< Jeremiasza 3 >

1 Pan mówi: Opuściłliby mąż żonę swoję, a ona odszedłszy od niego szłaby za innego męża, izali się więcej do niej wróci? Izaliby nie była wielce splugawiona ona ziemia? Ale ty, chociażeś nierząd płodziła z wielą zalotników, wszakże nawróć się d o mnie, mówi Pan.
“Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn, ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá? Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí? Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́, ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?” ni Olúwa wí.
2 Podnieś oczu swych na miejsca wysokie, a obacz, jeźliś gdzie nierządu nie płodziła. Na drogach siadałaś kwoli nim, jako Arabczyk na puszczy, a splugawiłaś ziemię wszeteczeństwem twem, i złością twoją.
“Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́? Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́, bí i ará Arabia kan nínú aginjù, ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́ pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.
3 A chociaż zawściągnione są dżdże jesienne, a deszczu na wiosnę nie bywało, przecieżeś czoło niewiasty wszetecznej mając, nie chciałaś się wstydzić.
Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn, kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò. Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà, ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.
4 Azaż od tego czasu wołać będziesz na mnie: Ojcze mój! Tyś wodzem młodości mojej?
Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé, ‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.
5 Izali Bóg zatrzyma gniew na wieczność? Izali go zachowa na wieki? Oto mówisz i czynisz złe, ile możesz.
Ìwọ yóò ha máa bínú títí? Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’ Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀ ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe.”
6 Tedy Pan rzekł do mnie za dni Jozyjasza króla: Widziałżeś, co uczyniła odporna córka Izraelska? jako chodziła na każdą górę wysoką, i pod każde drzewo zielone, i tam nierząd płodziła.
Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, “Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀.
7 A chociażem rzekł, gdy to wszystko uczyniła: Nawróć się do mnie! przecie się nie nawróciła; a na to patrzyła przestępnica siostra jej, córka Judzka.
Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i.
8 A tak zdało mi się dla tych wszystkich przyczyn, ponieważ nierząd płodziła uporna córka Izraelska, opuścić ją, i dać jej list rozwodny; a przecież się nie ulękła przestępnica siostra jej, córka Judzka, ale szedłszy i sama nierząd płodziła.
Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè.
9 I stało się, że haniebnym nierządem swoim splugawiła ziemię; bo cudzołożyła z kamieniem i z drewnem.
Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi.
10 A wszakże w tem wszystkiem nie nawróciła się do mnie przestępnica siostra jej, córka Judzka, z wszystkiego serca swego; ale obłudnie, mówi Pan.
Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́,” ni Olúwa wí.
11 Przetoż rzekł Pan do mnie: Usprawiedliwiła duszę swą odporna córka Izraelska więcej, niżeli przestępnica Judzka.
Olúwa wí fún mi pé, “Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ.
12 Idźże, a wołaj temi słowy ku północy a mów: Nawróć się, odporna córko Izraelska! mówi Pan, a nie obórzy się twarz moja surowa na was, bom Ja dobrotliwy, mówi Pan, a nie chowam gniewu na wieki.
Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá: “‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́, nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí. Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé.
13 Tylko uznaj nieprawość twoję, żeś od Pana, Boga swego, odstąpiła, a tam i sam biegała drogami swemi do obcych bogów pod każde drzewo zielone, a głosu mojego nie słuchaliście, mówi Pan.
Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ, ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀, ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’” ni Olúwa wí.
14 Nawróćcież się, synowie uporni! mówi Pan; bom Ja jest małżonkiem waszym, a przyjmę was jednego z miasta, a dwóch z rodzaju, abym was wprowadził do Syonu,
“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni.
15 Gdzie wam dam pasterzy według serca mego, i będą was paść umiejętnie i rozumnie.
Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀.
16 I stanie się, gdy się rozmnożycie a rozrodzicie się w tej ziemi w oneż dni, mówi Pan, nie będą więcej mówić: "Skrzynia przymierza Pańskiego", ani wstąpi na serce, ani wspomną na nią, ani jej nawiedzać, ani jej więcej poważać będą.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa.’ Kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́.
17 Czasu onego nazwane będzie Jeruzalem stolicą Pańską, a zgromadzą się do niego wszystkie narody, do imienia Pańskiego, do Jeruzalemu, i nie będą więcej chodzić za uporem serca swego złośliwego.
Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́.
18 W one dni pójdą dom Judzki z domem Izraelskim, i przyjdą pospołu z ziemi północnej do ziemi, którąm dał w dziedzictwo ojcom waszym.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.
19 Chociażem Ja rzekł: Jakożbym cię położył między synami, a dał ci ziemię pożądaną, dziedzictwo zacne zastępów pogańskich? chyba żebyś mię wzywał, mówiąc: Ojcze mój! a od naśladowania mnie nie odwrócił się.
“Èmi fúnra mi sọ wí pé, “‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’ Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’ o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.
20 Ponieważ jako żona przeniewierza się mężowi swemu, takeście mi się przeniewierzyli, o domie Izraelski! mówi Pan.
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi. Ìwọ ilé Israẹli,” ni Olúwa wí.
21 Głos na wysokich miejscach niech będzie słyszany, płacz modlitw synów Izraelskich; bo przewrotne uczyniwszy drogi swe zapamiętali na Pana, Boga swego,
A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga, ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po, wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.
22 Mówiącego: Nawróćcie się, synowie odporni! a uleczę odwrócenia wasze; mówcie: Oto my idziemy do ciebie, boś ty jest Pan, Bóg nasz.
“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́, Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn.” “Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.
23 Zaiste próżna jest nadzieja w pagórkach i w mnóstwie gór; zaiste w Panu, Bogu naszym, jest zbawienie Izraelskie.
Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè kéékèèké àti àwọn òkè gíga, nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà Israẹli wà.
24 Bo ta hańba pożarła pracę ojców naszych od młodości naszej, trzody ich, i stada ich, syny ich, i córki ich.
Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run, ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn, ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
25 Leżymy w pohańbieniu swem, a przykrywa nas zelżywość nasza; albowiemśmy przeciwko Panu, Bogu naszemu, zgrzeszyli, my i ojcowie nasi, od młodości naszej aż do dnia tego, a nie usłuchaliśmu głosu Pana, Boga naszego.
Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa, kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀. A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, àwa àti àwọn baba wa, láti ìgbà èwe wa títí di òní a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”

< Jeremiasza 3 >