< Luke 10 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Olúwa sì yan méjìléláàádọ́rin ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn pẹ̀lú, ó sì rán wọn ní méjì méjì lọ ṣáájú rẹ̀, sí gbogbo ìlú àti ibi tí òun tìkára rẹ̀ yóò sì dé.
Le Seigneur, après cela, désigna encore soixante et dix autres disciples, et il leur donna mission de le précéder deux par deux dans toute ville, dans tout endroit où lui-même devait aller.
2 Ó sì wí fún wọn pé, “Ìkórè pọ̀, ṣùgbọ́n àwọn alágbàṣe kò tó nǹkan, nítorí náà ẹ bẹ Olúwa ìkórè, kí ó lè rán àwọn alágbàṣe sínú ìkórè rẹ̀.
Il leur disait: «La moisson est grande et les ouvriers en petit nombre; priez donc le maître de la moisson d'envoyer des ouvriers dans sa moisson.»
3 Ẹ mú ọ̀nà yín pọ̀n: sá wò ó, èmi rán yín lọ bí ọ̀dọ́-àgùntàn sáàrín ìkookò.
«Allez; voici que je vous envoie comme des agneaux au milieu de loups.»
4 Ẹ má ṣe mú àpò, ẹ má ṣe mú àpamọ́wọ́, tàbí bàtà: ẹ má sì ṣe kí ẹnikẹ́ni lọ́nà.
«N'emportez ni bourse, ni sac, ni chaussures, et en chemin ne saluez personne.
5 “Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá wọ̀, kí ẹ kọ́ wí pé, ‘Àlàáfíà fún ilé yìí!’
Dans toute maison où vous entrerez que votre première parole soit: «Paix à cette maison!»
6 Bí ọmọ àlàáfíà bá sì wà níbẹ̀, àlàáfíà yín yóò bà lé e: ṣùgbọ́n bí kò bá sí, yóò tún padà sọ́dọ̀ yín.
Et s'il s'y trouve quelque enfant de paix, sur lui reposera votre paix; sinon elle reviendra à vous.
7 Ẹ dúró sínú ilé náà, kí ẹ máa jẹ, kí ẹ sì máa mu ohunkóhun tí wọ́n bá fi fún yín, nítorí ọ̀yà alágbàṣe tọ́ sí i. Ẹ má ṣe lọ láti ilé dé ilé.
Demeurez dans cette maison-là, mangeant et buvant ce qui s'y trouvera, car l'ouvrier est digne de son salaire.» «Ne pérégrinez pas de maison en maison.»
8 “Ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá wọ̀, tí wọ́n bá sì gbà yín, ẹ jẹ ohunkóhun tí a bá gbé ka iwájú yín.
«Dans toute ville où vous entrerez, et où l'on vous recevra, mangez ce qui vous sera offert;
9 Ẹ sì mú àwọn aláìsàn tí ń bẹ nínú rẹ̀ láradá, kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀ sí yín!’
guérissez les malades qui sont dans la ville, et dites-leur: «Le Règne de Dieu s'est approché de vous.»
10 Ṣùgbọ́n ní ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, tí wọn kò bá sì gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá sì jáde ní ìgboro ìlú náà, kí ẹ̀yin sì wí pé,
Dans toute ville où vous entrerez et où l'on ne vous recevra pas, sortez sur les places publiques et dites:
11 ‘Eruku ìlú yín tí ó kù sí wa lẹ́sẹ̀, a gbọ̀n ọ́n sílẹ̀ fún yín! Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.’
«La poussière même de votre ville qui s'est attachée à nos pieds, nous la secouons pour vous la rendre; sachez cependant ceci: «Le Règne de Dieu approche!»
12 Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Sodomu ní ọjọ́ náà, ju fún ìlú náà lọ.
Je vous déclare qu'en ce jour-là! il y aura moins de rigueur pour Sodome que pour cette ville-là.
13 “Ègbé ni fún ìwọ, Korasini! Ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Nítorí ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ agbára tí a ṣe nínú yín, ní Tire àti Sidoni, wọn ìbá ti ronúpìwàdà lọ́jọ́ pípẹ́ sẹ́yìn, wọn ìbá sì jókòó nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti nínú eérú.
Malheur à toi Chorazein, malheur à toi Bethsaïda, car, si les miracles faits au milieu de vous l'avaient été dans Tyr et dans Sidon, elles se seraient depuis longtemps repenties en se revêtant d'un sac et assises dans la cendre.
14 Ṣùgbọ́n yóò sàn fún Tire àti Sidoni nígbà ìdájọ́ jù fún yín lọ.
Aussi y aura-t-il au jugement moins de rigueur pour Tyr et pour Sidon que pour vous.
15 Àti ìwọ, Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga dé òkè ọ̀run? A ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ dé isà òkú. (Hadēs g86)
Et toi, Capharnaüm, crois-tu que tu seras élevée jusqu'au ciel? Tu seras abaissée jusqu'à la Demeure-des-morts.» (Hadēs g86)
16 “Ẹni tí ó bá gbọ́ tiyín, ó gbọ́ tèmi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ yín, ó kọ̀ mi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ mi, ó kọ ẹni tí ó rán mi.”
«Qui vous écoute, m'écoute; qui vous méprise, me méprise; or qui me méprise, méprise Celui qui m'a envoyé.»
17 Àwọn àádọ́rin náà sì fi ayọ̀ padà, wí pé, “Olúwa, àwọn ẹ̀mí èṣù tilẹ̀ foríbalẹ̀ fún wa ní orúkọ rẹ.”
Les soixante-dix revinrent pleins de joie; ils disaient: «Seigneur, les démons mêmes se soumettent à nous en ton nom.»
18 Ó sì wí fún wọn pé, “Èmí rí Satani ṣubú bí mọ̀nàmọ́ná láti ọ̀run wá.
Il leur répondit: «Je voyais Satan tomber du ciel comme un éclair!
19 Kíyèsi i, èmí fún yín ní àṣẹ láti tẹ ejò àti àkéekèe mọ́lẹ̀, àti lórí gbogbo agbára ọ̀tá, kò sì ṣí ohun kan bí ó ti wù tí ó ṣe, tí yóò pa yín lára.
Oui, je vous ai donné la puissance de fouler aux pieds et des serpents et des scorpions et toutes les forces de l'Ennemi, et aucun mal ne vous arrivera.
20 Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe yọ̀ nítorí èyí pé, àwọn ẹ̀mí ń foríbalẹ̀ fún yín; ṣùgbọ́n ẹ kúkú yọ̀, pé; a kọ̀wé orúkọ yín ní ọ̀run!”
Toutefois ne vous réjouissez pas de ce que les Esprits vous sont soumis; réjouissez-vous de ce que vos noms sont écrits dans les cieux!»
21 Ní wákàtí kan náà Jesu yọ̀ nínú Ẹ̀mí mímọ́ ó sì wí pé, “Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ pa nǹkan wọ̀nyí mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n àti amòye, ìwọ sì fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ ọwọ́. Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, bẹ́ẹ̀ ni ó sá à yẹ ní ojú rẹ.
En ce moment même, il dit dans un transport de joie venu de l’Esprit saint: «Je te bénis, ô Père, ô Seigneur du ciel et de la terre, de ce que tu as caché ces choses à des sages et à des savants, et de ce que tu les as révélées à de petits enfants. Oui, Père, je te bénis de ce que tel a été ton bon plaisir.
22 “Ohun gbogbo ni a ti fi fún mi láti ọ̀dọ̀ Baba mi; kò sì ṣí ẹni tí ó mọ ẹni tí ọmọ jẹ́, bí kò ṣe Baba, àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wu ọmọ láti fi í hàn fún.”
Tout m'a été confié par mon Père, et personne ne sait qui est le Fils excepté le Père, et qui est le Père excepté le Fils et celui à qui il plaît au Fils de le révéler.»
23 Ó sì yípadà sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní apá kan. Ó ní, “Ìbùkún ni fún ojú tí ń rí ohun tí ẹ̀yin ń rí.
Puis, se tournant vers les disciples, il leur dit en particulier: «Heureux les yeux qui voient ce que vous voyez!
24 Nítorí mo wí fún yín, ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì àti àwọn ọba ni ó ń fẹ́ láti rí ohun tí ẹ̀yin ń rí, wọn kò sì rí wọn, àti láti gbọ́ ohun tí ẹ̀yin ń gbọ́, wọn kò sì gbọ́ wọn.”
Je vous déclare, en effet, que nombre de prophètes et de rois ont voulu voir ce que vous, vous voyez, et ne l'ont pas vu, entendre ce que vous entendez, et ne l'ont pas entendu.»
25 Sì kíyèsi i amòfin kan dìde, ó ń dán an wò, ó ní, “Olùkọ́, kín ni èmi ó ṣe kí èmi lè jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
Voulant le mettre à l'épreuve, un légiste se leva et lui dit: «Maître, que dois-je faire pour acquérir la vie éternelle?» — (aiōnios g166)
26 Ó sì bi í pé, “Kí ni a kọ sínú ìwé òfin? Báwo ni ìwọ sì ti kà á?”
«Qu'y a-t-il d'écrit dans la Loi? lui demanda Jésus; qu'est-ce que tu y lis?»
27 Ó sì dáhùn wí pé, “‘Kí ìwọ fi gbogbo àyà rẹ, àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ, àti gbogbo inú rẹ fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ’; àti, ‘Ẹnìkejì rẹ bí ara rẹ.’”
Le légiste lui fit cette réponse: «Tu aimeras le Seigneur ton Dieu de tout ton coeur, de toute ton âme, de toute ta force, de toute ta pensée et ton prochain comme toi-même.» —
28 Ó sì wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn rere. Ṣe èyí, ìwọ ó sì yè.”
«Parfaitement répondu! dit Jésus; fais cela et tu vivras.»
29 Ṣùgbọ́n ó ń fẹ́ láti da ara rẹ̀ láre, ó wí fún Jesu wí pé, “Ta ha sì ni ẹnìkejì mi?”
Mais le légiste, voulant se justifier lui-même, dit à Jésus: «Qui donc est «mon prochain?»;
30 Jesu sì dáhùn ó wí pé, “Ọkùnrin kan ń ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jeriko, ó sì bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà; wọ́n gbà á ní aṣọ, wọ́n sá a lọ́gbẹ́, wọ́n sì fi sílẹ̀ lọ ní àìpatán.
Jésus reprit alors: «Un homme descendait de Jérusalem à Jéricho; il tomba entre les mains de brigands qui le dépouillèrent et partirent, le laissant couvert de blessures et à moitié mort.
31 Ní kòńgẹ́ àkókò yìí ni àlùfáà kan sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ lọ́nà náà. Nígbà tí ó sì rí i ó kọjá lọ níhà kejì.
Or un prêtre descendait, par hasard, par la même route; il vit l'homme, et il passa outre.
32 Bẹ́ẹ̀ náà sì ni ọmọ Lefi kan pẹ̀lú, nígbà tí ó dé ibẹ̀, tí ó sì rí i, ó kọjá lọ níhà kejì.
Un Lévite fit de même; arrivé à l'endroit, il vit, et il passa outre.
33 Ṣùgbọ́n ará Samaria kan, bí ó ti ń re àjò, ó dé ibi tí ó gbé wà; nígbà tí ó sì rí i, àánú ṣe é.
Mais un certain Samaritain, qui était en voyage, arriva près de l'homme et fut, en le voyant, touché de compassion;
34 Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì di ọgbẹ́ rẹ̀, ó da òróró àti ọtí wáìnì sí i, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti òun tìkára rẹ̀, ó sì mú un wá sí ilé èrò, a sì ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
il s'approcha de lui, il banda ses plaies après y avoir versé de l'huile et du vin, puis il le plaça sur sa propre monture, l'amena dans une hôtellerie, et lui donna des soins.
35 Nígbà tí ó sì lọ ní ọjọ́ kejì, ó fi owó idẹ méjì fún olórí ilé èrò ó sì wí fún un pé, ‘Máa tọ́jú rẹ̀; ohunkóhun tí ìwọ bá sì ná kún un, nígbà tí mo bá padà dé, èmi ó san án fún ọ.’
Le lendemain, il tira deux deniers, les remit à l'hôtelier et lui dit: «Tu prendras soin de cet homme; et ce que tu dépenseras de plus, moi-même, à mon retour, je te le rembourserai.»
36 “Nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí, ta ni ìwọ rò pé ó jẹ́ ẹnìkejì ẹni tí ó bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà?”
Lequel de ces trois te paraît avoir été le prochain de celui qui était tombé entre les mains des brigands?» —
37 Ó sì dáhùn wí pé, “Ẹni tí ó ṣàánú fún un ni.” Jesu sì wí fún un pé, “Lọ, kí o ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́!”
«C'est celui qui a été compatissant envers lui», répondit le Légiste. Jésus lui dit alors: «Va et agis de même, toi aussi.»
38 Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, o wọ ìletò kan, obìnrin kan tí a ń pè ní Marta sì gbà á sí ilé rẹ̀.
Dans un village où Jésus entra pendant qu'ils étaient en route, ce fut une femme nommée Marthe qui le reçut dans sa maison.
39 Ó sì ní arábìnrin kan tí a ń pè ní Maria tí ó sì jókòó lẹ́bàá ẹsẹ̀ Olúwa, tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Elle avait une soeur appelée Marie, qui, assise aux pieds du Seigneur, écoutait sa parole.
40 Ṣùgbọ́n Marta ń ṣe ìyọnu ohun púpọ̀, ó sì tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Olúwa, ìwọ kò sì bìkítà sí ti arábìnrin mi pé ó fi mí sílẹ̀ láti máa nìkan ṣe ìránṣẹ́? Wí fún un kí ó ràn mí lọ́wọ́.”
Marthe cependant était absorbée par toutes sorte de soins; elle s'arrêta pour dire: «Seigneur, n'as-tu aucun souci de ce que ma soeur m'a laissée servir toute seule? dis-lui donc de m'aider.»
41 Ṣùgbọ́n Olúwa sì dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Marta, Marta, ìwọ ń ṣe àníyàn àti làálàá nítorí ohun púpọ̀.
Mais le Seigneur lui fit cette réponse: «Marthe, Marthe, tu t'inquiètes, tu te troubles pour une multitude de choses;
42 Ṣùgbọ́n ohun kan ni a kò lè ṣe aláìní, Maria sì ti yan ipa rere náà tí a kò lè gbà lọ́wọ́ rẹ̀.”
une seule chose est nécessaire. Marie a choisi la bonne part qui ne lui sera point ôtée.»

< Luke 10 >