< Daniel 4 >

1 Nebukadnessari ọba, sí gbogbo ènìyàn, orílẹ̀ àti onírúurú èdè, tí ó ń gbé ní àgbáyé. Kí àlàáfíà máa pọ̀ sí i fún un yín. Kí ẹ ṣe rere tó pọ̀!
Król Nabuchodonozor do wszystkich ludzi, narodów i języków, którzy mieszkają w całej ziemi: Niech pokój się wam rozmnoży!
2 Ó jẹ́ ìdùnnú fún mi láti fi iṣẹ́ àmì àti ìyanu tí Ọlọ́run Ọ̀gá-Ògo ti ṣe fún mi hàn.
Uważałem za stosowne opowiedzieć o znakach i cudach, które uczynił dla mnie Bóg Najwyższy.
3 Báwo ni àmì rẹ̀ ti tóbi tó,
Jakże wielkie [są] jego znaki i jak potężne jego cuda! Jego królestwo [jest] królestwem wiecznym i jego władza [trwa] z pokolenia na pokolenie.
4 Èmi Nebukadnessari wà ní ààfin mi, pẹ̀lú ìtẹ́lọ́rùn àti àlàáfíà.
Ja, Nabuchodonozor, żyłem spokojnie w swoim domu i rozkwitałem w swoim pałacu.
5 Mo lá àlá kan èyí tí ó bà mí lẹ́rù. Nígbà tí mo wà lórí ibùsùn mi, ìran tí ó jáde lọ́kàn mi dẹ́rùbà mí.
Miałem sen, który mnie przestraszył, a myśli, [które miałem] na swoim łożu, oraz widzenia w mojej głowie zatrwożyły mnie.
6 Nígbà náà, ni mo pàṣẹ pé kí a mú gbogbo àwọn amòye Babeli wá, kí wọn wá sọ ìtumọ̀ àlá náà fún mi.
Wydałem więc dekret, aby przyprowadzano przede mnie wszystkich mędrców Babilonu, żeby oznajmili mi znaczenie tego snu.
7 Nígbà tí àwọn apidán, àwọn apògèdè, àwọn awòràwọ̀ àti àwọn aláfọ̀ṣẹ wá, mo sọ àlá náà fún wọn, ṣùgbọ́n wọn kò le è sọ ìtumọ̀ àlá náà fún mi.
Wtedy przyszli magowie, astrologowie, Chaldejczycy i wróżbici; i opowiedziałem im sen, ale nie potrafili mi oznajmić jego znaczenia;
8 Ní ìkẹyìn Daniẹli wá síwájú mi, mo sì sọ àlá náà fún. (Ẹni tí à ń pè ní Belṣassari gẹ́gẹ́ bí orúkọ òrìṣà mi àti pé ẹ̀mí àwọn ọlọ́run mímọ́ wà nínú rẹ̀.)
Aż w końcu przyszedł przede mnie Daniel, którego imię brzmi Belteszassar, zgodnie z imieniem mojego boga, a w którym [jest] duch świętych bogów, i przed nim opowiedziałem sen;
9 Mo wí pé, “Belṣassari, olórí àwọn amòye, èmi mọ̀ wí pé ẹ̀mí ọlọ́run mímọ́ wà nínú rẹ, kò sì ṣí àṣírí kan tí ó ṣòro jù fún ọ. Sọ àlá mi kí o sì túmọ̀ rẹ̀ fún mi.
Belteszassarze, przełożony magów, wiem, że duch świętych bogów [jest] w tobie i że żadna tajemnica nie jest dla ciebie trudna. [Posłuchaj] widzenia z mojego snu, który miałem, i powiedz [mi] jego znaczenie.
10 Èyí ni ìran náà tí mo rí nígbà tí mo wà lórí ibùsùn mi, mo rí igi kan láàrín ayé, igi náà ga gidigidi.
Takie są widzenia w mojej głowie, jakie miałem na swoim łożu: Patrzyłem, a oto drzewo pośrodku ziemi, a jego wysokość była ogromna.
11 Igi náà tóbi, ó sì lágbára, orí rẹ̀ sì ń kan ọ̀run; a sì rí i títí dé òpin ayé.
Drzewo rosło i było potężne, a jego wysokość dosięgła nieba i było widoczne aż po krańce całej ziemi.
12 Ewé rẹ̀ lẹ́wà, èso rẹ̀ sì pọ̀, ó sì ń pèsè oúnjẹ fún gbogbo ènìyàn. Abẹ́ ẹ rẹ̀ ni àwọn ẹranko igbó fi ṣe ibùgbé, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ń gbé ní ẹ̀ka rẹ̀, nínú rẹ̀ ni gbogbo alààyè ti ń jẹ.
Jego liście były piękne, jego owoc obfity i na nim [był] pokarm dla wszystkich. Pod nim znajdowały cień zwierzęta polne, na jego gałęziach mieszkało ptactwo niebieskie i z niego miało pożywienie wszelkie ciało.
13 “Lórí ibùsùn mi, mo rí ìran náà, olùṣọ́ kan dúró síwájú u mi, àní ẹni mímọ́ kan, ó ń bọ̀ wá láti ọ̀run
Widziałem [jeszcze] w widzeniach w mojej głowie na swoim łożu: Oto stróż i święty zstąpił z nieba;
14 ó kígbe sókè wí pé, ‘Gé igi náà kí o sì gé àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kúrò; gbọn ewé rẹ̀ ká, kí o sì fọ́n èso rẹ̀ dànù. Jẹ́ kí àwọn ẹranko tí ó wà lábẹ́ rẹ̀ sá àti àwọn ẹyẹ tí ó wà ní ẹ̀ka rẹ̀ kúrò.
Zawołał ze wszystkich sił i tak powiedział: Wyrąbcie to drzewo i obetnijcie jego gałęzie, otrząśnijcie jego liście i rozrzućcie jego owoc. Niech zwierzę ucieknie spod niego i ptactwo z jego gałęzi.
15 Ṣùgbọ́n fi kùkùté àti gbòǹgbò rẹ̀ tí a fi irin àti idẹ dè ṣẹ́kù sórí ilẹ̀ àti sí orí koríko igbó. “‘Jẹ́ kí ìrì ọ̀run sẹ̀ sí i lára, kí ó sì jẹ́ kí ìpín in rẹ̀ wà pẹ̀lú àwọn ẹranko igbó láàrín ilẹ̀ ayé.
Lecz pień jego korzenia zostawcie w ziemi i to w okowach żelaza i brązu na polnej trawie, aby był skrapiany rosą z nieba, a trawę ziemi niech dzieli ze zwierzętami.
16 Jẹ́ kí ọkàn rẹ̀ kí ó yí padà kúrò ní ti ènìyàn, kí a sì fún un ní ọkàn ẹranko, títí ìgbà méje yóò fi kọjá lórí i rẹ̀.
Niech się odmieni jego ludzkie serce i niech będzie mu dane serce zwierzęce, a niech przejdzie nad nim siedem czasów.
17 “‘Olùṣọ́ ni ó gbé ìpinnu náà jáde, àṣẹ sì wá láti ọ̀dọ̀ ẹni mímọ́, kí gbogbo alààyè le mọ̀ wí pé, Ọ̀gá-ògo ni olórí ìjọba ènìyàn, ó sì ń fi fún ẹnikẹ́ni tí ó wù ú, òun sì ń gbé onírẹ̀lẹ̀ lórí i wọn.’
[Ta] sprawa jest według dekretu stróżów i to żądanie [jest] według słowa świętych po to, aby wszyscy żyjący poznali, że Najwyższy panuje nad królestwem ludzkim i daje je, komu chce, a najniższych z ludzi ustanawia nad nim.
18 “Èyí ni àlá tí èmi Nebukadnessari ọba lá. Ní ìsinsin yìí ìwọ Belṣassari, sọ ohun tí ó túmọ̀ sí fún mi, nítorí kò sí amòye kan ní ìjọba mi, tí ó lè sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi. Ṣùgbọ́n ìwọ lè sọ ìtumọ̀ rẹ̀, nítorí tí ẹ̀mí Ọlọ́run mímọ́ wà ní inú rẹ.”
Taki sen miałem ja, król Nabuchodonozor. A ty, Belteszassarze, powiedz jego znaczenie, gdyż wszyscy mędrcy mojego królestwa nie mogli mi oznajmić jego znaczenia. Ale ty możesz, bo duch świętych bogów [jest] w tobie.
19 Nígbà náà ni Daniẹli (ẹni tí à ń pè ní Belṣassari) páyà gidigidi fún ìgbà díẹ̀, èrò inú rẹ̀ sì bà á lẹ́rù. Nígbà náà ni ọba wí pé, “Belṣassari, má ṣe jẹ́ kí àlá náà tàbí ìtumọ̀ rẹ̀ kí ó dẹ́rùbà ọ́.” Belṣassari sì dáhùn wí pé, “Olúwa mi, kí àlá yìí jẹ́ ti àwọn ọ̀tá a rẹ, kí ìtumọ̀ rẹ̀ sì jẹ́ ti àwọn aṣòdì sí.
Wtedy Daniel, który miał na imię Belteszassar, stał osłupiony przez jedną godzinę i jego myśli trwożyły go. Król odezwał się i powiedział: Belteszassarze, niech cię nie trwoży sen i jego znaczenie. Belteszassar odpowiedział: Mój panie, niech ten sen [spadnie] na tych, którzy cię nienawidzą, a jego znaczenie na twoich wrogów.
20 Igi tí ìwọ rí, tí ó dàgbà, tí ó sì lágbára, tí orí rẹ̀ sì ń kan ọ̀run, tí ó lẹ́wà àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ èso, tí ó ń pèsè oúnjẹ fún gbogbo ènìyàn, tí ó ṣe ààbò lórí ẹranko igbó àti èyí tí ẹ̀ka rẹ̀ pèsè ààyè fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
Drzewo, które widziałeś, które rosło i było potężne, jego wysokość dosięgła nieba, a było widoczne na całej ziemi;
21 Èyí tí ewé e rẹ̀ lẹ́wà, tí èso rẹ̀ si pọ̀, nínú èyí tí oúnjẹ sì wà fún gbogbo ẹ̀dá, lábẹ́ èyí tí àwọn ẹranko igbó ń gbé, lórí ẹ̀ka èyí ti àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní ibùgbé wọn.
Którego liście [były] piękne, a owoc obfity, na którym był pokarm dla wszystkich, pod którym mieszkało zwierzę polne i na którego gałęziach przebywało ptactwo niebieskie;
22 Ìwọ ọba ni igi náà, ìwọ ti dàgbà, o sì lágbára, títóbi i rẹ ga ó sì kan ọ̀run, ìjọba rẹ sì gbilẹ̀ títí dé òpin ayé.
To ty, królu, który rosłeś i stałeś się potężny, twoja wielkość urosła i dosięgła nieba, a twoja władza – aż po krańce ziemi.
23 “Ìwọ ọba, rí ìránṣẹ́ ẹni mímọ́ kan, tí ó ń bọ̀ láti ọ̀run ó sì sọ pé, ‘Gé igi náà kí o sì run ún, ṣùgbọ́n fi kùkùté rẹ tí a dè pẹ̀lú irin àti idẹ sílẹ̀ nínú koríko igbó, nígbà tí gbòǹgbò rẹ̀ sì wà nínú ilẹ̀ kí o sì jẹ́ kí ìrì ọ̀run sẹ̀ sórí i rẹ̀, jẹ́ kí ìpín in rẹ̀ wà láàrín ẹranko búburú títí ìgbà méje yóò fi kọjá lórí i rẹ̀.’
A to, że król widział stróża i świętego zstępującego z nieba i mówiącego: Wyrąbcie to drzewo i zniszczcie je, lecz pień jego korzeni zostawcie w ziemi i to w okowach żelaza i brązu na polnej trawie, aby był skrapiany rosą z nieba; a trawę polną niech dzieli ze zwierzętami polnymi, aż wypełni się siedem czasów nad nim;
24 “Èyí ni ìtumọ̀ àlá rẹ ọba àti àṣẹ tí Ọ̀gá-ògo mú wá sórí ọba olúwa mi.
Takie jest znaczenie, o królu, i dekret Najwyższego, który przyszedł na króla, mego pana;
25 A ó lé ọ jáde kúrò láàrín ènìyàn, ìwọ yóò sì máa gbé láàrín ẹranko búburú, ìwọ yóò jẹ koríko bí i màlúù, ìrì ọ̀run yóò sì sẹ̀ sára rẹ. Ìgbà méje yóò sì kọjá lórí rẹ, títí ìwọ yóò fi mọ̀ wí pé Ọ̀gá-ògo ń jẹ ọba lórí ìjọba ènìyàn, ó sì ń fi fún ẹni tí ó bá wù ú.
Wypędzą cię spośród ludzi, będziesz mieszkał ze zwierzętami polnymi, będą cię żywić trawą jak woły, będziesz skrapiany rosą z nieba i wypełni się nad tobą siedem czasów, aż poznasz, że Najwyższy panuje nad królestwem ludzkim i daje je, komu chce.
26 Bí wọ́n ṣe pàṣẹ pé kí wọn fi kùkùté àti gbòǹgbò igi náà sílẹ̀, èyí túmọ̀ sí wí pé a ó dá ìjọba rẹ padà fún ọ lẹ́yìn ìgbà tí o bá ti mọ̀ wí pé, Ọ̀run jẹ ọba.
A to, że rozkazano zostawić pień korzeni tego drzewa, [oznacza], że twoje królestwo zostanie przy tobie, gdy poznasz, że niebiosa sprawują władzę.
27 Nítorí náà ọba, jẹ́ kí ìmọ̀ràn mi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún ọ, kọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ sílẹ̀ kí o sì ṣe rere, àti ìwà búburú rẹ nípa ṣíṣe àánú fún àwọn tálákà. Ó lè jẹ́ pé nígbà náà ni ìwọ yóò ṣe rere.”
Dlatego, królu, niech ci się spodoba moja rada i przerwij swoje grzechy sprawiedliwością, a swoje nieprawości miłosierdziem nad biednymi; może przedłuży się twój pokój.
28 Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ṣẹlẹ̀ sí Nebukadnessari ọba.
To wszystko przyszło na króla Nabuchodonozora.
29 Lẹ́yìn oṣù kejìlá, bí ọba ṣe ń rìn káàkiri lórí òrùlé ààfin ìjọba Babeli,
Po upływie dwunastu miesięcy, gdy przechadzał się w pałacu królewskim w Babilonie;
30 ó sọ pé, “Èyí ha kọ́ ni Babeli ńlá tí mo kọ́ gẹ́gẹ́ bí ilé ọba, nípa agbára à mi àti fún ògo ọláńlá à mi?”
Król zaczął mówić: Czy to nie jest ten wielki Babilon, który ja, w sile swej potęgi, zbudowałem jako siedzibę królestwa i dla chwały swojego majestatu?
31 Bí ọba ṣe ń sọ ọ̀rọ̀ náà lọ́wọ́ ohùn kan wá láti ọ̀run, “Ìwọ Nebukadnessari ọba, ìwọ ni a ti pàṣẹ nípa rẹ̀, a ti gba ìjọba à rẹ kúrò ní ọwọ́ ọ̀ rẹ.
[A gdy] słowo to jeszcze było w ustach króla, [oto] spadł głos z nieba: Do ciebie się mówi, królu Nabuchodonozorze. [Twoje] królestwo odeszło od ciebie.
32 A ó lé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, ìwọ yóò sì lọ máa gbé àárín àwọn ẹranko igbó; ìwọ yóò jẹ koríko bí i màlúù, ìgbà méje yóò kọjá lórí i rẹ títí ìwọ yóò fi mọ̀ wí pé, Ọ̀gá-ògo jẹ ọba lórí ìjọba ènìyàn àti pé ó ń fi fún ẹni tí ó bá wù ú.”
Wypędzą cię spośród ludzi, będziesz mieszkał ze zwierzętami polnymi, będą cię żywić trawą jak woły i wypełni się nad tobą siedem czasów, aż poznasz, że Najwyższy panuje nad królestwem ludzkim i daje je, komu chce.
33 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ni ohun tí a sọ nípa Nebukadnessari ṣẹlẹ̀ sí i. A lé e kúrò láàrín ènìyàn, ó sì ń jẹ koríko bí i màlúù, ìrì ọ̀run sì ń sẹ̀ sí ara rẹ̀, títí irun orí rẹ̀ fi gùn bí i ti ìyẹ́ ẹyẹ idì, tí èékánná rẹ̀ sì dàbí i ti ẹyẹ.
Tej godziny wypełniło się to słowo nad Nabuchodonozorem: Wypędzono go spośród ludzi, jadł trawę jak woły i jego ciało było skrapiane rosą z nieba, aż jego włosy urosły jak [pióra] orłów, a jego paznokcie jak [szpony] ptaków.
34 Ní òpin ìgbà náà, èmi, Nebukadnessari gbé ojú mi sókè sí ọ̀run, iyè mi sì sọjí. Mo fi ọpẹ́ fún Ọ̀gá-ògo; mo fi ọlá àti ògo fún ẹni tí ó wà láéláé.
Pod koniec tych dni, ja, Nabuchodonozor, podniosłem swoje oczy do nieba i wrócił mi mój rozum. Wtedy błogosławiłem Najwyższego i chwaliłem [go], i wysławiałem Żyjącego na wieki, bo jego władza to władza wieczna, a jego królestwo [trwa] z pokolenia na pokolenie.
35 Gbogbo àwọn ènìyàn ayé
Wszyscy mieszkańcy ziemi są uważani za nic. Według swojej woli postępuje z wojskiem niebieskim i z mieszkańcami ziemi, a nie ma nikogo, kto by wstrzymał jego rękę lub powiedział mu: Co czynisz?
36 Ní àkókò kan náà, iyè mi padà, ọlá àti ògo dídán mi padà tọ̀ mí wá fún ògo ìjọba mi. Àwọn ìgbìmọ̀ àti àwọn ọlọ́lá mi, wá mi rí, wọ́n sì dá mi padà sórí ìjọba mi, mo sì di alágbára ju ti ìṣáájú lọ.
W tym czasie wrócił mi mój rozum i ku chwale mego królestwa wróciła do mnie moja dostojność i mój blask. Ponadto moi doradcy i książęta szukali mnie, zostałem umocniony w swoim królestwie i dano mi jeszcze większy majestat.
37 Báyìí, èmi, Nebukadnessari fi ọpẹ́, mo sì gbé Ọlọ́run ga, mo sì fi ògo fún ọba ọ̀run, nítorí pé gbogbo nǹkan tí ó ṣe ló dára, gbogbo ọ̀nà rẹ̀ sì tọ́. Gbogbo àwọn tó sì ń rìn ní ìgbéraga ni ó le rẹ̀ sílẹ̀.
[A] teraz ja, Nabuchodonozor, chwalę, wywyższam i wysławiam Króla niebios, którego wszystkie dzieła [są] prawdą, a jego ścieżki sprawiedliwością, a tych, którzy postępują w pysze, może on poniżyć.

< Daniel 4 >