< Zachariasza 12 >

1 Brzemię słowa Pańskiego nad Izraelem. Tak mówi Pan, który rozpostarł niebiosa, a ugruntował ziemię, który tworzy ducha człowieczego we wnętrznościach jego:
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa fún Israẹli ni. Olúwa wí, ẹni tí ó na àwọn ọ̀run, tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, tí ó sì da ẹ̀mí ènìyàn tí ń bẹ ni inú rẹ̀,
2 Oto Ja postawię Jeruzalem kubkiem opojenia wszystkim narodom okolicznym, którzy będą przeciwko Judzie na oblężenie, i przeciwko Jeruzalemowi.
“Kíyèsi í, èmi yóò sọ Jerusalẹmu dí àgọ́ ìwárìrì sí gbogbo ènìyàn yíká, nígbà tí wọn yóò dó ti Juda àti Jerusalẹmu.
3 Owszem, stanie się dnia onego, że uczynię Jeruzalem kamieniem ciężkim wszystkim narodom; wszyscy, którzy go dźwigać będą, bardzo się urażą, choćby się zgromadziły przeciwko niemu wszystkie narody ziemi.
Ní ọjọ́ náà, nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé bá parapọ̀ sí i, ni èmi yóò sọ Jerusalẹmu di òkúta ti ko ṣe yí kúrò fún gbogbo ènìyàn, gbogbo àwọn tí ó bá sì fẹ́ yí i ni a ó gé sí wẹ́wẹ́,
4 Dnia onego, mówi Pan, zarażę każdego konia zdrętwieniem i jeźdźca jego szaleństwem; ale nad domem Juda otworzę oczy moje, a każdego konia narodów zarażę ślepotą.
ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Ni èmi yóò fi ìdágìrì lu gbogbo ẹṣin, àti fi òmùgọ̀ kọlu ẹni tí ń gun un; èmi yóò sì ṣí ojú mi sí ilé Juda, èmi yóò sì bu ìfọ́jú lu gbogbo ẹṣin tí orílẹ̀-èdè.
5 I rzekną książęta Judzcy w sercu swem: Mamy siłę i obywatele Jeruzalemscy w Panu zastępów, Bogu swoim.
Àti àwọn baálẹ̀ Juda yóò sì wí ni ọkàn wọn pé, ‘Àwọn ara Jerusalẹmu ni agbára mi nípa Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run wọn.’
6 Dnia onego położę książąt Judzkich jako węgle ogniste między drwy, a jako pochodnię gorejącą między snopy; i pożrą na prawą i na lewą stronę wszystkie narody okoliczne, i zostanie jeszcze Jeruzalem na miejscu swem w Jeruzalemie.
“Ní ọjọ́ náà, ni èmi yóò ṣe àwọn baálẹ̀ Juda bí ààrò iná kan láàrín igi, àti bi ẹ̀fúùfù iná láàrín ìtí; wọn yóò sì jẹ gbogbo àwọn ènìyàn run yíká lápá ọ̀tún àti lápá òsì, a ó sì tún máa gbé inú Jerusalẹmu ní ipò rẹ̀.
7 Zachowa Pan i namioty Judzkie pierwej, aby się nie wywyższała chwała domu Dawidowego, i chwała obywateli Jeruzalemskich przeciwko Judzie.
“Olúwa pẹ̀lú yóò kọ́ tètè gba àgọ́ Juda là ná, kí ògo ilé Dafidi àti ògo àwọn ara Jerusalẹmu má ba gbé ara wọn ga sí Juda.
8 Dnia onego Pan będzie bronił obywateli Jeruzalemskich, a któryby był między nimi najsłabszy, stanie się dnia onego podobny Dawidowi, a dom Dawidowy podobny bogom, podobny Aniołowi Pańskiemu przed nimi.
Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò dáàbò bò àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu; ẹni tí ó bá sì ṣe àìlera nínú wọn ní ọjọ́ náà, yóò dàbí Dafidi; ilé Dafidi yóò sì dàbí Ọlọ́run, bí angẹli Olúwa níwájú wọn.
9 Bo się stanie dnia onego, że szukać będę wszystkie narody, które przyciągną przeciwko Jeruzalemowi, abym je wytracił.
Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, èmi yóò wá láti pa gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè run tí ó wá kọjú ìjà sí Jerusalẹmu.”
10 I wyleję na dom Dawidowy, i na obywateli Jeruzalemskich Ducha łaski i modlitw, a patrzyć będą na mię, którego przebodli; i płakać będą nad nim płaczem, jako nad jednorodzonym; gorzko, mówię, płakać będą nad nim, jako gorzko płaczą nad pierworodnym.
“Èmi ó sì tu ẹ̀mí oore-ọ̀fẹ́ àti ẹ̀bẹ̀ sórí ilé Dafidi àti sórí Jerusalẹmu, wọn ó sì máa wo ẹni tí wọn tí gún ni ọ̀kọ̀, wọn ó sì máa ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, bí ẹnìkan ti ń ṣọ̀fọ̀ fún ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo àti gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí wọn yóò sì wà ni ìbànújẹ́, bí ẹni tí ń banújẹ́ fún àkọ́bí rẹ̀.
11 Dnia onego będzie wielkie kwilenie w Jeruzalemie, jako kwilenie w Adadrymon na polu Magieddon;
Ní ọjọ́ náà ni ẹkún, ńlá ńlá yóò wà ni Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ọ̀fọ̀ Hadadi Rimoni ni àfonífojì Megido.
12 Bo ziemia kwilić będzie, każde pokolenie osobno, pokolenie domu Dawidowego osobno, i niewiasty ich osobno; pokolenie domu Natanowego osobno, i niewiasty ich osobno;
Ilẹ̀ náà yóò ṣọ̀fọ̀, ìdílé, kọ̀ọ̀kan fun ara rẹ, lọ́tọ̀ọ̀tọ̀; ìdílé Dafidi lọ́tọ̀; àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀; ìdílé Natani lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ́.
13 Pokolenie domu Lewiego osobno, i niewiasty ich osobno; pokolenie Semejego osobno, i niewisty ich osobno;
Ìdílé Lefi lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀; ìdílé Ṣimei lọ́tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀.
14 Wszystkie insze pokolenia, każde pokolenie osobno, i niewiasty ich osobno.
Gbogbo àwọn ìdílé tí o kù, ìdílé, ìdílé, lọ́tọ̀ọ̀tọ̀, àti àwọn aya wọn lọ́tọ̀ọ̀tọ̀.

< Zachariasza 12 >