< 1 Kings 10 >

1 Nígbà tí ayaba Ṣeba gbọ́ òkìkí Solomoni àti ì bà ṣe pọ̀ rẹ̀ ní ti orúkọ Olúwa, ó sì wá láti dán an wò pẹ̀lú ìbéèrè líle.
A gdy królowa Saby usłyszała o sławie Salomona [i] o imieniu PANA, przybyła, aby go przez zagadki poddać próbie.
2 Ó sì wá sí Jerusalẹmu pẹ̀lú ẹgbẹ́ èrò ńlá ńlá, pẹ̀lú ìbákasẹ tí ó ru tùràrí, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ wúrà, àti òkúta iyebíye, ó sì wá sí ọ̀dọ̀ Solomoni, ó sì bá a sọ gbogbo èyí tí ń bẹ ní ọkàn rẹ̀.
Przybyła do Jerozolimy z bardzo wielkim orszakiem, z wielbłądami niosącymi wonności, bardzo dużo złota i drogocenne kamienie. Gdy przyszła do Salomona, rozmawiała z nim o wszystkim, co leżało jej na sercu.
3 Solomoni sì dáhùn gbogbo ìbéèrè rẹ̀; kò sì sí èyí tí ó ṣòro fún ọba láti ṣàlàyé fún un.
Salomon zaś odpowiedział na wszystkie jej pytania. Nie było nic nieznanego królowi, czego nie mógłby jej odpowiedzieć.
4 Nígbà tí ayaba Ṣeba sì rí gbogbo ọgbọ́n Solomoni àti ààfin tí ó ti kọ́.
Gdy więc królowa Saby ujrzała całą mądrość Salomona i dom, który zbudował;
5 Oúnjẹ tí ó wà lórí i tábìlì rẹ̀, ìjókòó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti ìdúró àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti ìwọṣọ wọn, àwọn agbọ́tí rẹ̀, àti ẹbọ sísun tí ó sun ní ilé Olúwa, kò sì sí ẹ̀mí kan nínú rẹ̀ mọ́!
A także potrawy jego stołu, siadanie jego sług, stawanie jego służących, ich szaty, jego podczaszych oraz schody, po których wstępował do domu PANA, dech zamarł jej [w piersi];
6 Ó sì wí fún ọba pé, “Òtítọ́ ni ìròyìn tí mo gbọ́ ní orílẹ̀-èdè mi ní ti iṣẹ́ rẹ àti ọgbọ́n rẹ.
Wtedy przemówiła do króla: Prawdziwa była ta wieść, którą słyszałam w swojej ziemi o twoich dziełach i twojej mądrości.
7 Ṣùgbọ́n èmi kò sì gba nǹkan wọ̀nyí gbọ́ títí ìgbà tí mo wá, tí mo sì fi ojú ara mi rí i. Sì kíyèsi i, a kò sọ ìdajì wọn fún mi; ìwọ sì ti fi ọgbọ́n àti ìrora kọjá òkìkí tí mo gbọ́.
Jednak nie wierzyłam tym słowom, aż przybyłam i zobaczyłam [to] na własne oczy. I oto nie powiedziano mi nawet połowy. Twoja mądrość i [twój] dobrobyt są większe od sławy, o której słyszałam.
8 Báwo ni inú àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe dùn tó! Báwo ni inú dídùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí wọ́n ń dúró níwájú rẹ nígbà gbogbo, tí wọ́n sì ń gbọ́ ọgbọ́n rẹ!
Błogosławieni twoi ludzie, błogosławieni twoi słudzy, którzy zawsze stoją przed tobą i słuchają twojej mądrości.
9 Ìbùkún ni fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó ní inú dídùn sí ọ, tí ó sì gbé ọ ka orí ìtẹ́ Israẹli. Nítorí tí Olúwa fẹ́ràn Israẹli títí láé, ni ó ṣe fi ọ́ jẹ ọba, láti ṣe ìdájọ́ àti òdodo.”
Niech będzie błogosławiony PAN, twój Bóg, który cię sobie upodobał, aby cię posadzić na tronie Izraela; a ponieważ PAN umiłował Izraela na wieki, ustanowił cię królem, abyś czynił sąd i sprawiedliwość.
10 Ó sì fún ọba ní ọgọ́fà tálẹ́ǹtì wúrà, tùràrí olóòórùn dídùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, àti òkúta iyebíye. Kò sí irú ọ̀pọ̀lọpọ̀ tùràrí tí a mú wá tí ó dàbí irú èyí tí ayaba Ṣeba fi fún Solomoni ọba.
Następnie dała królowi sto dwadzieścia talentów złota i bardzo wiele wonności oraz drogocennych kamieni. Nigdy więcej nie przyniesiono tyle wonności, ile królowi Salomonowi dała królowa Saby.
11 (Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ọ̀wọ́-ọkọ̀ Hiramu tí ó mú wúrà láti Ofiri wá, wọ́n mú igi algumu lọ́pọ̀lọ́pọ̀ àti òkúta oníyebíye láti Ofiri wá.
Ponadto okręty Hirama, które przywoziły złoto z Ofiru, przywiozły także z Ofiru wielką ilość drewna sandałowego i drogocennych kamieni.
12 Ọba sì fi igi algumu náà ṣe òpó fún ilé Olúwa àti fún ààfin ọba, àti láti ṣe dùùrù pẹ̀lú àti ohun èlò orin olókùn fún àwọn akọrin. Irú igi algumu bẹ́ẹ̀ kò dé mọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò rí wọn títí di òní yìí.)
Z tego drzewa sandałowego król wykonał schody do domu PANA i do domu królewskiego oraz harfy i cytry dla śpiewaków. Nigdy nie sprowadzono takiego drzewa sandałowego i nie widziano aż do dziś.
13 Solomoni ọba sì fún ayaba Ṣeba ní gbogbo ìfẹ́ rẹ̀ àti ohun tí ó béèrè, yàtọ̀ sí èyí tí a fi fún un láti ọwọ́ Solomoni ọba wa. Nígbà náà ni ó yípadà, ó sì lọ sí ìlú rẹ̀, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Król Salomon zaś dał królowej Saby wszystko, czego zapragnęła [i] o co poprosiła, nie licząc [tego], co jej dał ze swojej królewskiej hojności. Potem odjechała i wróciła do swojej ziemi razem ze swoimi sługami.
14 Ìwọ̀n wúrà tí Solomoni ń gbà ní ọdún kan sì jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà tálẹ́ǹtì wúrà,
A waga złota, które wpływało do Salomona w ciągu jednego roku, wynosiła sześćset sześćdziesiąt sześć talentów złota;
15 láìka èyí tí ó ń gbà lọ́wọ́ àwọn ajẹ́lẹ̀ àti àwọn oníṣòwò, àti ti gbogbo àwọn ọba Arabia, àti àwọn baálẹ̀ ilẹ̀.
Nie licząc tego, [co dostawał] od kupców i handlarzy wonności, i od wszystkich królów arabskich oraz namiestników ziemi.
16 Solomoni ọba sì ṣe igba asà wúrà lílù; ẹgbẹ̀ta ṣékélì wúrà ni ó lọ sí asà kan.
Król Salomon wykonał więc dwieście tarcz z kutego złota. Na każdą tarczę wychodziło sześćset [syklów] złota.
17 Ó sì túnṣe ọ̀ọ́dúnrún asà wúrà lílù, pẹ̀lú òsùwọ̀n wúrà mẹ́ta tí ó tàn sí asà kọ̀ọ̀kan. Ọba sì kó wọn sí ilé igbó Lebanoni.
[Wykonał] także trzysta puklerzy z kutego złota, używając po trzy miny złota na każdy puklerz. Król umieścił je w domu lasu Libanu.
18 Nígbà náà ni ọba sì ṣe ìtẹ́ eyín erin ńlá kan, ó sì fi wúrà dídára bò ó.
Król również sporządził wielki tron z kości słoniowej i pokrył go czystym złotem.
19 Ìtẹ́ náà sì ní àtẹ̀gùn mẹ́fà, ẹ̀yìn rẹ̀ sì ṣe róbótó lókè. Ní ibi ìjókòó méjèèjì náà ni ìrọpá wà, pẹ̀lú kìnnìún tí ó dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn.
Tron [miał] sześć stopni i okrągły szczyt z tyłu. Po obu stronach siedzenia były poręcze, a przy poręczach stały dwa lwy.
20 Kìnnìún méjìlá sì dúró níbi àtẹ̀gùn mẹ́fẹ̀ẹ̀fà, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní òpin àtẹ̀gùn kọ̀ọ̀kan, kò tí ì sí irú rẹ̀ ní ìjọba kan rí.
Dwanaście lwów stało na tych sześciu stopniach po obu stronach. Czegoś takiego nie uczyniono w żadnym [innym] królestwie.
21 Gbogbo ohun èlò mímu Solomoni ọba sì jẹ́ wúrà àti gbogbo ohun èlò ààfin igbó Lebanoni sì jẹ́ kìkì wúrà. Kò sí nǹkan kan tí a fi fàdákà ṣe, nítorí a kò ka fàdákà sí nǹkan kan ní gbogbo ọjọ́ Solomoni.
Wszystkie naczynia, których król Salomon używał do picia, były ze złota, a także wszystkie naczynia domu lasu Libanu [były] ze szczerego złota. Nie było nic ze srebra, gdyż nie uważano go za cenne w czasach Salomona.
22 Ọba sì ní ọkọ̀ Tarṣiṣi kan pẹ̀lú ọkọ̀ Hiramu ní Òkun. Ẹ̀ẹ̀kan ní ọdún mẹ́ta ni ọkọ̀ Tarṣiṣi ń dé, tí ó ń mú wúrà àti fàdákà, eyín erin àti ìnàkí àti ẹyẹ-ológe wá.
Królewska flota Tarszisz [była] bowiem na morzu wraz z flotą Hirama. Raz na trzy lata przypływała flota Tarszisz, przywożąc złoto, srebro, kość słoniową, małpy i pawie.
23 Solomoni ọba sì pọ̀ ní ọrọ̀ àti ní ọgbọ́n ju gbogbo àwọn ọba ayé lọ.
Tak więc król Salomon przewyższał wszystkich królów ziemi bogactwem i mądrością.
24 Gbogbo ayé sì ń wá ojú Solomoni láti gbọ́ ọgbọ́n tí Ọlọ́run ti fi sí i ní ọkàn.
I cała ziemia pragnęła zobaczyć Salomona, aby słuchać jego mądrości, którą Bóg włożył w jego serce.
25 Bí ọdún ṣe ń gorí ọdún olúkúlùkù àwọn tí ń wá sì ń mú ẹ̀bùn tirẹ̀ wá, ohun èlò fàdákà àti ohun èlò wúrà àti ẹ̀wù, àti tùràrí olóòórùn dídùn, ẹṣin àti ìbáaka.
Każdy przynosił mu swoje dary: srebrne i złote naczynia, szaty, zbroje, wonności, konie i muły, rokrocznie.
26 Solomoni sì kó kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jọ; ó sì ní ẹgbàáje kẹ̀kẹ́ àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin, tí ó fi pamọ́ sí ìlú kẹ̀kẹ́ àti pẹ̀lú ọba ní Jerusalẹmu.
Salomon nagromadził rydwanów i jeźdźców, tak że miał tysiąc czterysta rydwanów i dwanaście tysięcy jeźdźców, których rozmieścił po miastach rydwanów oraz przy sobie w Jerozolimie.
27 Ọba sì jẹ́ kí fàdákà pọ̀ ní Jerusalẹmu bí òkúta, àti igi kedari ni ó ṣe kí ó dàbí igi sikamore tí ń bẹ ní àfonífojì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Król sprawił, że srebro w Jerozolimie było jak kamienie, a cedry tak liczne jak sykomory na nizinie.
28 A mú àwọn ẹṣin wá fún Solomoni láti Ejibiti àti láti Kue, oníṣòwò ọba rà wọ́n láti Kue fún owó.
Sprowadzono też dla Salomona konie z Egiptu i nić lnianą. A kupcy królewscy brali nić lnianą za [ustaloną] cenę.
29 Wọ́n ń mú kẹ̀kẹ́ kan gòkè láti Ejibiti wá fún ẹgbẹ̀ta ṣékélì fàdákà àti ẹṣin kan fún àádọ́jọ. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún mú wọn wá fún ọba àwọn ọmọ Hiti àti ọba àwọn ọmọ Aramu.
Rydwan wywożono i sprowadzono z Egiptu za sześćset srebrników, a konia – za sto pięćdziesiąt. W ten sposób wszyscy królowie chetyccy i królowie Syrii dostawali [je] za ich pośrednictwem.

< 1 Kings 10 >