< Micheasza 2 >

1 Biada tym, którzy wymyślają nieprawość, i knują złe na łożach swoich, a na świtaniu rano do skutku je przywodzą, gdyż to jest w mocy rąk ich.
Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn! Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
2 Pożądają pól, i wydzierają; także i domów, i odejmują; a tak przewodzą gwałt nad mężem i domem jego, nad każdym mężem i nad dziedzictwem jego.
Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n, àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n. Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.
3 Dlatego tak mówi Pan: Oto Ja złe myślę przeciwko rodzajowi temu, z którego nie wyjmiecie szyj waszych, ani będziecie chodzić pysznie; bo czas zły będzie.
Nítorí náà, Olúwa wí pé: “Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí, nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là. Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́, nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
4 W on dzień urośnie o was przypowieść, i narzekać będą nad wami płaczem żałośnym, mówiąc: Spustoszeniśmy do szczętu, Pan odmienił dział ludu mojego; o jakoć mi go odjął! jakoć wziąwszy pole nasze rozdzielił!
Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín; wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé: ‘Ní kíkó a ti kó wọn tán; Olúwa ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi; Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi! Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’”
5 Dlatego nie będziesz miał, ktoby rzucił sznurem na los w zgromadzeniu Pańskiem.
Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ Olúwa, tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.
6 Mówią: Nie prorokujcie, niech nam inni prorokują; bo nie prorokują tak jako ci; żaden z nich nie przestaje mów zelżywych.
“Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn wòlíì wọn wí. “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí; kí ìtìjú má ṣe le bá wa.”
7 O ty ludu, który słyniesz domem Jakóbowym! izali ukrócony ma być duch Pański? Izali takowe są sprawy jego? Azaż słowa moje nie są dobre temu, który chodzi w uprzejmości?
Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu: “Ǹjẹ́ ẹ̀mí Olúwa ha ń bínú bí? Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?” “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
8 Wczoraj był ludem moim, a dziś jako nieprzyjaciel powstaje; mając odzienie, zdzieracie płaszcz z tych, którzy chodzą bezpiecznie, którzy się wracają z wojny;
Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde bí ọ̀tá sí mi. Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀ kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu, bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
9 Żony ludu mego wyganiacie z domu rozkoszy ich, od dziatek ich ustawicznie odejmujecie sławę moję.
Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn, ẹ̀yin sì ti gba ògo mi, kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
10 Wstańcie, a odejdźcie, bo tu nie masz odpocznienia; pogubi was dla nieczystości, a to pogubieniem srogiem.
Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ! Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín, nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́ yóò pa yín run, àní ìparun kíkorò.
11 Gdy się kto za proroka udaje, a kłamstwo opowiadając mówi: Będęć prorokował o winie albo o napoju mocnym: takowyć bywa miłym prorokiem ludu tego.
Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé, ‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’ òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!
12 Zgromadzając cale cię zgromadzę, Jakóbie! zgromadzając zgromadzę ostatki Izraela, a spędzę je w gromadę jako owce Bocra, jako trzodę w pośród obory jego, i wyjdzie huk od ludu.
“Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu; Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ. Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran, gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn, ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
13 Zstąpi ten, który przełamywać będzie przed nimi; przełamie, a przejdą bramą, i wnijdą przez nią; nawet i król ich pójdzie przed nimi, a Pan na czele ich.
Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn; wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ. Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn, Olúwa ni yóò sì ṣe olórí wọn.”

< Micheasza 2 >