< Romarbrevet 15 >

1 Vi som äro starka äro pliktiga att bära de svagas skröpligheter och att icke leva oss själva till behag.
Àwa tí a jẹ́ alágbára nínú ìgbàgbọ́ yẹ kí ó máa ru ẹrù àìlera àwọn aláìlera, kí a má sì ṣe ohun tí ó wu ara wa.
2 Var och en av oss må leva sin nästa till behag, honom till fromma och honom till uppbyggelse.
Olúkúlùkù wa gbọdọ̀ máa ṣe ohun tí ó wu ọmọnìkejì rẹ̀ sí rere, láti gbé e ró.
3 Kristus levde ju icke sig själv till behag, utan med honom skedde såsom det är skrivet: "Dina smädares smädelser hava fallit över mig."
Nítorí Kristi pàápàá kò ṣe ohun tí ó wu ara rẹ̀, ṣùgbọ́n bí a ti kọ ọ́ pé, “Ẹ̀gàn àwọn ẹni tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mi.”
4 Ty allt vad som fordom har blivit skrivet, det är skrivet oss till undervisning, för att vi, genom ståndaktighet och genom den tröst som skrifterna giva, skola bevara vårt hopp.
Nítorí ohun gbogbo tí a kọ tẹ́lẹ̀, ni a kọ láti fi kọ́ wa pé, nípa sùúrù àti ìtùnú ìwé mímọ́, kí àwa lè ní ìrètí.
5 Och ståndaktighetens och tröstens Gud give eder att vara ens till sinnes med varandra i Kristi Jesu efterföljelse,
Kí Ọlọ́run, ẹni tí ń fún ni ní sùúrù àti ìtùnú fún yin láti ní inú kan sí ara yín gẹ́gẹ́ bí i Jesu Kristi,
6 så att I endräktigt och med en mun prisen vår Herres, Jesu Kristi, Gud och Fader.
kí ẹ̀yin kí ó lè fi ọkàn kan àti ẹnu kan fi ògo fún Ọlọ́run, Baba Olúwa wa Jesu Kristi.
7 Därför må den ene av eder vänligt upptaga den andre, såsom Kristus, Gud till ära, har upptagit eder.
Nítorí náà ẹ gba ara yín mọ́ra, gẹ́gẹ́ bí Kristi ti gbà wá mọ́ra fún ògo Ọlọ́run.
8 Vad jag vill säga är detta: För de omskurna har Kristus blivit en tjänare, till ett vittnesbörd om Guds sannfärdighet, för att bekräfta de löften som hade givits åt fäderna;
Mo sì wí pé, a rán Kristi láti ṣe ìránṣẹ́ ìkọlà àwọn tí ṣe Júù nítorí òtítọ́ Ọlọ́run, láti fi ìdí àwọn ìlérí tí a ti ṣe fún àwọn baba múlẹ̀,
9 hedningarna åter hava fått prisa Gud för hans barmhärtighets skull. Så är ock skrivet: "Fördenskull vill jag prisa dig bland hedningarna och lovsjunga ditt namn."
kí àwọn aláìkọlà kí ó lè yin Ọlọ́run lógo nítorí àánú rẹ̀; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Nítorí èyí ni èmi ó ṣe yìn ọ́ láàrín àwọn Kèfèrí, Èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.”
10 Och åter heter det: "Jublen, I hedningar, med hans folk";
Ó sì tún wí pé, “Ẹ̀yin Kèfèrí, ẹ ma yọ̀, pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.”
11 så ock: "Loven Herren, alla hedningar, ja, honom prise alla folk."
Àti pẹ̀lú, “Ẹyin Olúwa, gbogbo ẹ̀yin Kèfèrí; ẹ kọ orin ìyìn sí, ẹ̀yin ènìyàn gbogbo.”
12 Så säger ock Esaias: "Telningen från Jessais rot skall komma, ja, han som skall stå upp för att råda över hedningarna; på honom skola hedningarna hoppas."
Isaiah sì tún wí pé, “Gbòǹgbò Jese kan ń bọ̀ wá, òun ni ẹni tí yóò dìde ṣe àkóso àwọn Kèfèrí; Àwọn Kèfèrí yóò ní ìrètí nínú rẹ̀.”
13 Men hoppets Gud uppfylle eder med all glädje och frid i tron, så att I haven ett överflödande hopp i den helige Andes kraft.
Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run ìrètí kí ó fi gbogbo ayọ̀ òun àlàáfíà kún yín bí ẹ̀yin ti gbà á gbọ́, kí ẹ̀yin kí ó lè pọ̀ ní ìrètí nípa agbára Ẹ̀mí Mímọ́.
14 Jag är väl redan nu viss om att I, mina bröder, av eder själva ären fulla av godhet, uppfyllda med all kunskap, i stånd jämväl att förmana varandra.
Ẹ̀yin ará, èmi gan alára ti ní ìdánilójú, pé ẹ̀yin pàápàá kún fún oore, a sì fi gbogbo ìmọ̀ kún un yín, ẹ̀yin sì jáfáfá láti máa kọ́ ara yín.
15 Dock har jag, på ett delvis något dristigt sätt, skrivit till eder med ytterligare påminnelser, detta i kraft av den nåd som har blivit mig given av Gud:
Síbẹ̀ mo ti fi ìgboyà kọ̀wé sí yín lórí àwọn kókó-ọ̀rọ̀ kan, bí ẹni ti ń rán yín létí àwọn kókó-ọ̀rọ̀ náà, nítorí oore-ọ̀fẹ́ tí a ti fi fún mi láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run
16 att jag nämligen skall förrätta Kristi Jesu tjänst bland hedningarna och vara en prästerlig förvaltare av Guds evangelium, så att hedningarna bliva ett honom välbehagligt offer, helgat i den helige Ande.
láti jẹ́ ìránṣẹ́ Kristi Jesu láàrín àwọn Kèfèrí láti polongo ìyìnrere Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ojúṣe àlùfáà, kí àwọn Kèfèrí lè jẹ́ ẹbọ ọrẹ ìtẹ́wọ́gbà fún Ọlọ́run, èyí tí a ti fi Ẹ̀mí Mímọ́ yà sí mímọ́.
17 Alltså är det i Kristus Jesus som jag har något att berömma mig av i fråga om min tjänst inför Gud.
Nítorí náà, mo ní ìṣògo nínú Kristi Jesu nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ mi fún Ọlọ́run.
18 Ty jag skall icke drista mig att orda om något annat än vad Kristus, för att göra hedningarna lydaktiga, har verkat genom mig, med ord och med gärning,
Èmi kò sá à gbọdọ̀ sọ ohun kan bí kò ṣe èyí tí Kristi ti ọwọ́ mi ṣe, ní títọ́ àwọn Kèfèrí ṣọ́nà láti ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run nípa ọ̀rọ̀ àti ìṣe mi,
19 genom kraften i tecken och under, genom Andens kraft. Så har jag, från Jerusalem och runt omkring ända till Illyrien, överallt förkunnat evangelium om Kristus.
nípa agbára iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu, nípa agbára Ẹ̀mí Ọlọ́run, tó bẹ́ẹ̀ láti Jerusalẹmu àti yíkákiri, àní títí fi dé Illirikoni, mo ti polongo ìyìnrere Kristi ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́.
20 Och jag har härvid satt min ära i att icke förkunna evangelium, där Kristi namn redan var känt, ty jag ville icke bygga på en annans grundval;
Ó jẹ́ èrò mi ní gbogbo ìgbà láti wàásù ìyìnrere Kristi ní ibi gbogbo tí wọn kò tí ì mọ̀ ọ́n, kí èmi kí ó má ṣe máa mọ àmọlé lórí ìpìlẹ̀ ẹlòmíràn.
21 utan så har skett, som skrivet är: "De för vilka intet har varit förkunnat om honom skola få se, och de som intet hava hört skola förstå."
Ṣùgbọ́n, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Àwọn ẹni tí a kò tí ì sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ fún yóò rí i, àti àwọn tí kò tí ì gbọ́, òye yóò sì yé.”
22 Det är också härigenom som jag så många gånger har blivit förhindrad att komma till eder.
Ìdí nìyìí tí ààyè fi há pẹ́ tó bẹ́ẹ̀ fún mi kí n tó tọ̀ yín wa.
23 Men då jag nu icke mer har något att uträtta i dessa trakter och under ganska många år har längtat efter att komma till eder,
Ṣùgbọ́n báyìí tí kò tún sí ibòmíràn fún mi mọ́ láti ṣiṣẹ́ ní ẹkùn yìí, tí èmi sì ti ń pòǹgbẹ láti ọdún púpọ̀ sẹ́yìn láti bẹ́ yín wò,
24 vill jag besöka eder, när jag begiver mig till Spanien. Jag hoppas nämligen att på genomresan få se eder och att därefter av eder bliva utrustad för färden dit, sedan jag först i någon mån har fått min längtan efter eder stillad.
mo gbèrò láti ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà tí mo bá lọ sí Spania. Èmi yóò rí i yín ní ọ̀nà àjò mi, àti pé ẹ ó mú mi já ọ̀nà níbẹ̀ láti ọ̀dọ̀ yín lọ, lẹ́yìn tí mo bá gbádùn ẹgbẹ́ yín fún ìgbà díẹ̀.
25 Men nu far jag till Jerusalem med understöd åt de heliga.
Ṣùgbọ́n ní báyìí, mo ń lọ sí Jerusalẹmu láti sé ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn mímọ́ níbẹ̀.
26 Macedonien och Akaja hava nämligen känt sig manade att göra ett sammanskott åt dem bland de heliga i Jerusalem, som leva i fattigdom.
Nítorí pé ó wu àwọn tí ó wà ní Makedonia àti Akaia láti kó owó jọ fún àwọn tálákà tí ó wà ní àárín àwọn ènìyàn mímọ́ ní Jerusalẹmu.
27 Ja, därtill hava de känt sig manade; de stå också i skuld hos dem. Ty om hedningarna hava fått del i deras andliga goda, så äro de å sin sida skyldiga att vara dem till tjänst med sitt lekamliga goda. --
Pẹ̀lú ayọ̀ ni wọ́n ń ṣe èyí, nítorí wọ́n gbà wí pé, wọ́n jẹ́ ajigbèsè fún wọn. Nítorí bí ó bá ṣe pé a fi àwọn Kèfèrí ṣe alájọni nínú ohun ẹ̀mí wọn, ajigbèsè sì ni wọn láti fi ohun ti ara ta wọ́n lọ́rẹ.
28 När jag så har fullgjort detta och lämnat i deras händer vad som har blivit insamlat, ämnar jag därifrån begiva mig till Spanien och taga vägen genom eder stad.
Nítorí náà, nígbà tí mo bá ti ṣe èyí tán, tí mo bá sì di èdìdì èso náà fún wọn tán, èmi yóò ti ọ̀dọ̀ yín lọ sí Spania.
29 Och jag vet, att när jag kommer till eder, kommer jag med Kristi välsignelse i fullt mått.
Mo sì mọ̀ pé nígbà tí mo bá dé ọ̀dọ̀ yín, èmi yóò wà ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìbùkún ìyìnrere Kristi.
30 Och nu uppmanar jag eder, mina bröder, vid vår Herre Jesus Kristus och vid vår kärlek i Anden, att bistå mig i min kamp, genom att bedja för mig till Gud,
Èmí rọ̀ yín, ẹ̀yin arákùnrin àti arábìnrin, nítorí Olúwa wa Jesu Kristi, àti nítorí ìfẹ́ Ẹ̀mí, kí ẹ̀yin kí ó kún mi láti bá mi làkàkà nínú àdúrà yín sí Ọlọ́run fún mi.
31 att jag må bliva frälst undan de ohörsamma i Judeen, och att det understöd som jag för med mig till Jerusalem må bliva väl mottaget av de heliga.
Kí a lè kó mi yọ kúrò lọ́wọ́ àwọn aláìgbàgbọ́ ní Judea àti kí iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí mo ní sí Jerusalẹmu le jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn mímọ́ níbẹ̀,
32 Så skall jag, om Gud vill, med glädje komma till eder och vederkvicka mig tillsammans med eder.
kí èmi le fi ayọ̀ tọ̀ yín wa, nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, àti kí èmi lè ní ìtura pọ̀ pẹ̀lú yín.
33 Fridens Gud vare med eder alla. Amen.
Kí Ọlọ́run àlàáfíà wà pẹ̀lú gbogbo yín. Àmín.

< Romarbrevet 15 >