< John 4 >

1 Àwọn Farisi sì gbọ́ pé, Jesu ni, ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn púpọ̀ ju Johanu lọ.
ⲁ̅ϩⲟⲧⲉ ⲟⲩⲛ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ϫⲉ ⲁⲩⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲫⲁⲣⲓⲥⲉⲟⲥ ϫⲉ ⲁ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲑⲁⲙⲓⲉ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲙⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲛⲁϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥϯⲱⲙⲥ ⳿ⲉϩⲟⲧⲉ ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ.
2 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Jesu tìkára rẹ̀ kò ṣe ìtẹ̀bọmi bí kò ṣe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀,
ⲃ̅ⲕⲉⲧⲟⲓ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲁⲛ ⳿ⲉⲛⲁϥϯⲱⲙⲥ ⲁⲗⲗⲁ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲛⲉ.
3 Ó fi Judea sílẹ̀, ó sì tún lọ sí Galili.
ⲅ̅ⲁϥⲭⲱ ⳿ⲛϯⲓⲟⲩⲇⲉ⳿ⲁ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϣⲉ ⲛⲁϥ ⲟⲛ ⳿ⲉϯⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ.
4 Òun sì ní láti kọjá láàrín Samaria.
ⲇ̅ⲛⲉ ϩⲱϯ ⲇⲉ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲡⲉ ⳿ⲉⲥⲓⲛⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲧⲉⲛ ⳿ⲧⲥⲁⲙⲁⲣⲓⲁ.
5 Nígbà náà ni ó dé ìlú Samaria kan, tí a ń pè ní Sikari, tí ó súnmọ́ etí ilẹ̀ oko tí Jakọbu ti fi fún Josẹfu, ọmọ rẹ̀.
ⲉ̅ⲁϥ⳿ⲓ ⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲟⲩⲃⲁⲕⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲧⲥⲁⲙⲁⲣⲓ⳿ⲁ ⲉⲩⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟⲥ ϫⲉ ⲥⲩⲭⲁⲣ ⲉⲥϧⲉⲛⲧ ⳿ⲉⲡⲓⲓⲟϩⲓ ⲉⲧⲁ ⲓⲁⲕⲱⲃ ⲧⲏⲓϥ ⳿ⲛⲓⲱⲥⲏⲫ ⲡⲉϥϣⲏⲣⲓ.
6 Kànga Jakọbu sì wà níbẹ̀. Nítorí pé ó rẹ Jesu nítorí ìrìn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó jókòó létí kànga, ó sì jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́.
ⲋ̅ⲛⲁⲥⲭⲏ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲙⲟⲩⲙⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲓⲁⲕⲱⲃ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲛ ⲉⲧⲁϥϧⲓⲥⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲙⲱⲓⲧ ⳿ⲙⲙⲟϣⲓ ⲁϥϩⲉⲙⲥⲓ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ϩⲓϫⲉⲛ ϯⲙⲟⲩⲙⲓ ⲛⲉ ⳿ⲫⲛⲁⲩ ⳿ⲛⲁϫⲡ ⲡⲉ.
7 Obìnrin kan, ará Samaria sì wá láti fà omi, Jesu wí fún un pé ṣe ìwọ yóò fún mi ni omi mu.
ⲍ̅ⲁⲥ⳿ⲓ ⲟⲩⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲥⲁⲙⲁⲣⲓⲁ ⳿ⲉⲙⲁϩ ⲙⲱⲟⲩ ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⲙⲟⲓ ⲛⲏⲓ ⳿ⲛⲧⲁⲥⲱ.
8 Nítorí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ti lọ sí ìlú láti lọ ra oúnjẹ.
ⲏ̅ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲇⲉ ⲛⲉ ⲁⲩϣⲉ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲉ ϯⲃⲁⲕⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲟⲩϣⲱⲡ ⳿ⲛϩⲁⲛ⳿ϧⲣⲏⲟⲩⲓ ⲛⲱⲟⲩ.
9 Obìnrin ará Samaria náà sọ fún un pé, “Júù ni ìwọ, obìnrin ará Samaria ni èmi. Èétirí tí ìwọ ń béèrè ohun mímu lọ́wọ́ mi?” (Nítorí tí àwọn Júù kì í bá àwọn ará Samaria ṣe pọ̀.)
ⲑ̅ⲡⲉϫⲉ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲛⲁϥ ⳿ⲛⲥⲁⲙⲁⲣⲓⲧⲏⲥ ϫⲉ ⲡⲱⲥ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲟⲩⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⳿ⲕⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲛⲧⲟⲧ ⳿ⲉⲥⲱ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲟⲩ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲛⲥⲁⲙⲁⲣⲓⲧⲏⲥ ⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲡⲁⲣⲉ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ ⲙⲟⲩϫⲧ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲥⲁⲙⲁⲣⲓⲧⲏⲥ.
10 Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ìbá ṣe pé ìwọ mọ ẹ̀bùn Ọlọ́run, àti ẹni tí ó wí fún ọ pé, ‘Fún mi ni omi mu’, ìwọ ìbá sì ti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, òun ìbá ti fi omi ìyè fún ọ.”
ⲓ̅ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⳿ⲉⲛⲁⲣⲉ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉϯⲇⲱⲣⲉ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ ⲟⲩⲟϩ ϫⲉ ⲛⲓⲙ ⲡⲉⲧϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲉ ϫⲉ ⲙⲟⲓ ⲛⲏⲓ ⳿ⲛⲧⲁⲥⲱ ⳿ⲛⲑⲟ ⲛⲁⲣⲉⲉⲣⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥϯ ⲛⲉ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲱⲟⲩ ⲉϥⲟⲛϧ.
11 Obìnrin náà wí fún un pé, “Alàgbà, ìwọ kò ní igbá-ìfami tí ìwọ ó fi fà omi, bẹ́ẹ̀ ni kànga náà jì, Níbo ni ìwọ ó ti rí omi ìyè náà?
ⲓ̅ⲁ̅ⲡⲉϫⲉ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲛⲁϥ ϫⲉ Ⲡ⳪ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲁⲛ⳿ⲧⲗⲏⲙⲁ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲕ ⲟⲩⲟϩ ϯϣⲱϯ ϣⲏⲕ ⲉϥ⳿ⲉ⳿ⲛⲧⲟⲧⲕ ⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲑⲱⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲙⲱⲟⲩ ⲉⲧⲟⲛϧ.
12 Ìwọ pọ̀ ju Jakọbu baba wa lọ bí, ẹni tí ó fún wa ní kànga náà, tí òun tìkára rẹ̀ si mu nínú rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀, àti àwọn ẹran ọ̀sìn rẹ̀?”
ⲓ̅ⲃ̅ⲙⲏ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⳿ⲉⲡⲉⲛⲓⲱⲧ ⲓⲁⲕⲱⲃ ⲫⲏⲉⲧⲁϥϯ ⲛⲁⲛ ⳿ⲛⲧⲁⲓϣⲱϯ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲟϥ ϩⲱϥ ⲁϥⲥⲱ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⲛⲉⲙ ⲛⲉϥϣⲏⲣⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲉϥϣⲁⲛϣ.
13 Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá mu nínú omi yìí, òǹgbẹ yóò sì tún gbẹ ẹ́.
ⲓ̅ⲅ̅ⲁϥⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲑⲛⲁⲥⲱ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲙⲱⲟⲩ ⲫⲏ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⳿ⲉϯⲛⲁⲧⲏⲓϥ ⲛⲁϥ ⳿ⲛⲛⲉϥ⳿ⲓⲃⲓ ϣⲁ ⳿ⲉⲛⲉϩ.
14 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá mu nínú omi tí èmi ó fi fún un, òǹgbẹ kì yóò gbẹ ẹ́ mọ́ láé; ṣùgbọ́n omi tí èmi ó fi fún un yóò di kànga omi nínú rẹ̀, tí yóò máa sun si ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōn g165, aiōnios g166)
ⲓ̅ⲇ̅ⲁⲗⲗⲁ ⲡⲓⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲉϯⲛⲁⲧⲏⲓϥ ⲛⲁϥ ⲉϥ⳿ⲉϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲟⲩⲙⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲉϥ⳿ⲉϭⲓⲫⲉⲓ ⲉⲩⲱⲛϧ ⳿ⲛ⳿ⲉⲛⲉϩ. (aiōn g165, aiōnios g166)
15 Obìnrin náà sì wí fún u pé, “Alàgbà, fún mi ní omi yìí, kí òǹgbẹ kí ó má ṣe gbẹ mí, kí èmi kí ó má sì wá fa omi níbí mọ́.”
ⲓ̅ⲉ̅ⲡⲉϫⲉ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲡⲁ⳪ ⲙⲟⲓ ⲛⲏⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲙⲱⲟⲩ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲁ⳿ϣⲧⲉⲙ⳿ⲓⲃⲓ ϫⲉ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲛⲧⲁ⳿ϣⲧⲉⲙ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ⲙⲛⲁⲓ ⳿ⲉⲙⲁϩ ⲙⲱⲟⲩ.
16 Jesu wí fún un pé, “Lọ pe ọkọ rẹ, kí ó sì padà wá sí ìhín yìí.”
ⲓ̅ⲋ̅ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⲙⲁϣⲉ ⲛⲉ ⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲡⲉϩⲁⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲙⲏ ⳿ⲉ⳿ⲙⲛⲁⲓ.
17 Obìnrin náà dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Èmi kò ní ọkọ.” Jesu wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn dáradára pé, èmi kò ní ọkọ:
ⲓ̅ⲍ̅ⲁⲥⲉⲣⲟⲩⲱ ⳿ⲛϫⲉ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁⲥ ϫⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛϯ ϩⲁⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⲕⲁⲗⲱⲥ ⲁⲣⲉϫⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛϯ ϩⲁⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ.
18 Nítorí tí ìwọ ti ní ọkọ márùn-ún rí, ọkùnrin tí ìwọ sì ní báyìí kì í ṣe ọkọ rẹ. Ohun tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ tán yìí, òtítọ́ ni.”
ⲓ̅ⲏ̅ⲉ̅ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϩⲁⲓ ⲁⲣⲉϭⲓⲧⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲑⲛⲉⲙⲉ ϯⲛⲟⲩ ⲡⲉϩⲁⲓ ⲁⲛ ⲡⲉ ⲫⲁⲓ ⲟⲩⲙⲏⲓ ⲡⲉ ⲉⲧⲁⲣⲉϫⲟϥ.
19 Obìnrin náà wí fún un pé, “Alàgbà, mo wòye pé, wòlíì ni ìwọ ń ṣe.
ⲓ̅ⲑ̅ⲡⲉϫⲉ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲡⲁ⳪ ϯⲛⲁⲩ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲟⲩ⳿ⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ.
20 Àwọn baba wa sìn lórí òkè yìí; ẹ̀yin sì wí pé, Jerusalẹmu ni ibi tí ó yẹ tí à bá ti máa sìn.”
ⲕ̅ⲛⲉⲛⲓⲟϯ ⲁⲩⲟⲩⲱϣⲧ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲁⲓⲧⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲇⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲁⲣⲉ ⲡⲓⲙⲁ⳿ⲛⲟⲩⲱϣⲧ ϧⲉⲛ ⳿ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⲡⲓⲙⲁ ⲉⲧⲉ⳿ⲥϣⲉ ⳿ⲛⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
21 Jesu wí fún un pé, “Gbà mí gbọ́ obìnrin yìí, àkókò náà ń bọ̀, nígbà tí kì yóò ṣe lórí òkè yìí tàbí ní Jerusalẹmu ni ẹ̀yin ó máa sin Baba.
ⲕ̅ⲁ̅ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲧⲉⲛϩⲟⲩⲧ ϫⲉ ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲟⲩⲛⲟⲩ ϩⲟⲧⲉ ⲟⲩⲇⲉ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲁⲓⲧⲱⲟⲩ ⲟⲩⲇⲉ ϧⲉⲛ ⳿ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⲉⲩⲛⲁⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲙ⳿ⲫⲓⲱⲧ.
22 Ẹ̀yin ń sin ohun tí ẹ̀yin kò mọ̀, àwa ń sin ohun tí àwa mọ̀, nítorí ìgbàlà ti ọ̀dọ̀ àwọn Júù wá.
ⲕ̅ⲃ̅⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲙⲫⲏⲉⲧⲉⲧⲉ⳿ⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲁⲛ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲇⲉ ⲧⲉⲛⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲙⲫⲏⲉⲧⲉ⳿ⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϫⲉ ⲡⲓⲟⲩϫⲁⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲓⲟⲩⲇⲁⲓ.
23 Ṣùgbọ́n àkókò ń bọ̀, ó sì dé tán nísinsin yìí, nígbà tí àwọn olùsìn tòótọ́ yóò máa sin Baba ní ẹ̀mí àti ní òtítọ́, nítorí irú wọn ni Baba ń wá kí ó máa sin òun.
ⲕ̅ⲅ̅ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲟⲩⲛⲟⲩ ⲉⲧⲉ ϯⲛⲟⲩ ⲧⲉ ϩⲟⲧⲉ ⲛⲓⲣⲉϥⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲛⲧⲁ⳿ⲫⲙⲏⲓ ⲉⲩⲛⲁⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲙ⳿ⲫⲓⲱⲧ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲙⲉⲑⲙⲏ ⲓ ⲕⲉ ⲅⲁⲣ ⳿ⲫⲓⲱⲧ ⲁϥⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲁ ⲛⲁⲓ ⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲛⲏⲉⲑⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
24 Ẹ̀mí ni Ọlọ́run: àwọn ẹni tí ń sìn ín kò lè ṣe aláìsìn ín ní Ẹ̀mí àti ní òtítọ́.”
ⲕ̅ⲇ̅ⲟⲩⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲡⲉ ⲫϯ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲏⲉⲑⲛⲁⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲥⲉ⳿ⲙ⳿ⲡϣⲁ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲙⲙⲟϥ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲙⲉⲑⲙⲏⲓ.
25 Obìnrin náà wí fún un pé, mo mọ̀ pé, “Messia ń bọ̀ wá, tí a ń pè ní Kristi, nígbà tí Òun bá dé, yóò sọ ohun gbogbo fún wa.”
ⲕ̅ⲉ̅ⲡⲉϫⲉ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⲙⲉⲥⲓⲁⲥ ⲛⲏⲟⲩ ⲫⲏⲉⲧⲟⲩⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅ ⲉϣⲱⲡ ⲁϥϣⲁⲛ⳿ⲓ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲉⲑⲛⲁⲧⲁⲙⲟⲛ ⳿ⲉϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ.
26 Jesu sọ ọ́ di mí mọ̀ fún un pé, “Èmi ẹni tí ń bá ọ sọ̀rọ̀ yìí ni Òun.”
ⲕ̅ⲋ̅ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲡⲉ ⲫⲏⲉⲧⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙⲉ.
27 Lákokò yí ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ dé, ẹnu sì yà wọ́n pé ó ń bá obìnrin sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó wí pé, “Kí ni ìwọ ń wá?” tàbí “Èéṣe tí ìwọ fi ń bá a sọ̀rọ̀?”
ⲕ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ϧⲉⲛ ⲫⲁⲓ ⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏ ⲧⲏⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ϫⲉ ⳿ϥⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙ ⲟⲩ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⳿ⲙⲡⲉ ⳿ϩⲗⲓ ⲙⲉⲛⲧⲟⲓ ϫⲟⲥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲁⲕⲕⲱϯ ⳿ⲛⲥⲁ ⲟⲩ ⲓⲉ ⲉⲑⲃⲉⲟⲩ ⳿ⲕⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙⲁⲥ.
28 Nígbà náà ni obìnrin náà fi ládugbó rẹ̀ sílẹ̀, ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n lọ sí ìlú, ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé,
ⲕ̅ⲏ̅ⲁⲥⲭⲱ ⲟⲩⲛ ⳿ⲛⲧⲉⲥϩⲩⲇⲣⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛϫⲉ ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥϣⲉ ⲛⲁⲥ ⳿ⲉϯⲃⲁⲕⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁⲥ ⳿ⲛⲛⲓⲣⲱⲙⲓ.
29 “Ẹ wá wò ọkùnrin kan, ẹni tí ó sọ ohun gbogbo tí mo ti ṣe rí fún mi, èyí ha lè jẹ́ Kristi náà?”
ⲕ̅ⲑ̅ϫⲉ ⳿ⲁⲙⲱⲓⲛⲓ ⳿ⲁⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲡⲁⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲉⲁϥϫⲉ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲏⲓ ⲉⲧⲁⲓⲁⲓⲧⲟⲩ ⲙⲏⲧⲓ ⲫⲁⲓ ⲡⲉ Ⲡⲭ̅ⲥ̅.
30 Nígbà náà ni wọ́n ti ìlú jáde, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá.
ⲗ̅ⲛⲁⲩⲛⲏⲟⲩ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϯⲃⲁⲕⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲛⲏⲟⲩ ϩⲁⲣⲟϥ.
31 Láàrín èyí, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń rọ̀ ọ́ wí pé, “Rabbi, jẹun.”
ⲗ̅ⲁ̅ⲛⲁⲩϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲡⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲟⲩⲧⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙⲁϥ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲣⲁⲃⲃⲓ ⲧⲱⲛⲕ ⲟⲩⲱⲙ.
32 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Èmi ní oúnjẹ láti jẹ, tí ẹ̀yin kò mọ̀.”
ⲗ̅ⲃ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲟⲩⲟⲛϯ ⲟⲩ⳿ϧⲣⲉ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲙⲥ ⲑⲏ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲉⲧⲉⲧⲉ⳿ⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲁⲛ.
33 Nítorí náà ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ń bi ara wọn lérè wí pé, “Ẹnìkan mú oúnjẹ fún un wá láti jẹ bí?”
ⲗ̅ⲅ̅ⲛⲁⲩϫⲱ ⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲛⲟⲩⲉⲣⲏⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ϫⲉ ⲙⲏⲧⲓ ⲁⲛ ⲁ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲓⲛⲓ ⲛⲁϥ ⲉⲑⲣⲉϥⲟⲩⲱⲙ.
34 Jesu wí fún wọn pé, “Oúnjẹ mi ni láti ṣe ìfẹ́ ẹni tí ó rán mi, àti láti parí iṣẹ́ rẹ̀.
ⲗ̅ⲇ̅ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲧⲁ⳿ϧⲣⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲧⲉ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲁⲉⲣ ⳿ⲫⲟⲩⲱϣ ⳿ⲙⲫⲏⲉⲧⲁϥⲧⲁⲟⲩⲟⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲁϫⲱⲕ ⳿ⲙⲡⲉϥϩⲱⲃ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
35 Ẹ̀yin kò ha wí pé, ‘Ó ku oṣù mẹ́rin, ìkórè yóò sì dé?’ wò ó, mo wí fún un yín, Ẹ ṣí ojú yín sókè, kí ẹ sì wo oko; nítorí tí wọn ti pọ́n fún ìkórè.
ⲗ̅ⲉ̅ⲙⲏ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲁⲛ ⲉⲧϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲉⲧⲓ ⲕⲉⲇ̅ ⳿ⲛ⳿ⲁⲃⲟⲧ ⳿ϥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲱⲥϧ ϩⲏⲡⲡⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ϯϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϫⲉ ϥⲁⲓ ⳿ⲛⲛⲉⲧⲉⲛⲃⲁⲗ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲱⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲛⲓⲭⲱⲣⲁ ϫⲉ ⲁⲩⲟⲩⲃⲁϣ ⳿ⲉⲡⲟⲥϧⲟⲩ.
36 Kódà báyìí, ẹni tí ó ń kórè ń gba owó ọ̀yà rẹ̀, ó si ń kó èso jọ sí ìyè àìnípẹ̀kun, kí ẹni tí ó ń fúnrúgbìn àti ẹni tí ń kórè lè jọ máa yọ̀ pọ̀. (aiōnios g166)
ⲗ̅ⲋ̅ϩⲏⲇⲏ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁⲱⲥϧ ⳿ϥⲛⲁϭⲓ ⳿ⲙⲡⲉϥⲃⲉⲭ ⲉ ⲟⲩⲟϩ ⳿ϥⲛⲁⲑⲱⲟⲩϯ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲩⲧⲁϩ ⲉⲩⲱⲛϧ ⳿ⲛ⳿ⲉⲛⲉϩ ϩⲓⲛⲁ ⲫⲏⲉⲧⲥⲓϯ ⳿ⲛⲧⲉϥⲣⲁϣⲓ ⲉⲩⲥⲟⲡ ⲛⲉⲙ ⲫⲏⲉⲧⲱⲥϧ. (aiōnios g166)
37 Nítorí nínú èyí ni ọ̀rọ̀ náà fi jẹ́ òtítọ́, ‘Ẹnìkan ni ó fúnrúgbìn, ẹlòmíràn ni ó sì ń kórè jọ.’
ⲗ̅ⲍ̅ϧⲉⲛ ⲫⲁⲓ ⲅⲁⲣ ⲟⲩⲧⲁ⳿ⲫⲙⲏⲓ ⲡⲉ ⲡⲓⲥⲁϫⲓ ϫⲉ ⲕⲉⲟⲩⲁⲓ ⲡⲉⲧⲥⲓϯ ⲟⲩⲟϩ ⲕⲉⲟⲩⲁⲓ ⲡⲉⲧⲱⲥϧ.
38 Mo rán yín lọ kórè ohun tí ẹ kò ṣiṣẹ́ fún. Àwọn ẹlòmíràn ti ṣiṣẹ́, ẹ̀yin sì kórè èrè làálàá wọn.”
ⲗ̅ⲏ̅⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲁⲓⲟⲩⲉⲣⲡ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲱⲥϧ ⳿ⲙⲫⲏⲉⲧⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛϧⲓⲥⲓ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϩⲁⲛⲕⲉⲭⲱⲟⲩⲛⲓ ⲡⲉⲧⲁⲩϧⲓⲥⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛϣⲉ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲡⲟⲩϧⲓⲥⲓ.
39 Ọ̀pọ̀ àwọn ará Samaria láti ìlú náà wá sì gbà á gbọ́ nítorí ìjẹ́rìí obìnrin náà pé, “Ó sọ gbogbo ohun tí mo ti ṣe fún mi.”
ⲗ̅ⲑ̅⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ϯⲃⲁⲕⲓ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲁ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲛⲁϩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲥⲁⲙⲁⲣⲓⲧⲏ ⲥ ⲉⲑⲃⲉ ⳿ⲡⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲉⲥⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ϫⲉ ⲁϥϫⲉ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲏⲉⲧⲁⲓⲁⲓⲧⲟⲩ.
40 Nítorí náà, nígbà tí àwọn ará Samaria wá sọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n rọ̀ ọ́ pé, kí ó wà pẹ̀lú wọn, ó sì dúró fún ọjọ́ méjì.
ⲙ̅ϩⲟⲧⲉ ⲟⲩⲛ ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲥⲁⲙⲁⲣⲓⲧⲏ ⲥ ⲁⲩϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲟϩⲓ ϧⲁⲧⲟⲧⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲟϩⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲃ̅.
41 Àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ sì gbàgbọ́ sí i nítorí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
ⲙ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲁⲛⲕⲉⲙⲏϣ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ ⲁⲩⲛⲁϩϯ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲉϥⲥⲁϫⲓ.
42 Wọ́n sì wí fún obìnrin náà pé, “Kì í ṣe nítorí ọ̀rọ̀ rẹ nìkan ni àwa ṣe gbàgbọ́, nítorí tí àwa tìkára wa ti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àwa sì mọ̀ pé, nítòótọ́ èyí ni Kristi náà, Olùgbàlà aráyé.”
ⲙ̅ⲃ̅ⲛⲁⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲡⲉ ⳿ⲛϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲧⲉⲛϫⲓⲛⲥⲁϫⲓ ⲁⲛ ϫⲉ ⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ ⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲅⲁⲣ ϩⲱⲛ ⲁⲛⲥⲱⲧⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲧⲁ⳿ⲫⲙⲏⲓ ϫⲉ ⲫⲁⲓ ⲡⲉ ⲡⲓⲥⲱⲧⲏⲣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓⲕⲟⲥⲙⲟⲥ.
43 Lẹ́yìn ọjọ́ méjì ó sì ti ibẹ̀ kúrò, ó lọ sí Galili.
ⲙ̅ⲅ̅ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲇⲉ ⲃ̅ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲉϯⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ.
44 Nítorí Jesu tìkára rẹ̀ ti jẹ́rìí wí pé, Wòlíì kì í ní ọlá ní ilẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
ⲙ̅ⲇ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲅⲁⲣ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲁϥⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ϫⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲟⲩ⳿ⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲏⲥ ⲉϥⲧⲁⲓⲏⲟⲩⲧ ϧⲉⲛ ⲑⲏ ⲉⲧⲉⲑⲱϥ ⳿ⲙⲃⲁⲕⲓ.
45 Nítorí náà nígbà tí ó dé Galili, àwọn ará Galili gbà á, nítorí ti wọ́n ti rí ohun gbogbo tí ó ṣe ní Jerusalẹmu nígbà àjọ ìrékọjá; nítorí àwọn tìkára wọn lọ sí àjọ pẹ̀lú.
ⲙ̅ⲉ̅ϩⲟⲧⲉ ⲟⲩⲛ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉϯⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ⲁⲩϣⲟⲡϥ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲅⲁⲗⲓⲗⲉⲟⲥ ⲉⲧⲁⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲁϥⲁⲓⲧⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ϧⲉⲛ ⳿ⲡϣⲁⲓ ⲛⲉ ⲁⲩ⳿ⲓ ⲅⲁⲣ ϩⲱⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲁⲓ.
46 Bẹ́ẹ̀ ni Jesu tún wá sí Kana ti Galili, níbi tí ó gbé sọ omi di wáìnì. Ọkùnrin ọlọ́lá kan sì wá, ẹni tí ara ọmọ rẹ̀ kò dá ní Kapernaumu.
ⲙ̅ⲋ̅ⲁϥ⳿ⲓ ⲟⲛ ⳿ⲉ⳿ⲧⲕⲁⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ⲡⲓⲙⲁ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲑⲣⲉ ⲡⲓⲙⲱⲟⲩ ⲉⲣⲏⲣⲡ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲃⲁⲥⲓⲗⲓⲕⲟⲥ ⲡⲉ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲁϥ ⳿ⲛⲟⲩϣⲏ ⲣⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲉϥϣⲱⲛⲓ ϧⲉⲛ ⲕⲁⲫⲁⲣⲛⲁⲟⲩⲙ.
47 Nígbà tí ó gbọ́ pé Jesu ti Judea wá sí Galili, ó tọ̀ ọ́ wá, ó sì ń bẹ̀ ẹ́, kí ó lè sọ̀kalẹ̀ wá kí ó mú ọmọ òun láradá: nítorí tí ó wà ní ojú ikú.
ⲙ̅ⲍ̅ⲫⲁⲓ ⲁϥⲥⲱⲧⲉⲙ ϫⲉ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϯⲓⲟⲩⲇⲉ⳿ⲁ ⳿ⲉϯⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ⲁϥϣⲉ ⲛⲁϥ ϩⲁⲣⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿Ⲓ ⳿ⲉϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥⲧⲟⲩϫⲉ ⲡⲉϥϣⲏⲣⲓ ⲛⲁϥⲛⲁⲙⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⲡⲉ.
48 Nígbà náà ni Jesu wí fún un pé, “Bí kò ṣe pé ẹ̀yin bá rí àmì àti iṣẹ́ ìyanu, ẹ̀yin kì yóò gbàgbọ́ láé.”
ⲙ̅ⲏ̅ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲛ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲁⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ϣⲧⲉⲙⲛⲁⲩ ⳿ⲉϩⲁⲛⲙⲏⲓⲛⲓ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁϩϯ ⲁⲛ.
49 Ọkùnrin ọlọ́lá náà wí fún un pé, “Olúwa, sọ̀kalẹ̀ wá kí ọmọ mi tó kú.”
ⲙ̅ⲑ̅ⲡⲉϫⲉ ⲡⲓⲃⲁⲥⲓⲗⲓⲕⲟⲥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲡⲁ⳪ ⳿ⲁⲙⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲧⲉϥⲙⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲁ⳿ⲁⲗⲟⲩ.
50 Jesu wí fún un pé, “Máa bá ọ̀nà rẹ lọ; ọmọ rẹ yóò yè.” Ọkùnrin náà sì gba ọ̀rọ̀ Jesu gbọ́, ó sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
ⲛ̅ⲡⲉϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲙⲁϣⲉ ⲛⲁⲕ ⳿ϥⲟⲛϧ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉⲕϣⲏⲣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲛⲁϩϯ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲉⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⲉⲧⲁ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ϫⲟϥ ⲛⲁϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲙⲟϣⲓ.
51 Bí ó sì ti ń sọ̀kalẹ̀ lọ, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pàdé rẹ̀, wọ́n sì wí fún un pé, ọmọ rẹ ti yè.
ⲛ̅ⲁ̅ϩⲏⲇⲏ ⲉϥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⲓⲥ ⲛⲉϥⲉⲃⲓⲁⲓⲕ ⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲁϥ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⳿ϥⲟⲛϧ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉⲕϣⲏⲣⲓ.
52 Nígbà náà ni ó béèrè wákàtí tí ara rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í yá lọ́wọ́ wọn, wọ́n sì wí fún un pé, “Ní àná, ní wákàtí keje ni ibà náà fi í sílẹ̀.”
ⲛ̅ⲃ̅ⲛⲁϥϣⲓⲛⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲥⲁ ϯⲟⲩⲛⲟⲩ ⲑⲏ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲁⲥⲓⲁⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧⲥ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ⲛⲁϥ ϫⲉ ϧⲉⲛ ⲁϫⲡ ⲍ̅ ⳿ⲛⲥⲁϥ ⲁϥⲭⲁϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓ⳿ϧⲙⲟⲙ.
53 Bẹ́ẹ̀ ni baba náà mọ̀ pé ní wákàtí kan náà ni, nínú èyí tí Jesu wí fún un pé “Ọmọ rẹ̀ yè.” Òun tìkára rẹ̀ sì gbàgbọ́, àti gbogbo ilé rẹ̀.
ⲛ̅ⲅ̅ⲁϥ⳿ⲉⲙⲓ ⲟⲩⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉϥⲓⲱⲧ ϫⲉ ⲛⲉ ϯ ⲟⲩⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲧⲉ ⲉⲧⲁ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ϫⲟⲥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⳿ϥⲟⲛϧ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉⲕϣⲏⲣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲛⲁϩϯ ⲛⲉⲙ ⲡⲉϥⲏⲓ ⲧⲏⲣϥ.
54 Èyí ni iṣẹ́ àmì kejì tí Jesu ṣe nígbà tí ó ti Judea jáde wá sí Galili.
ⲛ̅ⲇ̅ⲫⲁⲓ ⲡⲉ ⲡⲓⲙⲏⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲙⲁϩ ⲃ̅ ⲉⲧⲁϥⲁⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ϯ ⲓⲟⲩⲇⲉ⳿ⲁ ⳿ⲉϯⲅⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ

< John 4 >