< Hosea 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Hosea ọmọ Beeri wá ní àkókò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah; àwọn ọba Juda àti ní àkókò ọba Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi ní Israẹli.
Słowo PANA, które doszło do Ozeasza, syna Beeriego, za dni Uzjasza, Jotama, Achaza, Ezechiasza, królów Judy, i za dni Jeroboama, syna Joasza, króla Izraela.
2 Nígbà tí Olúwa bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀ láti ẹnu Hosea, Olúwa wí fún un pé, “Lọ, fẹ́ àgbèrè obìnrin kan fún ara rẹ, kí ó sì bí ọmọ àgbèrè fún ọ nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin mìíràn, nítorí ilẹ̀ ti ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè púpọ̀ nípa yíyapa kúrò lọ́dọ̀ Olúwa.”
Początek słowa PANA przez Ozeasza. PAN powiedział do Ozeasza: Idź, weź sobie nierządnicę za żonę i dzieci nierządu. Ziemia bowiem uprawiała wstydliwy nierząd, odwróciła się od PANA.
3 Nígbà náà ni ó sì lọ, ó sì fẹ́ Gomeri ọmọbìnrin Diblaimu, ọmọbìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un.
Poszedł więc i wziął sobie za żonę Gomerę, córkę Diblaima, a ona poczęła i urodziła mu syna.
4 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Hosea pé, “Pe orúkọ ọmọ náà ní Jesreeli, nítorí pé láìpẹ́ ni èmi yóò jẹ ìdílé Jehu ní ìyà fún ẹ̀jẹ̀ àwọn ènìyàn tó pa ní ìpakúpa ní Jesreeli, Èmi yóò sì mú ìjọba Israẹli wá sí òpin.
PAN powiedział do niego: Nadaj mu imię Jizreel, bo już niedługo pomszczę na domu Jehu krew Jizreel i sprawię, [że] ustanie królestwo domu Izraela.
5 Ní ọjọ́ náà ni Èmi yóò ṣẹ́ ọrun Israẹli ní àfonífojì Jesreeli.”
W tym dniu złamię łuk Izraela w dolinie Jizreel.
6 Gomeri sì tún lóyún, ó sì bí ọmọbìnrin kan. Olúwa sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-ruhama, nítorí pé, Èmi kò ní ṣàánú fún ilé Israẹli mọ́, Èmi kò sì ní dáríjì wọ́n.
I poczęła znowu, i urodziła córkę. [PAN] powiedział do niego: Nadaj jej imię Lo-Ruchama, bo już nie zlituję się nad domem Izraela, lecz na pewno go wytępię.
7 Síbẹ̀, èmi yóò ṣàánú fún ilé Juda, èmi ó gbà wọ́n—kì í ṣe nípa ọfà, idà tàbí ogun, ẹṣin tàbí kẹ̀kẹ́ ẹlẹ́ṣin bí kò ṣe nípa Olúwa Ọlọ́run wọn.”
Ale zlituję się nad domem Judy i wybawię go przez PANA, jego Boga, lecz nie wybawię łukiem ani mieczem, ani wojną, ani końmi, ani jeźdźcami.
8 Lẹ́yìn ìgbà tí ó gba ọmú lẹ́nu Lo-ruhama, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn. Nígbà náà ni
Gdy odstawiła [od piersi] Lo-Ruchamę, znowu poczęła i urodziła syna.
9 Olúwa sì sọ fún un pé, “Pe orúkọ rẹ̀ ní Lo-Ammi, nítorí pé ẹ kì í ṣe ènìyàn mi, èmi náà kì í sì í ṣe Ọlọ́run yín.
I [PAN] powiedział: Nadaj mu imię Lo-Ammi, bo wy nie jesteście moim ludem, ja też nie będę waszym [Bogiem].
10 “Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli yóò pọ̀ bí i iyanrìn etí Òkun tí a kò le wọ́n, tí a kò sì le è kà, yóò sì ṣe. Ní ibi tí wọ́n ti sọ fún wọn pé. ‘Ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’ níbẹ̀ ni a ó ti máa pè wọ́n ní ‘Ọmọ Ọlọ́run alààyè.’
Jednak liczba synów Izraela będzie jak piasek morski, którego nie można zmierzyć ani zliczyć. I stanie się, że w miejscu, gdzie im mówiono: Nie jesteście moim ludem, będzie się do nich mówić: Wy jesteście synami Boga żywego.
11 Àwọn ènìyàn Juda àti àwọn ènìyàn Israẹli yóò parapọ̀, wọn yóò sì yan olórí kan tí yóò jáde láti ilẹ̀ náà, nítorí pé ọjọ́ ńlá ni ọjọ́ Jesreeli yóò jẹ́.
I będą zgromadzeni razem synowie Judy i synowie Izraela, ustanowią sobie jedną głowę i wyjdą z tej ziemi. Wielki bowiem [będzie] dzień Jizreel.

< Hosea 1 >