< Jeremiasza 2 >

1 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
2 Idź, a wołaj w uszy Jeruzalemskie, mówiąc: Tak mówi Pan: Wspomniałem na cię dla miłosierdzia młodości twojej pokazanego, i dla miłości ślubin twoich; gdyś chodziła za mną na puszczy, w ziemi, w której nie osiewają.
“Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
3 Kiedy Izrael był świątobliwością Panu, i pierwocinami urodzajów jego; wszyscy, którzy go pożerali, winni byli, złe rzeczy przyszły na nich, mówi Pan.
Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
4 Słuchajcie słowa Pańskiego, domie Jakóbowy, i wszystkie rodzaje domu Izraelowego!
Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
5 Tak mówi Pan: Jakąż nieprawość znaleźli ojcowie wasi przy mnie, iż się oddalili odemnie, a chodząc za marnością marnymi się stali?
Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
6 Tak iż ani rzekli: Gdzież jest Pan, który was wywiódł z ziemi Egipskiej? który nas wodził po puszczy, po ziemi pustej i strasznej, po ziemi suchej i cieniu śmierci, po ziemi, po której nikt nie chodził, a gdzie żaden człowiek nie mieszkał?
Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
7 Owszem, gdym was wprowadził do ziemi obfitej, abyście pożywali owoców jej, i dóbr jej, wszedłszy tam splugawiliście ziemię moję, a dziedzictwo moje uczyniliście obrzydliwością.
Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
8 Kapłani nie rzekli: Gdzież jest Pan? ani ci, którzy się obierają uczeni w zakonie, poznali mię, i pasterze odstąpili odemnie, i prorocy prorokowali przez Baala, i za rzeczami nie użytecznemi chodzili.
Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
9 Przeczże się wżdy wadzę z wami, mówi Pan, a z synami synów waszych śpierać się muszę?
“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
10 Przejdźcie przynajmniej wyspy Cytym, a obaczcie; i do Kedar poślijcie a uważajcie pilnie, i przypatrzcie się, jeźli się stało co takowego;
Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
11 Jeźli odmienił który naród bogów swoich, chociaż oni nie są bogami; ale lud mój odmienił sławę swoję w rzecz niepożyteczną.
Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
12 Zdumiejcie się niebiosa nad tem, a ulęknijcie się, a zatrwożcie się bardzo, mówi Pan;
Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
13 Bo dwojaką złość popełnił lud mój: mnie opuścili, źródło wód żywych, a wykopali sobie cysterny, cysterny dziurawe, które wody zatrzymać nie mogą.
“Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
14 Izali Izrael jest niewolnikiem albo wychowańcem w domu spłodzonym? Czemuż jest podany na łup?
Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
15 Ryczą nań lwięta, i wydawają głos swój, a obracają ziemię jego w pustynię; miasta jego spalone są, tak, że niemasz i jednego obywatela.
Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
16 Synowie też Nof i Tachpanes wierzch głowy twojej zetrą.
Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
17 Zaż tego sam sobie nie sprawujesz? opuszczając Pana, Boga swego, wtenczas, kiedy cię prowadzi drogą swą.
Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
18 A teraz co za sprawę masz na drogach Egipskich, iż pijesz wodę z Nilu? albo co masz za sprawę na drogach Assyryjczyków, iż pijesz wodę z rzeki ich?
Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
19 Skarze cię złość twoja a odwrócenie twoje sfuka cię. Wiedzże tedy i obacz, iż jest rzecz zła i gorzka, iżeś opuścił Pana, Boga twego, a niemasz bojaźni mojej w tobie, mówi Pan, Pan zastępów.
Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
20 Gdym dawno połamał jarzmo twoje, i rozerwałem związki twoje mówiłaś: Nie będę służyła bałwanom; a przecie na każdym pagórku wysokim, i pod każdem drzewem gałęzistem tułasz się, o nierządnico!
“Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
21 A Jam cię był nasadził winną macicą wyborną, którejby wszystko nasienie było prawdziwe; jakożeś mi się tedy odmieniła w płonne gałęzie obcej macicy?
Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
22 Bo choćbyś się umywała i saletrą, i mydłem się jako najbardziej tarła, przecież znaczna zostanie nieprawość twoja przedemną, mówi panujący Pan.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
23 Jakoż mówisz: Nie jestem splugawiona, za Baalami nie chodziłam? Spojrzyj na drogę twoję w tej dolinie, obacz, coś czyniła, o wielbłądzico prędka, która wiklesz drogi swoje?
“Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
24 Oślicaś dzika, przywykłaś na puszczy, która według żądzy duszy swej wiatr łapie, gdy się jej przyczyna da; któż ją odwróci? Wszyscy którzy jej szukają, nie strudzą się, i w miesiącu jej znajdą ją.
Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
25 Rzekęlić: Zawściągnij nogi twojej, aby bosa nie była, i gardło twe od pragnienia, tedy mówisz: Już to próżno, nie uczynię; bom się rozmiłowała w cudzych, i za nimi pójdę.
Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
26 Jako wstyd złodzieja, kiedy go zastaną, tak się zawstydzi dom Izraelski, sami królowie ich, książęta ich, i kapłani ich, i prorocy ich,
“Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
27 Którzy mówią drewnu: Tyś jest ojciec mój, a kamieniowi: Tyś mię spłodził. Bo się do mnie obrócili tyłem, a nie twarzą; ale czasu utrapienia swego mawiają: Wstań a wybaw nas.
Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
28 I gdzież są bogowie twoi, którycheś sobie naczynił? Niech wstaną, jeźli cię mogą wybawić czasu utrapienia twego, ponieważ ile masz miast swoich, tyle masz bogów swoich, o Judo!
Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
29 Czemuż się zemną spierać chcecie? Wyście wszyscy odstąpili odemnie, mówi Pan.
“Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
30 Próżnom bił synów waszych, karania nie przyjęli; miecz wasz pożarł przecie proroków waszych, jako lew tracący.
“Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
31 O narodzie! wy rozsądźcie słowa Pańskie. Izalim był pustynią Izraelowi? Izali ziemią ciemną? Przeczże mówi lud mój: Panujemy, nie pójdziemy więcej do ciebie?
“Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
32 Izali zapomina panna ubioru swego, i oblubienica klejnotów swoich? Ale lud mój zapomniał mię przez dni niezliczone.
Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
33 Przecz dobrą być twierdzisz drogę twoję, szukając tego, w czem się kochasz? Przecz i innych nierządnic uczysz złośliwych dróg twoich?
Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
34 Nadto i na podołkach twoich znajduje się krew dusz ubogich i niewinnych; nie z pracą znalazłem to, bo to widzieć na wszystkich podołkach twoich.
Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
35 A przecież mówisz: Ponieważem niewinną, pewnie odwrócona jest zapalczywość jego odemnie. Oto Ja w sąd wnijdę z tobą, przeto, że mówisz: Nie zgrzeszyłam.
ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
36 Przeczże tak biegasz, odmieniając drogi swe? Tak będziesz pohańbiona od Egipczanów, jakoś pohańbiona była od Assyryjczyków.
Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
37 I stamtąd wyjdziesz, mając ręce swe nad głową swą: bo Pan odrzuca ufności twoje, a nie poszczęścić się w nich.
Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.

< Jeremiasza 2 >