< Psalmów 140 >

1 Przedniejszemu śpiewakowi psalm Dawidowy. Wyrwij mię, Panie! od człowieka złego, od męża okrutnego strzeż mię;
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Olúwa, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì, yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì,
2 Którzy myślą złe rzeczy w sercu, a na każdy dzień zbierają się na wojnę.
ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn; nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.
3 Zaostrzają język swój, jako wąż; jad żmij pod wargami ich. (Sela)
Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò, oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.
4 Zachowaj mię, Panie! od rąk bezbożnika; od męża okrutnego strzeż mię, którzy myślili podwrócić nogi moje.
Olúwa, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú; yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú.
5 Hardzi na mię zastawili sidło, i powrozy; rozciągnęli sieci przy ścieszce, a sidła swe zastawili na mię. (Sela)
Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn: wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà; wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.
6 Rzekłem Panu: Tyś jest Bóg mój! wysłuchajże, Panie! głos modlitw moich.
Èmi wí fún Olúwa pé ìwọ ni Ọlọ́run mi; Olúwa, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
7 O Panie, Panie mocy zbawienia mego, który przykrywasz głowę moję w dzień bitwy!
Olúwa Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi, ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.
8 Nie dawaj, Panie! bezbożnemu czego żąda; ani myśli jego złej góry nie dawaj, żeby się nie podniósł. (Sela)
Olúwa, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un; má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́; kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. (Sela)
9 A wodza tych, którzy mię obstąpili, nieprawość warg ich niech ich okryje.
Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni, jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.
10 Niech na nich spadną węgle rozpalone; do ognia niech wrzuceni będą, i do dołów głębokich, skądby nie powstali.
A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára, Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná, sínú ọ̀gbun omi jíjìn, kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.
11 Potwarca nie będzie utwierdzony na ziemi, a mąż okrutny złością ułowiony będąc upadnie.
Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé; ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.
12 Wiem, że Pan uczyni sąd utrapionemu, i pomstę nędznych.
Èmi mọ̀ pé, Olúwa yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró, yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà.
13 A tak sprawiedliwi będą wysławiać imię twoje, a szczerzy będą mieszkać przed obliczem twojem.
Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ; àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.

< Psalmów 140 >