilket annat stort folk finnes, som har stadgar och rätter så rättfärdiga som hela denna lag, vilken jag i dag förelägger eder?
9 Kìkì i kí ẹ kíyèsára, kí ẹ sì ṣọ́ra a yín gidigidi kí ẹ má ba à gbàgbé àwọn ohun tí ojú yín ti rí, kí wọn má sì ṣe sá kúrò lóókan àyà yín níwọ̀n ìgbà tí ẹ sì wà láààyè. Ẹ máa fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ yín àti àwọn ọmọ wọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn wọn.
Allenast tag dig till vara och akta dig väl, så att du icke förgäter vad dina ögon sågo, och icke låter vika ifrån ditt hjärta i all dina livsdagar, utan kungör det för dina barn och dina barnbarn:
10 Ẹ rántí ọjọ́ tí ẹ dúró níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní Horebu, nígbà tí ó wí fún mi pé, “Kó àwọn ènìyàn wọ̀nyí jọ síwájú mi láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí wọ́n lè kọ́ láti máa bu ọlá náà fún mi ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá gbé lórí ilẹ̀ náà, kí wọ́n sì le è fi wọ́n kọ́ àwọn ọmọ wọn.”
vad som skedde den dag då du stod inför HERREN, din Gud, vid Horeb, då HERREN sade till mig: »Församla folket till mig, för att jag må låta dem höra mina ord; må de så lära sig att frukta mig, så länge de leva på jorden, och de lära sina barn detsamma.»
11 Ẹ̀yin súnmọ́ tòsí, ẹ sì dúró ní ẹsẹ̀ òkè náà, òkè náà sì ń jóná dé agbede-méjì ọrun, pẹ̀lú òkùnkùn, àti àwọsánmọ̀, àti òkùnkùn biribiri.
Och I trädden fram och blevo stående nedanför berget; och berget brann i eld ända upp till himmelen, och där var mörker, moln och töcken.
12 Olúwa sì bá yín sọ̀rọ̀ láti àárín iná náà wá. Ẹ gbọ́ àwọn ìró ohùn, ṣùgbọ́n ẹ kò rí ẹnikẹ́ni, ohùn nìkan ni ẹ gbọ́.
Och HERREN talade till eder ur elden orden hörden I, men I sågen ingen gestalt, I hörden allenast en röst.
13 Ó sọ àwọn májẹ̀mú rẹ̀ fún un yín àní àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó pàṣẹ fún un yín láti máa tẹ̀lé, ó sì kọ wọ́n sórí wàláà òkúta méjì.
Och han förkunnade eder sitt förbund, som han bjöd eder att hålla nämligen de tio orden; och han skrev dem på två stentavlor.
14 Olúwa sì pàṣẹ fún mi nígbà náà láti kọ yín ní ìlànà àti ìdájọ, kí ẹ̀yin kí ó lè máa ṣe wọ́n ní ilẹ̀ náà, ní ibi tí ẹ̀yin ń lọ láti gbà á.
Och mig bjöd HERREN då att jag skulle lära eder stadgar och rätter, för att I skullen göra efter dem i det land dit I nu dragen, till att taga det i besittning.
15 Ẹ kíyèsára gidigidi, torí pé, ẹ kò rí ìrísí ohunkóhun ní ọjọ́ tí Olúwa bá yín sọ̀rọ̀ ní Horebu láti àárín iná wá. Torí náà ẹ ṣọ́ra yín gidigidi,
Och eftersom I icke sågen någon gestalt den dag då HERREN talade till eder på Horeb ur elden, därför mån I nu noga hava akt på eder själva.
16 kí ẹ ma ba à ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe ère fún ara yín, àní ère lóríṣìíríṣìí yálà èyí tí ó ní ìrísí ọkùnrin tàbí tí obìnrin,
så att I icke tagen eder till, vad fördärvligt är, genom att göra eder någon beläte, något slags avgudabild, något bild av man eller av kvinna.
17 tàbí ti ẹranko orí ilẹ̀, tàbí ti ẹyẹ tí ń fò ní òfúrufú,
eller någon bild av något fyrfotadjur eller av någon bevingad fågel som flyger under himmelen,
18 tàbí ti àwòrán onírúurú ẹ̀dá tí ń fà lórí ilẹ̀, tàbí ti ẹja nínú omi.
eller av något kräldjur på marken eller av någon fisk i vattnet under jorden.
19 Bí ẹ bá wòkè tí ẹ rí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀: àwọn ohun tí a ṣe lọ́jọ̀ sójú ọ̀run, ẹ má ṣe jẹ́ kí wọ́n tàn yín jẹ dé bi pé ẹ̀yin yóò foríbalẹ̀ fún wọn, àti láti máa sin ohun tí Olúwa Ọlọ́run yín dá fún gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run.
Och när du lyfter dina ögon upp till himmelen och ser solen, månen och stjärnorna, himmelens hela härskara, då må du icke heller låta förföra dig att tillbedja dem och tjäna dem; ty HERREN, din Gud, har givit dem åt alla folk under hela himmelen till deras del.
20 Olúwa Ọlọ́run yín sì ti mú ẹ̀yin jáde kúrò nínú iná ìléru ńlá, àní ní Ejibiti, láti lè jẹ́ ènìyàn ìní i rẹ̀, bí ẹ̀yin ti jẹ́ báyìí.
Men eder har HERREN tagit, och han har fört eder ut ur smältugnen, ur Egypten, för att I skullen bliva hans arvfolk, såsom nu har skett.
21 Inú Olúwa ru sí mi nítorí yín, ó sì ti búra pé èmi kì yóò la Jordani kọjá, èmi kì yóò sì wọ ilẹ̀ rere tí Olúwa Ọlọ́run fi fún un yín, ní ìní yín.
Och HERREN vredgades på mig för eder skull, och svor att jag icke skulle få gå över Jordan och komma in i de goda land som HERREN, din Gud, vill giva dig till arvedel.
22 Èmi yóò kú ní ilẹ̀ yìí, èmi kì yóò la Jordani kọjá, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti fẹ́ rékọjá sí òdìkejì odò láti gba ilẹ̀ rere náà.
Ty jag skall dö i detta land och icke gå över Jordan, men I skolen gå över den och taga detta goda land i besittning.
23 Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín tí ó ti bá a yín dá. Ẹ má ṣe ṣe ère ní ìrísí ohunkóhun fún ara yín, èèwọ̀ ni Olúwa Ọlọ́run yín kà á sí.
Tagen eder då till vara för att förgäta det förbund som HERREN, eder Gud, har slutit med eder, därigenom att I, alldeles emot HERRENS, eder Guds, bud, gören eder något beläte, något slags bild.
24 Torí pé iná ajónirun ni Olúwa Ọlọ́run yín, Ọlọ́run owú ni.
Ty, HERREN, din Gud, är en förtärande eld, en nitälskande Gud.
25 Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ ti ní àwọn ọmọ àti àwọn ọmọ ọmọ, tí ẹ sì ti gbé ní ilẹ̀ yìí pẹ́, bí ẹ bá wá ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe irú ère yówù tó jẹ́, tí ẹ sì ṣe búburú lójú Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ sì mú un bínú.
Om nu så sker, när du har fått barn och barnbarn och I haven blivit gamla i landet, att I tagen eder till, vad fördärvligt är, genom att göra eder något beläte, något slags bild, så att I gören vad som är ont i HERRENS, din Guds, ögon och därmed förtörnen honom,
26 Mo pe ọ̀run àti ayé láti jẹ́rìí takò yín lónìí, pé kíákíá ni ẹ ó parun ní ilẹ̀ náà tí ẹ ń la Jordani kọjá lọ láti gbà. Ẹ kò ní pẹ́ ní ilẹ̀ náà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò run pátápátá.
då tager jag i dag himmel och jord till vittnen mot eder, att I med hast skolen förgås och utrotas ur det land dit I nu gån över Jordan, för att taga det i besittning; I skolen då icke längre leva där, utan skolen förvisso förgöras.
27 Olúwa yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn ènìyàn náà, àwọn díẹ̀ nínú yín ni yóò yè láàrín orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò fọ́n yín sí.
Och HERREN skall förströ eder bland folken, och allenast en ringa hop av eder skall bliva kvar bland de folk till vilka HERREN skall föra eder.
28 Ẹ ó sì máa sin ọlọ́run tí á fi ọwọ́ ènìyàn ṣe: tí wọ́n fi igi àti òkúta ṣe, èyí tí kò le ríran, gbọ́rọ̀, jẹun tàbí gbọ́ òórùn.
Och där skolen I tjäna gudar, gjorda av människohänder, gudar av trä och sten, som varken se eller höra eller äta eller lukta.
29 Bí ẹ̀yin bá wá Olúwa Ọlọ́run yín láti bẹ̀ ẹ́, ẹ ó ri i, bí ẹ bá wá a, pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà a yín.
Men när I där söken HERREN, din Gud, då skall du finna honom, om du frågar efter honom av allt ditt hjärta och av all din själ.
30 Bí ẹ bá wà nínú wàhálà, bí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ṣẹlẹ̀ sí yín, láìpẹ́ ẹ ó tún padà tọ Olúwa Ọlọ́run yín wá, ẹ ó sì gbọ́ tirẹ̀.
När du är i nöd och allt detta vederfares dig, i kommande dagar, då skall du vända åter till HERREN, din Gud, och höra hans röst.
31 Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín aláàánú ni, kò ní gbàgbé tàbí pa yín rẹ́ tàbí kó gbàgbé májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn baba ńlá yín, èyí tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ìbúra.
Ty HERREN, din Gud, är en barmhärtig Gud. Han skall icke förgäta eller fördärva dig; han skall icke förgäta det förbund han har ingått med dina fäder och med ed bekräftat.
32 Ẹ béèrè báyìí nípa ti àwọn ọjọ́ ìgbàanì ṣáájú kí a tó bí i yín, láti ìgbà tí Ọlọ́run ti dá ènìyàn sórí ilẹ̀ ayé. Ẹ béèrè láti igun ọ̀run kan sí èkejì. Ǹjẹ́ irú nǹkan olókìkí báyìí: ti ṣẹlẹ̀ rí? Ǹjẹ́ a ti gbọ́ irú u rẹ̀ rí?
Ty fråga framfarna tider, dem som hava varit före dig, från den dag då Gud skapade människor på jorden, fråga ifrån himmelens ena ända till den andra om någonsin något så stort som detta har skett, eller om man har hört talas om något som är detta likt,
33 Ǹjẹ́ àwọn ènìyàn mìíràn tí ì gbọ́ ohùn Ọlọ́run rí, tí ó sọ̀rọ̀ jáde láti inú iná, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti gbọ́ tí ẹ sì yè?
om något folk har hört Guds röst tala ur elden, såsom du har hört, och dock har blivit vid liv,
34 Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ti gbìyànjú àti mú orílẹ̀-èdè kan jáde kúrò nínú òmíràn fúnra rẹ̀ rí, nípa ìdánwò, nípa iṣẹ́ àmì, àti iṣẹ́ ìyanu nípa ogun, tàbí nípa ọwọ́ agbára tàbí nína apá, àti nípa ẹ̀rù ńlá: gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ṣe fún un yín ní Ejibiti ní ojú ẹ̀yin tìkára yín?
eller om någon gud har försökt att komma och hämta ett folk åt sig ut från ett annat folk, genom hemsökelser, tecken och under, genom krig, genom stark hand och uträckt arm, och genom stora, fruktansvärda gärningar, vilket allt HERREN, eder Guds, har gjort med eder i Egypten, inför dina ögon.
35 A fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn yín kí ẹ bá a lè gbà pé Olúwa ni Ọlọ́run. Kò sì sí ẹlòmíràn lẹ́yìn rẹ̀.
Du har själv fått se det, för att du skulle veta att HERREN är Gud, och ingen annan än han.
36 Ó jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ láti ọ̀run wá, láti kọ́ ọ yín. Ní ayé, ó fi iná ńlá rẹ̀ hàn yín, ẹ sì gbọ́ ohùn rẹ̀ láti àárín iná wá,
Från himmelen har han låtit dig höra sin röst för att undervisa dig, och på jorden har han låtit dig se sin stora eld, och du har hört hans ord ur elden.
37 torí pé ó fẹ́ràn àwọn baba ńlá yín, ó sì yan àwọn ọmọ wọn ní ipò lẹ́yìn wọn. Nípa ìwà láààyè àti nípa agbára ńlá rẹ̀ ni ó fi mú un yín kúrò ní Ejibiti.
Eftersom han nu älskade dina fäder och utvalde deras avkomlingar efter dem, och själv med sin stora kraft förde dig ut ur Egypten,
38 Láti lé àwọn orílẹ̀-èdè tí ó tóbi tí ó sì lágbára níwájú yín; láti le è mú un yín wá sí ilẹ̀ wọn kí ẹ lè jogún rẹ̀ bí ó ti rí lónìí.
och fördrev för dig folk som voro större och mäktigare än du, och lät dig komma in i deras land och gav det åt dig till arvedel, såsom nu har skett,
39 Ẹ gbà kí ẹ sì fi sọ́kàn lónìí pé Olúwa ni Ọlọ́run lókè ọ̀run lọ́hùn ún àti ní ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ níhìn-ín. Kò sí òmíràn mọ́.
därför skall du i dag veta och lägga på hjärtat att HERREN är Gud, uppe i himmelen och nere på jorden, han och ingen annan;
40 Ẹ pa àwọn ìlànà àti àṣẹ rẹ̀ mọ́ tí mo ń fún un yín lónìí; kí ó ba à le è yẹ yín, kí ẹ̀yin sì le è pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín ní gbogbo ìgbà.
och du skall hålla hans stadgar och bud, som jag i dag giver dig, på det att det må gå dig väl och dina barn efter dig, och på det att du må länge leva i det land som HERREN, din Gud, vill giva dig för all tid.
41 Mose sì ya àwọn ìlú mẹ́ta kan sọ́tọ̀ ní apá ìwọ̀-oòrùn Jordani.
Vid denna tid avskilde Mose tre städer på andra sidan Jordan, på östra sidan,
42 Kí apànìyàn kí ó lè máa sá síbẹ̀, tí ó bá ṣi ẹnìkejì rẹ̀ pa, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, àti pé bí ó bá sá sí ọ̀kan nínú ìlú wọ̀nyí kí ó lè là.
till vilka en dråpare skulle kunna fly, om han hade dräpt någon utan vett och vilja, och utan att förut hava burit hat till honom; om han flydde till någon av dessa städer, skulle han få bliva vid liv.
43 Àwọn ìlú mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà nìwọ̀nyí: Beseri ní ijù, ní ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, tí àwọn ọmọ Reubeni; Ramoti ní Gileadi, ti àwọn ọmọ Gadi àti Golani ní Baṣani, ti àwọn ará Manase.
De voro: Beser i öknen på slättlandet för Rubens stam, Ramot i Gilead för Gads stam och Golan i Basan för Manasse stam.
44 Èyí ni òfin tí Mose gbé kalẹ̀ fún àwọn ará Israẹli.
Och detta är den lag som Mose förelade Israels barn,
45 Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀rí, àti ìlànà àti ìdájọ́ tí Mose fi lélẹ̀ fún ún àwọn ọmọ Israẹli, lẹ́yìn tí wọ́n ti jáde kúrò ní Ejibiti.
dessa äro de vittnesbörd och stadgar och rätter som Mose föredrog för Israels barn, sedan de hade dragit ut ur Egypten,
46 Tí wọ́n sì wà ní ẹ̀bá àfonífojì Beti-Peori ní ìlà-oòrùn Jordani; ní ilẹ̀ Sihoni, ọba àwọn Amori tí ó jẹ ọba Heṣboni tí Mose àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun, bí wọ́n ṣe ń ti Ejibiti bọ̀.
på andra sidan Jordan i dalen, mitt emot Bet-Peor, i Sihons land, amoréernas konungs, som bodde i Hesbon, och som Mose och Israels barn slogo, när de hade dragit ut ur Egypten.
47 Wọ́n gba ilẹ̀ rẹ̀, àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani àwọn ọba Amori méjèèjì tí ń bẹ ní ìlà-oòrùn Jordani.
Ty de intogo hans land och Ogs land, konungens i Basan, amoréernas två konungars länder, på andra sidan Jordan, på östra sidan,
48 Ilẹ̀ wọ̀nyí bẹ̀rẹ̀ láti Aroeri ní etí odò Arnoni dé orí òkè Sirioni (èyí ni Hermoni).
från Aroer vid bäcken Arnons strand ända till berget Sion, det är Hermon,
49 Àti gbogbo aginjù ní ìlà-oòrùn Jordani títí dé Òkun Iyọ̀ ní ìsàlẹ̀ gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga.
och hela Hedmarken på andra sidan Jordan på östra sidan, ända till Hedmarkshavet, nedanför Pisgas sluttningar.

< Deuteronomy 4 >