< Mark 1 >

1 Ìbẹ̀rẹ̀ ìyìnrere nípa Jesu Kristi, Ọmọ Ọlọ́run.
Commencement de l’Évangile de Jésus-Christ.
2 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé wòlíì Isaiah pé, “Èmi yóò ran oníṣẹ́ mi síwájú rẹ, Ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe.”
Ainsi qu’il est écrit dans le prophète Ésaïe: «Voici j'envoie mon messager pour te précéder Et te préparer le chemin;
3 “Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ ṣe ojú ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.’”
Une voix crie dans le désert: Préparez la voie du Seigneur, Aplanissez ses sentiers, »
4 Johanu dé, ẹni tí ó ń tẹnibọmi ní aginjù, tí ó sì ń wàásù ìtẹ̀bọmi ìrònúpìwàdà fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀.
Jean parut dans le désert, donnant et prêchant un baptême de repentance pour la rémission des péchés.
5 Gbogbo àwọn tí ń gbé ní agbègbè Judea, àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu jáde tọ̀ ọ́ lọ, a sì ti ọwọ́ rẹ̀ tẹ gbogbo wọn bọ omi ni odò Jordani, wọ́n ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Tout le pays de Judée et tous les habitants de Jérusalem accouraient à lui et ils étaient baptisés par lui dans le Jourdain, en confessant leurs péchés.
6 Johanu sì wọ aṣọ irun ìbákasẹ. Ó sì di àmùrè awọ mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Eṣú àti oyin ìgàn sì ni oúnjẹ rẹ̀.
Jean avait un vêtement de poils de chameau et une ceinture de cuir autour des reins, et il se nourrissait de sauterelles et de miel sauvage.
7 Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù wí pé, “Ẹnìkan tí ó tóbi jù mí lọ ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó ẹni tí ń tú.
Il disait dans sa prédication: «Il va venir, après moi, celui qui est plus puissant que moi! Je ne suis pas même digne, en me baissant, de délier la courroie de ses sandales.
8 Èmi ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi yín, ṣùgbọ́n Òun yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ ṣe ìtẹ̀bọmi yín.”
Moi, je vous ai baptisés d'eau; mais lui vous baptisera avec l'Esprit saint.»
9 Ó sì ṣe ní ọjọ́ kan Jesu ti Nasareti ti Galili jáde wá, a sì ti ọwọ́ Johanu ṣe ìtẹ̀bọmi fún ní odò Jordani.
Or, ce fut en ces jours mêmes que Jésus arriva de Nazareth en Galilée et il fut baptisé par Jean dans le Jourdain.
10 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ tí Jesu ń ti inú omi jáde wá, ó rí ọ̀run tí ó ṣí sílẹ̀, Ẹ̀mí Mímọ́ bí àdàbà sọ̀kalẹ̀ lé e lórí.
Soudain, comme il sortait de l'eau, il vit les cieux ouverts et l'Esprit en forme de colombe descendre sur lui,
11 Ohùn kan sì ti ọ̀run wá wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ Ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
et des cieux vint une voix: «Tu es mon Fils bien-aimé, en toi je me complais.»
12 Lẹ́sẹ̀kan náà, Ẹ̀mí Mímọ́ sì darí Jesu sí ijù,
Et l'Esprit aussitôt entraîna Jésus au désert;
13 Ó sì wà ní ogójì ọjọ́ ní aginjù. A sì ti ọwọ́ Satani dán an wò, ó sì wà pẹ̀lú àwọn ẹranko ìgbẹ́. Àwọn angẹli sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún un.
et il fut quarante jours dans le désert, tenté par Satan, et il fut parmi les bêtes, et les anges le servaient.
14 Lẹ́yìn ìgbà tí ọba Herodu ti fi Johanu sínú ẹ̀wọ̀n tan, Jesu lọ sí Galili, ó ń wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run.
Après que Jean eut été livré, Jésus se rendit en Galilée et y prêcha l'Évangile de Dieu:
15 Ó sì kéde wí pé, “Àkókò náà dé wàyí, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀. Ẹ yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, kí ẹ sì gba ìyìnrere yìí gbọ́.”
«Les temps sont accomplis; le Royaume de Dieu est proche; repentez-vous et croyez à l'Évangile.
16 Ní ọjọ́ kan, bí Jesu ti ń rìn létí Òkun Galili, Ó rí Simoni àti Anderu arákùnrin rẹ̀, wọ́n ń fi àwọ̀n wọn pẹja torí pé apẹja ni wọ́n.
Comme il longeait la mer de Galilée, il vit Simon et son frère André jetant leurs filets dans la mer, car ils étaient pêcheurs.
17 Jesu sì ké sí wọn wí pé, “Ẹ máa tọ̀ mí lẹ́yìn. Èmi yóò sì sọ yín di apẹja ènìyàn.”
Jésus leur dit: «Venez après moi et je vous ferai devenir des pêcheurs d'hommes.»
18 Ní kánkán wọ́n fi àwọ̀n wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ Ọ́ lẹ́yìn.
Sur-le-champ ils abandonnèrent les filets et le suivirent.
19 Bí Ó sì ti rìn síwájú díẹ̀, ní etí Òkun, Ó rí Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu arákùnrin rẹ̀ nínú ọkọ̀, wọ́n ń tún àwọ̀n wọn ṣe.
S'étant avancé un peu plus loin, il vit, dans leurs barques, Jacques, fils de Zébédée, et Jean, son frère, qui raccommodaient leurs filets.
20 Ó sì ké sí àwọn náà lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, wọ́n fi Sebede baba wọn sílẹ̀ nínú ọkọ̀ pẹ̀lú àwọn alágbàṣe, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Il les appela aussitôt; et ceux-ci, laissant leur père Zébédée dans la barque avec les hommes de service, partirent à sa suite.
21 Lẹ́yìn náà, Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ ìlú Kapernaumu, nígbà tí ó di òwúrọ̀ ọjọ́ ìsinmi, ó lọ sínú Sinagọgu, ó sì ń kọ́ni.
Ils arrivèrent à Capharnaüm. Il commença immédiatement à entrer les jours de sabbat dans la synagogue et à y enseigner;
22 Ẹnu sì ya ìjọ ènìyàn nítorí ìkọ́ni rẹ̀, nítorí pé ó ń kọ́ni bí ẹni tí ó ní àṣẹ, kì í ṣe bí àwọn olùkọ́ òfin ṣe ń kọ́ àwọn ènìyàn.
et ils étaient extrêmement frappés de son enseignement; car il le donnait comme ayant autorité, et non comme les Scribes.
23 Ní àsìkò náà gan an ni ọkùnrin kan tí ó wà nínú Sinagọgu wọn, tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe wí pé,
Il y avait à ce moment même dans leur synagogue un homme possédé d'un esprit impur; il s'écria:
24 “Kí ni ìwọ ń wá lọ́dọ̀ wa, Jesu ti Nasareti? Ṣé ìwọ wá láti pa wá run ni? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe; Ìwọ ní ẹni Mímọ́ Ọlọ́run!”
«Qu'y a-t-il entre nous et toi, Jésus de Nazareth? Tu es venu pour nous perdre; je sais qui tu es: le Saint de Dieu!»
25 Jesu si bá a wí, ó wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí ó sì jáde kúrò lára rẹ̀.”
Jésus alors le menaça: «Tais-toi! sors de cet homme!»
26 Ẹ̀mí àìmọ́ náà sì gbé e ṣánlẹ̀ lógèdèǹgbé, ó ké ní ohùn rara, ó sì jáde kúrò lára ọkùnrin náà.
Agitant violemment le possédé, l'Esprit impur sortit de lui en poussant un grand cri.
27 Ẹnu sì ya àwọn ènìyàn, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi ń sọ láàrín ara wọn ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀. Wọ́n béèrè pẹ̀lú ìgbóná ara, pé, “Kí ni èyí? Irú ẹ̀kọ́ tuntun wo ni èyí? Ó ń fi agbára pàṣẹ fún àwọn ẹ̀mí àìmọ́ pàápàá wọ́n sì gbọ́ tirẹ̀.”
Tous les assistants, terrifiés, s'interrogeaient les uns les autres: «Qu'est-ce que ceci? Voilà un enseignement nouveau! il commande avec autorité même aux Esprits impurs, et ils lui obéissent.»
28 Ìròyìn nípa rẹ̀ tàn ká gbogbo agbègbè Galili.
Sa renommée se répandit promptement et partout aux environs, dans la Galilée entière.
29 Nígbà tí wọn sì jáde kúrò nínú Sinagọgu, wọ́n lọ pẹ̀lú Jakọbu àti Johanu sí ilé Simoni àti Anderu.
En sortant de la synagogue, ils se rendirent tout d'abord, accompagnés de Jacques et de Jean, dans la maison de Simon et d’André.
30 Ìyá ìyàwó Simoni tí ó dùbúlẹ̀ àìsàn ibà, wọ́n sì sọ fún Jesu nípa rẹ̀.
La belle-mère de Simon était couchée; elle avait la fièvre. On s'empressa de le dire à Jésus.
31 Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó fà á lọ́wọ́, ó sì gbé e dìde; lójúkan náà ibà náà fi sílẹ̀, ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
Alors, s'approchant d'elle, il la prit par la main et la fit lever. La fièvre disparut et elle se mit à les servir.
32 Nígbà tí ó di àṣálẹ́, tí oòrùn wọ̀, wọ́n gbé gbogbo àwọn aláìsàn àti àwọn tó ni ẹ̀mí àìmọ́ tọ̀ ọ́ wá.
Le soir venu, après le coucher du soleil, on lui apporta tous les malades et les démoniaques.
33 Gbogbo ìlú si péjọ ni ẹnu-ọ̀nà.
La ville entière se pressait à la porte.
34 Jesu sì wo ọ̀pọ̀ tí wọ́n ní onírúurú ààrùn sàn. Bákan náà ni ó lé ọ̀pọ̀ ẹ̀mí àìmọ́ jáde. Ṣùgbọ́n kò sì jẹ́ kí àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà kí ó sọ̀rọ̀, nítorí tí wọ́n mọ ẹni tí òun í ṣe.
Il guérit plusieurs malades atteints de maux divers; il chassa aussi beaucoup de démons et il défendait aux démons de parler, parce qu'ils savaient qui il était.
35 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ilẹ̀ tó mọ́, Jesu nìkan jáde lọ sí aginjù kan, láti lọ gbàdúrà.
S'étant levé de grand matin, avant le jour, il alla dans un lieu solitaire et là il priait.
36 Simoni àti àwọn ènìyàn rẹ̀ yòókù lọ láti wá a.
Simon et ceux qui étaient avec lui se mirent à sa recherche.
37 Nígbà tí wọ́n sì rí I, wọ́n sọ fún wí pé, “Gbogbo ènìyàn ń wá ọ!”
Quand ils l'eurent trouvé, ils lui dirent: «Tout le monde te cherche.»
38 Jesu sì dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sí àwọn ìlú mìíràn, kí ń lè wàásù níbẹ̀ pẹ̀lú. Nítorí èyí ni èmi sá à ṣe wá.”
Il leur répondit: «Allons dans les villages voisins, afin que j'y prêche aussi, car c'est pour cela que je suis sorti.»
39 Nítorí náà, ó ń kiri gbogbo agbègbè Galili, ó ń wàásù nínú Sinagọgu. Ó sì ń lé àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde.
Il alla donc prêcher dans leurs synagogues et dans toute la Galilée, en chassant les démons.
40 Ọkùnrin adẹ́tẹ̀ kan tọ̀ ọ́ wá, ó sì kúnlẹ̀ níwájú rẹ̀. Ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ìmúláradá. Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, ìwọ lè mú mi láradá.”
Un lépreux vint à lui et, se jetant à ses genoux, lui adressa cette prière: «Si tu le veux, tu peux me guérir!»
41 Jesu kún fún àánú, ó na ọwọ́ rẹ̀, ó fi ọwọ́ rẹ̀ bà a, ó wí pé, “Èmí fẹ́. Di mímọ́.”
Il en eut compassion; il étendit la main et le toucha en disant: «Je le veux, sois guéri.»
42 Lójúkan náà ẹ̀tẹ̀ náà fi sílẹ̀ lọ, ọkùnrin náà sì rí ìwòsàn.
La lèpre disparut à l'instant; cet homme fut guéri.
43 Jesu sì kìlọ̀ fún un gidigidi
Jésus le congédia immédiatement, en lui donnant cet avertissement sévère:
44 Ó wí pé, “Lọ fi ara rẹ̀ hàn àlùfáà Júù fún àyẹ̀wò. Ṣùgbọ́n má ṣe dúró sọ ohunkóhun fún ẹnikẹ́ni ní ọ̀nà. Mú ẹ̀bùn lọ́wọ́, èyí tí Mose pàṣẹ fún adẹ́tẹ̀ tí a mú láradá. Èyí tí í ṣe ẹ̀rí pé, ó ti rí ìwòsàn.”
«Garde-toi de parler de ceci à personne; mais va te montrer au prêtre et offre pour ta guérison ce que Moïse a prescrit; que ce leur soit un témoignage.»
45 Ṣùgbọ́n ó jáde lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í pòkìkí, ó ń tan ìròyìn kálẹ̀. Nítorí èyí, Jesu kò sì le wọ ìlú ní gbangba mọ́, ṣùgbọ́n ó wà lẹ́yìn odi ìlú ní aginjù. Síbẹ̀, àwọn ènìyàn tọ̀ ọ́ wá láti ibi gbogbo.
Mais, à peine parti, le lépreux se mit à répandre la nouvelle et à la proclamer; de sorte que Jésus ne pouvait plus même paraître publiquement dans une ville; mais il se tenait dehors dans des endroits déserts, et on venait à lui de toutes parts.

< Mark 1 >