< Acts 1 >

1 Nínú ìwé mi ìṣáájú, Teofilu, ni mo ti kọ ní ti ohun gbogbo tí Jesu bẹ̀rẹ̀ sí ṣe àti kọ́
ⲁ̅ⲡⲓϩⲟⲩⲓⲧ ⲙⲉⲛ ⳿ⲛⲥⲁϫⲓ ⲁⲓⲁⲓϥ ⲉⲑⲃⲉ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲱ ⲑⲉⲟⲫⲩⲗⲗⲉ ϧⲉⲛ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ϩⲓⲧⲟⲧϥ ⳿ⲉⲁⲓⲧⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϯ⳿ⲥⲃⲱ.
2 títí ó fi di ọjọ́ tí a gbà á lọ sókè ọ̀run, lẹ́yìn tí ó ti ti ipa Ẹ̀mí Mímọ́ pàṣẹ fún àwọn aposteli tí ó yàn.
ⲃ̅ϣⲁ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲁϥϩⲟⲛϩⲉⲛ ⳿ⲉⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲠⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁϥⲥⲟⲧⲡⲟⲩ ⲁⲩⲟⲗϥ ⳿ⲉ⳿ⲧⲫⲉ.
3 Lẹ́yìn ìjìyà rẹ̀, ó fi ara rẹ̀ hàn fún wọn àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀rí tí ó dájú pé òun wà láààyè. Ó fi ara hàn wọ́n fún ogójì ọjọ́, ó sì sọ̀rọ̀ nípa ìjọba Ọlọ́run.
ⲅ̅ⲛⲁⲓ ⳿ⲉⲧⲁϥⲟⲩⲟⲛϩϥ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲉϥⲟⲛϧ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⳿ⲉⲧⲁϥϣⲉⲡ⳿ⲙⲕⲁϩ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲙⲙⲏⲓⲛⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲉⲛ ⲙ̅ ⳿ⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲉϥⲟⲩⲟⲛϩ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ⲉⲑⲃⲉ ϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
4 Ní àkókò kan bí ó sì ti ń jẹun pẹ̀lú wọn, ó pàṣẹ yìí fún wọn, “Ẹ má ṣe kúrò ní Jerusalẹmu, ṣùgbọ́n ẹ dúró de ìlérí tí Baba mi ṣe ìlérí, èyí tí ẹ̀yin tí gbọ́ lẹ́nu mi.
ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲉϥⲟⲩⲱⲙ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ⲁϥϩⲟⲛϩⲉⲛ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ϣⲧⲉⲙⲫⲱⲣϫ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲒⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲉⲟϩⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲱϣ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫ̇ⲓⲱⲧ ⲫⲏ⳿ⲉⲧ⳿ⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲥⲟⲑⲙⲉϥ ⳿ⲛⲧⲟⲧ.
5 Nítorí Johanu fi omi bamitiisi yín, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ díẹ̀ sí i, a o fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi yín.”
ⲉ̅ϫⲉ Ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⲙⲉⲛ ⲁϥϯⲱⲙⲥ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲇⲉ ⲥⲉⲛⲁⲉⲙⲥ ⲑⲏⲛⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉϥⲟⲩⲁⲃ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲁⲛ ⳿ⲁ ⲛⲁⲓ ϣⲱⲡⲓ.
6 Nítorí náà, nígbà tí wọ́n sì péjọpọ̀, wọn bi í léèrè pé, “Olúwa, láti ìgbà yí lọ ìwọ yóò ha mú ìjọba padà fún Israẹli bí?”
ⲋ̅⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲙⲉⲛ ⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲑⲱⲟⲩϯ ⲛⲁⲩϣⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ Ⲡ⳪ ⲓⲉ ⳿ⲛ⳿ϩⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲓⲥⲏⲟⲩ ⳿ⲭⲛⲁ⳿ⲧⲫⲉ ϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲉⲠⲓ̅ⲥ̅ⲗ̅.
7 Ó sì wí fún wọn pé, “Kì í ṣe tiyín ni láti mọ àkókò tàbí ìgbà tí Baba ti yàn nípa àṣẹ òun tìkára rẹ̀.
ⲍ̅ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲫⲱⲧⲉⲛ ⲁⲛ ⲡⲉ ⳿ⲉ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉϩⲁⲛ⳿ⲭⲣⲟⲛⲟⲥ ⲓⲉ ϩⲁⲛⲥⲏⲟⲩ ⲛⲁⲓ ⳿ⲉⲧⲁ Ⲫ̇ⲓⲱⲧ ⲭⲁⲩ ϧⲁ ⲡⲉϥⲉⲣϣⲓϣⲓ.
8 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò gba agbára, nígbà tí Ẹ̀mí Mímọ́ bá bà lé e yín; ẹ̀yin yóò sì máa ṣe ẹlẹ́rìí mi ni Jerusalẹmu, àti ní gbogbo Judea, àti ní Samaria, àti títí dé òpin ilẹ̀ ayé.”
ⲏ̅ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉϭⲓ ⳿ⲛⲟⲩϫⲟⲙ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲁⲣⲉϣⲁⲛ ⲡⲠⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁϣⲱⲡⲓ ⲛⲏⲓ ⳿ⲙⲙⲉⲑⲣⲉ ϧⲉⲛ Ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⲛⲉⲙ ϯⲒⲟⲩⲇⲉ⳿ⲁ ⲧⲏⲣⲥ ⲛⲉⲙ ⳿ⲧⲤⲁⲙⲁⲣⲓ⳿ⲁ ⲛⲉⲙ ϣⲁ ⲁⲩⲣⲏϫϥ ⳿ⲙ⳿ⲡⲕⲁϩⲓ.
9 Nígbà tí ó sì tí wí nǹkan wọ̀nyí, a gbà á sókè lójú wọn; ìkùùkuu àwọsánmọ̀ sì gbà á kúrò lójú wọn.
ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲓ ⳿ⲉⲧⲁϥϫⲟⲧⲟⲩ ⲉⲩⲥⲟⲙⲥ ⲁⲩϥⲓⲧϥ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲱⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩϭⲏⲡⲓ ⲁⲥϣⲟⲡⲥ ⳿ⲉⲣⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲁ ⲛⲟⲩⲃⲁⲗ.
10 Bí wọ́n sì ti tẹjúmọ́ ojú ọ̀run bí ó ti ń lọ sókè, lójijì, àwọn ọkùnrin méjì tí ó wọ aṣọ funfun dúró létí ọ̀dọ̀ wọn.
ⲓ̅ⲛⲁⲩⲟⲓ ⲇⲉ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲉⲛⲁⲩⲓⲟⲣⲉⲙ ⲟⲩⲁⲓ ⲟⲩⲃⲉ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲉϥⲙⲟϣⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉ⳿ⲧⲫⲉ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲓⲥ ⲣⲱⲙⲓ ⲃ̅ ⲁⲩ⳿ⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲟⲩ ⲛⲁϩⲣⲁⲩ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛϩⲉⲃⲥⲱ ⲉⲩⲟⲩⲟⲃϣ.
11 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ̀yin ara Galili, èéṣe tí ẹ̀yin fi dúró tí ẹ̀ ń wo ojú ọ̀run? Jesu yìí, tí a gbà sókè ọ̀run kúrò lọ́wọ́ yín, yóò padà bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ ti rí tí ó ń lọ sì ọ̀run.”
ⲓ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓⲄⲁⲗⲓⲗⲉⲟⲥ ⲁϧⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲟϩⲓ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲥⲟⲙⲥ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲱⲓ ⳿ⲉ⳿ⲧⲫⲉ ⲫⲁⲓ ⲡⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲟⲗϥ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲱⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁⲣⲱⲧⲉⲛ ⲫⲁⲓ ⲟⲛ ⲡⲉ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲉⲧⲉϥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧ⳿ⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲉϥⲙⲟϣⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉ⳿ⲧⲫⲉ.
12 Lẹ́yìn náà ni wọ́n padà sí Jerusalẹmu láti orí òkè ti a ń pè ni olifi, tí ó tó ìwọ̀n ìrìn ọjọ́ ìsinmi kan.
ⲓ̅ⲃ̅ⲧⲟⲧⲉ ⲁⲩⲕⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲉⲒⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲁ ⲡⲓⲧⲱⲟⲩ ⳿ⲉϣⲁⲩⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⲫⲁⲛⲓϫⲱⲓⲧ ⲉⲧϧⲉⲛⲧ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲒⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ ⳿ⲙⲙⲟϣⲓ.
13 Nígbà tí wọn sì wọlé, wọn lọ sí iyàrá òkè, níbi tí wọ́n ń gbé. Àwọn tó wà níbẹ̀ ni: Peteru, Jakọbu, Johanu àti Anderu; Filipi àti Tomasi; Bartolomeu àti Matiu; Jakọbu ọmọ Alfeu, Simoni Sealoti, àti Judasi arákùnrin Jakọbu.
ⲓ̅ⲅ̅ⲧⲟⲧⲉ ⳿ⲉⲧⲁⲩϣⲉ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⲁⲩϣⲉ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲟⲩⲙⲁ ⲉϥⲥⲁ⳿ⲡϣⲱⲓ ⲡⲓⲙⲁ ⳿ⲉⲛⲁϥϣⲟⲡ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ⲛⲉⲙ Ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ Ⲓⲁⲕⲱⲃⲟⲥ ⲛⲉⲙ Ⲁⲛ⳿ⲇⲣⲉⲁⲥ Ⲫⲓⲗⲓⲡⲡⲟⲥ ⲛⲉⲙ Ⲑⲱⲙⲁⲥ Ⲃⲁⲣⲑⲟⲗⲟⲙⲉⲟⲥ ⲛⲉⲙ Ⲙⲁⲧⲑⲉⲟⲥ Ⲓⲁⲕⲱⲃⲟⲥ ⲫⲁ Ⲁⲗⲫⲉⲟⲥ ⲛⲉⲙ Ⲥⲓⲙⲱⲛ ⲡⲓⲣⲉϥⲭⲟϩ ⲛⲉⲙ Ⲓⲟⲩⲇⲁⲥ ⲫⲁ Ⲓⲁⲕⲱⲃⲟⲥ.
14 Gbogbo àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú àwọn obìnrin àti Maria ìyá Jesu àti àwọn arákùnrin rẹ̀ fi ọkàn kan dúró láti máa gbàdúrà.
ⲓ̅ⲇ̅ⲛⲁⲓ ⲇⲉ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲉⲩⲙⲏⲛ ⲉⲩⲥⲟⲡ ⳿ⲉϯ ⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭⲏ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛϩⲓ⳿ⲟⲙⲓ ⲛⲉⲙ Ⲙⲁⲣⲓ⳿ⲁ ⳿ⲑⲙⲁⲩ ⳿ⲛⲒⲏ̅ⲥ̅ ⲛⲉⲙ ⲛⲉϥ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ.
15 Ní ọjọ́ wọ̀nyí ni Peteru sí dìde dúró láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn (iye àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ́ ọgọ́fà)
ⲓ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲁⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲁϥⲧⲱⲛϥ ⳿ⲛϫⲉ Ⲡⲉⲧⲣⲟⲥ ϧⲉⲛ ⳿ⲑⲙⲏϯ ⳿ⲛⲛⲓ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲇⲉ ⲉⲩⲑⲟⲩⲏⲧ ϩⲓ ⲫⲁⲓ ⳿ⲉⲫⲁⲓ ⳿ⲉⲛⲁⲩⲛⲁⲉⲣⲣ̅ⲕ̅ ⳿ⲛⲣⲁⲛ ⲡⲉϫⲁϥ.
16 ó wí pé, “Ẹ̀yin ará, ìwé mímọ́ kò lè ṣe kí ó má ṣẹ, èyí tí Ẹ̀mí Mímọ́ ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu Dafidi nípa Judasi, tí ó ṣe atọ́nà fún àwọn tí ó mú Jesu.
ⲓ̅ⲋ̅ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⲛⲓ⳿ⲥⲛⲏⲟⲩ ϩⲱϯ ⲡⲉ ⳿ⲛⲧⲉⲥϫⲱⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ϯ⳿ⲅⲣⲁⲫⲏ ⲑⲏ⳿ⲉⲧⲁϥⲉⲣϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛϫⲟⲥ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲠⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲣⲱϥ ⳿ⲛⲆⲁⲩⲓⲇ ⲉⲑⲃⲉ Ⲓⲟⲩⲇⲁⲥ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲁϥⲉⲣϭⲁⲩⲙⲱⲓⲧ ⳿ⲛⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲁⲙⲁϩⲓ ⳿ⲛⲒⲏ̅ⲥ̅.
17 Nítorí ọ̀kan nínú wa ni òun ń ṣe tẹ́lẹ̀, òun sì ní ìpín nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ yìí.”
ⲓ̅ⲍ̅ϫⲉ ⲛⲁϥⲏⲡ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧⲉⲛ ⲡⲉ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁ ⲡⲓⲱⲡ ⳿ⲓ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲧⲁⲓⲇⲓ⳿ⲁⲕⲟⲛⲓⲁ.
18 (Judasi fi èrè àìṣòótọ́ rẹ̀ ra ilẹ̀ kan; nígbà tí ó sì ṣubú ni ògèdèǹgbé, ó bẹ́ ní agbede-méjì, gbogbo ìfun rẹ̀ sì tú jáde.
ⲓ̅ⲏ̅ⲫⲁⲓ ⲙⲉⲛ ⲟⲩⲛ ⲁϥϣⲱⲡ ⳿ⲛⲟⲩⲓⲟϩⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⳿ⲫⲃⲉⲭⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲧⲁⲇⲓⲕⲓⲁ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϩⲉⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲉϥϩⲟ ⲁϥⲕⲱϣ ϧⲉⲛ ⲧⲉϥⲙⲏϯ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲏⲉⲧⲥⲁϧⲟⲩⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲁⲩⲫⲱⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
19 Ó si di mí mọ̀ fún gbogbo àwọn ti ń gbé Jerusalẹmu; nítorí náà ni wọ́n fi ń pè ilẹ̀ náà ni Alkedama ní èdè wọn, èyí sì ni, Ilẹ̀ Ẹ̀jẹ̀.)
ⲓ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲟⲩⲟⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧϣⲟⲡ ϧⲉⲛ Ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ϩⲱⲥⲧⲉ ⳿ⲛⲥⲉⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉ⳿ⲫⲣⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲓⲓⲟϩⲓ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ϧⲉⲛ ⲧⲟⲩⲁⲥⲡⲓ ϫⲉ ⲁⲭⲉⲗⲇⲁⲙⲁⲅ ⳿ⲉⲧⲉ ⲡⲓⲓⲟϩⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓ⳿ⲥⲛⲟϥ.
20 Peteru sì wí pé, “Nítorí a ti kọ ọ́ nípa rẹ̀ nínú Ìwé Saamu pé, “‘Jẹ́ ki ibùgbé rẹ̀ di ahoro, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀,’ àti, “‘Ipò rẹ̀ ni kí ẹlòmíràn kí ó gbà.’
ⲕ̅⳿ⲥ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ⲅⲁⲣ ϩⲓ ⳿ⲡϫⲱⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲯⲁⲗⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲧⲉϥⲉⲣⲃⲓ ⲙⲁⲣⲉⲥϣⲱϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉⲛ⳿ⲑⲣⲉϥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲫⲏⲉⲧϣⲟⲡ ⳿ⲛϧⲏⲧⲥ ⲧⲉϥⲙ⳿ⲉⲧⲉⲡⲓⲥⲕⲟⲡⲟⲥ ⲙⲁⲣⲉ ⲕⲉⲟⲩⲁⲓ ϭⲓⲧⲥ.
21 Nítorí náà, ó di dandan láti yan ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ti ń bá wa rìn ni gbogbo àkókò tí Jesu Olúwa ń wọlé, tí ó sì jáde láàrín wa.
ⲕ̅ⲁ̅ϩⲱϯ ⲟⲩⲛ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿Ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲛϧⲏⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲥⲏⲟⲩ ⲧⲏⲣϥ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿Ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓϫⲱⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲉⲛ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅.
22 Bẹ́ẹ̀ láti ìgbà bamitiisi Johanu títí ó fi di ọjọ́ náà ti a gbe é lọ sókè kúrò lọ́dọ̀ wa. Ó yẹ kí ọ̀kan nínú àwọn wọ̀nyí ṣe ẹlẹ́rìí àjíǹde rẹ̀ pẹ̀lú wa.”
ⲕ̅ⲃ̅⳿ⲉⲁϥⲉⲣϩⲏⲧⲥ ⲓⲥϫⲉⲛ ⲡⲓⲱⲙⲥ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ϣⲁ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲟⲗϥ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲱⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲁⲣⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲓ ⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ⲛⲉⲙⲁⲛ ϧⲁ ⲧⲉϥ⳿ⲁⲛⲁⲥⲧⲁⲥⲓⲥ.
23 Wọn sì yan àwọn méjì, Josẹfu tí a ń pè ní Barsaba (ẹni tí a sọ àpèlé rẹ̀ ni Justu) àti Mattia.
ⲕ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲧⲁϩⲉ ⲃ̅ ⳿ⲉⲣⲁⲧⲟⲩ Ⲓⲱⲥⲏⲫ ⲫⲏ⳿⳿ⲉⲧⲟⲩⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⲃⲁⲣⲥⲁⲃⲃⲁⲥ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲁⲩϯⲣⲉⲛϥ ϫⲉ ⲓⲟⲩⲥⲧⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲙⲁⲑⲓⲁⲥ.
24 Wọn sì gbàdúrà, wọn sì wí pé, “Olúwa, ìwọ mọ ọkàn gbogbo ènìyàn, fihàn wá nínú àwọn méjì yìí, èwo ni ìwọ yàn
ⲕ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲧⲱⲃϩ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ϫⲉ Ⲡ⳪ ⳿ⲛⲑⲟⲕ ⲡⲉⲧⲥⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲙ⳿ⲡϩⲏⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲟⲩⲟⲛϩ ⳿ⲙⲫⲏ⳿ⲉⲧⲁⲕⲥⲟⲧⲡϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲁⲓⲃ̅ ⲟⲩⲁⲓ.
25 kí ó lè gba ipò nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ aposteli yìí, èyí tí Judasi kúrò nínú rẹ̀, ki òun kí ó lè lọ sí ipò ti ara rẹ̀.”
ⲕ̅ⲉ̅⳿ⲉϭⲓ ⳿ⲉ⳿ⲫⲙⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲧⲁⲓⲇⲓ⳿ⲁⲕⲟⲛⲓⲁ ⲛⲉⲙ ⲧⲁⲓⲙⲉⲧⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ ⲑⲏ⳿ⲉⲧⲁϥⲉⲣⲡⲁⲣⲁⲃⲉⲛⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲟⲩⲇⲁⲥ ⲉⲁϥϣⲉⲛⲁϥ ⳿ⲉⲡⲉϥⲙⲁ ⳿ⲉⲧⲉ ⲫⲱϥ ⲡⲉ.
26 Wọ́n sì dìbò fún wọn; ìbò sí mú Mattia; a sì kà á mọ́ àwọn aposteli mọ́kànlá.
ⲕ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϯ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲥ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲁ ⲡⲓ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲥ ⳿ⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲙⲁⲑⲓⲁⲥ ⲁⲩⲟⲡϥ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲓ̅ⲁ̅ ⳿ⲛ⳿ⲁⲡⲟⲥⲧⲟⲗⲟⲥ.

< Acts 1 >