< Aggeusza 1 >

1 Roku wtórego Daryjusza króla, miesiąca szóstego, dnia pierwszego tegoż miesiąca, stało się słowo Pańskie przez Aggieusza proroka do Zorobabela, syna Salatyjelowego, książęcia Judzkiego, i do Jesuego, syna Jozedekowego, kapłana najwyższego, mówiąc:
Ní ọdún kejì ọba Dariusi ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹfà, ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai sí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti sọ́dọ̀ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
2 Tak powiada Pan zastępów, mówiąc: Ten lud mówi: Jeszcze nie przyszedł czas, czas budowania domu Pańskiego.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí pé, ‘Kò tí ì tó àkókò láti kọ́ ilé Olúwa.’”
3 Przetoż się stało słowo Pańskie przez Aggieusza proroka, mówiąc:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá láti ọ̀dọ̀ wòlíì Hagai wí pé,
4 Izali wam jest czas, abyście mieszkali w domach waszych listwowanych, a dom ten aby pusty stał?
“Ǹjẹ́ àkókò ni fún ẹ̀yin fúnra yín láti máa gbé ní ilé tí a ṣe ní ọ̀ṣọ́ nígbà tí ilé yìí wà ni ahoro?”
5 Teraz tedy tak mówi Pan zastępów: Uważajcież, jako się wam powodzi;
Nísìnsinyìí, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
6 Siejecie wiele, a mało zbieracie; jecie, ale się nie nasycacie; pijecie, ale nie ugaszacie pragnienia; obłóczycie się, ale się nikt nie może zagrzać, a ten, co sobie zapłatę zgromadza, zgromadza ją do worka dziurawego.
Ẹ̀yin ti gbìn ohun ti ó pọ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kórè díẹ̀ níbẹ̀. Ẹ̀yin jẹun, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò yó. Ẹ̀yin mu ṣùgbọ́n kò tẹ́ ẹ yín lọ́run; ẹ̀yin wọ aṣọ, ṣùgbọ́n kò mú òtútù yin lọ; ẹyin gba owó iṣẹ́ ṣùgbọ́n ẹ ń gbà á sínú ajádìí àpò.”
7 Tak mówi Pan zastępów: Uważajcie, jako się wam powodzi;
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
8 Wstąpcie na tę górę, i zwoźcie drzewo; budujcie ten dom, a zakocham się w nim, i będę uwielbiony, mówiPan.
Ẹ gun orí àwọn òkè ńlá lọ, kí ẹ sì mú igi wá pẹ̀lú yín. Kí ẹ sì kọ́ ilé náà, kí inú mi bà le è dùn sí i, kí a sì yín mí lógo,” ni Olúwa wí.
9 Poglądacie na wiele, a oto, mało dostawacie, a co wnosicie do domu, to Ja rozdmuchywam; dlaczego? mówi Pan zastępów; dlatego, że dom mój jest pusty, a międzytem się każdy z was stara o dom swój.
“Ẹyin ti ń retí ọ̀pọ̀, ṣùgbọ́n kíyèsi i, o yípadà sí díẹ̀. Ohun tí ẹ̀yin mú wa ilé, èmi sì fẹ́ ẹ dànù. Nítorí kí ni?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí ilé mi tí ó dahoro; tí olúkúlùkù yín sì ń sáré fún ilé ara rẹ̀.
10 Przetoż się nad wami niebo zawarło, aby rosy nie dawało; ziemia także zawarła się, aby nie wydawała urodzaju swego.
Nítorí yín ni àwọn ọ̀run ṣe dá ìrì dúró tí ilẹ̀ sì kọ̀ láti mu èso jáde.
11 A tak przyzwałem suszę na tę ziemię, i na te góry, i na pszenicę, i na moszcz, i na oliwę, i na to, coby miała wydać ziemia, i na ludzi i na bydło, i na wszystkę pracę ręczną.
Mo sì ti pe ọ̀dá sórí ilẹ̀ àti sórí àwọn òkè ńlá, sórí ọkà àti sórí wáìnì tuntun, sórí òróró àti sórí ohun ti ilẹ̀ ń mú jáde, sórí ènìyàn, sórí ẹran àti sórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín.”
12 Tedy usłuchał Zorobabel, syn Salatyjelowy, i Jesua, syn Jozedekowy, kapłan najwyższy, i wszystkie ostatki ludu, głosu Pana, Boga swego, i słów Aggieusza proroka, ponieważ go posłał Pan, Bóg ich; bo się lud bał oblicza Pańskiego.
Nígbà náà ni Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ìyókù, gba ohùn Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́ àti ọ̀rọ̀ wòlíì Hagai, nítorí Olúwa Ọlọ́run ni ó rán an. Àwọn ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa.
13 Tedy Aggieusz, poseł Pański, rzekł do ludu, będąc w poselstwie Pańskiem, mówiąc: Jam z wami, mówi Pan.
Nígbà náà ni Hagai ìránṣẹ́ Olúwa ń jíṣẹ́ Olúwa fún àwọn ènìyàn pé, “Èmí wà pẹ̀lú yín,” ni Olúwa wí.
14 Wtem wzbudził Pan ducha Zorobabela, syna Salatyjelowego, książęcia Judzkiego, i ducha Jesuego, syna Jozedekowego, kapłana najwyższego, i ducha ostatków wszystkiego ludu, że przyszedłszy robili około domu Pana zastępów, Boga swego.
Nítorí náà, Olúwa ru ẹ̀mí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli sókè, baálẹ̀ Juda àti ẹ̀mí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti ẹ̀mí gbogbo ènìyàn ìyókù. Wọ́n sì wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ lórí ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run wọn,
15 Dnia dwudziestego i czwartego, miesiąca szóstego, roku wtórego Daryjusza króla;
ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ní ọdún kejì ọba Dariusi.

< Aggeusza 1 >