< Hioba 22 >

1 A odpowiadając Elifas Temańczyk rzekł:
Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani, dáhùn wí pé,
2 Izali Bogu człowiek może być pożytecznym? raczej pożyteczny jest sam sobie, mądrze się sprawując.
“Ènìyàn lè è ṣe rere fún Ọlọ́run? Bí ọlọ́gbọ́n ti í ṣe rere fún ara rẹ̀?
3 Izali się kocha Wszechmogący w tem, że się ty usprawiedliwiasz? albo co za zysk ma, gdy doskonałe pokazujesz drogi twoje?
Ohun ayọ̀ ha ni fún Olódùmarè pé olódodo ni ìwọ? Tàbí èrè kí ni fún un ti ìwọ mú ọ̀nà rẹ̀ pé?
4 Aza cię będzie karał bojąc się ciebie? albo z tobą pójdzie do sądu?
“Yóò ha bá ọ wí bí, nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ? Yóò ha bá ọ lọ sínú ìdájọ́ bí?
5 Azaż złość twoja nie jest wielka, i niemasz końca nieprawościom twoim?
Ìwà búburú rẹ kò ha tóbi, àti ẹ̀ṣẹ̀ rẹ láìníye?
6 Albowiemeś pobierał zastaw od braci twoich bez przyczyny, a z szat odzierałeś nagich.
Nítòótọ́ ìwọ béèrè fún ààbò ni ọwọ́ arákùnrin rẹ láìnídìí, ìwọ sì tú oníhòhò ní aṣọ wọn.
7 Wodyś spracowanemu nie podał, a głodnemu odmówiłeś chleba.
Ìwọ kò fi omi fún aláàárẹ̀ mu, ìwọ sì háwọ́ oúnjẹ fún ẹni tí ebi ń pa.
8 Ale człowiekowi możnemu dałeś ziemię, a ten, który był w powadze, mieszkał w niej.
Bí ó ṣe ti alágbára nì, òun ni ó ní ilẹ̀, ọlọ́lá sì tẹ̀dó sínú rẹ̀.
9 Wdowy puszczałeś próżne, a sierót ramiona potarłeś.
Ìwọ ti rán àwọn opó padà lọ ní ọwọ́ òfo, apá àwọn ọmọ aláìní baba ti di ṣiṣẹ́.
10 A przetoż ogarnęły cię sidła, a trwoży cię strach nagły.
Nítorí náà ni ìdẹ̀kùn ṣe yí ọ káàkiri, àti ìbẹ̀rù òjijì ń yọ ọ́ lẹ́nu.
11 Albo cię ogarnęły ciemności, iż nie widzisz? a wielkości wód okryły cię.
Èéṣe tí òkùnkùn fi pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè ríran. Èéṣe tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.
12 Mówisz: Izali Bóg nie jest na wysokości niebios? Spojrzyj proszę na wierzch gwiazd, jako są wysokie.
“Ọlọ́run kò ha jẹ́ ẹni gíga ọ̀run? Sá wo orí àwọn ìràwọ̀ bí wọ́n ti ga tó!
13 Przetoż mówisz: A cóż wie Bóg? izaż przez chmury sądzić będzie?
Ìwọ sì wí pé, Ọlọ́run ti ṣe mọ̀? Òun ha lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn wá bí?
14 Obłoki są skrytością jego, iż nie widzi, a po okręgu niebieskim przechadza się.
Ǹjẹ́ àwọsánmọ̀ tí ó nípọn jẹ ìbora fún un, tí kò fi lè ríran; ó sì ń rìn nínú àyíká ọ̀run.
15 Izaż ścieszki wieku przeszłego nie baczysz, którą deptali ludzie złośliwi?
Ǹjẹ́ ìwọ fẹ́ rin ipa ọ̀nà ìgbàanì tí àwọn ènìyàn búburú tí rìn?
16 Którzy są wykorzenieni przed czasem, a powodzią zalały się grunty ich.
A ké wọn lulẹ̀ kúrò nínú ayé láìpé ọjọ́ wọn, ìpìlẹ̀ wọn ti da bí odò ṣíṣàn.
17 Którzy mawiali Bogu: Odejdź od nas; cóżby im uczynił Wszechmogący?
Àwọn ẹni tí ó wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa! Kí ni Olódùmarè yóò ṣe fún wọn?’
18 Gdyż on był napełnił dobrem domy ich; (ale rada niepobożnych daleka jest odemnie.)
Síbẹ̀ ó fi ohun rere kún ilé wọn! Ṣùgbọ́n ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi!
19 Co widząc sprawiedliwi, weselili się, a niewinny naśmiewał się z nich.
Àwọn olódodo rí ìparun wọn, wọ́n sì yọ̀, àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀ sì fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà pé,
20 Zwłaszcza, iż nie była wycięta majętność nasza, lecz ostatki ich ogień pożarł.
‘Lóòtítọ́ àwọn ọ̀tá wa ni a ké kúrò, iná yóò sì jó oró wọn run.’
21 Przyuczaj się, proszę, z nim przestawać, a uczyń sobie z nim pokój: boć się tak będzie szczęściło.
“Fa ara rẹ súnmọ́ Ọlọ́run, ìwọ ó sì rí àlàáfíà; nípa èyí ni rere yóò wá bá ọ.
22 Przyjmij, proszę, z ust jego zakon, a złóż wyroki jego w sercu twojem.
Èmi bẹ̀ ọ́, gba òfin láti ẹnu rẹ̀ wá, kí o sì to ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí àyà rẹ.
23 Jeźli się nawrócisz do Wszechmocnego, zbudowany będziesz, a oddalisz nieprawość od przybytku twego:
Bí ìwọ bá yípadà sọ́dọ̀ Olódùmarè, a sì gbé ọ ró. Bí ìwọ bá sì mú ẹ̀ṣẹ̀ jìnnà réré kúrò nínú àgọ́ rẹ,
24 Tedy nakładziesz po ziemi wybornego złota; a złota z Ofir, jako kamienia z potoku.
tí ìwọ bá tẹ́ wúrà dáradára sílẹ̀, lórí erùpẹ̀ àti wúrà Ofiri lábẹ́ òkúta odò,
25 I będzie Wszechmocny wybornem złotem twojem, i srebrem, i siłą twoją.
nígbà náà ní Olódùmarè yóò jẹ́ wúrà rẹ, àní yóò sì jẹ́ fàdákà fún ọ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
26 Tedy się w Wszechmocnym rozkochasz, a podniesiesz ku Bogu oblicze twoje.
Lóòtítọ́ nígbà náà ní ìwọ ó ní inú dídùn nínú Olódùmarè, ìwọ ó sì gbé ojú rẹ sókè sọ́dọ̀ Ọlọ́run.
27 Będziesz mu się modlił, a wysłucha cię, i śluby twoje oddasz mu.
Bí ìwọ bá gbàdúrà rẹ sọ́dọ̀ rẹ̀, yóò sì gbọ́ tìrẹ, ìwọ ó sì san ẹ̀jẹ́ rẹ.
28 Bo cokolwiek postanowisz, będzieć się darzyło, a na drogach twoich rozjaśni się światłość.
Ìwọ ó sì gbìmọ̀ ohun kan pẹ̀lú, yóò sì fi ìdí múlẹ̀ fún ọ; ìmọ́lẹ̀ yóò sì mọ́ sípa ọ̀nà rẹ.
29 Gdy inni zniżeni będą, ty rzeczesz: Jam jest wywyższon; bo tego, co jest uniżonych oczów, Bóg zbawia.
Nígbà tí ipa ọ̀nà rẹ bá lọ sísàlẹ̀, nígbà náà ni ìwọ o wí pé, ‘Ìgbésókè ń bẹ!’ Ọlọ́run yóò sì gba onírẹ̀lẹ̀ là!
30 Wybawi i tego, który nie jest niewinny, i wybawion będzie w czystości rąk twoich.
Yóò gba ẹni tí kì í ṣe aláìjẹ̀bi là, a ó sì gbà á nípa mímọ́ ọwọ́ rẹ̀.”

< Hioba 22 >