< Deuteronomy 3 >

1 Lẹ́yìn èyí ní a yípadà tí a sì kọrí sí ọ̀nà tí ó lọ sí Baṣani, Ogu ọba Baṣani àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ ṣígun wá pàdé wa ní Edrei.
Sedan vände vi oss åt annat håll och drogo upp åt Basan till. Och Og, konungen i Basan, drog med allt sitt folk ut i strid mot oss, till Edrei.
2 Olúwa sọ fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀. Kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
Men HERREN sade till mig: »Frukta icke för honom, ty i din hand har jag givit honom och allt hans folk och honom på samma sätt som du gjorde med Sihon, amoréernas konung, som bodde i Hesbon.»
3 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wa fi Ogu ọba Baṣani àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lé wa lọ́wọ́. A kọlù wọ́n títí kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè.
Så gav HERREN, vår GUD, i vår hand också Og, konungen i Basan, och allt hans folk, och vi slogo honom och läto ingen av dem slippa undan.
4 Ní ìgbà náà ní a gba gbogbo àwọn ìlú rẹ̀. Kò sí ọ̀kankan tí a kò gbà nínú àwọn ọgọta ìlú tí wọ́n ní, gbogbo agbègbè Argobu, lábẹ́ ìjọba Ogu ní Baṣani.
Och vi intogo då alla hans städer, ingen stad fanns, som vi icke togo ifrån dem: sextio städer, hela landsträckan Argob, Ogs rike i Basan.
5 Gbogbo ìlú wọ̀nyí ní a mọ odi gíga yíká pẹ̀lú àwọn ìlẹ̀kùn àti irin. Ọ̀pọ̀ àwọn ìlú kéékèèké tí a kò mọ odi yíká sì tún wà pẹ̀lú.
Alla dessa städer voro befästa med höga murar, med portar och bommar. Därtill kom en stor mängd småstäder.
6 Gbogbo wọn ni a parun pátápátá gẹ́gẹ́ bí á ti ṣe sí Sihoni ọba Heṣboni, tí a pa gbogbo ìlú wọn run pátápátá: tọkùnrin tobìnrin àti àwọn ọmọ wọn.
Och vi gåvo dem till spillo, likasom vi hade gjort med Sihon, konungen i Hesbon; hela den manliga stadsbefolkningen gåvo vi till spillo, så ock kvinnor och barn.
7 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú wọn, fún ara wa.
Men all boskapen och rovet från städerna togo vi såsom byte.
8 Ní ìgbà náà ni a ti gba ilẹ̀ tí ó wà ní Jordani láti odò Arnoni, títí dé orí òkè Hermoni lọ́wọ́ àwọn ọba Amori méjèèjì wọ̀nyí.
Från amoréernas två konungar, som härskade på andra sidan Jordan, togo vi alltså då deras land, från bäcken Arnon ända till berget Hermon
9 (Àwọn ará Sidoni ń pe Hermoni ní Sirioni. Àwọn Amori sì ń pè é ní Seniri).
-- vilket av sidonierna kallas för Sirjon, men av amoréerna kallas för Senir --
10 Gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè olórí títẹ́ náà ni a gbà àti gbogbo Gileadi, àti gbogbo Baṣani, títí dé Saleka, àti Edrei, ìlú àwọn ọba Ogu ní ilẹ̀ Baṣani.
alla städerna på slätten och hela Gilead och hela Basan, ända till Salka och Edrei, städerna i Ogs rike, i Basan.
11 (Ogu tí í ṣe ọba Baṣani nìkan ni ó ṣẹ́kù nínú àwọn ará Refaimu. Ibùsùn rẹ̀ ni a fi irin ṣe, ó sì gùn ju ẹsẹ̀ bàtà mẹ́tàlá lọ ní gígùn àti ẹsẹ̀ bàtà mẹ́fà ní ìbú. Èyí sì wà ní Rabba ti àwọn Ammoni.)
Ty Og, konungen i Basan, var den ende som fanns kvar av de sista rafaéerna; hans gravkista, gjord av basalt, finnes, såsom känt är, i Rabba i Ammons barns land; den är nio alnar lång och fyra alnar bred, alnen beräknad efter längden av en mans underarm.
12 Nínú àwọn ilẹ̀ tí a gbà ní ìgbà náà, mo fún àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, ní ilẹ̀ tí ó wà ní àríwá Aroeri níbi odò Arnoni, pọ̀ mọ́ ìdajì ilẹ̀ òkè Gileadi pẹ̀lú gbogbo ìlú wọn.
När vi då hade intagit detta land, gav jag den del därav, som sträcker sig från Aroer vid bäcken Arnon, samt hälften av Gileads bergsbygd med dess städer åt rubeniterna och gaditerna.
13 Gbogbo ìyókù Gileadi àti gbogbo Baṣani, ní ilẹ̀ ọba Ogu ni mo fún ìdajì ẹ̀yà Manase. (Gbogbo agbègbè Argobu ni Baṣani tí a mọ̀ sí ilẹ̀ àwọn ará Refaimu.
Återstoden av Gilead och hela Basan, Ogs rike, gav jag åt ena hälften av Manasse stam, hela landsträckan Argob, hela Basan; detta kallas rafaéernas land.
14 Jairi ọ̀kan nínú àwọn ìran Manase gba gbogbo agbègbè Argobu títí dé ààlà àwọn ará Geṣuri àti àwọn ará Maakati; a sọ ibẹ̀ ní orúkọ rẹ̀ torí èyí ni Baṣani fi ń jẹ́ Hafoti-Jairi títí di òní.)
Jair, Manasses son, fick hela landsträckan Argob, ända till gesuréernas och maakatéernas område, och efter sitt eget namn kallade han landet -- nämligen Basan -- för Jairs byar, såsom det heter ännu i dag.
15 Mo sì fi Gileadi fún Makiri,
Och åt Makir gav jag Gilead.
16 ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Reubeni àti ọmọ Gadi ni mo fún ní ilẹ̀ láti Gileadi lọ dé odò Arnoni (àárín odò náà sì jẹ́ ààlà) títí ó fi dé odò Jabbok. Èyí tí i ṣe ààlà àwọn ará Ammoni.
Och åt rubeniterna och gaditerna gav jag landet från Gilead ända till Arnons dal, till dalens mitt -- den utgjorde gränsen -- och till bäcken Jabbok, som är Ammons barns gräns,
17 Pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah pẹ̀lú, àti Jordani gẹ́gẹ́ bí òpin ilẹ̀ rẹ̀, láti Kinnereti lọ títí dé Òkun pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah, àní Òkun Iyọ̀, ní ìsàlẹ̀ àwọn orísun Pisga ní ìhà ìlà-oòrùn.
vidare Hedmarken med Jordan, som utgör gränsen, från Kinneret ända till Pisgas sluttningar, på östra sidan.
18 Mo pàṣẹ fún un yín ní ìgbà náà pé, “Olúwa Ọlọ́run yín ti fi ilẹ̀ yìí fún un yín láti ní i. Ṣùgbọ́n, gbogbo àwọn ọkùnrin yín tí ó lera tí wọ́n sì ti dira ogun, gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín: ará Israẹli.
Och jag bjöd eder på den tiden och sade: »HERREN, eder Gud, har givit eder detta land till besittning. Men nu skolen alla I som ären stridbara män draga väpnade åstad i spetsen för edra bröder, Israels barn.
19 Àwọn ẹ̀yà a yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ohun ọ̀sìn in yín (mo mọ̀ pé ẹ ti ní ohun ọ̀sìn púpọ̀) lè dúró ní àwọn ìlú tí mo fi fún un yín,
Allenast edra hustrur och barn och eder boskap -- jag vet ju att I haven mycken boskap -- må stanna kvar i de städer som jag har givit eder,
20 títí di ìgbà tí Olúwa yóò fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi bí ó ti fún un yín, àti ìgbà tí àwọn náà yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún wọn ní ìhà kejì Jordani. Nígbà náà ni ọ̀kọ̀ọ̀kan yín tó lè padà lọ sí ìní rẹ̀ tí mo fún un.”
till dess att HERREN har låtit edra bröder komma till ro, såväl som eder, när också de hava tagit i besittning det land som HERREN, eder Gud, vill giva dem på andra sidan Jordan; sedan mån I vända tillbaka till de besittningar jag har givit eder, var och en till sin besittning.»
21 Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún Joṣua pé, “Ìwọ tí fi ojú rẹ rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ṣe sí àwọn ọba méjèèjì wọ̀nyí. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò ṣe sí àwọn ilẹ̀ ọba tí ẹ̀yin n lọ.
Och jag bjöd Josua på den tiden och sade: »Du har med egna ögon sett allt vad HERREN, eder Gud, har gjort med dessa två konungar. På samma sätt skall HERREN göra med alla riken där du drager fram.
22 Ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, Olúwa Ọlọ́run yín tìkára rẹ̀ ni yóò jà fún un yín.”
Frukten icke för dem, ty HERREN, eder Gud, skall själv strida för eder.»
23 Nígbà náà ni mo bẹ Olúwa wí pé,
Och på den tiden bad jag till HERREN och sade:
24 “Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí bẹ̀rẹ̀ sí fi títóbi rẹ àti ọwọ́ agbára rẹ han ìránṣẹ́ rẹ. Ọlọ́run wo ló tó bẹ́ẹ̀ láyé àti lọ́run tí ó lè ṣe àwọn iṣẹ́ agbára ńlá tí o ti ṣe?
»Herre, HERRE, du har begynt att låta sin tjänare se din storhet och din starka hand; ty vilken är den gud i himmelen eller på jorden, som kan göra sådana verk och sådana väldiga gärningar som du?
25 Jẹ́ kí n kọjá lọ wo ilẹ̀ rere ti ìkọjá Jordani, ilẹ̀ òkè dídára nì àti Lebanoni.”
Så låt mig nu få gå ditöver och se det goda landet på andra sidan Jordan, det goda berglandet där och Libanon.»
26 Ṣùgbọ́n torí i tiyín, Olúwa Ọlọ́run bínú sí mi kò sì gbọ́ tèmi. Olúwa sọ wí pé, “Ó tó gẹ́ẹ́, ìwọ kò gbọdọ̀ sọ ohunkóhun lórí ọ̀rọ̀ yìí sí mi mọ́.
Men HERREN hade blivit förgrymmad på mig för eder skull och ville icke höra mig, utan sade till mig: »Låt det vara nog; tala icke vidare till mig om denna sak.
27 Gòkè lọ sí orí òkè Pisga, sì wò yíká ìwọ̀-oòrùn, ìlà-oòrùn, àríwá àti gúúsù. Fi ojú ara rẹ wo ilẹ̀ náà níwọ̀n bí ìwọ kò tí ní kọjá Jordani yìí.
Stig nu upp på toppen av Pisga, och lyft upp dina ögon mot väster och norr och söder och öster, och se med dina ögon; ty över denna Jordan skall du icke komma.
28 Ṣùgbọ́n yan Joṣua, kí o sì gbà á níyànjú, mú un lọ́kàn le, torí pé òun ni yóò síwájú àwọn ènìyàn wọ̀nyí kọjá, yóò sì jẹ́ kí wọn jogún ilẹ̀ náà tí ìwọ yóò rí.”
Och insätt Josua i hans ämbete, och styrk honom att vara frimodig och oförfärad; ty det är han som skall gå ditöver i spetsen för detta folk, och det är han som skall utskifta åt dem såsom arv det land du ser.»
29 Báyìí ni a dúró ní àfonífojì ní ẹ̀bá Beti-Peori.
Och så stannade vi i dalen mitt emot Bet-Peor.

< Deuteronomy 3 >