< Rodzaju 36 >

1 A teć są rodzaje Ezawowe, który jest Edom.
Wọ̀nyí ni ìran Esau, ẹni tí a ń pè ní Edomu.
2 Ezaw pojął żony swoje z córek Chananejskich: Adę, córkę Elona, Hetejczyka; i Oolibamę, córkę Any, córki Sebeona, Hewejczyka;
Nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani ni Esau ti fẹ́ àwọn ìyàwó rẹ̀: Adah ọmọbìnrin Eloni ará Hiti àti Oholibama, ọmọbìnrin Ana, ọmọ ọmọ Sibeoni ará Hifi.
3 I Basemat, córkę Ismaelowę, siostrę Nebajotowę.
Ó sì tún fẹ́ Basemati ọmọ Iṣmaeli arábìnrin Nebaioti.
4 I urodziła Ada Ezawowi Elifasa, a Basemat urodziła Rehuela.
Adah bí Elifasi fún Esau, Basemati sì bí Reueli,
5 Oolibama też urodziła Jehusa, i Jeloma, i Korego. Ci są synowie Ezawowi, którzy mu się urodzili w ziemi Chananejskiej.
Oholibama pẹ̀lú sì bí Jeuṣi, Jalamu, àti Kora. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Esau bí ní Kenaani.
6 I wziął Ezaw żony swoje, i syny swoje, i córki swoje, i wszystkie dusze domu swego, i trzody swoje, i wszystko bydło swoje, i wszystkę majętność swoję, której był nabył w ziemi Chananejskiej, i odszedł do ziemi inszej od Jakóba, brata swego;
Esau sì mú àwọn aya rẹ̀, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ àti àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn àti gbogbo ohun ìní mìíràn tí ó ní, ni Kenaani, ó sì kó lọ sí ilẹ̀ mìíràn, jìnà sí ibi tí Jakọbu arákùnrin rẹ̀ wà.
7 Bo była majętność ich wielka, że nie mogli mieszkać pospołu, i nie mogła ich znieść ziemia pielgrzymowania ich, dla mnóstwa stad ich.
Ohun ìní wọn pọ̀ ju èyí tí àwọn méjèèjì lè máa gbé ní ojú kan lọ. Ilẹ̀ tí wọ́n wà kò le gba àwọn méjèèjì nítorí àwọn ohun ọ̀sìn wọn.
8 I mieszkał Ezaw na górze Seir, a ten Ezaw jest Edom.
Báyìí ni Esau (tí a tún mọ̀ sí Edomu) tẹ̀dó sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè tí Seiri.
9 A teć są pokolenia Ezawa, ojca Edomczyków, na górze Seir.
Èyí ni ìran Esau baba àwọn ará Edomu ní àwọn orílẹ̀-èdè olókè Seiri.
10 I te są imiona synów Ezawowych: Elifas, syn Ady, żony Ezawowej, Rehuel, syn Basematy, żony Ezawowej.
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Esau: Elifasi ọmọ Adah aya Esau àti Reueli, ọmọ Basemati tí í ṣe aya Esau pẹ̀lú.
11 Synowie zaś Elifasowi byli: Teman, Omar, Sefo, i Gaatan, i Kenaz.
Àwọn ọmọ Elifasi ni ìwọ̀nyí: Temani, Omari, Sefi, Gatamu, àti Kenasi.
12 A Tamna była założnica Elifasa, syna Ezawowego, i urodziła Elifasowi Amaleka. Ci są synowie Ady, żony Ezawowej.
Elifasi ọmọ Esau sì tún ní àlè tí a ń pè ní Timna pẹ̀lú, òun ló bí Amaleki fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọ Adah aya Esau.
13 Ci też są synowie Rehuelowi: Nahat i Zara, Samma i Meza; ci byli synowie Basematy, żony Ezawowej.
Àwọn ọmọ Reueli: Nahati, Sera, Ṣamma àti Missa. Àwọn ni ọmọ ọmọ Basemati aya Esau.
14 Ci zaś byli synowie Oolibamy, córki Any, córki Sebeona, żony Ezawowej: i urodziła Ezawowi Jehusa, i Jeloma, i Korego.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Oholibama ọmọbìnrin Ana ọmọ ọmọ Sibeoni: tí ó bí fún Esau: Jeuṣi, Jalamu àti Kora.
15 Teć są książęta z synów Ezawowych, synowie Elifasa pierworodnego Ezawowego: Książę Teman, książę Omar, książę Sefo, książę Kenaz.
Àwọn wọ̀nyí ni olórí nínú àwọn ọmọ Esau: àwọn ọmọ Elifasi, àkọ́bí Esau, Temani, Omari, Sefi, Kenasi,
16 Książę Kore, książę Gaatam, książę Amalek. Teć książęta z Elifasa poszły, w ziemi Edomskiej, ci są synowie z Ady.
Kora, Gatamu àti Amaleki. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Elifasi ní Edomu wá, wọ́n jẹ́ ọmọ ọmọ Adah.
17 Ci zaś są synowie Rehuela, syna Ezawowego: Książę Nahat, książę Zara, książę Samma, książę Meza. Te książęta poszły z Rehuela, w ziemi Edomskiej, ci są synowie Basematy żony Ezawowej.
Wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Esau, ọmọ Rueli: Nahati olórí, Sera olórí, Ṣamma olórí, Missa olórí. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Reueli jáde ní Edomu. Ọmọ ọmọ Basemati aya Esau ni wọ́n jẹ́.
18 Ci zaś są synowie Oolibamy, żony Ezawowej: Książę Jehus, książę Jelom, książę Kore. Te książęta poszły z Oolibamy, córki Any, żony Ezawowej.
Àwọn ọmọ Oholibama aya Esau: Jeuṣi, Jalamu, àti Kora, àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Oholibama ọmọ Ana, ìyàwó Esau wá.
19 Ci są synowie Ezawowi, i te książęta ich. Onże jest Edom.
Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Esau (ti o túmọ̀ sí Edomu). Àwọn wọ̀nyí ni olórí wọn.
20 Ci też są synowie Seira Chorejczyka, mieszkający w onej ziemi: Lotan, i Sobal, i Sebeon, i Hana.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Seiri ará Hori tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
21 I Dysson, i Eser, i Disan; teć są książęta Chorejskie, synowie Seirowi w ziemi Edomskiej.
Diṣoni, Eseri, àti Diṣani, àwọn wọ̀nyí olórí ènìyàn Hori, àwọn ọmọ Seiri ni ilẹ̀ Edomu.
22 A synowie Lotanowi byli Chory i Heman; a siostra Lotanowa Tamna.
Àwọn ọmọ Lotani: Hori àti Homamu: Timna sì ni arábìnrin Lotani.
23 Synowie zaś Sobalowi: Halwan, i Manahat, i Hewal, Sefo, i Onam.
Àwọn ọmọ Ṣobali: Alifani, Manahati, Ebali, Ṣefo àti Onamu.
24 Synowie też Sebeonowi ci są: Aja i Ana. Tenci to Ana, który wynalazł muły na puszczy, gdy pasł osły Sebeona, ojca swego.
Àwọn ọmọ Sibeoni: Aiah àti Ana. Èyí ni Ana tí ó rí ìsun omi gbígbóná ní inú aginjù bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣebeoni baba rẹ̀.
25 Dzieci zaś Anowe te są: Dyson, i Oolibama, córka Anowa.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ana: Diṣoni àti Oholibama ọmọbìnrin Ana.
26 A synowie Dysonowi: Hamdan, i Eseban, i Jetran, i Charan.
Àwọn ọmọ Diṣoni ni: Hemdani, Eṣbani, Itrani àti Kerani.
27 A synowie Eserowi są ci: Balaan, i Zawan, i Akan.
Àwọn ọmọ Eseri: Bilhani, Saafani àti Akani.
28 A zasię synowie Dysanowi: Hus i Aran.
Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi àti Arani.
29 Teć są książęta Chorejskie: książę Lotan, książę Sobal, książę Sebeon, książę Ana,
Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hori: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
30 Książę Dyson, książę Eser, książę Dysan. Te były książęta Chorejskie, według księstw ich, w ziemi Seir.
Diṣoni Eseri, àti Diṣani. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Hori gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Seiri.
31 Ci też byli królowie, którzy królowali w ziemi Edomskiej, pierwej niż królował król nad syny Izraelskimi.
Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli:
32 Królował tedy w Edom Bela, syn Beorów, a imię miasta jego Dynhaba.
Bela ọmọ Beori jẹ ní Edomu. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.
33 I umarł Bela, a królował miasto niego Jobab, syn Zerachów z Bosry.
Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
34 I umarł Jobab, a królował miasto niego Chusam, z ziemi Temańskiej.
Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
35 I umarł Chusam, a królował miasto niego Hadad, syn Badadów, który poraził Madyjańczyki, na polu Moabskiem, a imię miasta jego Hawid.
Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti.
36 I umarł Hadad, a królował miasto niego Samla z Masreki.
Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
37 I umarł Samla, a królował miasto niego Saul, z Rechobot u rzeki.
Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti, létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
38 I umarł Saul, a królował miasto niego Balanan, syn Achborów.
Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
39 I umarł Balanan, syn Achborów, a królował miasto niego Hadar, a imię miasta jego Pahu, a imię żony jego Mehetabel, córka Matredy, córki Mezaabowej.
Nígbà tí Baali-Hanani ọmọ Akbori kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau, orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu.
40 Teć są imiona książąt Ezawowych, według ich pokolenia, i według miejsc ich, i imion ich: Książę Tamna, książę Halwa, książę Jetet.
Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn baálẹ̀ tí ó ti ọ̀dọ̀ Esau jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti.
41 Książę Oolibama, książę Ela, książę Pynon.
Baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni,
42 Książę Kenaz, książę Teman, książę Mabsar
baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari,
43 Książę Magdyjel, książę Hyram, te są książęta Edomskie, według mieszkania ich, w ziemi osiadłości ich. Ten jest Ezaw, ojciec Edomczyków.
Magdieli, àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà. Èyí ni Esau baba àwọn ará Edomu.

< Rodzaju 36 >