< Micheasza 1 >

1 Słowo Pańskie, które się stało do Micheasza Morastytczyka za dni Joatama, Achaza, i Ezechyjasza, królów Judzkich, które w widzeniu słyszał o Samaryi i o Jeruzalemie.
Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
2 Słuchajcie wszystkie narody! niech słucha ziemia, i wszystko, co na niej jest, a niech będzie panujący Pan przeciwko wam świadkiem, panujący z kościoła świętobliwości swojej.
Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn, fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, kí Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
3 Bo oto Pan wyjdzie z miejsca swojego, a zstąpiwszy deptać będzie po wysokościach ziemi;
Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀; yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
4 I rozpłyną się góry pod nim, a doliny popadają się, tak jako wosk od ognia, i jako wody, które spadają na dół.
Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀, àwọn àfonífojì yóò sì pínyà, bí idà níwájú iná, bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
5 To wszystko się stanie dla przestępstwa Jakóbowego, i dla grzechów domu Izraelskiego. Któż jest przyczyną przestępstwa Jakóbowego? izali nie Samaryja? i któż wyżyn Judzkich? izali nie Jeruzalem?
Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí, àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli. Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu? Ǹjẹ́ Samaria ha kọ? Kí ni àwọn ibi gíga Juda? Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
6 Przetoż obrócę Samaryję w gromadę gruzu, jako bywa na polu około winnic, i powrzucam w dolinę kamienie jej, a grunty jej odkryję.
“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá, bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà. Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì. Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
7 I wszystkie obrazy jej ryte będą potłuczone, i wszystkie jej dary ogniem spalone, i wszystkie jej bałwany obrócę w pustynię; bo to z zapłaty nierządnicy zgromadziła, przetoż się to zaś na zapłatę nierządnicy obróci.
Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run. Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà, gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
8 Nad tem kwilić i narzekać będę, chodząc zewleczony i nagi; uczynię lament jako smoki i narzekanie jako młode strusięta;
Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún, èmi yóò sì pohùnréré ẹkún: èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò. Èmi yóò ké bí akátá, èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
9 Przeto, że nieuleczone są rany jej, gdyż doszły aż do Judy, a dosięgły do bramy ludu mego aż do Jeruzalemu.
Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán; ó sì ti wá sí Juda. Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi, àní sí Jerusalẹmu.
10 W Giet tego nie opowiadajcie, ani kwiląc płaczcie; walaj się w prochu w domu Orfa;
Ẹ má ṣe sọ ní Gati ẹ má ṣe sọkún rárá. Ní ilẹ̀ Beti-Ofra mo yí ara mi nínú eruku.
11 Przejdziesz ty, która mieszkasz na miejscu pięknem, obnażoną mając hańbę; nie wnijdzie ta, która mieszka na miejscu w bydło obfitem; płacz będzie w miejscach okolicznych, które od was mają żywność swoję.
Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú, ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri. Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani kì yóò sì jáde wá. Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀; a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
12 Będzie bowiem bolesna dla dobrych rzeczy ta, która mieszka na miejscach przykrych, przeto, że zstąpi złe od Pana aż do bramy Jeruzalemskiej.
Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre, ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
13 Zaprzęż w wóz prędkie konie, obywatelko Lachys! któraś powodem grzechu córki Syońskiej, gdyż w tobie znalezione są przestępstwa Izraelskie.
Ìwọ olùgbé Lakiṣi, dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára. Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ sí àwọn ọmọbìnrin Sioni, nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
14 Przetoż poślę upominki swe do Moreset w Giet; domy Achzyb na oszukanie będą królom Izraelskim.
Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún Moreṣeti Gati. Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
15 Jeszczeć dziedzice przywiodę, o obywatelko Maresy! przyjdzie aż do Odollam, i aż do chwały Izraelskiej.
Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa. Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli yóò sì wá sí Adullamu.
16 Obłyś się i ostrzyż się dla synów rozkoszy twoich; rozszerz łysinę twoję jako orzeł, bo się prowadzą od ciebie.
Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára, sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún, nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

< Micheasza 1 >