< Hioba 38 >

1 Tedy odpowiedział Pan Ijobowi z wichru, i rzekł:
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àjàyíká wá, ó sì wí pé,
2 Któż to jest, co zaciemnia radę Bożą mowami nieroztropnemi?
“Ta ni èyí tí ń fi ọ̀rọ̀ àìlóye láti fi ṣókùnkùn bo ìmọ̀ mi?
3 Przepasz teraz jako mąż biodra swoje, a będę cię pytał, a ty mi daj sprawę.
Di ẹ̀gbẹ́ ara rẹ ní àmùrè bí ọkùnrin nísinsin yìí, nítorí pé èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ kí o sì dá mi lóhùn.
4 Gdzieżeś był, kiedym Ja zakładał grunty ziemi? Powiedz, jeźliże nasz rozum.
“Níbo ni ìwọ wà nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀? Wí bí ìwọ bá mòye.
5 Któż uczynił rozmierzenie jej? powiedz, jeżli wiesz; albo kto sznur nad nią rozciągnął?
Ta ni ó fi ìwọ̀n rẹ lélẹ̀, dájú bí ìwọ bá mọ̀ ọ́n? Tàbí ta ni ó ta okùn wíwọ̀n sórí rẹ?
6 Na czem są podstawki jej ugruntowane? albo kto założył kamień jej węgielny?
Lórí ibo ni a gbé kan ìpìlẹ̀ rẹ̀ mọ́, tàbí ta ni ó fi òkúta igun rẹ̀ lélẹ̀,
7 Gdy wespół śpiewały gwiazdy zaranne, a weselili się wszyscy synowie Boży.
nígbà náà àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ jùmọ̀ kọrin pọ̀, tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọ́run hó ìhó ayọ̀?
8 Któż zamknął drzwiami morze, gdy się wyrywało, jakoby z żywota wychodząc?
“Tàbí ta ni ó fi ìlẹ̀kùn sé omi òkun mọ́, nígbà tí ó ya padà bí ẹni pé ó ti inú jáde wá.
9 Gdym położył obłok za szatę jego, a ciemność za pieluchy jego;
Nígbà tí mo fi àwọsánmọ̀ ṣe aṣọ rẹ̀, tí mo sì fi òkùnkùn biribiri ṣe ọ̀já ìgbà inú rẹ̀.
10 Gdym postanowił o niem dekret mój, a przyprawiłem zaworę i drzwi do niego,
Nígbà tí mo ti pàṣẹ ìpinnu mi fún un, tí mo sì ṣe bèbè àti ìlẹ̀kùn.
11 I rzekłem: Aż dotąd wychodzić będziesz, a dalej nie postąpisz, a tu położysz nadęte wały twoje.
Tí mo sì wí pé níhìn-ín ni ìwọ ó dé, kí o má sì rékọjá, níhìn-ín sì ni ìgbéraga rẹ yóò gbé dúró mọ?
12 Izażeś za dni twoich rozkazywał świtaniu, i ukazałeś zorzy miejsce jej?
“Ìwọ pàṣẹ fún òwúrọ̀ láti ìgbà ọjọ́ rẹ̀ wá, ìwọ sì mú ìlà-oòrùn mọ ipò rẹ̀,
13 Aby ogarnęła kończyny ziemi, a iżby byli z niej wyrzuceni niepobożni.
í ó lè di òpin ilẹ̀ ayé mú, ki a lè gbọ́n àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú rẹ̀?
14 Aby się odmieniała jako glina, do której pieczęć przykładają, a oni aby się stali jako szatą nakryci.
Kí ó yí padà bí amọ̀ fún èdìdì amọ̀, kí gbogbo rẹ̀ kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni pé nínú aṣọ ìgúnwà.
15 I aby była zawściągniona od niepobożnych światłość ich, a ramię wysokie było pokruszone.
A sì fa ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn búburú, apá gíga ni a sì ṣẹ́.
16 Izażeś przyszedł aż do źródeł morskich, a po dnie przepaści przechodziłeś się?
“Ìwọ ha wọ inú ìsun òkun lọ rí bí? Ìwọ sì rìn lórí ìsàlẹ̀ ibú ńlá?
17 Azaż odkryte są tobie bramy śmierci? bramy cienia śmierci widziałżeś?
A ha ṣílẹ̀kùn ikú sílẹ̀ fún ọ rí bí, ìwọ sì rí ìlẹ̀kùn òjìji òkú?
18 Izaliś rozumem twym doszedł szerokości ziemi? Powiedz mi, jeźli to wszystko wiesz?
Ìwọ mòye ìbú ayé bí? Sọ bí ìwọ bá mọ gbogbo èyí.
19 Gdzież jest ta droga do miejsca światłości? a ciemności gdzie mają miejsce swoje?
“Ọ̀nà wo ni ìmọ́lẹ̀ ń gbé? Bí ó ṣe ti òkùnkùn, níbo ni ipò rẹ̀,
20 Abyś ją ująwszy odprowadził do granicy jej, ponieważ zrozumiewasz ścieszki do domu jej.
tí ìwọ í fi mú un lọ sí ibi àlá rẹ̀, tí ìwọ ó sì le mọ ipa ọ̀nà lọ sínú ilé rẹ̀?
21 Wiedziałżeś na on czas, żeś się miał urodzić? i liczba dni twoich jak wielka być miała?
Ìwọ mọ èyí, nítorí nígbà náà ni a bí ọ? Iye ọjọ́ rẹ sì pọ̀.
22 Izaliś przyszedł do skarbów śniegów? aby skarby gradu widzałeśli?
“Ìwọ ha wọ inú ìṣúra ìdì òjò lọ rí bí, ìwọ sì rí ilé ìṣúra yìnyín rí,
23 Które zatrzymywam na czas ucisku, na dzień bitwy i wojny.
tí mo ti fi pamọ́ de ìgbà ìyọnu, dé ọjọ́ ogun àti ìjà?
24 Którąż się drogą dzieli światłość, i gdzie się rozchodzi wiatr wschodni po ziemi?
Ọ̀nà wo ni ó lọ sí ibi tí ìmọ́lẹ̀ fi ń la, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ń tàn káàkiri lórí ilẹ̀ ayé?
25 Któż rozdzielił stok powodziom? a drogę błyskawicy gromów?
Ta ni ó la ipadò fún ẹ̀kún omi, àti ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
26 Aby szedł deszcz na ziemię, w której nikt nie mieszka, i na pustynię, gdzie niemasz człowieka;
láti mú u rọ̀jò sórí ayé níbi tí ènìyàn kò sí, ní aginjù níbi tí ènìyàn kò sí;
27 Aby nasycił miejsce puste i niepłodne, a wywiódł z niego zieloną trawę.
láti mú ilẹ̀ tútù, ijù àti aláìro láti mú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ewéko rú jáde?
28 Izali ma deszcz ojca? a krople rosy kto płodzi?
Òjò ha ní baba bí? Tàbí ta ni o bí ìkún ìṣe ìrì?
29 Z czyjegoż żywota wychodzi mróz? a szron niebieski któż płodzi?
Láti inú ta ni ìdì omi ti jáde wá? Ta ni ó bí ìrì dídì ọ̀run?
30 Jakoż się kamieniem wody nakrywają, gdy wierzch przepaści zamarza.
Nígbà tí omi di líle bí òkúta, nígbà tí ojú ibú ńlá sì dìpọ̀.
31 Możeszże związać jasne gwiazdy Bab? albo związek Oryjona rozerwać?
“Ìwọ ha le fi ọ̀já de àwọn ìràwọ̀ Pleiadesi dáradára? Tàbí ìwọ le tún di ìràwọ̀ Orioni?
32 Izali wywiedziesz gwiazdy południowe czasu swego, albo Wóz niebieski z gwiazdami jego powiedziesz?
Ìwọ le mú àwọn àmì méjìlá ìràwọ̀ Masaroti jáde wá nígbà àkókò wọn? Tàbí ìwọ le ṣe amọ̀nà Beari pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀?
33 I znaszże porządek nieba? a możeszże rozrządzić panowanie jego na ziemi?
Ǹjẹ́ ìwọ mọ ìlànà ọ̀run? Ìwọ le fi ìjọba Ọlọ́run lélẹ̀ lórí ayé?
34 Izali podniesiesz ku obłokowi głos twój, aby cię wielkość wód okryła?
“Ìwọ le gbé ohùn rẹ sókè dé àwọsánmọ̀ kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kí ó lè bò ọ́?
35 Izali możesz wypuścić błyskawice, aby przyszły, i rzekłyć: Otośmy?
Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kí ó le lọ, ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Àwa nìyí’?
36 Któż złożył we wnętrznościach ludzkich mądrość, a kto dał rozumowi bystrość?
Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí odò ikùn tàbí tí ó fi òye sínú àyà?
37 Któż obrachował niebiosa mądrością swoją? a co się leje z nieba, któż uspokoi?
Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọsánmọ̀? Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,
38 Aby polany proch stężał, a bryły aby się społu zelgnęły?
nígbà tí erùpẹ̀ di líle, àti ògúlùtu dìpọ̀?
39 Izali lwowi łup łowisz, a lwiąt żywot napełniasz?
“Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí? Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọrọ kìnnìún lọ́rùn,
40 Gdy się tulą w jaskiniach swoich, i czyhają w cieniu jam swoich?
nígbà tí wọ́n bá mọ́lẹ̀ nínú ihò tí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?
41 Któż gotuje krukowi pokarm jego, gdy dzieci jego do Boga wołają a tułają się, nie mając pokarmu?
Ta ni ó ń pèsè ohun jíjẹ fún ẹyẹ ìwò, nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ń ké pe Ọlọ́run, tí wọ́n sì máa ń fò kiri nítorí àìní ohun jíjẹ?

< Hioba 38 >