< Rodzaju 35 >

1 Rzekł potem Bóg do Jakóba: Wstań, wstąp do Betela, a mieszkaj tam, i uczyń tam ołtarz Bogu, któryć się ukazał, gdyś uciekał przed obliczem Ezawa, brata twego.
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Jakọbu pé, “Gòkè lọ sí Beteli kí o sì tẹ̀dó síbẹ̀, kí ó mọ pẹpẹ níbẹ̀ fún Ọlọ́run tó farahàn ọ́ nígbà tí o ń sálọ kúrò níwájú Esau arákùnrin rẹ.”
2 Tedy rzekł Jakób do domowników swych, i do wszystkich, którzy z nim byli: Odrzućcie bogi cudze, którzy w pośrodku was są, a oczyśćcie się, i odmieńcie szaty wasze.
Nítorí náà, Jakọbu wí fún gbogbo ará ilé rẹ̀ pé, “Ẹ mú gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́dọ̀ yín kúrò, kí ẹ ya ara yín sí mímọ́, kí ẹ sì pààrọ̀ aṣọ yín.
3 A wstawszy pójdźmy do Betela, i uczynię tam ołtarz Bogu, który mię wysłuchał w dzień utrapienia mego, i był ze mną w drodze, którąm chodził.
Nígbà náà ni kí ẹ wá, kí ẹ jẹ́ kí a lọ sí Beteli, níbi tí n ó ti mọ pẹpẹ fún Ọlọ́run, tí ó dá mi lóhùn ní ọjọ́ ìpọ́njú mi tí ó sì ti ń pẹ̀lú mi níbi gbogbo tí mo ń lọ.”
4 A oddali Jakóbowi wszystkie bogi cudze, które mieli, i nausznice, które były na uszach ich, i zakopał je Jakób pod onym dębem, który był niedaleko Sychem.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fún Jakọbu ní gbogbo àjèjì òrìṣà tí ó wà lọ́wọ́ wọn, àti yẹtí etí wọn, Jakọbu sì bo gbogbo wọn mọ́lẹ̀ sábẹ́ igi óákù ní Ṣekemu.
5 I wyszli stamtąd; a strach Boży padł na miasta, które były około nich, iż nie gonili synów Jakóbowych.
Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn. Ìbẹ̀rù Ọlọ́run sì ń bẹ lára gbogbo ìlú tí ó yí wọn ká, wọ́n kò sì lépa àwọn ọmọ Jakọbu.
6 Przyszedł tedy Jakób do Luzy, która jest w ziemi Chananejskiej, ta jest Betel, sam i wszystek lud, który z nim był.
Jakọbu àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sì dé sí Lusi (ti o túmọ̀ sí Beteli) tí ó wà ní ilẹ̀ Kenaani.
7 I zbudował tam ołtarz, a nazwał miejsce ono El Betel; bo mu się tam był Bóg ukazał, gdy uciekał przed obliczem brata swego.
Níbẹ̀ ni ó sì mọ pẹpẹ kan tí ó pè ní El-Beteli, nítorí níbẹ̀ ni Ọlọ́run ti gbé fi ara hàn án nígbà tí ó ń sálọ fún arákùnrin rẹ̀.
8 Tedy umarła Debora, mamka Rebeki, i pogrzebiona jest przy Betel pod dębem, i nazwał imię onego miejsca, Allon Bachut.
Kò pẹ́ lẹ́yìn èyí ni Debora, olùtọ́jú Rebeka kú, a sì sin ín sábẹ́ igi óákù ní ìsàlẹ̀ Beteli. Nítorí náà a sọ ọ́ ní Aloni-Bakuti.
9 I ukazał się Bóg znowu Jakóbowi, gdy się wracał z Padan Syryjskiego, i błogosławił mu.
Lẹ́yìn tí Jakọbu padà dé láti Padani-Aramu, Ọlọ́run tún fi ara hàn án, ó sì súre fún un.
10 I rzekł mu Bóg: Imię twoje jest Jakób; nie tylko będzie zwane imię twoje na potem Jakób, ale Izrael będzie imię twoje; i nazwał imię jego Izrael.
Ọlọ́run sì wí fun un pé, “Jakọbu ni orúkọ rẹ, a kì yóò pè ọ́ ní Jakọbu mọ́; bí kò ṣe Israẹli.” Nítorí náà, ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
11 I rzekł mu Bóg: Jam jest Bóg wszechmogący, rozradzaj się, i rozmnażaj się; naród, i mnóstwo narodów będzie z ciebie, a królowie z biódr twoich wynijdą.
Ọlọ́run sì wí fún un pé, “Èmi ni Ọlọ́run alágbára, El-Ṣaddai; máa bí sí i, kí o sì máa pọ̀ sí i. Orílẹ̀-èdè àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá, àwọn ọba yóò sì jáde wá láti ara rẹ̀.
12 I ziemię, którąm dał Abrahamowi i Izaakowi, tobie ją dam, i nasieniu twemu po tobie dam tę ziemię.
Gbogbo ilẹ̀ tí mo fi fún Abrahamu àti Isaaki ni èmi yóò fún ọ pẹ̀lú, àti fún àwọn ìran rẹ tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn.”
13 I odszedł Bóg od niego z miejsca, na którem mówił z nim.
Nígbà náà ni Ọlọ́run gòkè lọ kúrò ní ibi tí ó ti ń bá a sọ̀rọ̀.
14 Zatem postawił Jakób znak na miejscu onem, gdzie Bóg mówił z nim, a znak on był kamienny, i pokropił go pokropieniem, i polał go oliwą.
Jakọbu sì fi òkúta ṣe ọ̀wọ̀n kan sí ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀, ó sì ta ọrẹ ohun mímu sí orí rẹ̀, ó sì da òróró olifi sí orí rẹ̀ pẹ̀lú.
15 I nazwał Jakób imię miejsca onego, gdzie Bóg z nim mówił, Betel.
Jakọbu sì pe orúkọ ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀ ní Beteli.
16 Potem odeszli z Betel; i było jeszcze jakoby mila drogi do Efraty, i rodziła Rachel a ciężkie rodzenie miała.
Nígbà náà ni wọ́n ń tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn láti Beteli. Nígbà tí ó sì ku díẹ̀ kí wọn dé Efrata, Rakeli bẹ̀rẹ̀ sí ní rọbí, ó sì ní ìdààmú púpọ̀.
17 A gdy ciężko pracowała przy rodzeniu, rzekła baba do niej: Nie bój się; bo i tego syna będziesz miała.
Bí ó sì ti ń rọbí pẹ̀lú ìrora yìí, agbẹ̀bí wí fún un pé, “Má bẹ̀rù nítorí ọmọkùnrin mìíràn ni ó ń bọ̀ yìí.”
18 A stało się, gdy wychodziła dusza jej, ( bo tamże umarła ), nazwała imię jego Ben Oni; ale ojciec jego nazwał go Benjamin.
Bí o sì ti fẹ́ gbé ẹ̀mí mi, torí pé ó ń kú lọ, ó pe ọmọ rẹ̀ náà ní Bene-Oni, ọmọ ìpọ́njú. Ṣùgbọ́n Jakọbu sọ ọmọ náà ní Benjamini, ọmọ oókan àyà mi.
19 A tak umarła Rachel, i pogrzebiona jest na drodze ku Efracie; tać jest Betlehem.
Báyìí ni Rakeli kú, a sì sin ín sí ọ̀nà Efrata (ti o túmọ̀ sí, Bẹtilẹhẹmu).
20 I postawił Jakób znak nad grobem jej; toć jest znak grobu Rachelinego aż po dziś dzień.
Jakọbu sì mọ ọ̀wọ́n kan sí ibojì rẹ̀, ọ̀wọ̀n náà sì tọ́ka sí ojú ibojì Rakeli títí di òní.
21 I poszedł stamtąd Izrael, i rozbił namiot swój za wieżą Heder.
Israẹli sì ń bá ìrìnàjò rẹ̀ lọ, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ sí Migida-Ederi, ilé ìṣọ́ Ederi.
22 Stało się tedy, gdy mieszkał Izrael w onej krainie, że szedł Ruben, i spał z Balą, założnicą ojca swego, i usłyszał to Izrael. A było synów Jakóbowych dwanaście.
Nígbà tí Israẹli sì ń gbé ní ibẹ̀, Reubeni wọlé tọ Biliha, àlè baba rẹ̀ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, Israẹli sì gbọ́ ọ̀rọ̀ náà. Jakọbu sì bí ọmọkùnrin méjìlá.
23 Synowie Lii: pierworodny Jakóbów Ruben, i Symeon, i Lewi, i Judas, i Isaszar, i Zabulon.
Àwọn ọmọ Lea, Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Jakọbu, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari àti Sebuluni.
24 Synowie Racheli: Józef i Benjamin.
Àwọn ọmọ Rakeli: Josẹfu àti Benjamini.
25 A synowie Bali, służebnicy Rachelinej: Dan i Neftali.
Àwọn ọmọ Biliha ìránṣẹ́bìnrin Rakeli: Dani àti Naftali.
26 Synowie też Zelfy, służebnicy Lii: Gad i Aser. Ci są synowie Jakóbowi, którzy mu się urodzili w Padanie Syryjskim.
Àwọn ọmọ Silipa ìránṣẹ́bìnrin Lea: Gadi àti Aṣeri. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Jakọbu bí ní Padani-Aramu.
27 I przyszedł Jakób do Izaaka, ojca swego, do Mamre, do miasta Arba, to jest Hebron, gdzie mieszkał Abraham i Izaak.
Jakọbu sì padà dé ilé lọ́dọ̀ Isaaki baba rẹ̀ ni Mamre nítòsí i Kiriati-Arba (ti o túmọ̀ sí Hebroni). Níbi tí Abrahamu àti Isaaki gbé.
28 A było dni Izaakowych sto lat, i osiemdziesiąt lat.
Ẹni ọgọ́sàn-án ọdún ni Isaaki.
29 I dokonał Izaak, i umarł, i przyłączony jest do ludu swego, stary i pełen dni; a pogrzebli go Ezaw, i Jakób, synowie jego.
Isaaki sì kú láìpẹ́ lẹ́yìn ìpadàbọ̀ Jakọbu, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Esau àti Jakọbu ọmọ rẹ̀ sì sin ín.

< Rodzaju 35 >