< Nehemiah 7 >

1 Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
Now it came to pass, when the wall was built, and I had set up the doors, and the porters and the singers and the Levites were appointed,
2 Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
That I gave my brother Hanani, and Hananiah the ruler of the palace, charge over Jerusalem: for he [was] a faithful man, and feared God above many.
3 Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
And I said to them, Let not the gates of Jerusalem be opened until the sun shall be hot; and while they stand by, let them shut the doors, and bar [them]: and appoint watches of the inhabitants of Jerusalem, every one in his watch, and every one [to be] over against his house.
4 Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
Now the city [was] large and great: but the people in it [were] few, and the houses [were] not built.
5 Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
And my God put into my heart to assemble the nobles, and the rulers, and the people, that they might be reckoned by genealogy. And I found a register of the genealogy of them who came up at the first, and found written in it,
6 Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
These [are] the children of the province, that went up out of the captivity, of those that had been carried away, whom Nebuchadnezzar the king of Babylon had carried away, and came again to Jerusalem and to Judah, every one to his city;
7 Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
Who came with Zerubbabel, Jeshua, Nehemiah, Azariah, Raamiah, Nahamani, Mordecai, Bilshan, Mispereth, Bigvai, Nehum, Baanah. The number, [I say], of the men of the people of Israel [was this];
8 àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
The children of Parosh, two thousand a hundred and seventy two.
9 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
The children of Shephatiah, three hundred and seventy two.
10 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
The children of Arah, six hundred and fifty two.
11 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
The children of Pahath-moab, of the children of Jeshua and Joab, two thousand and eight hundred [and] eighteen.
12 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
The children of Elam, a thousand two hundred and fifty four.
13 Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
The children of Zattu, eight hundred and forty five.
14 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
The children of Zaccai, seven hundred and sixty.
15 Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
The children of Binnui, six hundred and forty eight.
16 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
The children of Bebai, six hundred and twenty eight.
17 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
The children of Azgad, two thousand three hundred and twenty two.
18 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
The children of Adonikam, six hundred and sixty seven.
19 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
The children of Bigvai, two thousand and sixty seven.
20 Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
The children of Adin, six hundred and fifty five.
21 Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
The children of Ater of Hezekiah, ninety eight.
22 Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
The children of Hashum, three hundred and twenty eight.
23 Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
The children of Bezai, three hundred and twenty four.
24 Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
The children of Hariph, a hundred and twelve.
25 Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
The children of Gibeon, ninety five.
26 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
The men of Beth-lehem and Netophah, a hundred and eighty eight.
27 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
The men of Anathoth, a hundred and twenty eight.
28 Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
The men of Beth-azmaveth, forty two.
29 Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
The men of Kirjath-jearim, Chephirah, and Beeroth, seven hundred and forty three.
30 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
The men of Ramah and Gaba, six hundred and twenty one.
31 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
The men of Michmas, a hundred and twenty two.
32 Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
The men of Beth-el and Ai, a hundred and twenty three.
33 Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
The men of the other Nebo, fifty two.
34 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
The children of the other Elam, a thousand two hundred and fifty four.
35 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
The children of Harim, three hundred and twenty.
36 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
The children of Jericho, three hundred and forty five.
37 Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
The children of Lod, Hadid, and Ono, seven hundred and twenty one.
38 Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
The children of Senaah, three thousand nine hundred and thirty.
39 Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
The priests: the children of Jedaiah, of the house of Jeshua, nine hundred and seventy three.
40 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
The children of Immer, a thousand and fifty two.
41 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
The children of Pashur, a thousand two hundred and forty seven.
42 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
The children of Harim, a thousand and seventeen.
43 Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
The Levites: the children of Jeshua, of Kadmiel, [and] of the children of Hodevah, seventy four.
44 Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
The singers: the children of Asaph, a hundred and forty eight.
45 Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
The porters: the children of Shallum, the children of Ater, the children of Talmon, the children of Akkub, the children of Hatita, the children of Shobai, a hundred and thirty eight.
46 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
The Nethinims: the children of Ziha, the children of Hashupha, the children of Tabbaoth,
47 Kerosi, Sia, Padoni,
The children of Keros, the children of Sia, the children of Padon,
48 Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
The children of Lebana, the children of Hagaba, the children of Shalmai,
49 Hanani, Giddeli, Gahari,
The children of Hanan, the children of Giddel, the children of Gahar,
50 Reaiah, Resini, Nekoda,
The children of Reaiah, the children of Rezin, the children of Nekoda,
51 Gassamu, Ussa, Pasea,
The children of Gazzam, the children of Uzza, the children of Phaseah,
52 Besai, Mehuni, Nefisimu,
The children of Besai, the children of Meunim, the children of Nephishesim,
53 Bakbu, Hakufa, Harhuri,
The children of Bakbuk, the children of Hakupha, the children of Harhur,
54 Basluti, Mehida, Harṣa,
The children of Bazlith, the children of Mehida, the children of Harsha,
55 Barkosi, Sisera, Tema,
The children of Barkos, the children of Sisera, the children of Tamah,
56 Nesia, àti Hatifa.
The children of Neziah, the children of Hatipha.
57 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
The children of Solomon's servants: the children of Sotai, the children of Sophereth, the children of Perida,
58 Jaala, Darkoni, Giddeli,
The children of Jaala, the children of Darkon, the children of Giddel,
59 Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
The children of Shephatiah, the children of Hattil, the children of Pochereth of Zebaim, the children of Amon.
60 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
All the Nethinims, and the children of Solomon's servants, [were] three hundred and ninety two.
61 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
And these [were] they who went up [also] from Tel-mela, Tel-haresha, Cherub, Addon, and Immer: but they could not show their fathers house, nor their seed, whether they [were] of Israel.
62 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
The children of Delaiah, the children of Tobiah, the children of Nekoda, six hundred and forty two.
63 Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
And of the priests: the children of Habaiah, the children of Koz, the children of Barzillai, who took [one] of the daughters of Barzillai the Gileadite for a wife, and was called after their name.
64 Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
These sought their register [among] those that were reckoned by genealogy, but it was not found: therefore were they, as polluted, put from the priesthood.
65 Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
And the Tirshatha said to them, that they should not eat of the most holy things, till there should stand [up] a priest with Urim and Thummim.
66 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
The whole congregation together [was] forty two thousand three hundred and sixty.
67 yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
Besides their man-servants and their maid-servants, of whom [there were] seven thousand three hundred and thirty seven: and they had two hundred and forty five singing-men and singing-women.
68 Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
Their horses, seven hundred and thirty six: their mules, two hundred and forty five:
69 ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
[Their] camels, four hundred and thirty five: six thousand seven hundred and twenty asses.
70 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
And some of the chief of the fathers gave to the work. The Tirshatha gave to the treasure a thousand drams of gold, fifty basins, five hundred and thirty priests' garments.
71 Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
And [some] of the chief of the fathers gave to the treasure of the work, twenty thousand drams of gold, and two thousand and two hundred pounds of silver.
72 Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
And [that] which the rest of the people gave [was] twenty thousand drams of gold, and two thousand pounds of silver, and sixty seven priests' garments.
73 Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,
So the priests, and the Levites, and the porters, and the singers, and [some] of the people, and the Nethinims, and all Israel, dwelt in their cities; and when the seventh month came, the children of Israel [were] in their cities.

< Nehemiah 7 >