< 1 Kings 9 >

1 Nígbà tí Solomoni sì parí kíkọ́ ilé Olúwa àti ààfin ọba, tí ó sì ti ṣe gbogbo nǹkan tí ó ń fẹ́ láti ṣe,
Kiedy Salomon ukończył budowę domu PANA i domu królewskiego oraz wszystkiego, czego pragnął i co chciał wykonać;
2 Olúwa sì farahàn Solomoni ní ìgbà kejì, bí ó ti farahàn án ní Gibeoni.
PAN ukazał się Salomonowi po raz drugi, podobnie jak mu się ukazał w Gibeonie.
3 Olúwa sì wí fún un pé, “Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ tí ìwọ ti bẹ̀ níwájú mi, mo ti ya ilé yìí sí mímọ́, tí ìwọ ti kọ́, nípa fífi orúkọ mi síbẹ̀ títí láé. Ojú mi àti ọkàn mi yóò wà níbẹ̀ nígbà gbogbo.
PAN przemówił do niego: Wysłuchałem twojej modlitwy i prośby, które zanosiłeś przede mną. Poświęciłem ten dom, który zbudowałeś, aby tam przebywało moje imię na wieki. Tam będą moje oczy i serce po wszystkie dni.
4 “Bí ìwọ bá rìn níwájú mi ní ọkàn òtítọ́ àti ìdúró ṣinṣin, bí i Dafidi baba rẹ ti rìn, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí mo ti paláṣẹ fún ọ àti kí o sì pa àṣẹ mi àti òfin mi mọ́,
A jeśli będziesz postępował wobec mnie tak, jak postępował twój ojciec Dawid, w doskonałości serca i prawości, i będziesz czynił wszystko, co ci nakazałem, i będziesz przestrzegał moich nakazów i praw;
5 Èmi yóò fi ìdí ìtẹ́ ìjọba rẹ múlẹ̀ lórí Israẹli títí láé, bí mo ti ṣe ìlérí fún Dafidi baba rẹ nígbà tí mo wí pé, ‘Ìwọ kì yóò kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
Wtedy utwierdzę tron twego królestwa nad Izraelem na wieki, jak obiecałem Dawidowi, twemu ojcu, mówiąc: Nie zabraknie ci potomka na tronie Izraela.
6 “Ṣùgbọ́n tí ìwọ tàbí àwọn ọmọ rẹ bá yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ẹ kò sì pa òfin mi mọ́ àti àṣẹ mi tí mo ti fi fún ọ, tí ẹ sì lọ láti sin ọlọ́run mìíràn, tí ẹ sì ń sìn wọ́n,
Jeśli jednak wy lub wasi synowie zupełnie odwrócicie się ode mnie i nie będziecie strzec moich przykazań [i] nakazów, które wam dałem, ale pójdziecie służyć innym bogom, i będziecie im oddawać pokłon;
7 nígbà náà ni èmi yóò ké Israẹli kúrò ní ilẹ̀ tí èmi fi fún wọn, èmi yóò sì kọ ilé yìí tí èmi ti yà sí mímọ́ fún orúkọ mi. Nígbà náà ni Israẹli yóò sì di òwe àti ìmúṣẹ̀sín láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè.
Wtedy wytracę Izraela z ziemi, którą mu dałem, a dom, który poświęciłem swojemu imieniu, odrzucę sprzed swojego oblicza. Izrael zaś będzie [przedmiotem] przypowieści i pośmiewiskiem u wszystkich narodów.
8 Àti ilé yìí tí ó ga, ẹnu yóò sì ya olúkúlùkù ẹni tí ó kọjá lẹ́bàá rẹ̀, yóò sì pòṣé, wọn ó sì wí pé, ‘Èéṣe tí Olúwa fi ṣe irú nǹkan yìí sí ilẹ̀ yìí àti ilé yìí?’
A temu domowi, który był wyniosły, każdy przechodzący obok zdziwi się i świśnie. I będą pytać: Dlaczego PAN uczynił tak tej ziemi i temu domowi?
9 Àwọn ènìyàn yóò sì dáhùn wí pé, ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, tí ó mú àwọn baba wọn jáde láti Ejibiti wá, wọ́n sì ti gbá ọlọ́run mìíràn mú, wọ́n ń bọ wọ́n, wọ́n sì ń sìn wọ́n, ìdí nìyìí tí Olúwa ṣe mú gbogbo ìjàǹbá yìí wá sórí wọn.’”
Wtedy odpowiedzą: Ponieważ opuścili PANA, swego Boga, który wyprowadził ich ojców z ziemi Egiptu, a uchwycili się innych bogów, oddawali im pokłon i służyli im. Dlatego PAN sprowadził na nich całe to nieszczęście.
10 Lẹ́yìn ogún ọdún, nígbà tí Solomoni kọ́ ilé méjèèjì yìí tan: ilé Olúwa àti ààfin ọba.
A po upływie dwudziestu lat, w [czasie] których Salomon zbudował oba domy, dom PANA i dom królewski;
11 Solomoni ọba sì fi ogún ìlú ní Galili fún Hiramu ọba Tire, nítorí tí Hiramu ti bá a wá igi kedari àti igi firi àti wúrà gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìfẹ́ rẹ̀.
([A] Hiram, król Tyru, dostarczał Salomonowi drzew cedrowych i drzew cyprysowych, i złota, ile tylko chciał), król Salomon dał Hiramowi dwadzieścia miast w ziemi galilejskiej.
12 Ṣùgbọ́n nígbà tí Hiramu sì jáde láti Tire lọ wo ìlú tí Solomoni fi fún un, inú rẹ̀ kò sì dùn sí wọn.
Hiram wyruszył więc z Tyru, aby obejrzeć miasta, które dał mu Salomon, ale mu się nie spodobały.
13 Ó sì wí pé, “Irú ìlú wo nìwọ̀nyí tí ìwọ fi fún mi, arákùnrin mi?” Ó sì pè wọ́n ní ilẹ̀ Kabulu títí fi di òní yìí.
I zapytał: Cóż to za miasta, które mi dałeś, mój bracie? I nazwał je ziemią Kabul, i [nazywają się tak] aż do dziś.
14 Hiramu sì ti fi ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà ránṣẹ́ sí ọba.
Hiram bowiem posłał królowi sto dwadzieścia talentów złota.
15 Ìdí àwọn asìnrú ti Solomoni ọba kójọ ni èyí; láti kọ́ ilé Olúwa àti ààfin òun tìkára rẹ̀; Millo, odi Jerusalẹmu, Hasori, Megido àti Geseri.
A to [była] przyczyna poboru do robót, który król Salomon rozkazał na budowę domu PANA, swojego domu, Millo, muru Jerozolimy, Chasor, Megiddo i Gezer.
16 Farao ọba Ejibiti sì ti kọlu Geseri, ó sì ti fi iná sun ún, ó sì pa àwọn ará Kenaani tí ń gbé ìlú náà, ó sì fi ta ọmọbìnrin rẹ̀, aya Solomoni lọ́rẹ.
Faraon [bowiem], król Egiptu, wyruszył i zdobył Gezer, i spalił je ogniem, a Kananejczyków, którzy mieszkali w tym mieście, wymordował, i dał je w posagu swojej córce, żonie Salomona.
17 Solomoni sì tún Geseri kọ́, àti Beti-Horoni ìsàlẹ̀,
Salomon odbudował więc Gezer i Bet-Choron dolne;
18 àti Baalati àti Tadmori ní aginjù, láàrín rẹ̀,
Baalat i Tadmor na pustyni w tej ziemi;
19 àti gbogbo ìlú ìṣúra tí Solomoni ní, àti ìlú kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ìlú fún àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, àti èyí tí ó ń fẹ́ láti kọ́ ní Jerusalẹmu, ní Lebanoni àti ní gbogbo ilẹ̀ ìjọba rẹ̀ tí ó ń ṣe àkóso.
I wszystkie miasta spichlerze, które należały do Salomona, miasta dla rydwanów i miasta dla jeźdźców [oraz wszystko], co Salomon pragnął wybudować w Jerozolimie, Libanie i całej ziemi swego panowania.
20 Gbogbo ènìyàn tí ó kù nínú àwọn ará Amori ará Hiti, Peresi, Hifi àti Jebusi, àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ará Israẹli,
Wszystkie ludy, które ocalały spośród Amorytów, Chetytów, Peryzzytów, Chiwwitów i Jebusytów, które nie były z synów Izraela;
21 ìyẹn ni pé àwọn ọmọ wọn tí ó kù ní ilẹ̀ náà, tí àwọn ọmọ Israẹli kò le parun pátápátá, àwọn ni Solomoni bu iṣẹ́ ẹrú fún títí di òní yìí.
[Mianowicie] potomstwo tych, którzy pozostali po nich w ziemi, których synowie Izraela nie mogli wytracić, Salomon obciążył pracą przymusową aż do dziś.
22 Ṣùgbọ́n, Solomoni kò fi ẹnìkankan ṣe ẹrú nínú àwọn ọmọ Israẹli; àwọn ni ológun rẹ̀ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ìjòyè rẹ̀, àti àwọn balógun rẹ̀, àti àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ àti ti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
Lecz spośród synów Izraela Salomon nikogo nie uczynił niewolnikiem, byli tylko żołnierzami, jego sługami, dostojnikami, oficerami oraz dowódcami jego rydwanów i jeźdźców.
23 Àwọn sì tún ni àwọn olórí olùtọ́jú tí wọ́n wà lórí iṣẹ́ Solomoni, àádọ́ta dín lẹ́gbẹ̀ta, ní ń ṣe àkóso lórí àwọn ènìyàn tí ń ṣe iṣẹ́ náà.
Naczelnych przełożonych, którzy nadzorowali pracę dla Salomona, [było] pięciuset pięćdziesięciu. Oni to kierowali ludźmi, którzy wykonywali pracę.
24 Lẹ́yìn ìgbà tí ọmọbìnrin Farao ti gòkè láti ìlú Dafidi wá sí ààfin tí Solomoni kọ́ fún un, nígbà náà ni ó kọ́ Millo.
Gdy tylko córka faraona przeprowadziła się z miasta Dawida do swego domu, który jej zbudował [Salomon], wtedy zbudował Millo.
25 Nígbà mẹ́ta lọ́dún ni Solomoni ń rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà lórí pẹpẹ tí ó tẹ́ fún Olúwa, ó sì sun tùràrí níwájú Olúwa pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni ó parí ilé náà.
Trzy razy w roku Salomon składał całopalenia i ofiary pojednawcze na ołtarzu, który zbudował dla PANA, a spalał kadzidło na [ołtarzu], który był przed PANEM. Tak ukończył dom.
26 Solomoni ọba sì túnṣe òwò ọkọ̀ ní Esioni-Geberi, tí ó wà ní ẹ̀bá Elati ní Edomu, létí Òkun Pupa.
Król Salomon zbudował też okręty w Esjon-Geber koło Elat, nad brzegiem Morza Czerwonego, w ziemi Edomu.
27 Hiramu sì rán àwọn ènìyàn rẹ̀, àwọn atukọ̀ tí ó mọ Òkun, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ Solomoni.
I Hiram posłał na tych okrętach swoje sługi, żeglarzy obeznanych z morzem, razem ze sługami Salomona;
28 Wọ́n sì dé Ofiri, wọ́n sì mú irinwó ó lé ogún tálẹ́ǹtì wúrà, tí wọ́n ti gbà wá fún Solomoni ọba.
Przypłynęli oni do Ofiru i wzięli stamtąd czterysta dwadzieścia talentów złota, i przywieźli [je] do króla Salomona.

< 1 Kings 9 >