< Hioba 37 >

1 A nad tem zdumiewa się serce moje, i porusza się z miejsca swego.
“Àyà sì fò mi sí èyí pẹ̀lú, ó sì kúrò ní ipò rẹ̀.
2 Słuchajcie z pilnością grzmienia głosu jego, i dźwięku który wychodzi z ust jego.
Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀, kí ẹ sì gbọ́ ìró ohùn rẹ̀, àti èyí tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde wá.
3 Pod wszystkiem niebem prosto go wypuszcza, a światłość jego po wszystkich kończynach ziemi.
Ó ṣe ìlànà rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ọ̀run gbogbo, mọ̀nàmọ́ná rẹ̀ ni ó sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́ dé òpin ilẹ̀ ayé.
4 Za nią wnet huczy dźwiękiem, grzmi głosem zacności swojej, i nie odkłada innych rzeczy, gdy bywa słyszany głos jego.
Lẹ́yìn mọ̀nàmọ́ná ohùn kan fọ̀ ramúramù; ó sì fi ohùn ọláńlá rẹ̀ sán àrá. Òhun kì yóò sì dá àrá dúró, nígbà tí ó bá ń gbọ́ ohùn rẹ̀.
5 Dziwnie Bóg grzmi głosem swoim; sprawuje rzeczy tak wielkie, że ich rozumieć nie możemy.
Ọlọ́run fi ohùn rẹ̀ sán àrá ní ọ̀nà ìyanu; ohùn ńlá ńlá ni í ṣe tí àwa kò le mọ̀.
6 Bo mówi do śniegu: Padaj na ziemię; także i do deszczu wolnego, i do deszczu gwałtownego.
Nítorí tí ó wí fún yìnyín pé, ‘Ìwọ rọ̀ sílẹ̀ ayé,’ àti pẹ̀lú fún ọwọ́ òjò, ‘Fún òjò ńlá agbára rẹ̀.’
7 Rękę wszystkich ludzi zawiera, aby nikt z ludzi nie doglądał roboty swojej.
Ó fi èdìdì di ọwọ́ gbogbo ènìyàn kí gbogbo wọn kí ó lè mọ iṣẹ́ rẹ̀, ó sì tún dá olúkúlùkù ènìyàn dúró lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀.
8 Tedy zwierz wchodzi do jaskini, a w jamach swoich zostaje.
Nígbà náà ní àwọn ẹranko wọ inú ihò lọ, wọn a sì wà ni ipò wọn.
9 Wicher z skrytych miejsc wychodzi, a zima z wiatrów północnych.
Láti ìhà gúúsù ni ìjì àjàyíká tí jáde wá, àti òtútù láti inú afẹ́fẹ́ ti tú àwọsánmọ̀ ká.
10 Tchnieniem swojem Bóg czyni lód, tak iż się szerokość wód ściska.
Nípa ẹ̀mí Ọlọ́run a fi ìdí omi fún ni, ibú omi á sì súnkì.
11 Także dla pokropienia ziemi obciąża obłok, i rozpędza chmurę światłem swojem.
Pẹ̀lúpẹ̀lú ó fi omi púpọ̀ mú àwọsánmọ̀ wúwo, a sì tú àwọsánmọ̀ ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ká ara wọn.
12 A ten się obraca w koło według rady jego, aby czynił wszystko, co Bóg rozkaże, na oblicze okręgu ziemskiego.
Àwọn wọ̀nyí yí káàkiri nípa ìlànà rẹ̀, kí wọn kí ó lè ṣe ohunkóhun tí ó pàṣẹ fún wọn lórí ilẹ̀ ayé.
13 A czyni to Bóg, że się stawia bądź na skaranie, bądź dla pożytku ziemi swojej, bądź dla jakiej dobroczynności.
Ó mú àwọsánmọ̀ wá, ìbá ṣe fún ìkìlọ̀, tàbí omi wá sí ayé láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.
14 Słuchajże tego pilnie, Ijobie! zastanów się, a uważaj dziwne sprawy Boże.
“Jobu, dẹtí sílẹ̀ sí èyí; dúró jẹ́ẹ́ kí o sì ro iṣẹ́ ìyanu Ọlọ́run.
15 Izali wiesz, kiedy co Bóg stanowi o tych rzeczach? albo gdy ma rozjaśnić światło obłoku swego?
Ṣe ìwọ mọ àkókò ìgbà tí Ọlọ́run ṣe wọ́n lọ́jọ̀, tí ó sì mú ìmọ́lẹ̀ àwọsánmọ̀ rẹ̀ dán?
16 Izali wiesz, co za waga obłoków? Izali wiesz cuda Doskonałego we wszelakiej umiejętności?
Ṣé ìwọ mọ ìgbà tí àwọsánmọ̀ í fò lọ, iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀?
17 Wieszże, jako cię szaty twoje ogrzewają, gdy ucisza ziemię od południa?
Ìwọ ẹni ti aṣọ rẹ̀ ti máa n gbóná, nígbà tí ó fi atẹ́gùn ìhà gúúsù mú ayé dákẹ́.
18 Izażeś z nim rozpościerał niebiosa, które są trwałe, a zwierciadłu odlewanemu podobne?
Ìwọ ha ba tẹ́ pẹpẹ ojú ọ̀run, tí ó dúró ṣinṣin, tí ó sì dàbí dígí tí ó yọ̀ dà?
19 Ukażże nam, co mu mamy powiedzieć; bo nie możemy sporządzić słów dla ciemności.
“Kọ́ wa ní èyí tí a lè wí fún un; nítorí pé àwa kò le wádìí ọ̀rọ̀ náà nítorí òkùnkùn wa.
20 Izali mu kto odniesie to, cobym mówił? I owszem, gdyby to kto przedłożył, byłby pewnie pożarty.
A ó ha wí fún un pé, èmi fẹ́ sọ̀rọ̀? Tàbí ẹnìkan lè wí pé, ìfẹ́ mi ni pé kí a gbé mi mì?
21 Wszak teraz nie mogą ludzie patrzyć i na światło, gdy jest jasne na obłokach, gdy wiatr przechodzi, i przeczyszcza je.
Síbẹ̀ nísinsin yìí ènìyàn kò rí oòrùn tí ń dán nínú àwọsánmọ̀, ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ń kọjá, a sì gbá wọn mọ́.
22 Od północy jako złoto przychodzi, ale w Bogu straszniejsza jest chwała.
Wúrà dídán ti inú ìhà àríwá jáde wá; lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ọláńlá ẹ̀rù ńlá wa.
23 Wszechmogący jest, doścignąć go nie możemy; wielki w mocy, wszakże sądem i ostrą sprawiedliwością ludzi nie trapi.
Nípa ti Olódùmarè àwa kò le wádìí rẹ̀, ó rékọjá ní ipá; nínú ìdájọ́ àti títí bi òun kì í ba ẹ̀tọ́ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òtítọ́ jẹ́.
24 Przetoż boją się go ludzie; nie ma względu na żadnego, by też był i najmędrszy.
Nítorí náà ènìyàn ha máa bẹ̀rù rẹ̀, òun kì í ṣe ojú sájú ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́n ní ayé?”

< Hioba 37 >