< Rodzaju 33 >

1 A podniósłszy Jakób oczy swe ujrzał, a oto, Ezaw idzie, a z nim cztery sta mężów; i rozdzielił dzieci, z osobna Lii, i z osobna Racheli, i z osobna dwu służebnic.
Jakọbu sì gbójú sókè, ó sì rí Esau àti irinwó ọkùnrin tí wọ́n ń bọ̀, ó sì pín àwọn ọmọ fún Lea, Rakeli àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì.
2 I postawił służebnice, i dzieci ich, na przodku, a Liję, i syny jej, za nimi, Rachelę zaś z Józefem na ostatku.
Ó sì ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn síwájú, Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọ̀wọ́ kejì tí ó tẹ̀lé wọn, Rakeli àti Josẹfu sì wà lẹ́yìn pátápátá.
3 A sam szedł przed nimi, i pokłonił się aż do ziemi siedem kroć, niż przyszedł do brata swego.
Jakọbu fúnra rẹ̀ wa lọ síwájú pátápátá, ó sì tẹríba ní ìgbà méje bí ó ti ń súnmọ́ Esau, arákùnrin rẹ̀.
4 I zaszedł mu drogę Ezaw, i obłapiwszy go, upadł na szyję jego, i całował go; i płakali.
Ṣùgbọ́n Esau sáré pàdé Jakọbu, ó sì dì mọ́ ọn, ó rọ̀ mọ́ ọn lọ́rùn, ó sì fẹnukò ó lẹ́nu. Àwọn méjèèjì sì sọkún.
5 Potem podniósłszy ( Ezaw ) oczy swe, ujrzał żony i dzieci, i rzekł: A ci co zacz są, twoiż to? i odpowiedział: Dziatki to są, które Bóg dał z łaski słudze twemu.
Nígbà tí Esau sì ṣe àkíyèsí àwọn ìyàwó àti ọmọ Jakọbu, ó béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ti ta ni àwọn wọ̀nyí?” Jakọbu sì fèsì wí pé, “Èyí ni àwọn ọmọ tí Ọlọ́run nínú àánú rẹ̀ ti fi fún ìránṣẹ́ rẹ.”
6 I przybliżyły się służebnice i synowie ich, a pokłoniły się.
Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn súnmọ́ tòsí, wọ́n sì tẹríba.
7 Przybliżyła się też i Lija, i dzieci jej, i pokłonili się; a potem przybliżył się Józef i Rachel, i pokłonili się.
Lẹ́yìn náà ni Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú dé, wọ́n sì tún tẹríba. Ní ìkẹyìn ni Josẹfu àti Rakeli dé, wọ́n sì tún tẹríba pẹ̀lú.
8 I rzekł Ezaw: A ów wszystek hufiec na co, z którymem się spotkał? Odpowiedział Jakób: Abym znalazł łaskę przed oczyma pana mego.
Esau sì béèrè pé, “Kí ni èrò rẹ tí o fi to àwọn ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ tí mo pàdé wọ̀nyí?” Jakọbu dáhùn pé, “Kí n ba le rí ojúrere rẹ ni olúwa mi.”
9 Tedy rzekł Ezaw: Mam ja dosyć, bracie miły, miej ty swoje.
Ṣùgbọ́n Esau wí pé, “Tèmi ti tó mi, pa èyí tí o ní mọ́ fún ara rẹ.”
10 I rzekł Jakób: Nie tak będzie proszę; jeźlim teraz znalazł łaskę w oczach twoich, weźmij upominek mój z ręki mojej, przeto, iżem widział oblicze twoje, jakobym widział oblicze Boże, i łaskawieś mię przyjął;
Jakọbu bẹ̀ ẹ́ wí pé, “Rárá bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ó bá ṣe pé, mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ gba ọrẹ lọ́wọ́ mi. Bí mo ṣe rí ojú rẹ̀ yìí, ó dàbí wí pé mo rí ojú Ọlọ́run ni báyìí, tí inú rẹ̀ ti dùn sí mi.
11 Przyjmijże proszę dar mój, którym ci przyniósł, gdyż mię hojnie błogosławił Bóg, a mam wszystkiego dosyć. A tak uprosił go, że to przyjął.
Jọ̀wọ́ gba àwọn ohun tí mo mú wá wọ̀nyí lọ́wọ́ mi. Nítorí Ọlọ́run ti fi oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ hàn sí mi, gbogbo ohun tí mo fẹ́ sì ni mo ní.” Nígbà tí Jakọbu sì rọ̀ ọ́ pé Esau gbọdọ̀ gbà wọ́n, Esau sì gbà á.
12 Tedy rzekł Ezaw: Ruszmy się, a idźmy, a ja pójdę przed tobą.
Nígbà náà ni Esau wí pé, “Jẹ́ kí a máa lọ, n ó sìn ọ.”
13 I odpowiedział mu Jakób: Wie pan mój, że z sobą mam dziatki młode, i owce kotne, i krowy cielne, które jeźlibym przegnał dnia jednego, pozdychają wszystkie stada.
Ṣùgbọ́n Jakọbu wí fún un pé, “Ṣe ìwọ náà ṣe àkíyèsí pé ọ̀pọ̀ nínú àwọn ọmọ wọ̀nyí kéré, àwọn màlúù àti àgùntàn pẹ̀lú sì ní àwọn ọmọ kéékèèké. Bí a bá dà wọ́n rìn jìnnà ju bí agbára wọn ṣe mọ lọ, wọ́n lè kú.
14 Niech w przód proszę jedzie pan mój przed sługą swoim, a ja poprowadzę się z lekka, jako zdąży trzoda, która jest przede mną, i jako nadążą dzieci, aż przyjdę do pana mego do Seir.
Èmi bẹ̀ ọ́, máa lọ síwájú ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ó sì máa rọra bọ̀, títí èmi àti àwọn ọmọ yóò fi dé ọ̀dọ̀ olúwa mi ní Seiri.”
15 Tedy rzekł Ezaw: Niech wżdy zostawię przy tobie cokolwiek ludu, który jest ze mną. A on odpowiedział: A na cóż to? byłem znalazł łaskę w oczach pana mego.
Esau wí pé, “Jẹ́ kí n fi díẹ̀ sílẹ̀ fún ọ nínú àwọn ọkùnrin mi nígbà náà.” Jakọbu wí pé, “Èéṣe, àní kí n sá à rí ojúrere olúwa mi?”
16 I wrócił się dnia onego Ezaw drogą swą do Seir.
Ní ọjọ́ náà gan an ni Esau padà lọ sí Seiri.
17 A Jakób obrócił się do Suchot, i zbudował sobie dom, i dla stad swoich poczynił obory, a dla tego nazwał imię miejsca onego Suchot.
Jakọbu sì lọ sí Sukkoti, ó sì kọ́ ilé fún ara rẹ̀, ó sì ṣe ọgbà fún àwọn ẹran. Ìdí èyí ní a fi ń pe ibẹ̀ ní Sukkoti.
18 I przyszedł Jakób zdrowo do miasta Sychem, które było w ziemi Chananejskiej, gdy się wrócił z Padan Syryjskiego, i położył się przed miastem.
Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu tí Padani-Aramu dé, àlàáfíà ni Jakọbu dé ìlú Ṣekemu ní ilẹ̀ Kenaani, ó sì pàgọ́ sí itòsí ìlú náà.
19 I kupił część pola, na którem rozbił namiot swój, od synów Hemora, ojca Sychemowego, za sto jagniąt;
Ó sì ra ilẹ̀ kan tí ó pàgọ́ sí ni ọgọ́rùn-ún owó fàdákà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Hamori tí í ṣe baba Ṣekemu.
20 A postawił tam ołtarz, i nazwał go: Mocny Bóg Izraelski.
Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan tí ó pè ní El Elohe Israẹli.

< Rodzaju 33 >