< Zachariasza 11 >

1 Otwórz, Libanie! wrota swe, niech pożre ogień cedry twoje.
Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn rẹ sílẹ̀, ìwọ Lebanoni, kí iná bá lè jẹ igi kedari rẹ run.
2 Rozkwil się jodło! bo upadł cedr, bo wielmożni spustoszeni są; kwilcie dęby Basańskie, bo wycięty jest las ogrodzony.
Hu, igi junifa; nítorí igi kedari ṣubú, nítorí tí a ba àwọn igi tí o lógo jẹ́: hu, ẹ̀yin igi óákù tí Baṣani, nítorí gé igbó àjàrà lulẹ̀.
3 Głos narzekania pasterzy słyszany jest, iż zburzona jest wielmożność ich; głos ryku lwiąt, iż zburzona jest pycha Jordanu.
Gbọ́ ohun igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn; ògo wọn bàjẹ́; gbọ́ ohùn bíbú àwọn ọmọ kìnnìún nítorí ògo Jordani bàjẹ́.
4 Tak mówi Pan, Bóg mój: Paś owce na rzeź zgotowane;
Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run mi wí: “Bọ́ ọ̀wọ́ ẹran àbọ́pa.
5 Które dzierżawcy ich zabijają, a nie bywają obwinieni, i owszem, sprzedawający je mówią: Błogosławiony Pan, żeśmy się zbogacili, a którzy je pasą, nie mają litości nad niemi.
Tí àwọn olúwa wọn ń pa wọ́n, tí wọn kò sì ka ara wọn sí pé wọn jẹ̀bi: àti àwọn tí ń tà wọ́n wí pé, ‘Ìbùkún ni fún Olúwa, nítorí tí mo dí ọlọ́rọ̀!’ Àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn kò sì ṣàánú wọn.
6 Przetoż nie sfolguję więcej obywatelom tej ziemi, mówi Pan; bo oto Ja podam tych ludzi każdego w rękę bliźniego jego, i w rękę króla ich, i potrą ziemię, a nie wyrwie jej z rąk ich.
Nítorí èmi kì yóò ṣàánú fún àwọn ara ilẹ̀ náà mọ́,” ni Olúwa wí, “Ṣí kíyèsi í, èmi yóò fi olúkúlùkù ènìyàn lé aládùúgbò rẹ̀ lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ ọba rẹ̀, wọn yóò sì fọ́ ilẹ̀ náà, èmi kì yóò sì gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn.”
7 Bom pasł owce zgotowane na rzeź, was, mówię, o nędzne owce! i wziąwszy sobie dwie laski, jednęm nazwał Uciechą, a drugąm nazwał Związujących, a pasłem one owce.
Èmi yóò sì bọ́ ẹran àbọ́pa, àní ẹ̀yin òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran. Mo sì mu ọ̀pá méjì sọ́dọ̀; mo pè ọ̀kan ni Oore-ọ̀fẹ́, mo pè èkejì ni Àmùrè; mo sì bọ́ ọ̀wọ́ ẹran náà.
8 I zgładziłem trzech pasterzy w jednym miesiącu; ale utęskniła sobie dusza moja z nimi, przeto, że dusza ich brzydziła się mną.
Olùṣọ́-àgùntàn mẹ́ta ni mo sì gé kúrò ní oṣù kan. Ọkàn mi sì kórìíra wọn, ọkàn wọn pẹ̀lú sì kórìíra mi.
9 Rzekłem tedy: Nie będęć was pasł; co zdycha, niech zdechnie, a co ma być wygładzone, niech będzie wygładzone, a które pozostaną, niech pożera mięso jedna drugiej.
Mo sì wí pé, “Èmi kì yóò bọ́ yin: èyí ti ń ku lọ, jẹ́ kí òkú o kú; èyí tí a o ba sì gé kúrò, jẹ́ kí a gé e kúrò; ki olúkúlùkù nínú àwọn ìyókù jẹ́ ẹran-ara ẹnìkejì rẹ̀.”
10 Przetoż wziąwszy laskę moję Uciechy, porąbałem ją, wzruszywszy przymierze moje, którem postanowił z tym wszystkim ludem.
Mo sì mu ọ̀pá mi, ti a ń pè ní Oore-ọ̀fẹ́, mo ṣẹ́ si méjì, ki èmi bá lè da májẹ̀mú mi tí mo tí bá gbogbo àwọn ènìyàn náà dá.
11 A dnia onego, gdy wzruszone było, pewnie poznali nędzni z trzody, którzy się na mię oglądali, że to słowo Pańskie.
Ó sì dá ni ọjọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni àwọn òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran náà tí ó dúró tì mí mọ̀ pé, ọ̀rọ̀ Olúwa ni.
12 Bom rzekł do nich: Jeźli to jest dobre w oczach waszych, dajcie zapłatę moję, a jeźli nie, zaniechajcież; tedy odważyli zapłatę moję trzydzieści srebrników.
Mo sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá dára ní ojú yin, ẹ fún mi ni owó ọ̀yà mi; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ mú un lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọn ọgbọ̀n owó fàdákà fún iye owó ọ̀yà mi.
13 Zatem rzekł Pan do mnie: Porzuć je przed garncarza; zacnaż to zapłata, którąm jest od nich tak drogo oszacowany! Wziąłem tedy trzydzieści srebrników, a porzuciłem je w domu Pańskim przed garncarza.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Sọ ọ sí amọ̀kòkò.” Iye dáradára náà, tí wọn yọ owó mi sí. Mo sì mu ọgbọ̀n owó fàdákà náà, mo sì sọ wọ́n sí àpótí ìṣúra ní ilé Olúwa.
14 Potem porąbałem laskę moję drugą Związujących, wzruszywszy braterstwo między Judą i między Izraelem.
Mo sì ṣẹ́ ọ̀pá mi kejì, àní Àmùrè, sí méjì, kí èmi lè ya ìbátan tí ó wà láàrín Juda àti láàrín Israẹli.
15 I rzekł Pan do mnie: Weźmij sobie jeszcze oręż pasterza głupiego.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Tún mú ohun èlò aṣiwèrè olùṣọ́-àgùntàn kan sọ́dọ̀ rẹ̀.
16 Bo oto Ja wzbudzę pasterza w tej ziemi, który nie będzie obłąkanych nawiedzał, ani będzie jagniątek szukał, złamanego też leczyć, i tego, co ustanie, nosić nie będzie; ale mięso tłustych jeść będzie, a kopyta ich postrąca.
Nítorí Èmi o gbé Olùṣọ́-àgùntàn kan dìde ni ilẹ̀ náà, tí kí yóò bẹ àwọn tí ó ṣègbé wò, ti kì yóò sì wá èyí tí ó yapa; tí kì yóò ṣe ìtọ́jú èyí tí a pa lára tàbí kí ó bọ́ àwọn tí ara wọn dá pépé: Ṣùgbọ́n òun yóò jẹ ẹran èyí tí ó ni ọ̀rá, àwọn èyí tiwọn fi èékánná wọn ya ara wọn pẹ́rẹpẹ̀rẹ.
17 Biada pasterzowi niepożytecznemu, który opuszcza trzodę! miecz nad ramieniem jego i nad prawem okiem jego; ramię jego cale uschnie, a prawe oko jego cale zaćmione będzie.
“Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn asán náà, tí ó fi ọ̀wọ́ ẹran sílẹ̀! Idà yóò gé apá rẹ̀ àti ojú ọ̀tún rẹ̀: apá rẹ̀ yóò gbẹ pátápátá, ojú ọ̀tún rẹ̀ yóò sì fọ́ pátápátá!”

< Zachariasza 11 >