< Przysłów 16 >

1 Człowiek sporządza myśli serca swego; ale od Pana jest odpowiedź języka.
Ti ènìyàn ni ìgbèrò inú ọkàn ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìdáhùn ahọ́n ti ń wá.
2 Wszystkie drogi człowiecze zdadzą się być czyste przed oczyma jego; ale Pan jest, który waży serca.
Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dàbí i pé ó dára lójú ara rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ló ń díwọ̀n èrò inú ọkàn.
3 Włóż na Pana sprawy twe, a będą utwierdzone zamysły twoje.
Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé Olúwa lọ́wọ́, èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe.
4 Pan dla siebie samego wszystko sprawił, nawet i niezbożnika na dzień zły.
Olúwa ti ṣe ohun gbogbo láti mú kí ó rí bí ó ṣe fẹ́ kódà ènìyàn búburú fún ọjọ́ ìpọ́njú.
5 Obrzydliwością jest Panu każdy wyniosłego serca; który choć sobie innych na pomoc weźmie, nie ujdzie pomsty.
Olúwa kórìíra gbogbo ẹni tí ń gbéraga lọ́kàn rẹ̀ mọ èyí dájú pé wọn kò ní lọ láìjìyà.
6 Miłosierdziem i prawdą oczyszczona bywa nieprawość, a w bojaźni Pańskiej odstępujemy od złego.
Nípasẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣe ètùtù ẹ̀ṣẹ̀ nípasẹ̀ ìbẹ̀rù Olúwa ènìyàn sá fún ibi.
7 Gdy się podobają Panu drogi człowieka, i nieprzyjaciół jego do zgody z nim przywodzi.
Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ Olúwa lọ́rùn, yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn án bá a gbé ní àlàáfíà.
8 Lepsza jest trocha z sprawiedliwością, niż wiele dochodów niesprawiedliwych.
Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodo ju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú lọ.
9 Serce człowiecze rozrządza drogi swe; ale Pan sprawuje kroki jego.
Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀ ṣùgbọ́n Olúwa ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀.
10 Sprawiedliwy rozsądek jest w wargach królewskich; w sądzie nie błądzą usta jego.
Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa àṣẹ sí i ẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ ṣèké.
11 Waga i szale są ustawą Pańską, a wszystkie gwichty sprawiedliwe w worku są za sprawą jego.
Òdínwọ̀n àti òsùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀.
12 Obrzydliwością jest królom czynić niezbożność; bo sprawiedliwością stolica umocniona bywa.
Àwọn ọba kórìíra ìwà àìtọ́ nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀.
13 Przyjemne są królom wargi sprawiedliwe, a szczerych w mowie miłują.
Àwọn ọba ní inú dídùn sí ètè tí ń ṣọ òtítọ́, wọ́n sì fẹ́ ẹni tí ń sọ̀rọ̀ òtítọ́.
14 Gniew królewski jest posłem śmierci; ale mąż mądry ubłaga go.
Ìránṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́ ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú.
15 W jasności twarzy królewskiej jest żywot, a łaska jego jest jako obłok z deszczem późnym.
Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè; ojúrere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò.
16 Daleko lepiej jest nabyć mądrości, niżeli złota najczystszego; a nabyć roztropności lepiej, niż srebra.
Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọ àti láti yan òye dípò o fàdákà!
17 Gościniec uprzejmych jest odstąpić od złego; strzeże duszy swej, kto strzeże drogi swojej.
Òpópó ọ̀nà àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yàgò fún ibi, ẹni tí ó ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀, ṣọ́ ẹnu ara rẹ̀.
18 Przed zginieniem przychodzi pycha, a przed upadkiem wyniosłość ducha.
Ìgbéraga ní í ṣáájú ìparun, agídí ọkàn ní í ṣáájú ìṣubú.
19 Lepiej jest być uniżonego ducha z pokornymi, niżeli dzielić korzyści z pysznymi.
Ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrín àwọn olùpọ́njú jù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.
20 Kto ma wzgląd na słowa, znajduje dobre; a kto ufa w Panu, błogosławiony jest.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ìre, ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
21 Kto jest mądrego serca, słynie rozumnym, a słodkość warg przydaje nauki.
Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóye ọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.
22 Zdrój żywota jest roztropność tym, którzy ją mają; ale umiejętność głupich jest głupstwem.
Òye jẹ́ orísun ìyè fún àwọn tí ó ní i, ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.
23 Serce mądrego roztropnie sprawuje usta swoje, a wargami swemi przydaje nauki.
Ọkàn ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀ ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ dàgbà.
24 Powieści wdzięczne są jako plastr miodu, słodkością duszy, a lekarstwem kościom.
Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyin ó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.
25 Zda się podczas droga być prosta człowiekowi; wszakże dokończenie jej pewna droga na śmierć.
Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.
26 Człowiek pracowity pracuje sobie; bo go pobudzają usta jego.
Ọkàn alágbàṣe ń ṣiṣẹ́ fún ara rẹ̀; nítorí ebi rẹ̀ mú kí ó máa ṣiṣẹ́ lọ.
27 Człowiek niezbożny wykopuje złe, a w wargach jego jako ogień pałający.
Ènìyàn búburú ń pète ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì dàbí i iná tí ń jóni.
28 Mąż przewrotny rozsiewa zwady, a klatecznik rozłącza przyjaciół.
Aláyídáyidà ènìyàn dá ìjà sílẹ̀ olófòófó a sì máa pín ọ̀rẹ́ kòríkòsùn ní yà.
29 Mąż okrutny przewabia bliźniego swego, i wprowadza go na drogę niedobrą.
Oníjàgídíjàgan ènìyàn tan aládùúgbò rẹ̀ ó sì mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà tí kò dára.
30 Kto mruga oczyma swemi, zmyśla przewrotności; a kto rucha wargami swemi, broi złe.
Ẹni tí ń ṣẹ́jú ń pètekéte; ẹni tí ó ṣu ẹnu jọ ń pète aburú.
31 Koroną chwały jest sędziwość; znajduje się na drodze sprawiedliwości.
Adé ògo ni ewú orí jẹ́, ìgbé ayé òdodo ní í mú ni dé bẹ̀.
32 Lepszy jest nierychły do gniewu, niżeli mocarz; a kto panuje sercu swemu, lepszy jest, niżeli ten, co dobył miasta.
Ó sàn láti jẹ́ onísùúrù ju ajagun ènìyàn lọ, ẹni tí ó pa ìbínú mọ́ra ju ajagun ṣẹ́gun ìlú lọ.
33 Los na łono rzucają; ale od Pana jest wszystko rozrządzenie jego.
A ṣẹ́ kèké si ìṣẹ́po aṣọ, ṣùgbọ́n gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.

< Przysłów 16 >