< Psalmów 62 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi Jedytunowi psalm Dawidowy. Tylko na Boga spolega dusza moja, od niegoć jest zbawienie moje.
Fún adarí orin. Fun Jedutuni. Saamu Dafidi. Nínú Ọlọ́run nìkan ni ọkàn mi ti rí ìsinmi; ìgbàlà mi ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá.
2 Tylkoć on jest skałą moją i wybawieniem mojem, twierdzą moją; przeto się bardzo nie zachwieję.
Òun nìkan ní àpáta mi àti ìgbàlà mi; Òun ni ààbò mi, a kì yóò sí mi ní ipò padà.
3 Dokądże będziecie myślić złe przeciwko człowiekowi? Wszyscy wy zabici będziecie; będziecie jako ściana pochylona, a jako mur walący się.
Ẹ̀yin ó ti máa kọ́lú ènìyàn kan pẹ́ tó? Gbogbo yín ni ó fẹ́ pa á, bí ògiri tí ó fẹ́ yẹ̀, àti bí ọgbà tí ń wó lọ?
4 Przecież jednak radzą, jakoby go zepchnąć z dostojeństwa jego; kochają się w kłamstwie, usty swemi dobrorzeczą, ale w sercu swem złorzeczą. (Sela)
Kìkì èrò wọn ni láti bì ṣubú kúrò nínú ọlá rẹ̀; inú wọn dùn sí irọ́. Wọ́n ń fi ẹnu wọn súre, ṣùgbọ́n wọ́n ń gégùn ún nínú ọkàn wọn. (Sela)
5 Ty przecież na Bogu spolegaj, duszo moja! bo od niego jest oczekiwanie moje.
Nínú Ọlọ́run nìkan ni ìsinmi wà, ìwọ Ọlọ́run mi. Ìrètí mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ.
6 Onci sam jest skałą moją zbawieniem mojem, i twierdzą moją; przetoż nie zachwieję się.
Òun nìkan ní àpáta àti ìgbàlà mi; Òun ni ààbò mi, a kì yóò ṣí mi ní ipò.
7 W Bogu wybawienie moje, i chwała moja skała mocy mojej; nadzieja moja jest w Bogu.
Ìgbàlà mi àti ògo mi dúró nínú Ọlọ́run; Òun ní àpáta ńlá mi, àti ààbò mi.
8 Ufajcież w nim na każdy czas, o narody! Wylewajcie przed obliczem jego serca wasze: Bóg jest ucieczką naszą. (Sela)
Gbẹ́kẹ̀lé ní gbogbo ìgbà, ẹ̀yin ènìyàn; tú ọkàn rẹ jáde sí i, nítorí Ọlọ́run ni ààbò wa.
9 Zaprawdęć marnością są synowie ludzcy, kłamliwi synowie mocarzy; będąli pospołu włożeni na wagę, lekciejszymi będą nad marność.
Nítòótọ́, asán ni àwọn ọmọ ènìyàn, èké sì ni àwọn olóyè, wọ́n gòkè nínú ìwọ̀n, lápapọ̀ wọ́n jẹ́ èémí.
10 Nie ufajcież w krzywdzie ani w drapiestwie, a nie będźcie marnymi; przybędzieli wam majętności, nie przykładajcież serca do nich.
Má ṣe gbẹ́kẹ̀lé ìnilára, tàbí gbéraga nínú olè jíjà, nítòótọ́ bí ọrọ̀ rẹ̀ ń pọ̀ sí i, má ṣe gbẹ́kẹ̀ rẹ lé wọn.
11 Razci rzekł Bóg, dwakrociem to słyszał, iż moc jest Boża,
Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kejì, ni mo gbọ́ èyí pé, “Ti Ọlọ́run ni agbára,
12 A że Panie! twoje jest miłosierdzie, a że ty oddasz każdemu według uczynków jego.
pẹ̀lúpẹ̀lú, Olúwa, tìrẹ ni àánú; nítorí tí ìwọ san án fún olúkúlùkù ènìyàn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀.”

< Psalmów 62 >