< Zachariasza 7 >

1 Potem stało się roku czwartego Daryjusza króla, stało się słowo Pańskie do Zacharyjasza dnia czwartego, miesiąca dziewiątego, który jest Kislew;
Ó sì ṣe ní ọdún kẹrin Dariusi ọba, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ Sekariah wá ni ọjọ́ kẹrin oṣù Kisleu tí ń ṣe oṣù kẹsànán.
2 Gdy posłał lud do domu Bożego Sarassara i Regiemmelecha, i mężów jego, aby się modlili przed obliczem Pańskiem;
Nígbà tí wọ́n ènìyàn Beteli rán Ṣareseri àti Regemmeleki, àti àwọn ènìyàn wọn sí ilé Ọlọ́run láti wá ojúrere Olúwa.
3 I aby mówili do kapłanów, którzy byli w domu Pana zastępów, także i do proroków, mówiąc: Izali jeszcze płakać będę miesiąca piątego, wyłączywszy się tak, jakom już czynił przez kilka lat?
Àti láti bá àwọn àlùfáà tí ó wà ní ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti àwọn wòlíì sọ̀rọ̀ wí pé, “Ṣé kí èmi ó sọkún ní oṣù karùn-ún kí èmi ya ara mi sọ́tọ̀, bí mo ti ń ṣe láti ọdún mélòó wọ̀nyí wá bí?”
4 I stało się słowo Pana zastępów do mnie, mówiąc:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tọ̀ mí wá pé,
5 Rzecz do wszystkiego ludu tej ziemi, i do kapłanów, mówiąc: Gdyście pościli i płakali piątego i siódmego miesiąca przez te siedmdziesiąt lat, izażeście mnie, mnie, mówię, post pościli?
“Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti fún àwọn àlùfáà pé, ‘Nígbà tí ẹ̀yin gbààwẹ̀, tí ẹ sì ṣọ̀fọ̀ ní oṣù karùn-ún àti keje, àní fun àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, ǹjẹ́ èmi ni ẹ̀yin ha ń gbààwẹ̀ yín fún?
6 A gdy jecie albo pijecie, izali nie sobie jecie i nie sobie pijecie?
Nígbà tí ẹ sì jẹ, àti nígbà tí ẹ mu, fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin jẹ, àti fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin mú bí?
7 Izaliście nie tak czynić mieli według słowa, które przepowiedział Pan przez proroków przeszłych, gdy jeszcze Jeruzalem bezpieczeństwa i pokoju używało, i miasta jego około niego, i lud w stronie południowej i po polach mieszkał (w pokoju?)
Wọ̀nyí kọ́ ni ọ̀rọ̀ ti Olúwa ti kígbe láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì ìṣáájú wá, nígbà tí a ń gbé Jerusalẹmu, tí ó sì wà ní àlàáfíà, pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀ tí ó yí i káàkiri, nígbà tí a ń gbé gúúsù àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.’”
8 I stało się słowo Pańskie do Zacharyjasza, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Sekariah wá, wí pé,
9 Tak powiedział Pan zastępów, mówiąc: Sprawiedliwie sądźcie, a miłosierdzie i litość pokazujcie każdy nad bliźnim swoim;
“Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ṣe ìdájọ́ òtítọ́, kí ẹ sì ṣe àánú àti ìyọ́nú olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀.
10 A wdowy i sieroty, i przychodnia, i ubogiego nie uciskajcie, i złego jeden przeciwko drugiemu nie myślcie w sercu swojem.
Má sì ṣe ni opó lára tàbí aláìní baba, àlejò, tàbí tálákà; kí ẹnikẹ́ni nínú yín má ṣe gbèrò ibi ní ọkàn sí arákùnrin rẹ̀.’
11 Ale nie chcieli dbać; i obrócili się tyłem, a uszy swe zatulili, aby nie słuchali.
“Ṣùgbọ́n wọ́n kọ̀ láti gbọ́, wọ́n sì gún èjìká, wọ́n sì pa ẹ̀yìn dà, wọ́n di etí wọn, kí wọn má ba à gbọ́.
12 Serca też swe zatwardzili jako dyjament, aby nie słuchali zakonu tego i słów, które posyłał Pan zastępów duchem swoim przez proroków przeszłych, skąd przyszedł wielki gniew od Pana zastępów.
Wọ́n sé ọkàn wọn bí òkúta líle, kí wọn má ba à gbọ́ òfin, àti ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti fi ẹ̀mí rẹ̀ rán nípa ọwọ́ àwọn wòlíì ìṣáájú wá. Ìbínú ńlá sì dé láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
13 Bo jako oni, gdy ich wołano, nie słuchali, tak też, gdy oni wołali, nie wysłuchałem, mówi Pan zastępów.
“‘Ó sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ó ti kígbe, tí wọn kò sì fẹ́ gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kígbe, tí èmi kò sì fẹ́ gbọ́,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
14 I rozproszyłem ich jako wicher między wszystkie narody, które nie znali, i ta ziemia spustoszała po nich, tak, że nie był przechodzący i wracający się, a tak ziemię pożądaną w spustoszenie obrócili.
‘Mo sì fi ìjì tú wọn ká sí gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọn kò mọ̀. Ilẹ̀ náà sì dahoro lẹ́yìn wọn, tí ẹnikẹ́ni kò là á kọjá tàbí kí ó padà bọ̀, wọ́n sì sọ ilẹ̀ ààyò náà dahoro.’”

< Zachariasza 7 >