< Księga Sędziów 17 >

1 A był niektóry mąż z góry Efraim, imieniem Michas.
Nígbà náà ni ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika láti agbègbè òkè Efraimu
2 Ten rzekł do matki swojej: Tysiąc i sto srebrników, któreć było ukradziono, o któreś przeklinała, i mówiłaś, gdym i ja słyszał, oto srebro to u mnie jest, jam je wziął. I rzekł matka jego: Błogosławionyś, synu mój, od Pana.
sọ fún ìyá rẹ̀ pé, “Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà èyí tí wọ́n jí mọ́ ọ lọ́wọ́, àti nípa èyí tí mo gbọ́ tí ìwọ ń ṣẹ́ èpè. Kíyèsi fàdákà náà wà ní ọ̀dọ̀ mi, èmi ni mo kó o.” Nígbà náà ni ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Kí Olúwa bùkún ọ ọmọ mi!”
3 A tak wrócił tysiąc i sto srebrników matce swojej; i rzekła matka jego: Zaiste poświęciłam to srebro Panu z ręki mojej dla ciebie, synu mój, aby uczyniono z niego ryty i lany obraz, przetoż teraz oddawam ci je.
Nígbà tí ó da ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀fà ṣékélì fàdákà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Èmi ti fi òtítọ́ inú ya sílífà náà sọ́tọ̀ sí Olúwa fún ọmọ mi láti fi dá ère dídá àti ère gbígbẹ́. Èmi yóò dá a padà fún ọ.”
4 I wrócił ono srebro matce swojej. Tedy wziąwszy matka jego dwieście srebrników, dała je złotnikowi; i uczynił z nich obraz ryty i lany, który był w domu Michasowym.
Nítorí náà òun dá sílífà náà padà fún ìyá rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì mú igba ṣékélì fàdákà, ó sì fún alágbẹ̀dẹ fàdákà ẹni tí ó fi wọ́n rọ ère fínfín àti ère dídà. Wọ́n sì kó wọn sí ilé Mika.
5 A miał ten Michas kaplicę bogów, sprawił też był Efod i Terafim, a poświęcił ręce jednego z synów swych, aby mu był za kapłana.
Ọkùnrin náà, Mika sì ní ojúbọ kan. Òun sì ra ẹ̀wù efodu kan, ó sì ṣe àwọn ère kan, ó sì fi ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin ṣe àlùfáà rẹ̀.
6 W one dni nie było króla w Izraelu; każdy, co był dobrego w oczach jego, czynił.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọmọ Israẹli kò ní ọba; olúkúlùkù ṣe bí ó ti rò pé ó tọ́ ní ojú ara rẹ́.
7 I był młodzieniec z Betlehem Juda, które było w pokoleniu Juda, a ten będąc Lewitą był tam przychodniem.
Ọ̀dọ́mọkùnrin kan sì ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda wá, tí í ṣe ìdílé Juda, ẹni tí í ṣe ẹ̀yà Lefi, òun sì ṣe àtìpó níbẹ̀,
8 Wyszedł tedy on mąż z miasta Betlehem Juda, aby mieszkał, gdzieby mu się trafiło; i przyszedł na górę Efraim aż do domu Michasowego, idąc drogą swoją.
ọkùnrin náà sì ti ìlú Bẹtilẹhẹmu ti Juda lọ, láti ṣe àtìpó ní ibikíbi tí ó bá rí. Ní ojú ọ̀nà àjò rẹ̀, ó dé ilẹ̀ Mika nínú àwọn ilẹ̀ òkè Efraimu.
9 Tedy rzekł do niego Michas: Skąd idziesz? I odpowiedział mu: Jam jest Lewita z Betlehem Juda, a idę, abym mieszkał gdzieby mi się trafiło.
Mika bi í pé, “Níbo ni ó ti ń bọ̀?” Ó dáhùn pé, “Ọmọ Lefi ni mí láti Bẹtilẹhẹmu Juda, mo sì ń wá ibi tí èmi yóò máa gbé.”
10 I rzekł mu Michas: Zostań u mnie, a bądź mi za ojca i za kapłana, a jać dam dziesięć srebrników do roku, i dwie szaty, i pożywienie twoje; i szedł za nim on Lewita.
Mika sì sọ fún un wí pé, “Dúró lọ́dọ̀ mi kí ìwọ sì jẹ́ baba mi àti àlùfáà fún mi, èmi ó sì máa fún ọ ní ṣékélì mẹ́wàá fàdákà ní ọdọọdún, pẹ̀lú aṣọ àti oúnjẹ rẹ̀.”
11 I upodobało się Lewicie mieszkać z mężem onym; a był przy nim on młodzieniec jako jeden z synów jego.
Ọmọ Lefi náà sì gbà láti máa bá a gbé, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì dàbí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
12 I poświęcił Michas ręce Lewity, i był mu on młodzieniec za kapłana, i mieszkał w domu Michasowym.
Nígbà náà ni Mika ya ará Lefi náà sí mímọ́, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì di àlùfáà rẹ̀, ó sì ń gbé ilé rẹ̀.
13 Tedy rzekł Michas: Teraz wiem, że mi będzie Pan błogosławił, gdyż mam Lewitę za kapłana.
Mika sì wí pé, “Báyìí, èmi mọ̀ pé Olúwa yóò ṣe mi ní oore nítorí pé mo ní ọmọ Lefi ní àlùfáà mi.”

< Księga Sędziów 17 >