< Księga Sędziów 16 >

1 Potem szedł Samson do Gazy, a ujrzawszy tam niewiastę nierządną, wszedł do niej.
Ní ọjọ́ kan Samsoni lọ sí Gasa níbi tí ó ti rí obìnrin panṣágà kan. Ó wọlé tọ̀ ọ́ láti sun ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òru ọjọ́ náà.
2 I powiedziano mieszczanom w Gazie: Przyszedł tu Samson; którzy obstąpiwszy go, strzegli nań całą noc w bramie miejskiej, a sprawując się cicho przez onę całą noc, mówili: Gdy się pocznie rozedniwać, zabijemy go.
Àwọn ará Gasa sì gbọ́ wí pé, “Samsoni wà níbí.” Wọ́n sì yí agbègbè náà ká, wọ́n ń ṣọ́ ọ ní gbogbo òru náà ní ẹnu-bodè ìlú náà. Wọn kò mira ní gbogbo òru náà pé ní “àfẹ̀mọ́júmọ́ àwa yóò pa á.”
3 Ale Samson spał aż do północy, a wstawszy o północy, ujął wrota bramy miejskiej ze dwiema podwojami, i wyrwał je z zaworą, i włożył na ramiona swoje, a zaniósł je na wierzch góry, która była przeciw Hebronowi.
Ṣùgbọ́n Samsoni sùn níbẹ̀ di àárín ọ̀gànjọ́. Òun sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó fi ọwọ́ di àwọn ìlẹ̀kùn odi ìlú náà mú, pẹ̀lú òpó méjèèjì, ó sì fà wọ́n tu, pẹ̀lú ìdábùú àti ohun gbogbo tí ó wà lára rẹ̀. Ó gbé wọn lé èjìká rẹ̀ òun sì gbé wọn lọ sí orí òkè tí ó kọjú sí Hebroni.
4 I stało się potem, że się rozmiłował niewiasty w dolinie Sorek, której imię Dalila.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ó sì ní ìfẹ́ obìnrin kan ní àfonífojì Soreki, orúkọ ẹni tí í ṣe Dẹlila.
5 I przyszli do niej książęta Filistyńskie, i mówili jej: Oszukaj go, a wywiedz się, w czem jest moc jego wielka, a jako byśmy go przemóc i związawszy utrapić mogli? a dać każdy z nas tysiąc i sto srebrników.
Àwọn ìjòyè Filistini sì lọ bá obìnrin náà, wọ́n sọ fún un wí pé, “Bí ìwọ bá le tàn án kí òun sì fi àṣírí agbára rẹ̀ hàn ọ́, àti bí àwa ó ti lè borí rẹ̀, kí àwa sì dè é kí àwa sì ṣẹ́gun rẹ̀. Ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú wa yóò sì fún ọ ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà fàdákà.”
6 Tedy rzekła Dalila do Samsona: Powiedz mi proszę, w czem jest moc twoja wielka, a czem byś związany i utrapiony być mógł?
Torí náà Dẹlila sọ fún Samsoni pé, “Sọ àṣírí agbára ńlá rẹ fún mi àti bí wọ́n ti le dè ọ́, àti bí wọ́n ṣe lè borí rẹ.”
7 I odpowiedział jej Samson: Jeźliby mię związano siedmią wici surowych, które jeszcze nie uschły, tedy osłabieję, i będę jako inny człowiek.
Samsoni dá a lóhùn wí pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fi okùn tútù méje tí ẹnìkan kò sá gbẹ dè mí, èmi yóò di aláìlágbára bí i gbogbo àwọn ọkùnrin yòókù.”
8 I przyniosły jej książęta Filistyńskie siedem wici surowych, które jeszcze nie były uschły, i związała go niemi.
Àwọn olóyè Filistini sì mú okùn tútù méje tí ẹnikẹ́ni kò sá gbẹ wá fún Dẹlila òun sì fi wọ́n dè é.
9 A oni się byli nań zasadzili w komorze, i rzekła mu: Filistynowie nad tobą, Samsonie; ale on zerwał wici, jakoby kto zerwał nić zgrzebną, ogniem napaloną; i nie poznano, w czem była moc jego.
Nígbà tí àwọn ènìyàn tí sá pamọ́ sínú yàrá, òun pè pé, “Samsoni àwọn Filistini ti dé láti mú ọ.” Ṣùgbọ́n òun já àwọn okùn náà bí òwú ti í já nígbà tí ó bá wà lẹ́bàá iná. Torí náà wọn kò mọ àṣírí agbára rẹ̀.
10 Rzekła potem Dalila do Samsona: Otoś mię oszukał, i skłamałeś przede mną; teraz powiedz mi proszę, czem by cię związać?
Dẹlila sì sọ fún Samsoni pé, ìwọ ti tàn mí; o sì purọ́ fún mi. Wá báyìí kí o sì sọ bí a ti ṣe le dè ọ́.
11 A on jej odpowiedział: Jeźliby mię związano powrozami nowemi, których jeszcze nie używano, tedy osłabieję, i będę jako inny człowiek.
Òun dáhùn pé, “Bí wọ́n bá lè fi okùn tuntun tí ẹnikẹ́ni kò tí ì lò rí dì mí dáradára, èmi yóò di aláìlágbára, èmi yóò sì dàbí àwọn ọkùnrin yòókù.”
12 A tak wzięła Dalila powrozy nowe, i związała go niemi, i rzekła do niego: Filistynowie nad tobą, Samsonie; (a oni się byli nań zasadzili w komorze, ) ale porwał je na ramionach swych jako nici.
Dẹlila sì mú àwọn okùn tuntun, ó fi wọ́n dì í. Nígbà tí àwọn ọkùnrin Filistini ti fi ara pamọ́ sínú yàrá, òun kígbe sí i pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ,” òun sì já okùn náà kúrò ní ọwọ́ rẹ̀ bí òwú.
13 Rzekła zatem Dalila do Samsona: Pókiż ze mnie szydzić będziesz, i kłamać przede mną? powiedzże mi, czem byś mógł być związany? I powiedział jej? Gdybyś przywiła siedem kędzierzy głowy mojej do wału tkackiego.
Dẹlila sì tún sọ fún Samsoni pé, “Títí di ìsinsin yìí ìwọ sì ń tún tàn mí, o sì tún purọ́ fún mi. Sọ fún mi ọ̀nà tí wọ́n fi le dè ọ́.” Samsoni dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ bá hun ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí mi pẹ̀lú okùn, tí ó sì le dáradára kí o sì fi ẹ̀mú mú un mọ́lẹ̀, èmi yóò di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.” Nígbà tí òun ti sùn, Dẹlila hun àwọn ìdí irun méjèèje tí ó wà ní orí rẹ̀,
14 Ona tedy przybiwszy gwoździem do wału tkackiego rzekła do niego: Filistynowie nad tobą, Samsonie; ale on ocuciwszy się ze snu swego, wyrwał gwóźdź z osnową i z wałem.
ó sì fi ìhunṣọ dè wọ́n. Ó sì tún pè é pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun sì jí ní ojú oorun, ó sì fa ìdè ìhunṣọ náà tu pẹ̀lú ohun gbogbo tí wọ́n fi kàn án mọ́lẹ̀.
15 Znowu rzekła do niego: Jakoż mówisz, miłuję cię? a serce twoje nie jest ze mną. Jużeś mię po trzy kroć oszukał, i nie powiedziałeś mi, w czem jest twoja moc wielka.
Dẹlila sì sọ fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi wí pé, ‘Èmi fẹ́ràn rẹ,’ nígbà tí ìwọ kò fi ọkàn tán mi. Èyí ni ìgbà kẹta tí ìwọ ti tàn mí jẹ, tí ìwọ kò sì sọ àṣírí ibi tí agbára ńlá rẹ gbé wà fún mi.”
16 A gdy mu się uprzykrzała słowy swemi na każdy dzień, i trapiła go, aż zemdlała dusza jego na śmierć,
Ó sì ṣe nígbà tí ó fi ọ̀rọ̀ rẹ̀ rọ̀ ọ́ ní ojoojúmọ́ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ rẹ̀ títí dé bi pé ó sú dé òpin ẹ̀mí rẹ̀.
17 Tedy jej otworzył cale serce swoje, i powiedział jej: Brzytwa nigdy nie postała na głowie mojej, gdyżem jest Nazarejczykiem Bożym zaraz z żywota matki mojej; gdyby mię ogolono, odejdzie ode mnie moc moja, i osłabieję, i będę jako inny człowiek.
Òun sì sọ ohun gbogbo tí ó wà ní ọkàn rẹ̀ fún un. Ó ní, “Abẹ kò tí ì kan orí mi rí, nítorí pé Nasiri, ẹni ìyàsọ́tọ̀ fún Ọlọ́run ni mo jẹ́ láti ìgbà ìbí mi wá. Bí a bá fá irun orí mi, agbára mi yóò fi mí sílẹ̀, èmi yóò sì di aláìlágbára bí àwọn ọkùnrin yòókù.”
18 Widząc tedy Dalila, że jej otworzył cale serce swoje, posłała i wezwała książąt Filistyńskich, mówiąc: Pójdźcież jeszcze raz, boć mi otworzył cale serce swoje; i przyszły do niej książęta Filistyńskie, niosąc srebro w rękach swych.
Nígbà tí Dẹlila rí i pé ó ti sọ ohun gbogbo fún òun tan, Dẹlila ránṣẹ́ sí àwọn ìjòyè Filistini pé, “Ẹ wá lẹ́ẹ̀kan sí i, ó ti sọ ohun gbogbo fún mi.” Torí náà àwọn olóyè Filistini padà, wọ́n sì mú owó ìpinnu náà lọ́wọ́.
19 Tedy go uśpiła na łonie swojem, a przyzwawszy niektórego człowieka, dała ogolić siedem kędzierzy głowy jego; potem go jęła draźnić, gdy odeszła moc jego od niego,
Òun sì mú kí Samsoni sùn lórí itan rẹ̀, òun sì pe ọkùnrin kan láti fá àwọn ìdì irun orí rẹ̀ méjèèje, òun sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣẹ́gun rẹ̀. Agbára rẹ̀ sì fi í sílẹ̀ lọ.
20 I rzekła: Filistynowie nad tobą, Samsonie. A ocuciwszy się ze snu swego, rzekł: Wynijdę jako i pierwej, a wybiję się; a nie wiedział, że Pan odstąpił od niego.
Òun pè é wí pé, “Samsoni àwọn Filistini dé láti mú ọ.” Òun jí ní ojú oorun rẹ̀, ó sì sọ pé, “Èmi yóò jáde lọ bí í ti àtẹ̀yìnwá, kí èmi sì gba ara mi, kí n di òmìnira.” Ṣùgbọ́n òun kò mọ̀ pé Olúwa ti fi òun sílẹ̀.
21 Tedy pojmawszy go Filistynowie, wyłupili mu oczy, i wiedli go do Gazy, związawszy go dwoma miedzianymi łańcuchami, i musiał mleć w domu więźniów.
Nígbà náà ni àwọn Filistini mú un, wọ́n yọ ojú rẹ̀ méjèèjì wọ́n sì mú un lọ sí Gasa. Wọ́n fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ idẹ dè é, wọ́n sì fi sí ibi iṣẹ́ ọlọ lílọ̀ nínú ilé túbú.
22 Potem poczęły włosy na głowie jego odrastać po onem goleniu.
Ṣùgbọ́n irun orí rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í tún hù lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti fá a.
23 A książęta Filistyńskie zebrali się sprawować ofiary wielkie Dagonowi, bogu swemu, weselili się, i mówili: Podał bóg nasz w ręce nasze Samsona, nieprzyjaciela naszego.
Àwọn ìjòyè, àwọn ará Filistini sì péjọpọ̀ láti ṣe ìrúbọ ńlá sí Dagoni ọlọ́run wọn àti láti ṣe ayẹyẹ wọ́n wí pé, ọlọ́run wa ti fi Samsoni ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́.
24 Którego też ujrzawszy lud chwalili boga swego, bo mówili: Podał bóg nasz w ręce nasze nieprzyjaciela naszego, a tego, który pustoszył ziemię naszę, i który wiele z naszych pozabijał.
Nígbà tí àwọn ènìyàn rí Samsoni wọ́n yin ọlọ́run wọn wí pé, “Ọlọ́run wa ti fi ọ̀tá wa lé wa lọ́wọ́. Àní ẹni tí ó ti run ilẹ̀ wa ẹni tí ó ti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wa.”
25 I stało się, gdy byli dobrej myśli, że rzekli: Zawołajcie Samsona, aby błaznował przed nami. A tak zawołano Samsona z domu więźniów, aby błaznował przed nimi; i postawili go między dwoma słupami.
Nígbà tí inú wọn dùn gidigidi tí wọ́n ń yọ ayọ̀ ńlá, wọ́n pariwo pé, ẹ mú Samsoni wá kí ó wá dá wa lára yá. Wọ́n sì pe Samsoni jáde láti ọgbà ẹ̀wọ̀n náà, òun sì ń ṣeré fún wọn. Nígbà tí wọ́n mú un dúró láàrín àwọn òpó.
26 Zatem rzekł Samson do chłopca, który go trzymał za rękę jego. Przywiedź mię, abym pomacał słupów, na których dom stoi, i podparł się na nich.
Samsoni sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí ó di ọwọ́ rẹ̀ mú pé, “Ẹ fi mí si ibi tí ọwọ́ mi yóò ti le tó àwọn òpó tí ó gbé tẹmpili dúró mú, kí èmi lè fẹ̀yìn tì wọ́n.”
27 A dom pełen był mężów i niewiast; tamże były wszystkie książęta Filistyńskie, a na dachu około trzech tysięcy mężów i niewiast, którzy się przypatrowali, gdy błaznował Samson.
Ní àsìkò náà, tẹmpili yìí kún fún àwọn ọkùnrin àti obìnrin; gbogbo àwọn ìjòyè Filistini wà níbẹ̀, ní òkè ilé náà, níbi tí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àwọn ọkùnrin àti obìnrin tí ń wòran Samsoni bí òun ti ń ṣeré.
28 Wzywał tedy Samson Pana, i rzekł: Panie Boże, wspomnij na mię, proszę, a zmocnij mię proszę tylko ten raz; Boże, abym się raz pomścił obu oczu moich nad Filistynami.
Nígbà náà ni Samsoni ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, rántí mi. Háà Ọlọ́run jọ̀wọ́ fi agbára fún mi lẹ́ẹ̀kan yìí sí i, kí èmi lè gbẹ̀san lára àwọn Filistini nítorí àwọn ojú mi méjèèjì.”
29 A ująwszy Samson oba słupy pośrednie, na których dom stał, wsparł się o nie, o jeden prawą ręką swoją a o drugi lewą ręką swoją.
Samsoni sì na ọwọ́ mú àwọn òpó méjèèjì tí ó wà láàrín gbùngbùn, orí àwọn tí tẹmpili náà dúró lé, ó fi ọwọ́ ọ̀tún mú ọ̀kan àti ọwọ́ òsì mú èkejì, ó fi ara tì wọ́n,
30 Zatem rzekł Samson: Niech umrze dusza moja z Filistynami; a gdy się o nie mocno oparł, upadł dom na książęta, i na wszystek lud, który w nim był, i było umarłych, które on pobił umierając, więcej niż onych, które pobił za żywota swego.
Samsoni sì wí pé, “Jẹ́ kí èmi kú pẹ̀lú àwọn Filistini!” Òun sì fi agbára ńlá tì wọ́n, bẹ́ẹ̀ ni ilé náà wó lu àwọn ìjòyè àti gbogbo àwọn tí ó wà nínú rẹ̀. Báyìí ni ó pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nígbà ikú rẹ̀ ju ìgbà ayé rẹ̀ lọ.
31 A przyszedłszy bracia jego, i wszystek dom ojca jego, wzięli go, a wróciwszy się pogrzebli go między Saraa, i między Estaol, w grobie Manue, ojca jego. A on sądził Izraela przez dwadzieścia lat.
Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ ní àpapọ̀ gòkè lọ wọ́n sì gbé e, wọ́n gbé e padà wá, wọ́n sì sin ín sí agbede-méjì Sora àti Eṣtaoli, sínú ibojì Manoa baba rẹ̀. Òun ti ṣe àkóso Israẹli ní ogún ọdún.

< Księga Sędziów 16 >