< Luke 4 >

1 Jesu sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó padà ti Jordani wá, a sì ti ọwọ́ Ẹ̀mí darí rẹ̀ sí ijù,
As Jesus left the Jordan [River valley], the Holy Spirit was completely controlling him.
2 Ogójì ọjọ́ ni a fi dán an wò lọ́wọ́ èṣù. Kò sì jẹ ohunkóhun ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì: nígbà tí wọ́n sì parí, lẹ́yìn náà ni ebi wá ń pa á.
For 40 days the Spirit led him around in the desolate area. During that time Jesus was being tempted by the devil {the devil was tempting him}, and Jesus did not eat anything. When that time ended, he was [very] hungry.
3 Èṣù sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, pàṣẹ fún òkúta yìí kí ó di àkàrà.”
Then the devil said to Jesus, “Because you [claim that you] ([have a relationship with] God as a son [has with his father] [MET]/are the man who is both God and man), [prove it by] telling these stones to become bread [so that you can eat them]!”
4 Jesu sì dáhùn, ó wí fún un pé, “A ti kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ènìyàn kì yóò wà láààyè nípa àkàrà nìkan.’”
Jesus replied, “[No, I will not change stones into bread, because it is written] {[Moses] wrote} [in the Scriptures] that [eating] food sustains people physically, but it does not [sustain them spiritually. They also need food for their spirits].”
5 Lójúkan náà, èṣù sì mú un lọ sí orí òkè gíga, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ ọba ayé hàn án.
Then the devil took him on top of [a high mountain] and showed him in an instant all the nations in the world.
6 Èṣù sì wí fún un pé, “Ìwọ ni èmi ó fi gbogbo agbára yìí àti ògo wọn fún: nítorí á sá ti fi fún mi. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wù mí, èmi a fi í fún.
Then he said to [Jesus], “I will give you the authority [to rule] all these areas and will make you famous. [I can do this] because [God] has permitted me [to control these areas], and I can allow anyone I desire to rule them!
7 Ǹjẹ́ bí ìwọ bá foríbalẹ̀ fún mi, gbogbo rẹ̀ ni yóò jẹ́ tìrẹ.”
So if you worship me, I will [let] you [rule] them all!”
8 Jesu sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Kúrò lẹ́yìn mi, Satani, nítorí tí a kọ̀wé rẹ̀ pé, ‘Ìwọ foríbalẹ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, òun nìkan ṣoṣo ni kí ìwọ kí ó sì máa sìn.’”
But Jesus replied, “[No, I] will not [worship you, because] it is written {[the Psalmist] wrote} [in the Scriptures], ‘It is the Lord, your God, whom you must worship, and you must serve only him!’”
9 Èṣù sì mú un lọ sí Jerusalẹmu, ó sì gbé e lé ibi ṣóńṣó tẹmpili, ó sì wí fún un pé, “Bí ìwọ bá ṣe Ọmọ Ọlọ́run, bẹ́ sílẹ̀ fún ara rẹ láti ibí yìí.
Then the devil took [Jesus] to Jerusalem. He set him on the highest part of the Temple and said to him, “Because you [claim that you] ([have a relationship with God as a son has with his father] [MET]/are the man who is both God and man), [prove it by] jumping down from here.
10 A sá ti kọ̀wé rẹ̀ pé, “‘Yóò pàṣẹ fún àwọn angẹli rẹ̀ nítorí rẹ, láti máa ṣe ìtọ́jú rẹ;
[You will not be hurt], because it is written {the [Psalmist] wrote} [in the Scriptures], ‘God will command his angels to protect you [(sg)].
11 àti pé ní ọwọ́ wọn ni wọn ó gbé ọ sókè, kí ìwọ kí ó má ba à fi ẹsẹ̀ rẹ gbún òkúta.’”
They will lift you up with their hands [when you are falling], so that [you will not get hurt]. You will not [even] strike your foot on a stone.’”
12 Jesu sì dáhùn ó wí fún un pé, “A ti kọ́ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ dán Olúwa Ọlọ́run rẹ wò.’”
But Jesus replied, “[No, I] will not [do that, because] it is written {[Moses] wrote} [in the Scriptures]: ‘Do not try to test the Lord your God [to see if he will prevent something bad from happening to you when you do something foolish]’.”
13 Nígbà tí èṣù sì parí ìdánwò náà gbogbo, ó fi í sílẹ̀ lọ fun sá à kan.
Then, after the devil had finished trying to tempt [Jesus] in many ways, he left him. He wanted to try to tempt him later at an appropriate time.
14 Jesu sì fi agbára Ẹ̀mí padà wá sí Galili, òkìkí rẹ̀ sì kàn kálẹ̀ ní gbogbo agbègbè tí ó yí i ká.
As the Spirit empowered him, Jesus returned to Galilee [district. People] throughout all that region heard about what he [was doing].
15 Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu wọn; a ń yìn ín lógo láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn ènìyàn wá.
He taught [people] in their (synagogues/meeting places). [As a result], he was praised by everyone {everyone praised him}.
16 Ó sì wá sí Nasareti, níbi tí a gbé ti tọ́ ọ dàgbà: bí ìṣe rẹ̀ ti rí, ó sì wọ inú Sinagọgu lọ ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì dìde láti kàwé.
Then [Jesus] went to Nazareth, [the town] where he grew up. (On the Sabbath/On the Jewish rest day) he went (to the synagogue/to the Jewish meeting place), as he usually did. He stood up [to indicate that he wanted] to read [Scriptures] to them.
17 A sì fi ìwé wòlíì Isaiah fún un. Nígbà tí ó sì ṣí ìwé náà, ó rí ibi tí a gbé kọ ọ́ pé:
A scroll containing [the words] that the prophet Isaiah [had written] was given to him {[Someone] gave to him a scroll containing [the words] that the prophet Isaiah [had written]}. He opened the scroll and found the place from which he [wanted to] read. [He read these words]:
18 “Ẹ̀mí Olúwa ń bẹ lára mi, nítorí tí ó fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn òtòṣì. Ó ti rán mi wá láti wàásù ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn, àti ìmúnríran fún àwọn afọ́jú, àti láti jọ̀wọ́ àwọn tí a pa lára lọ́wọ́,
The Spirit (of the Lord/of God) is upon me. He has appointed [MTY] me to declare God’s good news to the poor. He has sent me [here] to proclaim that God will deliver those whom [Satan] has captured, and he will [enable me to] enable those who are blind to see. He will enable me to free people who have been oppressed {whom [others] have oppressed}.
19 láti kéde ọdún ojúrere Olúwa.”
And he sent me to declare that now is the time when (the Lord/God) will [act] favorably [toward people].
20 Ó sì pa ìwé náà dé, ó fi í fún ìránṣẹ́, ó sì jókòó. Gbogbo àwọn tí ó ń bẹ nínú Sinagọgu sì tẹjúmọ́ ọn.
Then he rolled up the scroll and gave it back to the attendant, and sat down [to teach the people]. Everyone in the synagogue was looking intently [MTY] at him.
21 Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wí fún wọn pé, “Lónìí ìwé mímọ́ yìí ṣẹ ní etí yín.”
He said to them, “Today as you have been hearing [MTY] [me speak], [I am beginning] to fulfill this Scripture passage.”
22 Gbogbo wọn sì jẹ́rìí rẹ̀, háà sì ṣe wọ́n sí ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ tí ń jáde ní ẹnu rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Ọmọ Josẹfu kọ́ yìí?”
[At first] everyone there spoke well about him, and they were amazed at the charming words that he spoke. [But then some of] them said, “(He is [only] Joseph’s son!/Isn’t he [only] Joseph’s son?) [RHQ] [So] ([it is useless for us(exc) to listen to what he says!/why should we(exc) listen to what he says]?) [RHQ]”
23 Jesu sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni ẹ̀yin ó pa òwe yìí sí mi pé, ‘Oníṣègùn, wo ara rẹ̀ sàn! Àwọn ohun tí àwa gbọ́ pé o ti ọwọ́ rẹ ṣe ní Kapernaumu, ṣe é níhìn-ín yìí pẹ̀lú ní ilẹ̀ ara rẹ.’”
He said to them, “Surely [some of] you will quote to me the proverb that says, ‘Doctor, heal yourself!’ [What you will mean is], ‘People told us that you did miracles in Capernaum [town, but we(exc) do not know if those reports are true. So] do miracles here in your own hometown, too!’”
24 Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún un yín, kò sí wòlíì tí a tẹ́wọ́gbà ní ilẹ̀ baba rẹ̀.
Then he said, “It is certainly true that [people] do not accept [the message of] a prophet when he speaks in his hometown, [just like you(pl) are not accepting my message now].
25 Ṣùgbọ́n mo wí fún un yín nítòótọ́, opó púpọ̀ ni ó wà ní Israẹli nígbà ọjọ́ wòlíì Elijah, nígbà tí ọ̀run fi sé ní ọdún mẹ́ta òun oṣù mẹ́fà, nígbà tí ìyàn ńlá fi mú ká ilẹ̀ gbogbo.
But think about this: There were many widows in Israel during the time when [the prophet] Elijah [lived. During that time], because of there being no rain [MTY] for three years and six months, there was a great famine throughout the country.
26 Kò sì sí ẹnìkan nínú wọn tí a rán Elijah sí, bí kò ṣe sí obìnrin opó kan ní Sarefati, ìlú kan ní Sidoni.
But [God] did not send Elijah to [help] any of those [Jewish] widows. [God sent him] to Zarepath [town] near Sidon [city], to [help] a [non-Jewish] widow.
27 Adẹ́tẹ̀ púpọ̀ ní sì ń bẹ ní Israẹli nígbà wòlíì Eliṣa; kò sì ṣí ọ̀kan nínú wọn tí a wẹ̀nùmọ́, bí kò ṣe Naamani ará Siria.”
There were also many [Jewish] lepers in Israel during the time when the prophet Elisha [lived]. But [Elisha] did not heal any of them. He healed only Naaman, a [non-Jewish] man from Syria.”
28 Nígbà tí gbogbo àwọn tí ó wà nínú Sinagọgu gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, inú bi wọ́n gidigidi,
When all the people in the synagogue heard him say that, they were very angry, [because they realized that he was inferring that he similarly would help non-Jewish people instead of helping Jews] (OR, [that they also were not worthy of receiving God’s help]).
29 wọ́n sì dìde, wọ́n tì í sóde sí ẹ̀yìn ìlú, wọ́n sì fà á lọ sí bèbè òkè níbi tí wọ́n gbé tẹ ìlú wọn dó, kí wọn bá à lè sọ sílẹ̀ ní ògèdèǹgbé.
So they all got up and shoved him out of the town. They took him to the top of the hill outside their town in order to throw him off the cliff [and kill him].
30 Ṣùgbọ́n ó kọjá láàrín wọn, ó bá tirẹ̀ lọ.
But he [simply] walked through their midst and went away.
31 Ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Kapernaumu, ìlú kan ní Galili, ó sì ń kọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi.
[One day] Jesus went [with his disciples] down to Capernaum, a town in Galilee [district]. On the next (Sabbath/Jewish day of rest) (OR, Each (Sabbath/Jewish day of rest)), he taught the people ([in the synagogue/in the Jewish meeting place]).
32 Ẹnu sì yà wọ́n sí ẹ̀kọ́ rẹ̀: nítorí tàṣẹtàṣẹ ni ọ̀rọ̀ rẹ̀.
They were continually amazed at what he was teaching, because [he spoke] ([with authority/as people speak who have] the right to command others what to do).
33 Ọkùnrin kan sì wà nínú Sinagọgu, ẹni tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, ó kígbe ní ohùn rara,
[That day], (OR, On one of those Jewish days of rest, ) there was a man in the synagogue who was controlled by an evil spirit. That man shouted very loudly,
34 “Ó wí pé, kín ni ṣe tàwa tìrẹ, Jesu ará Nasareti? Ìwọ́ wá láti pa wá run bí? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe, Ẹni Mímọ́ Ọlọ́run.”
“Hey! Jesus, from Nazareth! [We(exc) evil spirits] have nothing in common with you, so ([do not interfere with us now!/why should you interfere with us now]?) [RHQ] (Do not destroy us [now!]/Have you come to destroy us [now]?) [RHQ] I know who you are. You are the Holy One [who has come] from God!”
35 Jesu sì bá a wí gidigidi, ó wí fun pe, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí o sì jáde lára rẹ̀.” Nígbà tí ẹ̀mí èṣù náà sì gbé e ṣánlẹ̀ ní àwùjọ, ó jáde kúrò lára rẹ̀, kò sì pa á lára.
Jesus rebuked [the evil spirit], saying, “Be quiet! And come out [of the man]!” The demon threw the man down on the ground in the midst of the people. But without harming the man, the demon left him.
36 Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì ń bá ara wọn sọ wí pé, “Irú ẹ̀kọ́ kín ni èyí? Nítorí pẹ̀lú àṣẹ àti agbára ni ó fi bá àwọn ẹ̀mí àìmọ́ wí, wọ́n sì jáde kúrò.”
The people were all amazed. They said to each other, “(What he says to the demons [has great power!/] [kind of] teaching is this?) [RHQ] He speaks to them like he knows that they must obey him, and as a result they leave people!”
37 Òkìkí rẹ̀ sì kàn níbi gbogbo ní agbègbè ilẹ̀ náà yíká.
The people were telling everyone in [every village] in the surrounding region what Jesus [had done].
38 Nígbà tí ó sì dìde kúrò nínú Sinagọgu, ó sì wọ̀ ilé Simoni lọ; ibà sì ti dá ìyá ìyàwó Simoni dùbúlẹ̀, wọ́n sì bẹ̀ ẹ́ nítorí rẹ̀.
Jesus [and his disciples] left (the synagogue/the Jewish meeting place) and entered Simon’s house. Simon’s mother-in-law was sick and had a high fever. So [others in Simon’s family] (OR, [the disciples]) asked Jesus to [heal] her.
39 Ó sì súnmọ́ ọ, ó bá ibà náà wí; ibà sì náà sì fi sílẹ̀. O sì dìde lọ́gán, ó ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
So he bent over her and commanded the fever to leave her. At once she became well! She got up and served them [some food].
40 Nígbà tí oòrùn sì ń wọ̀, àwọn ènìyàn gbe àwọn aláìsàn, tó ní onírúurú àìsàn wá sọ́dọ̀ Jesu; ó sì fi ọwọ́ lé olúkúlùkù wọn, ó sì mú wọn láradá.
When the sun was setting [that day, and the restriction about not traveling] (on [the Sabbath/on the Jewish rest day]) [was ended], many people [HYP] whose [friends or relatives] were sick or who had various diseases brought them to Jesus. He put his hands on them and healed [all of] them.
41 Àwọn ẹ̀mí èṣù sì jáde lára ẹni púpọ̀ pẹ̀lú, wọ́n ń kígbe, wí pé, “Ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run!” Ó sì ń bá wọn wí kò sì jẹ́ kí wọn kí ó fọhùn, nítorí tí wọ́n mọ̀ pé Òun ni Kristi náà.
He also was [expelling demons] from many people. As the demons left those people, they shouted to Jesus, “You are (the Son of God/the one who is God and man)!” But he rebuked those demons and would not allow them to tell [people about him], because they knew that he was the Messiah, and [for various reasons he did not want everyone to know that yet].
42 Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, Jesu sì jáde lọ, ó sì ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀. Ìjọ ènìyàn sì ń wá a kiri, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì dá a dúró, nítorí kí ó má ba à lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
[Early] the next morning [Jesus] left that house and went to an uninhabited place [to pray]. Many people searched for him, and when they found him they kept urging him not to leave them.
43 Ṣùgbọ́n ó sì wí fún wọn pé, “Èmi kò lè ṣàìmá wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run fún àwọn ìlú mìíràn pẹ̀lú, nítorí náà ni a sá ṣe rán mi.”
But he said to them, “I must tell [people] in other towns also the good message about how God wants to rule [MET] their lives, because that is what I was sent {[God] sent me} to do.”
44 Ó sì ń wàásù nínú Sinagọgu ti Judea.
So he kept preaching in (the synagogues/Jewish worship places) [in various towns] in Judea [province].

< Luke 4 >