< Deuteronomy 32 >

1 Fetísílẹ̀, ẹ̀yin ọ̀run, èmi yóò sọ̀rọ̀; ẹ gbọ́, ìwọ ayé, ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Lyssnen, I himlar, ty jag vill tala; och jorden höre min muns ord.
2 Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ ọ̀ mi máa rọ̀ bí òjò, kí àwọn ọ̀rọ̀ mi máa sọ̀kalẹ̀ bí ìrì, bí òjò wíníwíní sára ewéko tuntun, bí ọ̀wààrà òjò sára ohun ọ̀gbìn.
Såsom regnet drype min lära, såsom daggen flöde mitt tal, såsom rikligt regn på grönska och såsom en regnskur på gräsets brodd.
3 Èmi yóò kókìkí orúkọ Olúwa. Ẹyin títóbi Ọlọ́run wa!
Ty HERRENS namn vill jag förkunna; ja, given ära åt vår Gud.
4 Òun ni àpáta, iṣẹ́ ẹ rẹ̀ jẹ́ pípé, gbogbo ọ̀nà an rẹ̀ jẹ́ òdodo. Ọlọ́run olóòtítọ́ tí kò ṣe àṣìṣe kan, Ó dúró ṣinṣin, òdodo àti òtítọ́ ni òun.
Vår klippa -- ostraffliga äro hans gärningar, ty alla hans vägar äro rätta. En trofast Gud och utan svek, rättfärdig och rättvis är han.
5 Wọ́n ti ṣe iṣẹ́ ìbàjẹ́ sọ́dọ̀ ọ rẹ̀; fún ìtìjú u wọn, wọn kì í ṣe ọmọ rẹ̀ mọ́, ṣùgbọ́n ìran tí ó yí sí apá kan tí ó sì dorí kodò.
De åter handlade illa mot honom; de voro icke hans barn, utan en skam för Israel, det vrånga och avoga släktet!
6 Ṣé báyìí ni ẹ̀yin yóò ṣe san an fún Olúwa, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìgbọ́n ènìyàn? Ǹjẹ́ òun kọ́ ni baba yín, Ẹlẹ́dàá yín, tí ó dá a yín tí ó sì mọ yín?
Är det så du lönar HERREN, du dåraktiga och ovisa folk? Är han då icke din fader, som skapade dig? Han danade ju dig och beredde dig.
7 Rántí ìgbà láéláé; wádìí àwọn ìran tí ó ti kọjá. Béèrè lọ́wọ́ baba à rẹ yóò sì sọ fún ọ, àwọn àgbàgbà rẹ, wọn yóò sì ṣàlàyé fún ọ.
Tänk på de dagar som fordom voro; akta på förgångna släktens år. Fråga din fader, han skall förkunna dig det, dina äldste, de skola säga dig det.
8 Nígbà tí Ọ̀gá-ògo fi ogún àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, nígbà tí ó pín onírúurú ènìyàn, ó sì gbé ààlà kalẹ̀ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iye ọmọkùnrin Israẹli.
När den Högste gav arvslotter åt folken, när han fördelade människors barn, då utstakade han gränserna för folken efter antalet av Israels barn.
9 Nítorí ìpín Olúwa ni àwọn ènìyàn an rẹ̀, Jakọbu ni ìpín ìní i rẹ̀.
Ty HERRENS folk är hans del, Jakob är hans arvedels lott.
10 Ní aginjù ni ó ti rí i, ní aginjù níbi tí ẹranko kò sí. Ó yíká, ó sì tọ́jú rẹ̀, ó pa á mọ́ bí ẹyin ojú u rẹ̀.
Han fann honom i öknens land, i ödsligheten, där ökendjuren tjöto. Då tog han honom i sitt beskärm och sin vård, han bevarade honom såsom sin ögonsten.
11 Bí idì ti í ru ìtẹ́ rẹ̀ ti ó sì ń rábàbà sórí ọmọ rẹ̀, tí ó na ìyẹ́ apá rẹ̀ láti gbé wọn ki ó sì gbé wọn sórí ìyẹ́ apá rẹ̀.
Likasom en örn lockar sin avkomma ut till flykt och svävar upp ovanför sina ungar, så bredde han ut sina vingar och tog honom och bar honom på sina fjädrar.
12 Olúwa ṣamọ̀nà; kò sì sí ọlọ́run àjèjì pẹ̀lú rẹ̀.
HERREN allena ledsagade honom, och ingen främmande gud jämte honom.
13 Ó mú gun ibi gíga ayé ó sì fi èso oko bọ́ ọ. Ó sì jẹ́ kí ó mú oyin láti inú àpáta wá, àti òróró láti inú akọ òkúta wá.
Han förde honom fram över landets höjder och lät honom äta av markens gröda; han lät honom suga honung ur hälleberget och olja ur den hårda klippan.
14 Pẹ̀lú u wàràǹkàṣì àti wàrà àgùntàn àti ti àgbò ẹran àti pẹ̀lú ọ̀rá ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, pẹ̀lú àgbò irú u ti Baṣani tí ó sì mu ẹ̀jẹ̀ èso àjàrà, àní àti wáìnì.
Gräddmjölk av kor, söt mjölk av får, fett av lamm fick du ock, vädurar från Basan och bockar, därtill fetaste märg av vete; och av druvors blod drack du vin.
15 Jeṣuruni sanra tán ó sì tàpá; ìwọ sanra tán, ìwọ ki tan, ọ̀rá sì bò ọ́ tán. O kọ Ọlọ́run tí ó dá ọ o sì kọ àpáta ìgbàlà rẹ.
Då blev Jesurun fet och istadig; du blev fet och tjock och stinn. Han övergav Gud, sin skapare, och föraktade sin frälsnings klippa.
16 Wọ́n sì fi òrìṣà mú un jowú, ohun ìríra ni wọ́n fi mú un bínú.
Ja, de retade honom genom sina främmande gudar, med styggelser förtörnade de honom.
17 Wọ́n rú ẹbọ sí iwin búburú, tí kì í ṣe Ọlọ́run, ọlọ́run tí wọn kò mọ̀ rí, ọlọ́run tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ farahàn láìpẹ́, ọlọ́run tí àwọn baba yín kò bẹ̀rù.
De offrade åt onda andar, skengudar, åt gudar som de förut icke kände, nya, som nyss hade kommit till, och som edra fäder ej fruktade för.
18 Ìwọ kò rántí àpáta, tí ó bí ọ; o sì gbàgbé Ọlọ́run tí ó dá ọ.
Din klippa, som hade fött dig, övergav du, du glömde Gud, som hade givit dig livet.
19 Olúwa sì rí èyí ó sì kọ̀ wọ́n, nítorí tí ó ti bínú nítorí ìwà ìmúnibínú àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ.
När HERREN såg detta, förkastade han dem, ty han förtörnades på sina söner och döttrar.
20 Ó sì wí pé, “Èmi yóò pa ojú mi mọ́ kúrò lára wọn, èmi yóò sì wò ó bí ìgbẹ̀yìn in wọn yóò ti rí; nítorí wọ́n jẹ́ ìran alágídí, àwọn ọmọ tí kò sí ìgbàgbọ́ nínú wọn.
Han sade: »Jag vill fördölja mitt ansikte för dem, jag vill se vilket slut de få; ty ett förvänt släkte äro de, barn i vilka ingen trohet är.
21 Wọ́n fi mí jowú nípa ohun tí kì í ṣe Ọlọ́run, wọ́n sì fi ohun asán an wọn mú mi bínú. Èmi yóò mú wọn kún fún ìlara láti ọ̀dọ̀ àwọn tí kì í ṣe ènìyàn; èmi yóò sì mú wọn bínú láti ọ̀dọ̀ aṣiwèrè orílẹ̀-èdè.
De hava retat mig med gudar som icke äro gudar, förtörnat mig med de fåfängligheter de dyrka; därför skall jag reta dem med ett folk som icke är ett folk, med ett dåraktigt hednafolk skall jag förtörna dem.
22 Nítorí pé iná kan ràn nínú ìbínú mi, yóò sì jó dé ipò ikú ní ìsàlẹ̀. Yóò sì run ayé àti ìkórè e rẹ̀ yóò sì tiná bọ ìpìlẹ̀ àwọn òkè ńlá. (Sheol h7585)
Ty eld lågar fram ur min näsa, och den brinner ända till dödsrikets djup; den förtär jorden med dess gröda och förbränner bergens grundvalar. (Sheol h7585)
23 “Èmi yóò kó àwọn ohun búburú lé wọn lórí èmi ó sì na ọfà mi tán sí wọn lára.
Jag skall hopa olyckor över dem, alla mina pilar skall jag avskjuta på dem.
24 Èmi yóò mú wọn gbẹ, ooru gbígbóná àti ìparun kíkorò ni a ó fi run wọ́n. Pẹ̀lú oró ohun tí ń rákò nínú erùpẹ̀.
De skola utsugas av hunger och förtäras av feberglöd, av farsoter som bittert pina; jag skall sända över dem vilddjurs tänder och stoftkrälande ormars gift.
25 Idà ní òde, àti ẹ̀rù nínú ìyẹ̀wù, ni yóò run ọmọkùnrin àti wúńdíá. Ọmọ ẹnu ọmú àti arúgbó eléwú irun pẹ̀lú.
Ute skall svärdet förgöra deras barn, och inomhus skall förskräckelsen göra det: ynglingar såväl som jungfrur, spenabarn tillsammans med gråhårsmän.
26 Mo ní èmi yóò tú wọn ká èmi yóò sì mú ìrántí i wọn dà kúrò nínú àwọn ènìyàn,
Jag skulle säga: 'Jag vill blåsa bort dem, göra slut på deras åminnelse bland människor',
27 nítorí bí mo ti bẹ̀rù ìbínú ọ̀tá, kí àwọn ọ̀tá a wọn kí ó má ba à wí pé, ‘Ọwọ́ wa lékè ni; kì í sì í ṣe Olúwa ni ó ṣe gbogbo èyí.’”
om jag icke fruktade att deras fiender då skulle vålla mig grämelse, att deras ovänner skulle misstyda det, att de skulle säga: 'Vår hand var så stark, det var icke HERREN som gjorde allt detta.'»
28 Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí òye nínú wọn.
Ty ett rådlöst folk äro de, och förstånd finnes icke i dem.
29 Bí ó ṣe pé wọ́n gbọ́n, kí òye yìí sì yé wọn kí wọn ro bí ìgbẹ̀yìn wọn yóò ti rí!
Vore de visa, så skulle de begripa detta, de skulle första vilket slut de måste få.
30 Báwo ni ẹnìkan ṣe lè lé ẹgbẹ̀rún, tàbí tí ẹni méjì sì lè lé ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sá, bí kò ṣe pé àpáta wọn ti tà wọ́n, bí kò ṣe pé Olúwa wọn ti fi wọ́n tọrẹ?
Huru kunde en jaga tusen framför sig och två driva tiotusen på flykten, om icke deras klippa hade sålt dem, och om icke HERREN hade prisgivit dem?
31 Nítorí pé àpáta wọn kò dàbí àpáta wa, àní àwọn ọ̀tá wa tìkára wọn ń ṣe onídàájọ́.
Ty de andras klippa är icke såsom vår klippa; våra fiender kunna själva döma därom.
32 Igi àjàrà a wọn wá láti igi àjàrà Sodomu àti ti ìgbẹ́ ẹ Gomorra. Èso àjàrà wọn kún fún oró, ìdì wọn korò.
Ty av Sodoms vinträd är deras ett skott, det stammar från Gomorras fält; deras druvor äro giftiga druvor, deras klasar hava bitter smak.
33 Ọtí wáìnì wọn ìwọ ti dragoni ni, àti oró mímú ti ejò paramọ́lẹ̀.
Deras vin är drakars etter, huggormars gruvligaste gift.
34 “Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́ èmi kò sì fi èdìdì dì í ní ìṣúra mi?
Ja, sådant ligger förvarat hos mig, förseglat i mina förrådshus.
35 Ti èmi ni láti gbẹ̀san. Èmi yóò san án fún wọn ní àkókò tí ẹ̀ṣẹ̀ wọn yóò yọ; ọjọ́ ìdààmú wọn súnmọ́ etílé ohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”
Min är hämnden och vedergällningen, sparad till den tid då deras fot skall vackla. Ty nära är deras ofärds dag, och vad dem väntar kommer med hast.
36 Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tán tí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.
Ty HERREN skall skaffa rätt åt sitt folk, och över sina tjänare skall han förbarma sig, när han ser att deras kraft är borta, och att det är ute med alla och envar.
37 Yóò wí pé, “Òrìṣà wọn dà báyìí, àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,
Då skall han fråga: Var äro nu deras gudar, klippan till vilken de togo sin tillflykt?
38 ọlọ́run tí ó jẹ ọ̀rá ẹran ẹbọ wọn tí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn? Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n! Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!
Var äro de som åto deras slaktoffers fett och drucko deras drickoffers vin? Må de stå upp och hjälpa eder, må de vara edert beskärm.
39 “Wò ó báyìí pé, Èmi fúnra à mi, Èmi ni! Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi. Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè. Mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná, kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.
Sen nu att jag allena är det, och att ingen Gud finnes jämte mig. Jag dödar, och jag gör levande, jag har slagit, men jag helar ock. Ingen finnes, som kan rädda ur min hand.
40 Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé, Èmi ti wà láààyè títí láé,
Se, jag lyfter min hand upp mot himmelen, jag säger: Så sant jag lever evinnerligen:
41 nígbà tí mo bá pọ́n idà dídán mi àti tí mo bá sì fi ọwọ́ mi lé ìdájọ́, Èmi yóò san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá mi Èmi ó sì san fún àwọn tí ó kórìíra à mi.
när jag har vässt mitt ljungande svärd och min hand tager till att skipa rätt, då skall jag utkräva hämnd av mina ovänner och vedergällning av dem som hata mig.
42 Èmi yóò mú ọfà mu ẹ̀jẹ̀, nígbà tí idà mi bá jẹ ẹran: ẹ̀jẹ̀ ẹni pípa àti ẹni ìgbèkùn, láti orí àwọn aṣáájú ọ̀tá.”
Jag skall låta mina pilar bliva druckna av blod, och mitt svärd skall mätta sig av kött, av de slagnas och fångnas blod, av fiendehövdingars huvuden.
43 Ẹ yọ̀ ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ nítorí òun yóò gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀; yóò sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá a rẹ̀ yóò sì ṣe ètùtù fún ilẹ̀ àti ènìyàn rẹ̀.
Jublen, I hedningar, över hans folk, ty han hämnas sina tjänares blod, han utkräver hämnd av sina ovänner och bringar försoning för sitt land, för sitt folk.
44 Mose sì wá ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ òfin yìí ní etí àwọn ènìyàn náà, òun, àti Hosea ọmọ Nuni.
Och Mose kom med Hosea, Nuns son, och föredrog hela denna sång inför folket.
45 Nígbà tí Mose parí i kíka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí Israẹli.
Och när Mose hade föredragit alltsammans till slut för hela Israel,
46 Ó sọ fún un pé, “Ẹ gbé ọkàn an yín lé gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ láàrín yín lónìí, kí ẹ̀yin lè pàṣẹ fún àwọn ọmọ yín láti gbọ́rọ̀ àti láti ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí.
sade han till dem: »Akten på alla de ord som jag i dag gör till vittnen mot eder, så att I given edra barn befallning om dem, att de skola hålla alla denna lags ord och göra efter dem.
47 Wọn kì í ṣe ọ̀rọ̀ asán fún ọ, ìyè e yín ni wọ́n. Nípa wọn ni ẹ̀yin yóò gbé pẹ́ lórí ilẹ̀ tí ẹ̀yin ń gòkè e Jordani lọ láti gbà.”
Ty det är icke ett tomt ord, som ej angår eder, utan det gäller edert liv; och genom detta ord skolen I länge leva i det land dit I nu dragen över Jordan, för att taga det i besittning.»
48 Ní ọjọ́ kan náà, Olúwa sọ fún Mose pé,
Och HERREN talade till Mose på denna samma dag och sade:
49 “Gòkè lọ sí Abarimu sí òkè Nebo ní Moabu, tí ó kọjú sí Jeriko, kí o sì wo ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí mo ń fi fún àwọn ọmọ Israẹli, bí ìní i wọn.
»Stig upp här på Abarimberget, på berget Nebo i Moabs land, gent emot Jeriko, så skall du få se Kanaans land, som jag vill giva åt Israels barn till besittning.
50 Ní orí òkè tí ìwọ ń gùn lọ ìwọ yóò kùú níbẹ̀, kí a sì sin ọ́ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ, gẹ́gẹ́ bí arákùnrin in rẹ Aaroni ti kú ní orí òkè Hori tí a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn an rẹ̀.
Och du skall dö där på berget, dit du stiger upp, och du skall samlas till dina fäder, likasom din broder Aron dog på berget Hor och blev samlad till sina fäder;
51 Ìdí ni pé ẹ̀yin méjèèjì ṣẹ̀ sí mi láàrín àwọn ọmọ Israẹli ní ibi omi Meriba Kadeṣi ní aginjù Sini àti nítorí ẹ̀yin kò yà mí sí mímọ́ láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
detta därför att I handladen trolöst mot mig bland Israels barn vid Meribas vatten vid Kades, i öknen Sin, i det att I icke höllen mig helig bland Israels barn.
52 Nítorí náà, ìwọ yóò rí ilẹ̀ náà ní ọ̀kánkán, o kì yóò wọ inú rẹ̀ ilẹ̀ ti mo ti fi fún àwọn ọmọ Israẹli.”
Mitt framför dig skall du se landet; men du skall icke komma dit, in i det land som jag vill giva åt Israels barn.» Se Jesurun i Ordförkl

< Deuteronomy 32 >