< Psalmów 137 >

1 Nad rzekami Babilońskiemi, tameśmy siadali i płakali, wspominając na Syon.
Ní ẹ̀bá odò Babeli, níbẹ̀ ni àwa gbé jókòó àwa sì sọkún nígbà tí àwa rántí Sioni.
2 Na wierzbach, które są w nim, zawieszaliśmy harfy nasze.
Àwa fi dùùrù wa kọ́ sí orí igi wílò, tí ó wà láàrín rẹ̀.
3 A gdy nas tam pytali ci, którzy nas zawiedli w niewolę, o słowa pieśni, ( chociażeśmy byli zawiesili pieśni radości, ) mówiąc: Śpiewajcie nam pieśń z pieśni Syońskich,
Nítorí pé níbẹ̀ ni àwọn tí ó kó wa ní ìgbèkùn béèrè orin lọ́wọ́ wa, àti àwọn tí ó ni wá lára béèrè ìdárayá; wọn wí pé, “Ẹ kọ orin Sioni kan fún wa!”
4 Odpowiedzieliśmy: Jakoż mamy śpiewać pieśń Pańską w ziemi cudzoziemców?
Àwa ó ti ṣe kọ orin Olúwa ní ilẹ̀ àjèjì
5 Jeźliże cię zapomnę, o Jeruzalemie! niech zapomni sama siebie prawica moja.
Jerusalẹmu, bí èmi bá gbàgbé rẹ jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó gbàgbé ìlò rẹ̀.
6 Niech przylgnie język mój do podniebienia mego, jeźlibym na cię nie pomniał, jeźlibym nie przełożył Jeruzalemu nad najwiekszę wesele moje.
Bí èmi kò bá rántí rẹ, jẹ́ kí ahọ́n mi kí ó lẹ̀ mọ́ èrìgì mi; bí èmi kò bá fi Jerusalẹmu ṣáájú olórí ayọ̀ mi gbogbo.
7 Wspomnij, Panie! na synów Edomskich, i na dzień Jeruzalemski, w który mówili: Poburzcie, poburzcie aż do gruntu w nim.
Olúwa rántí ọjọ́ Jerusalẹmu, lára àwọn ọmọ Edomu, àwọn ẹni tí ń wí pé, “Wó o palẹ̀, wó o palẹ̀ dé ìpìlẹ̀ rẹ̀!”
8 O córko Babilońska! i ty będziesz spustoszona. Błogosławiony, któryć odda nagrodę twoję, za to, coś nam złego uczyniła.
Ìwọ, ọmọbìnrin Babeli, ẹni tí a ó parun; ìbùkún ni fún ẹni tí ó san án fún ọ bí ìwọ ti rò sí wa.
9 Błogosławiony, który pochwyci i roztrąci dziatki twe o skałę.
Ìbùkún ni fún ẹni tí ó mú ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ tí ó sì fi wọ́n ṣán òkúta.

< Psalmów 137 >