< Rodzaju 25 >

1 Potem Abraham pojął drugą żonę, której imię było Ketura.
Abrahamu sì tún fẹ́ aya mìíràn, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ketura.
2 Która mu urodziła Zamrama, i Joksana, i Madana, i Midyjana, i Jesobaka, i Suacha.
Ó sì bí Simrani, Jokṣani, Medani, Midiani, Iṣbaki, àti Ṣua
3 A Joksan spłodził Sabę, i Dedana; a synowie Dedanowi byli Asurymowie i Letusymowie, i Leumymowie.
Jokṣani ni baba Ṣeba àti Dedani, àwọn ìran Dedani ni àwọn ara Asṣuri, Letusi àti Leumiti.
4 Synowie zaś Midyjanowi byli Hefa, i Hefer, i Henoch, i Abyda, i Eldaa; wszyscy ci byli synowie Ketury.
Àwọn ọmọ Midiani ni Efani, Eferi, Hanoku, Abida àti Eldaa. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ìran Ketura.
5 I dał Abraham wszystko, co miał, Izaakowi.
Abrahamu sì fi ohun gbogbo tí ó ní fún Isaaki.
6 A synom założnic, które miał Abraham, dał upominki; i wyprawił je od Izaaka syna swego, jeszcze za żywota swego, ku wschodowi do krainy wschodniej.
Ṣùgbọ́n kí Abrahamu tó kú, Abrahamu fún àwọn ọmọ tí àwọn àlè rẹ̀ bí fún un ní ẹ̀bùn, ó sì lé wọn jáde lọ fún Isaaki ọmọ rẹ sí ilẹ̀ ìlà-oòrùn.
7 Teć są dni lat żywota Abrahamowego, które przeżył, sto i siedemdziesiąt, i pięć lat.
Gbogbo àpapọ̀ ọdún tí Abrahamu lò láyé jẹ́ igba kan ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
8 I ustawając umarł Abraham w starości dobrej, zeszły w leciech, i syty dni; i przyłączon jest do ludu swego.
Abrahamu sì kú ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ó dàgbà, ó darúgbó kí ó tó kú. A sì sin ín sí ibojì àwọn ènìyàn rẹ̀.
9 I pogrzebli go Izaak i Ismael, synowie jego, w jaskini Machpela, na polu Efrona, syna Socharowego, Hetejczyka, które było przeciwko Mamre;
Àwọn ọmọ rẹ̀, Isaaki àti Iṣmaeli sì sin ín sínú ihò àpáta ni Makpela ní ẹ̀gbẹ́ Mamre, ní oko Efroni ọmọ Sohari ará Hiti,
10 Na polu, które był kupił Abraham u synów Hetowych; tam pogrzebiony jest Abraham, i Sara, żona jego.
inú oko tí Abrahamu rà lọ́wọ́ ara Hiti yìí ni a sin Abrahamu àti Sara aya rẹ̀ sí.
11 A po śmierci Abrahamowej błogosławił Bóg Izaakowi, synowi jego, a Izaak mieszkał u studni Żywiącego i Widzącego mię.
Lẹ́yìn ikú Abrahamu, Ọlọ́run sì bùkún fún Isaaki ọmọ rẹ̀, tí ó ń gbé nítòsí kànga Lahai-Roi ní ìgbà náà.
12 A teć są rodzaje Ismaela, syna Abrahamowego, którego urodziła Hagar, Egipczanka, służebnica Sary, Abrahamowi.
Wọ̀nyí ni ìran Iṣmaeli, ọmọ Abrahamu ẹni tí Hagari ará Ejibiti, ọmọ ọ̀dọ̀ Sara bí fún un.
13 I te są imiona synów Ismaelowych w nazwiskach ich, według rodzajów ich: pierworodny Ismaelów, Nebajot; po nim Kedar, i Abdeel, i Mabsan.
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Iṣmaeli bí a ṣe bí wọn, bẹ̀rẹ̀ láti orí: Nebaioti àkọ́bí, Kedari, Adbeeli, Mibsamu,
14 I Masma, i Duma, i Masa.
Miṣima, Duma, Massa,
15 Hadar, i Tema, Jetur, Nafis i Kedma.
Hadadi, Tema, Jeturi, Nafiṣi, àti Kedema.
16 Ci są synowie Ismaelowi, i te imiona ich, według miasteczek ich, i zamków ich, dwanaście książąt w familijach ich.
Wọ̀nyí sì ni orúkọ àwọn ọmọ Iṣmaeli, wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọba méjìlá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn.
17 A było lat żywota Ismaelowego, sto lat, i trzydzieści lat i siedem lat, i zszedł a umarł, i przyłączon jest do ludu swego.
Àpapọ̀ ọdún tí Iṣmaeli lò láyé jẹ́ ẹ̀tàdínlógóje ọdún, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
18 I mieszkali od Hewila aż do Sur, która leży na przeciwko Egiptowi, idąc do Asyryi; przed obliczem wszystkich braci swych umarł.
Àwọn ìran rẹ̀ sì tẹ̀dó sí agbègbè Hafila títí tí ó fi dé Ṣuri, ní ẹ̀bá ààlà Ejibiti, bí ìwọ ti ń lọ sí ìhà Asiria. Ó sì kú níwájú àwọn arákùnrin rẹ̀ gbogbo.
19 Te zaś są rodzaje Izaaka syna Abrahamowego: Abraham spłodził Izaaka.
Wọ̀nyí ni ìtàn ìran Isaaki ọmọ Abrahamu. Abrahamu bí Isaaki.
20 A Izaak miał czterdzieści lat, gdy sobie pojął Rebekę, córkę Batuela Syryjczyka, z krainy Syryjskiej, siostrę Labana, Syryjczyka, za żonę.
Nígbà tí Isaaki di ọmọ ogójì ọdún ni ó gbé Rebeka ọmọ Betueli ará Aramu ti Padani-Aramu tí í ṣe arábìnrin Labani ará Aramu ní ìyàwó.
21 Tedy się modlił Izaak Panu za żonę swą, iż była niepłodna; i wysłuchał go Pan, i poczęła Rebeka, żona jego.
Isaaki sì gbàdúrà sì Olúwa, nítorí aya rẹ̀ tí ó yàgàn, Olúwa sì gbọ́ àdúrà rẹ̀, Rebeka sì lóyún.
22 A gdy się dziatki trącały w żywocie jej, rzekła: Jeźliż tak miało być, dlaczegożem poczęła? Szła tedy, aby się pytała Pana.
Àwọn ọmọ náà ń gbún ara wọn nínú rẹ̀, ó sì wí pé, “Èéṣe tí èyí ń ṣẹlẹ̀ sí mi,” ó sì lọ béèrè lọ́dọ̀ Olúwa.
23 I rzekł jej Pan: dwa narody są w żywocie twoim, i dwojaki lud z żywota twego rozdzieli się, a jeden lud nad drugi lud możniejszy będzie, i większy będzie służył mniejszemu.
Olúwa sì wí fún un pé, “Orílẹ̀-èdè méjì ni ń bẹ nínú rẹ, irú ènìyàn méjì ni yóò yà láti inú rẹ; àwọn ènìyàn kan yóò jẹ́ alágbára ju èkejì lọ, ẹ̀gbọ́n ni yóò máa sin àbúrò.”
24 A gdy się wypełniły dni jej, aby porodziła, oto bliźnięta były w żywocie jej.
Nígbà tí ó tó àkókò fún un láti bímọ, ìbejì ni ó wà nínú rẹ̀, ọkùnrin sì ni wọ́n.
25 I wyszedł pierwszy syn lisowaty, i wszystek jako szata kosmaty; i nazwali imię jego Ezaw.
Èyí tí ó kọ jáde jẹ́ ọmọ pupa, irun sì bo gbogbo ara rẹ̀ bí aṣọ onírun, nítorí náà, wọ́n pè é ní Esau.
26 A potem wyszedł brat jego, ręką swą trzymając za piętę, Ezawa i nazwano imię jego Jakób; a Izaakowi było sześćdziesiąt lat, gdy mu się oni narodzili.
Lẹ́yìn èyí ni arákùnrin èkejì jáde wá, ọwọ́ rẹ̀ sì di Esau ni gìgísẹ̀ mú, nítorí náà ni wọn ṣe pe orúkọ rẹ ni Jakọbu. Ọmọ ọgọ́ta ọdún ni Isaaki, nígbà tí Rebeka bí wọn.
27 A gdy urosły one dzieci, Ezaw był mężem w myślistwie biegłym i rolnikiem, a Jakób był mąż prosty mieszkający w namieciech.
Àwọn ọmọkùnrin náà sì dàgbà. Esau sì di ọlọ́gbọ́n ọdẹ, ẹni tí ó fẹ́ràn àti máa dúró ní oko. Jakọbu sì jẹ́ ènìyàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí ó ń gbé láàrín ìlú.
28 I miłował Izaak Ezawa, iż jadał z łowu jego; Rebeka zaś miłowała Jakóba.
Isaaki, ẹni tí ó fẹ́ràn ẹran igbó fẹ́ràn Esau nítorí ẹran igbó tí Esau máa ń pa, ṣùgbọ́n Rebeka fẹ́ràn Jakọbu.
29 I uwarzył sobie Jakób potrawę, a na ten czas przyszedł Ezaw z pola spracowany.
Ní ọjọ́ kan, Jakọbu sì pa ìpẹ̀tẹ̀, Esau sì ti igbó ọdẹ dé, ó sì ti rẹ̀ ẹ́.
30 Tedy rzekł Ezaw do Jakóba: Daj mi jeść, proszę cię z tej czerwonej potrawy, bom się spracował: a przetoż nazwano imię jego Edom.
Esau wí fún Jakọbu pé, “Èmí bẹ̀ ọ, fi ìpẹ̀tẹ̀ rẹ pupa n nì bọ́ mi, nítorí tí ó rẹ̀ mí gidigidi.” (Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ rẹ̀ ní Edomu.)
31 Któremu rzekł Jakób: Przedajże mi dziś pierworodztwo twoje.
Jakọbu dáhùn pé, “Kò burú, ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ta ogún ìbí rẹ fún mi ná.”
32 I rzekł Ezaw: Otom ja bliski śmierci, cóż mi po pierworodztwie?
Esau sì dáhùn pé, “Wò ó mo ti fẹ́rẹ kú, àǹfààní kín sì ni ogún ìbí jẹ́ fún mi?”
33 I rzekł Jakób: Przysiążże mi dziś, i przysiągł mu. I sprzedał pierworodztwo swoje Jakóbowi.
Ṣùgbọ́n, Jakọbu dáhùn pé, “Kọ́kọ́ búra fún mi pé tèmi ni ogún ìbí náà yóò jẹ́.” Báyìí ni Esau búra tí ó sì gbé ogún ìbí rẹ̀ tà fún Jakọbu.
34 Tedy Jakób dał Ezawowi chleba, i potrawę z soczewicy, a on jadł i pił, a potem powstawszy odszedł; i pogardził Ezaw pierworodztwem swojem.
Nígbà náà ni Jakọbu fi àkàrà àti ìpẹ̀tẹ̀ lẹntili fún Esau. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì bá tirẹ̀ lọ. Báyìí ni Esau gan ogún ìbí rẹ̀.

< Rodzaju 25 >