< Zachariasza 5 >

1 Potemem się obrócił, a podniósłszy oczu swych ujrzałem, a oto księga leciała.
Nígbà náà ni mo yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ìwé kíká ti ń fò.
2 I rzekł do mnie: Cóż widzisz? I rzekłem: Widzę księgę lecącą, której długość na dwadzieścia łokci, a szerokość na dziesięć łokci.
Ó sì wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ rí?” Èmi sì dáhùn pé, “Mo rí ìwé kíká tí ń fò; gígùn rẹ̀ jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́, ìbú rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá.”
3 I rzekł do mnie: Toć jest przeklęstwo, które wyjdzie na oblicze wszystkiej ziemi: bo każdy złodziej według tego przeklęstwa, jako i ta ziemia, wygładzony, i każdy fałszywie przysięgający według niego, jako i ona, wygładzony będzie.
Ó sì wí fún mi pé, “Èyí ni ègún tí ó jáde lọ sí gbogbo ilẹ̀ ayé, nítorí gbogbo àwọn tí ó bá jalè ni a ó ké kúrò láti ìhín lọ nípa rẹ̀; gbogbo àwọn tí ó bá sì búra èké ni a ó ké kúrò láti ìhín lọ nípa rẹ̀.
4 Wywiodę je, mówi Pan zastępów, aby przyszło na dom złodzieja, i na dom kłamliwie przez imię moje przysięgającego; owszem, mieszkać będzie w pośrodku domu jego, i zniszczy go, i drzewo jego i kamienie jego.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò mú un jáde, Èmi yóò si wọ inú ilé olè lọ, àti inú ilé ẹni ti o bá fi orúkọ mi búra èké, yóò si wà ni àárín ilé rẹ̀, yóò si rún pẹ̀lú igi àti òkúta inú rẹ̀.’”
5 Wyszedł tedy Anioł on, który zemną mówił, i rzekł mi: Podnieśże teraz oczu swych, a obacz, co to jest, co wychodzi.
Angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ sì jáde lọ, ó sì wí fún mi pé, “Gbé ojú rẹ sókè nísinsin yìí, kí o sì wo nǹkan tí yóò jáde lọ.”
6 I rzekłem: Cóż jest? A on odpowiedział: To jest efa wychodzące. Potem rzekł: Toć jest oko ich przypatrujące się wszystkiej ziemi.
Mo sì wí pé, “Kí ni nǹkan náà?” Ó sì wí pé, “Èyí ni òsùwọ̀n tí ó jáde lọ.” Ó sì wí pé, “Èyí ni àwòrán ní gbogbo ilẹ̀ ayé.”
7 A oto sztukę ołowiu niesiono, a przytem była niewiasta jedna, która siedziała w pośrodku efa.
Sì kíyèsi i, a gbé tálẹ́ǹtì òjé sókè, obìnrin kan sì nìyìí tí ó jókòó sí àárín àpẹẹrẹ òsùwọ̀n.
8 Tedy rzekł Anioł: Toć jest ona niezbożność; i wrzucił ją w pośród efa, wrzucił i onę sztukę ołowiu na wierzch efy.
Ó sì wí pé, “Èyí ni ìwà búburú.” Ó sì ti sí àárín òsùwọ̀n, ó sì ju ìdérí òjé sí ẹnu rẹ̀.
9 A podniósłszy oczu swych ujrzałem, a oto dwie niewiasty wychodziły, mające wiatr w skrzydłach swych, a miały skrzydła, jako skrzydła bocianie, i podniosły ono efa między ziemię i między niebo.
Mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, obìnrin méjì jáde wá, ẹ̀fúùfù sì wá nínú ìyẹ́ wọn; nítorí wọ́n ní ìyẹ́ bí ìyẹ́ àkọ̀, wọ́n sì gbé àpẹẹrẹ òsùwọ̀n náà dé àárín méjì ayé àti ọ̀run.
10 Tedym rzekł do onego Anioła, który mówił zemną: Dokądże niosą to efa?
Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Níbo ni àwọn wọ̀nyí ń gbé òsùwọ̀n náà lọ.”
11 I rzekł do mnie: Aby mu zbudowano dom w ziemi Senaar, gdzieby umocnione było i postawione na podstawku swoim.
Ó si wí fún mi pé, “Sí orílẹ̀-èdè Babeli láti kọ ilé fún un. Tí ó bá ṣetán, a ó sì fi ìdí rẹ̀ mulẹ̀, a o sì fi ka orí ìpìlẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.”

< Zachariasza 5 >