< Sofoniasza 2 >

1 Wejrzyjcie w się, wejrzyjcie w się, mówię, o narody przemierzłe!
Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìtìjú,
2 Pierwej, niżeli wyjdzie dekret, i niż dzień jako plewa przeminie; pierwej niż przyjdzie na was gniew zapalczywości Pańskiej, pierwej niż przyjdzie na was dzień gniewu Pańskiego.
kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà, kí gbígbóná ìbínú Olúwa tó dé bá a yín, kí ọjọ́ ìbínú Olúwa kí ó tó dé bá a yín.
3 Szukajcie Pana wszyscy pokorni na ziemi, którzy sąd jego czynicie; szukajcie sprawiedliwości, szukajcie pokory, snać się ukryjecie w dzień zapalczywości Pańskiej;
Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà, ẹ̀yin tí ń ṣe ohun tí ó bá pàṣẹ. Ẹ wá òdodo, ẹ wá ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú, bóyá á ó pa yín mọ́ ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.
4 Bo Gaza opuszczona będzie, i Aszkalon spustoszony, Azot w południe wyrzucą, a Akkaron wykorzeniony będzie.
Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀, Aṣkeloni yóò sì dahoro. Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde, a ó sì fa Ekroni tu kúrò.
5 Biada mieszkającym w krainie pomorskiej, narodowi Ceretejczyków! słowo Pańskie przeciwko wam jest, o ziemio Chananejska Filystyńczyków! że cię tak wytracę, aby nie było obywatela.
Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun, ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti; ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani, ilẹ̀ àwọn ara Filistini. “Èmi yóò pa yín run, ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”
6 I będzie kraina pomorska owczarniami i budami pasterskiemi, i oborą dla trzód.
Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti, ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.
7 Będzie też i ostatkowi domu Judzkiego krainą dla pasienia; w domach Aszkalon na wieczór legać będą, gdyż ich nawiedzi Pan, Bóg ich, i przywróci zaś więźniów ich.
Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda, níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran. Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́. Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò, yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.
8 Słyszałem urąganie Moabczyków i hańbienia synów Amonowych, któremi urągali ludowi mojemu, i wynosili się na granicach ich.
“Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu, àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni, àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
9 Przetoż jako żyję Ja, mówi Pan zastępów, Bóg Izraelski, że się Moab stanie jako Sodoma, a synowie Ammonowi jako Gomora, miejscem pokrzyw i jamą solną i pustynią aż na wieki; ostatki ludu mego rozchwycą ich, i pozostali z ludu mego osiędą ich.
Nítorí náà, bí Èmi tí wà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí, “nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu, àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra, ibi tí ó kún fún yèrèpè, àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé. Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn; àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni yóò jogún ilẹ̀ wọn.”
10 To ich spotka za pychę ich, iż lżyli i wynosili się nad lud Pana zastępów.
Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn, nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
11 Straszny im będzie Pan, bo sprawi, że schudną wszyscy bogowie ziemi; i będzie mu się kłaniał każdy z miejsca swego, wszystkie wyspy narodów.
Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn; nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run. Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn, olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.
12 I wy też, Murzynowie! mieczem moim pobici będziecie;
“Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú, a ó fi idà mi pa yín.”
13 Bo wyciągnę rękę moję na północy, i wytracę Assura, i podam Niniwę w spustoszenie i suszę, jako pustynię.
Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá, yóò sì pa Asiria run, yóò sì sọ Ninefe di ahoro, àti di gbígbẹ bí aginjù.
14 I będą trzody legały w pośrodku jego, i wszystek zwierz narodów, i pelikan i sowa na gałkach jego przebywać będą, głos ptastwa w oknach słyszany będzie, podwoje jego spustoszeją, gdy cedrowe listwowania jego odedrą.
Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀, àti gbogbo ẹranko àwọn orílẹ̀-èdè. Òwìwí aginjù àti ti n kígbe ẹyẹ òwìwí yóò wọ bí ẹyẹ ni ọwọ̀n rẹ̀. Ohùn wọn yóò kọrin ni ojú fèrèsé, ìdahoro yóò wà nínú ìloro ẹnu-ọ̀nà, òun yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá kedari sílẹ̀.
15 Takieć będzie ono miasto weselące się, które siedzi bezpiecznie, mówiące w sercu swojem: Jam miasto, a oprócz mnie niemasz takiego. Jakoć się stało spustoszeniem! jaskinią zwierzowi! każdy przechodzący przez nie zaświśnie, i kiwać będzie ręką swo ją.
Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu. Ó sì sọ fun ara rẹ̀ pé, “Èmi ni, kò sì sí ẹnìkan tí ó ń bẹ lẹ́yìn mi.” Irú ahoro wo ni òun ha ti jẹ́, ibùgbé fún àwọn ẹranko igbó! Gbogbo ẹni tí ó bá kọjá ọ̀dọ̀ rẹ̀ yóò fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà, wọ́n yóò sì gbọn ẹsẹ̀ wọn.

< Sofoniasza 2 >