< Rodzaju 32 >

1 A Jakób też poszedł w drogę swoję i potkali się z nim Aniołowie Boży.
Jakọbu sì ń bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ, àwọn angẹli Ọlọ́run sì pàdé rẹ̀.
2 I rzekł Jakób ujrzawszy je: Obóz to Boży; i nazwał imię miejsca onego Mahanaim.
Nígbà tí Jakọbu rí wọn, ó wí pé, “Àgọ́ Ọlọ́run ni èyí!” Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ni Mahanaimu.
3 Potem posłał Jakób posły przed sobą do Ezawa, brata swego, do ziemi Seir, do krainy Edomskiej.
Jakọbu sì rán àwọn oníṣẹ́ ṣáájú ara rẹ̀ sí Esau arákùnrin rẹ̀ ni ilẹ̀ Seiri ní orílẹ̀-èdè Edomu.
4 I rozkazał im mówiąc: Tak rzeczecie do pana mego Ezawa: To mówi sługa twój Jakób: U Labana byłem gościem, i mieszkałem z nim aż do tego czasu.
Ó pàṣẹ fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò wí fún Esau olúwa mi, Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, ‘Mo ti ṣe àtìpó lọ́dọ̀ Labani títí ó fi di àsìkò yìí.
5 A mam woły i osły, owce, i sługi, i służebnice, a posyłam odpowiedzieć panu memu, żebym znalazł łaskę w oczach twoich.
Mo ní màlúù, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn àti ewúrẹ́. Mo tún ni àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin. Mo ń ránṣẹ́ yìí sí olúwa mi kí èmi le è rí ojúrere rẹ.’”
6 I wrócili się posłowie do Jakóba, mówiąc: Przyszliśmy do brata twego Ezawa, który też idzie przeciwko tobie, a cztery sta mężów z nim.
Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà padà tọ Jakọbu wà, wọ́n wí pé “Esau arákùnrin rẹ ti múra láti wá pàdé rẹ pẹ̀lú irinwó ọkùnrin.”
7 I zląkł się Jakób bardzo a strwożył się; i rozdzielił lud, który z nim był, i owce, i woły, i wielbłądy, na dwa hufce;
Pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìbànújẹ́ ni Jakọbu fi pín àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sí ìpín méjì, ó sì pín àwọn ẹran ọ̀sìn, agbo ẹran àti ìbákasẹ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.
8 I rzekł: Jeźliby przyszedł Ezaw do jednego hufca, a poraziłby go, tedy hufiec, który pozostanie, będzie zachowany.
Nítorí ó rò ó nínú rẹ̀ pé, “Bí Esau bá kọjú ogun sí ìpín kan, ìpín kejì yóò sá àsálà.”
9 I rzekł Jakób: Boże ojca mego Abrahama, i Boże ojca mego Izaaka, Panie, któryś do mnie rzekł: Wróć się do ziemi twojej, i do rodziny twojej, a uczynięć dobrze.
Nígbà náà ni Jakọbu gbàdúrà pe, “Ọlọ́run Abrahamu baba mi, àti Ọlọ́run Isaaki baba mi, Olúwa tí ó wí fún mi pé, ‘Padà sí orílẹ̀-èdè rẹ àti sọ́dọ̀ àwọn ìbátan rẹ, èmi yóò sì ṣe ọ́ ní rere,’
10 Mniejszym jest niż wszystkie zmiłowania, i niż wszystka prawda, którąś uczynił z sługą swym. Albowiem tylko o lasce mojej przeszedłem ten Jordan, a teraz mam dwa hufce.
èmi kò tilẹ̀ yẹ fún àánú àti òtítọ́ tí o ń fihàn fún ìránṣẹ́ rẹ. Nítorí pé, kìkì ọ̀pá mi ni mo mu kúrò ni ilé kọjá Jordani yìí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, èmi ti di ẹgbẹ́ méjì.
11 Wyrwij mię proszę z ręki brata mego, z ręki Ezawa; boć się go boję, by snać przyszedłszy nie zabił mię, i matki z synami.
Jọ̀wọ́ Olúwa gbà mí lọ́wọ́ Esau arákùnrin mi, nítorí ẹ̀rù ń bà mí pé yóò wá dojú ìjà kọ mí àti àwọn ìyàwó pẹ̀lú àwọn ọmọ mi.
12 Wszakeś rzekł: Dobrze czyniąc będęć dobrze czynił, a rozmnożę nasienie twoje jako piasek morski, który zliczon być nie może, dla mnóstwa.
Ṣùgbọ́n ìwọ ti ṣèlérí pé, ‘Èmi yóò mú ọ gbilẹ̀, èmi yóò sì mú kí àwọn ìran rẹ dà bì í yanrìn òkun tí ẹnikẹ́ni kò le è kà.’”
13 I przenocował tam onej nocy, i wziął z tego, co miał przy ręku, upominek dla Ezawa, brata swego.
Ó sì lo òru ọjọ́ náà níbẹ̀. Ó mú ẹ̀bùn fún Esau arákùnrin rẹ̀ nínú ohun ìní rẹ̀.
14 To jest kóz dwieście, i kozłów dwadzieścia, owiec dwieście, i baranów dwadzieścia.
Igba ewúrẹ́, ogún òbúkọ, igba àgùntàn, ogún àgbò,
15 Wielbłądzic odchowujących młode, ze źrebięty ich, trzydzieści, krów czterdzieści, i wołów dziesięć, dwadzieścia oślic, i dziesięć ośląt.
ọgbọ̀n abo ìbákasẹ pẹ̀lú ọmọ wọn, ogójì abo màlúù àti akọ màlúù mẹ́wàá, ogún abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá.
16 I oddał je w ręce sług swoich, każde stado z osobna, i rzekł do sług swoich: Idźcie przede mną, a plac uczyńcie między stadem a między stadem.
Ó sì fi wọ́n lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ṣáájú mi, kí ẹ sì jẹ́ kí àlàfo wà láàrín ọ̀wọ́ agbo ẹran kọ̀ọ̀kan sí èkejì.”
17 I rozkazał pierwszemu, mówiąc: Gdy się spotka z tobą Ezaw, brat mój, a spyta cię, mówiąc: Czyjeś ty? i dokąd idziesz? a czyje to stado przed tobą?
Ó pàṣẹ fún èyí tí ó ṣáájú pé, “Nígbà tí arákùnrin mi Esau bá pàdé rẹ tí ó sì béèrè ẹni tí ìwọ í ṣe àti ibi tí ìwọ ń lọ àti ẹni tí ó ni agbo ẹran tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ,
18 Tedy powiesz: Sługi twego Jakóba jest to upominek, posłany panu memu Ezawowi, a oto, i sam idzie za nami.
nígbà náà ni ìwọ yóò wí pé, ‘Ti ìránṣẹ́ rẹ Jakọbu ni wọ́n. Ẹ̀bùn ni ó sì fi wọ́n ṣe fún Esau olúwa mi, òun pàápàá ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’”
19 Także też rozkazał drugiemu, i trzeciemu, i wszystkim idącym za temi stady, mówiąc: Temiż słowy mówcie do Ezawa, gdy go potkacie.
Jakọbu sì pàṣẹ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ fún ọ̀wọ́ kejì àti ẹ̀kẹta àti àwọn tókù tí ó tẹ̀lé agbo ẹran pé, “Ohun kan ṣoṣo yìí náà ni kí ẹ sọ fún Esau nígbà tí ẹ bá pàdé rẹ̀.
20 Powiecie mu też: Oto, sługa twój Jakób idzie za nami, mówił bowiem: Ubłagam oblicze jego upominkiem, który idzie przede mną, a potem ujrzę oblicze jego; owa mię snać w łaskę przyjmie.
Kí ẹ rí i dájú wí pé, ẹ sọ fún un pé, ‘Jakọbu ìránṣẹ́ rẹ̀ ń bọ̀ lẹ́yìn wa.’” Èrò Jakọbu ni láti fi àwọn ẹ̀bùn wọ̀nyí tu Esau lójú pé bóyá inú Esau yóò dùn sí òun nígbà tí àwọn bá pàdé.
21 I poszedł w przód on upominek przed obliczem jego, a sam przenocował onej nocy z hufcem swoim.
Nítorí náà ẹ̀bùn Jakọbu ṣáájú rẹ̀ lọ, Jakọbu pàápàá sì lo òru ọjọ́ náà nínú àgọ́.
22 Wstawszy tedy onej nocy, wziął obie żony swe, i dwie służebnice swoje, i jedenaście synów swoich, i przeszedł przez bród Jabok,
Ó sì dìde ní òru ọjọ́ náà, ó mú àwọn aya rẹ̀ méjèèjì, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ méjèèjì, àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ mọ́kọ̀ọ̀kànlá, wọ́n sì kọjá ní ìwọdò Jabbok.
23 A wziąwszy je, przeprawił je przez tęż rzekę, i przeprowadził wszystko, co miał.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti rán wọn kọjá odò tán sí òkè odò, ó sì rán àwọn ohun ìní rẹ̀ kọjá pẹ̀lú.
24 A tylko sam Jakób został.
Ó sì ku Jakọbu nìkan, ọkùnrin kan sì bá a ja ìjàkadì títí ó fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
25 A oto, biedził się z nim mąż aż do wejścia zorzy; który widząc, że go nie mógł przemóc, uderzył Jakóba w staw biodry jego, i wytrąciła się z stawu biodra Jakóbowa, gdy się z nim mocował.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà rí i pé òun kò le borí Jakọbu, ó fọwọ́ kàn án ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀, egungun náà sì yẹ̀ kúrò lórí ike, bí ó ti ń ja ìjàkadì.
26 I rzekł: Puść mię, bo już wschodzi zorza. I odpowiedział: Nie puszczę cię, aż mi będziesz błogosławił.
Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí fún un pé, “Jẹ́ kí ń máa lọ, nítorí ojúmọ́ ti mọ́.” Ṣùgbọ́n Jakọbu dá a lóhùn pé, “Èmi kò ní jẹ́ kí o lọ, àyàfi bí o bá súre fún mi.”
27 Tedy mu rzekł: Co za imię twoje? I odpowiedział: Jakób.
Ọkùnrin náà béèrè orúkọ rẹ̀. Ó sì wí fún un pé, “Jakọbu ni òun ń jẹ́.”
28 I rzekł: Nie będzie nazywane więcej imię twoje Jakób, ale Izrael; boś sobie mężnie poczynał z Bogiem, i z ludźmi, i przemogłeś.
Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí pé, “Orúkọ rẹ kì yóò jẹ́ Jakọbu mọ́ bí kò ṣe Israẹli, nítorí pé ìwọ ti bá Ọlọ́run àti ènìyàn jà, o sì borí.”
29 I spytał Jakób mówiąc: Oznajmij mi proszę imię twoje; a on odpowiedział: Czemu się pytasz o imieniu mojem? I tamże mu błogosławił.
Jakọbu sì bẹ ọkùnrin náà pé, “Sọ orúkọ rẹ fún mi.” Ṣùgbọ́n ọkùnrin náà sá à dáhùn pé, “Èéṣe tí o ń béèrè orúkọ mi?” Lẹ́yìn náà ó súre fún Jakọbu níbẹ̀.
30 Tedy nazwał Jakób imię miejsca onego Fanuel, mówiąc: Iżem widział Boga twarzą w twarz, a zachowana jest dusza moja.
Jakọbu sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Penieli pé, “Mo rí Ọlọ́run ní ojúkojú, síbẹ̀ a dá ẹ̀mí mi sí.”
31 I weszło mu słońce, kiedy minął miejsce Fanuel, a on uchramował na biodrę swoję.
Bí ó sì ti ń kọjá Penieli, oòrùn ràn bá a, ó sì ń tiro nítorí itan rẹ̀.
32 Przetoż nie jadają synowie Izraelscy żyły skurczonej, która jest przy stawie biodry, aż do dnia tego, iż był uderzył w staw biodry Jakóbowej, i w żyłę skurczoną.
Ìdí nìyí tí àwọn ọmọ Israẹli kì í fi í jẹ iṣan tí ó wà ní ọ̀ọ́kán ibi tí eegun itan ti bẹ̀rẹ̀ títí di òní olónìí, nítorí níbi iṣan náà ni a ti fọwọ́ kan ibi tí egungun itan Jakọbu ti bẹ̀rẹ̀.

< Rodzaju 32 >