< Luke 3 >

1 Ní ọdún kẹ́ẹ̀dógún ìjọba Tiberiu Kesari, nígbà tí Pọntiu Pilatu jẹ́ baálẹ̀ Judea, tí Herodu sì jẹ́ tetrarki Galili, Filipi arákùnrin rẹ̀ sì jẹ́ tetrarki Iturea àti ti Trakoniti, Lisania sì jẹ́ tetrarki Abilene,
When the Emperor Tiberius had been ruling [the Roman Empire] for 15 years, and while Pontius Pilate was the governor of Judea [district], and Herod [Antipas] was ruling Galilee [district], and his brother Philip was ruling Iturea and Trachonitis [districts], and Lysanius was ruling Abilene [district],
2 tí Annasi òun Kaiafa ń ṣe olórí àwọn àlùfáà, nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Johanu ọmọ Sekariah wá ní ijù.
and while Annas and Caiaphas were the high priests [in Jerusalem], God gave messages to Zechariah’s son John while he was living in the desolate region.
3 Ó sì wá sí gbogbo ilẹ̀ aginjù Jordani, ó ń wàásù ìtẹ̀bọmi ìrònúpìwàdà fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀,
[So] John went all over the area close to the Jordan [River]. He kept telling people, “If you want [God] to forgive you for your sins, you must (repent/turn away from your sinful behavior) [before you ask me] to baptize [you]!”
4 bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah pé, “Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ mú ipa ọ̀nà rẹ̀ tọ́.
John was the one who [fulfilled] these words that had [been written] by the prophet Isaiah {that the prophet Isaiah had written} on a scroll [long ago]: In a desolate area, someone [SYN] will be heard shouting [to the people who pass by], “Prepare yourselves [to receive] the Lord when he comes! [Make yourselves ready so that you will be prepared when he comes], [just like people] straighten out the road [MET] [for an important official] [MET, DOU]!
5 Gbogbo ọ̀gbun ni a yóò kún, gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni a ó tẹ́ pẹẹrẹ. Wíwọ́ ni a ó ṣe ní títọ́, àti ọ̀nà gbọ́ngungbọ̀ngun ni a o sọ di dídán.
[Just like people] level off all the places where the land rises and [just like they] fill all the ravines, and [just like people] make the road straight wherever it is crooked, and [just like people] make smooth the bumps in the road, [similarly you need to remove all the obstacles which prevent God from blessing you]!
6 Gbogbo ènìyàn ni yóò sì rí ìgbàlà Ọlọ́run.’”
Then people [SYN] everywhere will understand how God can save [MTY] [people].”
7 Nígbà náà ni ó wí fún ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn tí ó wá láti ṣe ìtẹ̀bọmi lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ìran paramọ́lẹ̀, ta ni ó kìlọ̀ fún un yín láti sá kúrò nínú ìbínú tí ń bọ̀?
Although large groups of people came to John to be baptized {in order that he would baptize them}, [he knew that many of them were not sincere]. So he kept saying to them, “You [people are evil] [MET] [like] poisonous snakes! [I] warn you that [God] will some day punish [MTY] [everyone] who sins. And (do not think that you can escape [from his punishing] [MTY] [you if you do not turn from your sinful behavior!/did someone tell you] that you can escape [from his punishing] [MTY] [you if you do not turn from your sinful behavior]?) [RHQ] (OR, Who told you that you could escape [God’s punishment?])
8 Nítorí náà kí ẹ̀yin kí ó so èso tí ó yẹ fún ìrònúpìwàdà, kí ẹ má sì ṣe sí í wí nínú ara yín pé, ‘Àwa ní Abrahamu ní baba.’ Kí èmi kí ó wí fún un yín, Ọlọ́run lè gbé ọmọ dìde fún Abrahamu nínú òkúta wọ̀nyí.
Do what is appropriate for people who have truly turned from their sinful behavior! [God promised to give Abraham many] descendants. In order to fulfill that promise, God does not need you! I tell you that he can change these stones to make them descendants of Abraham! So do not begin to say to yourselves, ‘We [(exc)] are descendants of Abraham, [so God will not punish us, even though we have] sinned!’
9 Àti nísinsin yìí pẹ̀lú, a fi àáké lé gbòǹgbò igi náà, gbogbo igi tí kò bá so èso rere, a óò ge lulẹ̀, a sì wọ jù sínú iná.”
[God is ready to punish you if you do not turn away from your sinful behavior, just like a man] [MET] lays his axe at the roots [of a fruit] tree [to chop it down and throw it into the fire if it does not produce good fruit] [MET].”
10 Àwọn ènìyàn sì ń bi í pé, “Kí ni kí àwa kí ó ṣe?”
[Then] various ones in the crowd asked John, “What shall we [(exc)] do [to escape God punishing us] (OR), [to show that we have repented]?”
11 Ó dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ẹni tí ó bá ní ẹ̀wù méjì, kí ó fi ọ̀kan fún ẹni tí kò ní; ẹni tí ó bá sì ní oúnjẹ, kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.”
He answered them, “If any of you has two shirts, you should give one of them to someone who has no shirt. If any of you has [plenty of] food, you should give some to those who have no food.”
12 Àwọn agbowó òde sì tọ̀ ọ́ wá láti ṣe ìtẹ̀bọmi lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì bi í pé, “Olùkọ́, kí ni àwa ó ha ṣe?”
[Some] tax collectors came [and asked] to be baptized ([asked him] to baptize them}. They asked him, “Teacher, what shall we [(exc)] do [to please God]?”
13 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe fi agbára gbà jù bí a ti rán yín lọ mọ́.”
He said to them, “Do not take from the people any more money than [the Roman government] tells you to take!”
14 Àwọn ọmọ-ogun sì béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Àti àwa, kí ni àwa ó ṣe?” Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe hùwà ipá sí ẹnikẹ́ni, kí ẹ má sì ṣe ka ẹ̀sùn èké sí ẹnikẹ́ni; kí òwò ọ̀yà yín tó yín.”
Some soldiers asked him, “What about us? What should we [(exc)] do [to please God]?” He said to them, “Do not [say to anyone], ‘[If you(sg) do not give me] some money, I will hurt you,’ and do not take [people to court and] falsely accuse them of doing something wrong! And be content with your wages.”
15 Bí àwọn ènìyàn sì ti ń retí, tí gbogbo wọn sì ń rò nínú ara wọn nítorí Johanu, bí òun ni Kristi tàbí òun kọ́;
People were expecting [that the Messiah would come soon]. Because of that, many of them wondered about John. [Some of them asked him] if he was the Messiah.
16 Johanu dáhùn ó sì wí fún gbogbo wọn pé, “Lóòótọ́ ni èmi ń fi omi bamitiisi yín, ṣùgbọ́n ẹni tí ó lágbára jù mí lọ ń bọ̀, okùn bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó tú, Òun ni yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ àti iná bamitiisi yín.
John replied to them all, “No, [I am not]. I used [only] water when I baptized you. But [the Messiah] will soon come! He is far greater than I am. [He is so great that] I am not worthy to [be like his slave and] untie his sandals [MET] [like] a slave would do! He will put [his] Holy Spirit within [MTY] you [to truly change your lives], and [he will judge others of you and punish you in] the fire [MET] [in hell]. (questioned)
17 Ẹni tí àtẹ rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀, láti gbá ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ mọ́ tó tó, kí ó sì kó alikama rẹ̀ sínú àká; ṣùgbọ́n ìyàngbò ni yóò fi iná àjóòkú sun.”
He [is like a man] [MET] [who wants to] clear away the grain on the ground where it has been threshed {they have threshed it}. That man [uses] a huge fork [to throw the grain into the air] to separate the wheat from the chaff [MET], and then he cleans up the threshing area. [Similarly, God] will [separate righteous people from the evil people, like a man who] gathers the wheat into his storage area, and then he will burn [those who are like] chaff with a fire (that will never be put out/that will burn forever).”
18 Johanu lo oríṣìíríṣìí ọ̀rọ̀ púpọ̀ láti gba àwọn ènìyàn níyànjú àti láti wàásù ìyìnrere fún wọn.
John kept telling people many things to urge them [to turn to God], as he told them the good message [from God].
19 Ṣùgbọ́n nígbà ti Johanu bú Herodu tetrarki, tí ó bá wí nítorí Herodia aya Filipi arákùnrin rẹ̀, àti nítorí ohun búburú gbogbo tí Herodu tí ṣe,
He also rebuked [the ruler of the district], Herod [Antipas. He rebuked him] for [marrying] Herodias, his brother’s wife, [while his brother was still alive], and for doing many other evil things.
20 Ó fi èyí parí gbogbo rẹ̀ nígbà tí ó fi Johanu sínú túbú.
But Herod [had his soldiers] put John in prison. That was another evil thing he did.
21 Nígbà tí a ṣe ìtẹ̀bọmi àwọn ènìyàn gbogbo tán, ó sì ṣe, a bamitiisi Jesu pẹ̀lú, bí ó ti ń gbàdúrà, ọ̀run ṣí sílẹ̀,
[But before John was put in prison], when many people were being baptized {when he was baptizing many people}, after Jesus was baptized {he baptized Jesus} and Jesus was praying, the sky opened.
22 Ẹ̀mí Mímọ́ sì sọ̀kalẹ̀ sí orí rẹ̀ ní àwọ̀ àdàbà, ohùn kan sì ti ọ̀run wá, tí ó wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ ọmọ mi; ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
Then the Holy Spirit, resembling a dove, descended upon [Jesus]. And [God] [SYN/EUP] spoke to Jesus from heaven, saying, “You [(sg)] are my Son, whom I love dearly. I am very pleased with you!”
23 Jesu tìkára rẹ̀ ń tó bí ẹni ọgbọ̀n ọdún, nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ ó jẹ́ (bí a ti fi pè) ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Eli,
When Jesus began [his work for God], he was about 30 years old. It was {[People]} thought that he was [the son of] Joseph. [Joseph was the son] of Heli.
24 tí í ṣe ọmọ Mattati, tí í ṣe ọmọ Lefi, tí í ṣe ọmọ Meliki, tí í ṣe ọmọ Janai, tí í ṣe ọmọ Josẹfu,
[Heli was the son] of Matthat. [Matthat was the son] of Levi. [Levi was the son] of Melchi. [Melchi was the son] of Jannai. [Jannai was the son] of Joseph.
25 tí í ṣe ọmọ Mattatia, tí í ṣe ọmọ Amosi, tí í ṣe ọmọ Naumu, tí í ṣe ọmọ Esili, tí í ṣe ọmọ Nagai,
[Joseph was the son] of Mattathias. [Mattathias was the son] of Amos. [Amos was the son] of Nahum. [Nahum was the son] of Esli. [Esli was the son] of Naggai.
26 tí í ṣe ọmọ Maati, tí í ṣe ọmọ Mattatia, tí í ṣe ọmọ Ṣimei, tí í ṣe ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Joda,
[Naggai was the son] of Maath. [Maath was the son] of Mattathias. [Mattathias was the son] of Semein. [Semein was the son] of Josech. [Josech was the son] of Joda.
27 tí í ṣe ọmọ Joana, tí í ṣe ọmọ Resa, tí í ṣe ọmọ Serubbabeli, tí í ṣe ọmọ Ṣealitieli, tí í ṣe ọmọ Neri,
[Joda was the son] of Joanan. [Joanan was the son] of Rhesa. [Rhesa was the son] of Zerubbabel. [Zerubbabel was the son] of Shealtiel. [Shealtiel was the son] of Neri.
28 tí í ṣe ọmọ Meliki, tí í ṣe ọmọ Adi, tí í ṣe ọmọ Kosamu, tí í ṣe ọmọ Elmadamu, tí í ṣe ọmọ Eri,
[Neri was the son] of Melchi. [Melchi was the son] of Addi. [Addi was the son] of Cosam. [Cosam was the son] of Elmadam. [Elmadam was the son] of Er.
29 tí í ṣe ọmọ Joṣua, tí í ṣe ọmọ Elieseri, tí í ṣe ọmọ Jorimu, tí í ṣe Mattati, tí í ṣe ọmọ Lefi,
[Er was the son] of Joshua. [Joshua was the son] of Eliezer. [Eliezer was the son] of Jorim. [Jorim was the son] of Matthat. [Matthat was the son] of Levi.
30 tí í ṣe ọmọ Simeoni, tí í ṣe ọmọ Juda, tí í ṣe ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Jonamu, tí í ṣe ọmọ Eliakimu,
[Levi was the son] of Simeon. [Simeon was the son] of Judah. [Judah was the son] of Joseph. [Joseph was the son] of Jonam. [Jonam was the son] of Eliakim.
31 tí í ṣe ọmọ Melea, tí í ṣe ọmọ Menna, tí í ṣe ọmọ Mattata, tí í ṣe ọmọ Natani, tí í ṣe ọmọ Dafidi,
[Eliakim was the son] of Melea. [Melea was the son] of Menna. [Menna was the son] of Mattatha. [Mattatha was the son] of Nathan. [Nathan was the son] of David.
32 tí í ṣe ọmọ Jese, tí í ṣe ọmọ Obedi, tí í ṣe ọmọ Boasi, tí í ṣe ọmọ Salmoni, tí í ṣe ọmọ Nahiṣoni,
[David was the son] of Jesse. [Jesse was the son] of Obed. [Obed was the son] of Boaz. [Boaz was the son] of Sala. [Sala was the son] of Nahshon.
33 tí í ṣe ọmọ Amminadabu, tí í ṣe ọmọ Ramu, tí í ṣe ọmọ Hesroni, tí í ṣe ọmọ Peresi, tí í ṣe ọmọ Juda.
[Nahshon was the son] of Amminadab. [Amminadab was the son] of Admin. [Admin was the son] of Arni. [Arni was the son] of Hezron. [Hezron was the son] of Perez. [Perez was the son] of Judah.
34 Tí í ṣe ọmọ Jakọbu, tí í ṣe ọmọ Isaaki, tí í ṣe ọmọ Abrahamu, tí í ṣe ọmọ Tẹra, tí í ṣe ọmọ Nahori,
[Judah was the son] of Jacob. [Jacob was the son] of Isaac. [Isaac was the son] of Abraham. [Abraham was the son] of Terah. [Terah was the son] of Nahor.
35 tí í ṣe ọmọ Serugu, tí í ṣe ọmọ Reu, tí í ṣe ọmọ Pelegi, tí í ṣe ọmọ Eberi, tí í ṣe ọmọ Ṣela.
[Nahor was the son] of Serug. [Serug was the son] of Reu. [Reu was the son] of Peleg. [Peleg was the son] of Eber. [Eber was the son] of Shelah.
36 Tí í ṣe ọmọ Kainani, tí í ṣe ọmọ Arfaksadi, tí í ṣe ọmọ Ṣemu, tí í ṣe ọmọ Noa, tí í ṣe ọmọ Lameki,
[Shelah was the son] of Cainan. [Cainan was the son] of Arphaxad. [Arphaxad was the son] of Shem. [Shem was the son] of Noah. [Noah was the son] of Lamech.
37 tí í ṣe ọmọ Metusela, tí í ṣe ọmọ Enoku, tí í ṣe ọmọ Jaredi, tí í ṣe ọmọ Mahalaleli, tí í ṣe ọmọ Kainani.
[Lamech was the son] of Methuselah. [Methuselah was the son] of Enoch. [Enoch was the son] of Jared. [Jared was the son] of Mahalalel. [Mahalalel was the son] of Cainan.
38 Tí í ṣe ọmọ Enosi, tí í ṣe ọmọ Seti, tí í ṣe ọmọ Adamu, tí í ṣe ọmọ Ọlọ́run.
[Cainan was the son] of Enos. [Enos was the son] of Seth. [Seth was the son] of Adam. [Adam was the man] God created.

< Luke 3 >