< Genesis 16 >

1 Sarai, aya Abramu kò bímọ fún un, ṣùgbọ́n ó ní ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin ará Ejibiti kan tí ń jẹ́ Hagari.
Saraj, żona Abrama, nie urodziła mu [dzieci]. Miała zaś służącą Egipcjankę, która miała na imię Hagar.
2 Nítorí náà, Sarai wí fún Abramu pé, “Kíyèsi i Olúwa ti sé mi ní inú, èmi kò sì bímọ, wọlé tọ ọmọ ọ̀dọ̀ mi lọ, bóyá èmi yóò le ti ipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.” Abramu sì gba ohun tí Sarai sọ.
I powiedziała Saraj do Abrama: Oto PAN nie pozwolił mi urodzić. Wejdź, proszę, do mojej służącej, może z niej będę miała dzieci. I Abram usłuchał głosu Saraj.
3 Lẹ́yìn ọdún mẹ́wàá tí Abramu ti ń gbé ni Kenaani ni Sarai mú ọmọbìnrin, ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Hagari, tí í ṣe ará Ejibiti fún Abramu ọkọ rẹ̀ láti fi ṣe aya.
Wzięła więc Saraj, żona Abrama, swoją służącą Hagar, Egipcjankę, i dała ją swemu mężowi Abramowi za żonę po dziesięciu latach zamieszkania Abrama w ziemi Kanaan.
4 Abramu sì bá Hagari lòpọ̀, ó sì lóyún. Nígbà tí ó sì ti mọ̀ pé òun lóyún, ó bẹ̀rẹ̀ sì ní kẹ́gàn ọ̀gá rẹ̀.
Obcował więc z Hagar, a ona poczęła. A gdy spostrzegła, że poczęła, ze wzgardą patrzyła na swoją panią.
5 Nígbà náà ni Sarai wí fún Abramu pé, “Ìwọ ni ó jẹ́ kí ẹ̀gbin yìí máa jẹ mí, mo fa ọmọ ọ̀dọ̀ mi lé ọ lọ́wọ́, nígbà tí ó sì rí i pé òun lóyún, mo di ẹni ẹ̀gàn ní ojú rẹ̀. Kí Olúwa kí ó ṣe ìdájọ́ láàrín tèmi tìrẹ.”
I Saraj powiedziała do Abrama: Jesteś winien mojej krzywdy. Dałam moją służącą w twe ramiona. [Ona] jednak, widząc, że poczęła, patrzyła na mnie ze wzgardą. Niech PAN rozsądzi między mną a tobą.
6 Abramu dáhùn pé, “Ìwọ ló ni ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣe ohunkóhun tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ sí i.” Nígbà náà ni Sarai fi ìyà jẹ Hagari, ó sì sálọ.
Abram powiedział do Saraj: Oto twoja służąca jest w twoim ręku, zrób z nią, co uważasz za słuszne. I gdy Saraj dręczyła ją, uciekła od niej.
7 Angẹli Olúwa sì rí Hagari ní ẹ̀gbẹ́ ìsun omi ní ijù, ìsun omi tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà tí ó lọ sí Ṣuri.
I Anioł PANA znalazł ją u źródła wód na pustyni, u źródła przy drodze do Szur.
8 Ó sì wí pé, “Hagari, ìránṣẹ́ Sarai, níbo ni o ti ń bọ̀, níbo sì ni ìwọ ń lọ?” Ó sì dáhùn pé, “Mo ń sálọ kúrò lọ́dọ̀ ọ̀gá mi Sarai ni.”
I zapytał: Hagar, służąco Saraj, skąd przyszłaś i dokąd idziesz? [Ona] odpowiedziała: Uciekam od swojej pani Saraj.
9 Angẹli Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ kí o sì tẹríba fún un.”
Anioł PANA powiedział jej: Wróć do swojej pani i poddaj się pod jej władzę.
10 Angẹli Olúwa náà sì fi kún fún un pé, “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, ìran rẹ kì yóò sì lóǹkà.”
Powiedział jej też Anioł PANA: Rozmnożę twoje potomstwo tak bardzo, że z powodu jego mnogości nie będzie go [można] policzyć.
11 Angẹli Olúwa náà sì wí fún un pé, “Ìwọ ti lóyún, ìwọ yóò sì bí ọmọkùnrin kan. Ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli, nítorí tí Olúwa ti rí ìpọ́njú rẹ.
Potem Anioł PANA powiedział jej: Oto poczęłaś i urodzisz syna, a nadasz mu imię Izmael, bo PAN usłyszał twoje cierpienie.
12 Òun yóò jẹ́ oníjàgídíjàgan ènìyàn ọwọ́ rẹ̀ yóò wà lára ènìyàn gbogbo, ọwọ́ ènìyàn gbogbo yóò sì wà lára rẹ̀, yóò sì máa gbé ní ìkanra pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀.”
Będzie on dzikim człowiekiem: jego ręka [będzie] przeciwko wszystkim, a ręka wszystkich przeciwko jemu; i będzie mieszkać w obecności wszystkich swoich braci.
13 Ó sì pe orúkọ Olúwa tí o bá sọ̀rọ̀ ní, “Ìwọ ni Ọlọ́run tí ó rí mi,” nítorí tí ó wí pé, “Mo ti ri ẹni tí ó rí mi báyìí.”
I nazwała PANA, który mówił do niej: Ty jesteś Bogiem, który mnie widzi. Powiedziała bowiem: Czyż tu nie spoglądałam na tego, który widzi mnie?
14 Nítorí náà ni a ṣe ń pe kànga náà ní Beeri-Lahai-Roi; kànga ẹni alààyè tí ó rí mi. Ó wà ní agbede-méjì Kadeṣi àti Beredi.
Dlatego nazwała [tę] studnię studnią Żyjącego, który widzi mnie. Jest ona między Kadesz i Bered.
15 Hagari sì bí ọmọkùnrin kan fún Abramu, Abramu sì pe orúkọ rẹ̀ ní Iṣmaeli.
Potem Hagar urodziła Abramowi syna. I nadał Abram swemu synowi, którego urodziła Hagar, imię Izmael.
16 Abramu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndínláàádọ́rùn-ún nígbà tí Hagari bí Iṣmaeli fún un.
A Abram miał osiemdziesiąt sześć lat, gdy Hagar urodziła mu Izmaela.

< Genesis 16 >