< Hioba 20 >

1 A odpowiadając Sofar Naamatczyk rzekł:
Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,
2 Do tego mię myśli moje przywodzą, abym odpowiedział; przetożem się pospieszył.
“Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn, àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
3 Słyszałem mnie hańbiącą naganę; ale duch wyrozumienia mego odpowie za mię.
Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.
4 Izaż nie wiesz, że to jest od wieku, od tego czasu, jako postawił Bóg człowieka na ziemi?
“Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
5 Iż chwała niepobożnych krótka jest, a wesele obłudnika na mgnienie oka?
pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
6 By też wstąpiła aż do nieba hardość jego, a obłoku się dotknęła głowa jego:
Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
7 A wszakże na wieki zginie jako gnój jego, a ci, którzy go widzieli, rzeką: Gdzież się podział?
ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
8 Uleci jako sen, a nie znajdą go; bo uciecze, jako widzenie nocne.
Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i, àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
9 Oko, które go widziało, nie ogląda go więcej, i nie ujrzy go więcej miejsce jego.
Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
10 Synowie jego będą się korzyć ubogim; bo ręce jego muszą wracać, co wydarł.
Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
11 Kości jego napełnione są grzechami młodości jego, a w prochu z nim leżeć będą.
Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
12 A choć złość słodnieje w ustach jego, i tai ją pod językiem swoim;
“Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
13 Kocha się w niej, a nie opuszcza jej, zatrzymywając ją w pośrodku podniebienia swego:
bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀, tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
14 Wszakże pokarm jego we wnętrznościach jego odmieni się; żółcią padalcową stanie się w trzewach jego.
ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà, ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
15 Bogactwa, które pożarł, zwróci, a z brzucha jego wyżenie je Bóg.
Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
16 Głowę padalcową ssać będzie; zabije go język jaszczurczy.
Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú; ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
17 Nie ogląda źródeł rzek, strumieni mówię miodu i masła.
Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
18 Wróci pracę cudzą, a nie zażyje jej; i choć znowu nabędzie wielkich majętności, nie ucieszy się niemi.
Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
19 Bo ubogich dręczył i opuszczał, złupił dom, którego nie budował; przetoż nic spokojnego nie poczuje w żywocie swoim,
Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n; nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
20 Ani rzeczy swych wdzięcznych nie będzie mógł zatrzymać.
“Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
21 Nic nie zostanie z pokarmów jego, ani się rozmnoży dobro jego.
Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀; nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
22 Choćby i nazbyt miał wszystkiego, ściśniony będzie; wszelka ręka trapiących oburzy się nań.
Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a; àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
23 Choć będzie miał czem napełnić brzuch swój, przecież nań Bóg puści popędliwość gniewu swego, którą jako deszcz spuści nań, i na pokarmy jego.
Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun, Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́, yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
24 Gdy uciekać będzie przed bronią żelazną, przebije go łuk hartowny.
Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
25 Wyjęta będzie strzała z sajdaku wypuszczona, a grot przeniknie żółć jego; a gdy uchodzić będzie, ogarną go strachy.
O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá. Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
26 Wszystkie nieszczęścia zasadziły się nań w tajemnych miejscach jego, a pożre go ogień nierozdymany: pozostały w przybytku jego utrapiony będzie.
òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀. Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
27 Odkryją niebiosa złość jego, a ziemia powstanie przeciwko niemu.
Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóò sì dìde dúró sí i.
28 Przeniesie się urodzaj domu jego; dobra jego rozpłyną się w dzień gniewu jego.
Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
29 Tenci jest dział człowieka niepobożnego od Boga, to dziedzictwo naznaczone mu od Boga.
Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”

< Hioba 20 >