< Romarbrevet 14 >

1 Om någon är svag i tron, så upptagen honom dock vänligt, utan att döma över andras betänkligheter.
Ẹ gba ẹni tí ó bá ṣe àìlera ní ìgbàgbọ́ mọ́ra, kí ẹ má ṣe tọpinpin ìṣeyèméjì rẹ̀.
2 Den ene har tro till att äta vad som helst, under det att den som är svag allenast äter vad som växer på jorden.
Ẹnìkan gbàgbọ́ pé òun lè máa jẹ ohun gbogbo: ṣùgbọ́n ẹlòmíràn tí ó sì jẹ́ aláìlera ní ìgbàgbọ́ ń jẹ ewébẹ̀ nìkan.
3 Den som äter må icke förakta den som icke äter. Ej heller må den som icke äter döma den som äter; ty Gud har upptagit honom,
Kí ẹni tí ń jẹ ohun gbogbo má ṣe kẹ́gàn ẹni tí kò jẹ; kí ẹni tí kò sì jẹ ohun gbogbo kí ó má ṣe dá ẹni tí ń jẹ lẹ́bi nítorí Ọlọ́run ti gbà á.
4 och vem är du som dömer en annans tjänare? Om han står eller faller, det kommer allenast hans egen herre vid; men han skall väl bliva stående, ty Herren är mäktig att hålla honom stående.
Ta ni ìwọ láti dá ọmọ ọ̀dọ̀ ẹlòmíràn lẹ́jọ́? Lójú olúwa tirẹ̀ ni òun dúró, tàbí ṣubú. Òun yóò sì dúró nítorí Ọlọ́run ní agbára láti mú kí òun dúró.
5 Den ene gör skillnad mellan dag och dag, den andre håller alla dagar för lika; var och en vare fullt viss i sitt sinne.
Ẹnìkan bu ọlá fún ọjọ́ kan ju òmíràn; ẹlòmíràn bu ọlá fún ọjọ́ gbogbo bákan náà. Kí olúkúlùkù kí ó dá ara rẹ̀ lójú ní inú ara rẹ̀.
6 Om någon särskilt aktar på någon dag, så gör han detta för Herren, och om någon äter, så gör han detta för Herren; han tackar ju Gud. Så ock, om någon avhåller sig från att äta, gör han detta för Herren, och han tackar Gud.
Ẹni tí ó bá ya ọjọ́ kan sí ọ̀tọ̀, ó ń yà á sọ́tọ̀ fún Olúwa. Ẹni tí ó ń jẹ ẹran, ó ń jẹ ẹran fún Olúwa, nítorí pé òun náà dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run; ẹni tí kò bá sì jẹ ẹran, kò jẹ ẹran fún Olúwa, òun náà dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run.
7 Ty ingen av oss lever för sig själv, och ingen dör för sig själv.
Nítorí kò sí ẹnìkan tí ó wà láààyè fún ara rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹni tí ó kú fún ara rẹ̀.
8 Leva vi, så leva vi för Herren; dö vi, så dö vi för Herren. Evad vi leva eller dö, höra vi alltså Herren till.
Bí a bá wà láààyè, a wà láààyè fún Olúwa; bí a bá sì kú, a kú fún Olúwa. Nítorí náà, bí a wà láààyè, tàbí bí a kú, ti Olúwa ni àwa i ṣe.
9 Ty därför har Kristus dött och åter blivit levande, att han skall vara herre över både döda och levande.
Nítorí ìdí èyí náà ni Kristi ṣe kú, tí ó sì tún yè, kí ó bá le jẹ́ Olúwa òkú àti alààyè.
10 Men du, varför dömer du din broder? Och du åter, varför föraktar du din broder? Vi skola ju alla en gång stå inför Guds domstol.
Èéṣe nígbà náà tí ìwọ fi ń dá arákùnrin tàbí arábìnrin rẹ lẹ́jọ́? Tàbí èéṣe tí ìwọ fi ń gàn wọn? Nítorí gbogbo wa ni yóò dúró níwájú ìtẹ́ ìdájọ́ Ọlọ́run.
11 Ty det är skrivet: "Så sant jag lever, säger Herren, för mig skola alla knän böja sig, och alla tungor skola prisa Gud."
A ti kọ ìwé rẹ̀ pé: “‘Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè,’ ni Olúwa wí, ‘gbogbo eékún ni yóò wólẹ̀ fún mi; gbogbo ahọ́n ni yóò jẹ́wọ́ fún Ọlọ́run.’”
12 Alltså skall var och en av oss inför Gud göra räkenskap för sig själv.
Ǹjẹ́ nítorí náà, olúkúlùkù wa ni yóò jíyìn ara rẹ̀ fún Ọlọ́run.
13 Låtom oss därför icke mer döma varandra. Dömen hellre så, att ingen må för sin broder lägga en stötesten eller något som bliver honom till fall.
Nítorí náà, ẹ má ṣe tún jẹ́ kí a máa dá ara wa lẹ́jọ́ mọ́. Ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀, ẹ pinu nínú ọkàn yín láti má ṣe fi ohun ìkọ̀sẹ̀ tàbí òkúta ìdìgbòlù kankan sí ọ̀nà arákùnrin tàbí arábìnrin yín.
14 Jag vet väl och är i Herren Jesus viss om att intet i sig självt är orent; allenast om någon håller något för orent, så är det för honom orent.
Mo mọ̀ dájú gbangba bí ẹni tí ó wà nínú Jesu Olúwa pé, kò sí ohun tó ṣe àìmọ́ fún ara rẹ̀. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ka ohunkóhun sí àìmọ́, òun ni ó ṣe àìmọ́ fún.
15 Om nu genom din mat bekymmer vållas din broder, så vandrar du icke mer i kärleken. Bliv icke genom din mat till fördärv för den som Kristus har lidit döden för.
Bí inú arákùnrin tàbí arábìnrin rẹ ba bàjẹ́ nítorí oúnjẹ rẹ, ìwọ kò rìn nínú ìfẹ́ mọ́. Má ṣe fi oúnjẹ rẹ sọ ẹni tí Kristi kú fún di ẹni ègbé.
16 Låten alltså icke det goda som I haven fått bliva utsatt för smädelse.
Nítorí náà, ẹ má ṣe jẹ́ kí a máa sọ̀rọ̀ ohun tí ẹ mọ̀ sí rere ní búburú.
17 Ty Guds rike består icke i mat och dryck, utan i rättfärdighet och frid och glädje i den helige Ande.
Nítorí ìjọba ọ̀run kì í ṣe jíjẹ àti mímu, bí kò ṣe nípa ti òdodo, àlàáfíà àti ayọ̀ nínú Ẹ̀mí Mímọ́,
18 Den som häri tjänar Kristus, han är välbehaglig för Gud och håller provet inför människor.
nítorí ẹni tí ó bá sin Kristi nínú nǹkan wọ̀nyí ni ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ Ọlọ́run, tí ó sì ní ìyìn lọ́dọ̀ ènìyàn.
19 Vi vilja alltså fara efter det som länder till frid och till inbördes uppbyggelse.
Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí a ṣa gbogbo ipá wa láti máa lépa àlàáfíà, àti ohun tí àwa yóò fi gbé ara wa ró.
20 Bryt icke för mats skull ned Guds verk. Väl är allting rent, men om ätandet för någon är en stötesten, så bliver det för den människan till ondo;
Má ṣe bi iṣẹ́ Ọlọ́run ṣubú nítorí oúnjẹ. Gbogbo oúnjẹ ni ó mọ́, ṣùgbọ́n ohun búburú ni fún ẹni náà tí ó jẹ ohunkóhun tí ó le mú ẹlòmíràn kọsẹ̀.
21 du gör väl i att avhålla dig från att äta kött och dricka vin och från annat som för din broder bliver en stötesten.
Ó dára kí a má tilẹ̀ jẹ ẹran tàbí mu wáìnì tàbí ṣe ohunkóhun tí yóò mú arákùnrin tàbí arábìnrin rẹ ṣubú.
22 Den tro du har må du hava för dig själv inför Gud. Salig är den som icke måste döma sig själv, när det gäller något som han har prövat vara rätt.
Nítorí náà, ohun tí ìwọ bá gbàgbọ́ nípa gbogbo nǹkan wọ̀nyí, pa á mọ́ ní àárín ìwọ àti Ọlọ́run. Alábùkún fún ni ẹni náà tí kò dá ara rẹ̀ lẹ́bi nínú ohun tí ó yàn.
23 Men om någon hyser betänkligheter och likväl äter, då är han dömd, eftersom det icke sker av tro. Ty allt som icke sker av tro, det är synd.
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó ṣe iyèméjì, ó jẹ̀bi bí ó ba jẹ ẹ́, nítorí jíjẹ ẹ́ rẹ̀ kò ti inú ìgbàgbọ́ wá; bẹ́ẹ̀ sì ni, ohun gbogbo tí kò bá ti inú ìgbàgbọ́ wá, ẹ̀ṣẹ̀ ni.

< Romarbrevet 14 >