< Rodzaju 24 >

1 A Abraham był stary i podeszły w leciech, a Pan błogosławił mu we wszystkiem.
Abrahamu sì ti di arúgbó ní àkókò yìí, Olúwa sì ti bùkún fún un ni gbogbo ọ̀nà,
2 Tedy rzekł Abraham do starszego sługi swego w domu swym, który wszystkiem rządził, co miał: Połóż, proszę, rękę twoję pod biodro moje;
Abrahamu wí fún olórí àwọn ìránṣẹ́ ilẹ̀ rẹ̀, tí ó jẹ́ alábojútó ohun gbogbo tí ó ní pé, “Fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi.
3 A zaprzysięgnę cię przez Pana, Boga nieba, i Boga ziemi, abyś nie brał żony synowi memu z córek Chananejskich, między któremi ja mieszkam;
Èmi yóò mú ọ búra lórúkọ Olúwa Ọlọ́run ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ kì yóò fẹ́ aya fún ọmọ mi nínú àwọn ọmọbìnrin ará Kenaani, láàrín àwọn ẹni tí èmi ń gbé.
4 Ale pójdziesz do ziemi mojej, i do rodziny mojej, a stamtąd weźmiesz żonę Izaakowi, synowi memu.
Ṣùgbọ́n, ìwọ yóò lọ sí orílẹ̀-èdè mi, láàrín àwọn ará mi láti fẹ́ aya fún Isaaki, ọmọ mi.”
5 Tedy mu rzekł sługa: A jeźliby snać nie chciała niewiasta ona iść ze mną do tej ziemi, mamże odprowadzić syna twego do ziemi, z którejś ty wyszedł?
Ìránṣẹ́ náà bi í wí pé, “Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà bá kọ̀ láti bá mi wá sí ilẹ̀ yìí ń kọ́? Ǹjẹ́ mo lè mú ọmọ rẹ padà lọ sí orílẹ̀-èdè níbi tí ìwọ ti wá?”
6 I rzekł mu Abraham: Strzeż się, abyś tam zasię nie zaprowadzał syna mego.
Abrahamu sì wí fún un pé, “Rí i dájú pé ìwọ kò mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
7 Pan Bóg niebieski, który mię wziął z domu ojca mego, i z ziemi rodziny mojej, i który mówił ze mną, a który mi przysiągł, mówiąc: Nasieniu twemu dam ziemię tę; on pośle Anioła swego przed obliczem twojem, i weźmiesz stamtąd żonę synowi memu.
“Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run tí ó mú mi jáde láti ilẹ̀ baba mi àti ní ilẹ̀ tí a bí mi, tí ó bá mi sọ̀rọ̀ tí ó sì búra fún mi pé, ‘Irú-ọmọ rẹ ni n ó fi ilẹ̀ yìí fún,’ yóò rán angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ, kí ìwọ kí ó lè rí aya fẹ́ wá fún ọmọ mi láti ibẹ̀.
8 A jeźliby nie chciała ona niewiasta iść z tobą, wolny będziesz od tego poprzysiężenia mego; tylko syna mego nie zaprowadzaj tam.
Bí obìnrin náà kò bá fẹ́ tẹ̀lé ọ wá, nígbà náà ni a tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ìbúra yìí, ṣùgbọ́n pàtàkì ni pé ìwọ kò gbọdọ̀ mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
9 Podłożył tedy sługa rękę swoję pod biodro Abrahama, pana swego, i przysiągł mu na to.
Ìránṣẹ́ náà sì fi ọwọ́ rẹ̀ sí abẹ́ itan Abrahamu olúwa rẹ̀, ó sì búra fún nítorí ọ̀rọ̀ náà.
10 I wziął on sługa dziesięć wielbłądów, z wielbłądów pana swego, i poszedł; bo wszystkie dobra pana swego miał w rękach swych; a wstawszy puścił się do Aram Naharaim, do miasta Nachorowego.
Ìránṣẹ́ náà sì mú ìbákasẹ mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Naharaimu, sí ìlú Nahori,
11 I postawił wielbłądy przed miastem u studni wody, pod wieczór, tego czasu, którego zwykły niewiasty wychodzić czerpać wodę.
ó sì mú àwọn ìbákasẹ náà kúnlẹ̀ nítòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.
12 I rzekł: Panie, Boże pana mego Abrahama! Niech mię proszę spotka dziś, czego żądam, a uczyń miłosierdzie z panem moim Abrahamem.
Ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa à mi; jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lónìí, sì fi àánú hàn fún Abrahamu olúwa mi.
13 Oto, ja stoję u studni, a córki obywateli miasta tego wyjdą czerpać wodę;
Kíyèsi i, mo dúró ní ẹ̀bá kànga omi yìí, àwọn ọmọbìnrin ìlú yìí sì ń jáde wá pọn omi.
14 Panienka tedy, do której bym rzekł: Nachyl proszę wiadra twego, że się napiję, a ona by rzekła: Pij, owszem i wielbłądy twoje napoję; ta niech będzie, którąś zgotował słudze twemu Izaakowi; a po tem poznam, żeś uczynił miłosierdzie z panem moim.
Jẹ́ kí ó ṣe pé nígbà tí mo bá wí fún ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin pe, ‘Jọ̀wọ́ sọ ládugbó rẹ kalẹ̀, kí n le mu omi,’ tí ó bá sì wí pé, ‘Mu ún, èmi ó sì fún àwọn ìbákasẹ rẹ náà mu pẹ̀lú,’ jẹ́ kí ó ṣe èyí tí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ Isaaki. Nípa èyí ni n ó fi mọ̀ pé o ti fi àánú hàn fún olúwa mi.”
15 I stało się, że pierwej niż przestał mówić, oto, Rebeka wychodziła, która się urodziła Batuelowi, synowi Melchy, żony Nachora, brata Abrahamowego, niosąc wiadro na ramieniu swem.
Kí o tó di pé, ó parí àdúrà, Rebeka dé pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀. Ọmọ Betueli ni. Betueli yìí ni Milka bí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
16 A dzieweczka ona była bardzo piękna na wejrzeniu, panna, a której mąż nie uznał; ta przyszedłszy do studni, napełniła wiadro swe, i wracała się.
Ọmọbìnrin náà rẹwà, wúńdíá ni, kò sì tí ì mọ ọkùnrin, ó lọ sí ibi ìsun omi náà, ó sì pọn omi sínú ìkòkò omi, ó sì gbé e, ó ń gòkè bọ̀ kúrò níbi omi.
17 Tedy zabieżał jej on sługa, i rzekł: Daj mi się proszę napić trochę wody z wiadra twego.
Ìránṣẹ́ náà súré lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fun un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ni omi díẹ̀ nínú ìkòkò omi rẹ.”
18 A ona rzekła: Pij, panie mój, i prędko złożyła wiadro swe na rękę swoję, i dała mu pić.
Òun náà dáhùn pé, “Mu, olúwa mi,” ó sì yára sọ ìkòkò omi náà ka ọwọ́ rẹ̀, ó sì fún un mu.
19 A gdy mu się dała napić, rzekła: I wielbłądom twoim naczerpię, aż się napiją.
Lẹ́yìn tí ó ti fún un ni omi mu tán, ó wí pé, “Èmi ó bu omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú títí wọn yóò fi mu àmutẹ́rùn.”
20 I wylała prędko wodę z wiadra swego w koryto, a bieżawszy jeszcze do studni czerpać, naczerpała wszystkim wielbłądom jego.
Ó sì yára da omi inú ìkòkò omi rẹ̀ sínú ìbùmu, ó sáré padà lọ sí ibi omi láti pọn sí i wá fún àwọn ìbákasẹ, títí tí ó fi pọn fún gbogbo wọn.
21 A on mąż zdumiewał się nad nią, uważając z milczeniem, jeźli mu Pan zdarzył drogę jego, czyli nie.
Láìsọ ọ̀rọ̀ kan, ìránṣẹ́ yìí ń wo ọmọbìnrin náà fínní fínní láti mọ̀ bóyá Olúwa ti ṣe ìrìnàjò òun ní rere tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
22 I gdy się napiły wielbłądy, wyjął on mąż nausznicę złotą, która ważyła pół sykla, i dwie manele, i dał na ręce jej, które ważyły dziesięć syklów złota.
Lẹ́yìn tí àwọn ìbákasẹ náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọ̀n ṣékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n ṣékélì wúrà mẹ́wàá.
23 I rzekł: Czyjaś ty córka, powiedz mi, proszę? a jeźli w domu ojca twego miejsce dla nas, gdzie byśmy przenocowali?
Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”
24 A ona mu rzekła: Jestem córka Batuela, syna Melchy, którego urodziła Nachorowi.
Ó dáhùn pé, “Betueli ọmọ tí Milka bí fún Nahori ni baba mi.”
25 Nad to rzekła mu: Jest u nas dosyć plew i pastwy, i miejsce do przenocowania.
Ó sì fi kún un pé, “Àwa ní koríko àti ṣakaṣaka tó pẹ̀lú, àti ààyè láti wọ̀ sí.”
26 I pokłonił się on człowiek i dał chwałę Panu,
Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa,
27 I rzekł: Błogosławiony Pan, Bóg pana mego Abrahama, który nie oddalił miłosierdzia swego i prawdy swojej od pana mojego, albowiem gdym był w drodze, przyprowadził mię Pan w dom braci pana mego.
wí pe, “Olùbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìnàjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”
28 Bieżała tedy dzieweczka, i oznajmiła w domu matki swej, jako się co stało.
Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀.
29 I miała Rebeka brata imieniem Labana; i wybieżał Laban przeciwko onemu mężowi aż ku studni.
Rebeka ní arákùnrin tí ń jẹ́ Labani; Labani sì sáré lọ bá ọkùnrin náà ní etí odò.
30 Bo ujrzawszy nausznicę, i manele na ręku siostry swej, i usłyszawszy słowa Rebeki, siostry swej, mówiącej: Tak mówił do mnie ten mąż; przyszedł do onego męża, a oto, on stał przy wielbłądach u studni.
Bí ó sì ti rí òrùka imú àti ẹ̀gbà ní ọwọ́ arábìnrin rẹ̀ tí ó sì tún gbọ́ ohun tí Rebeka sọ pé ọkùnrin náà sọ fún òun, ó jáde lọ bá ọkùnrin náà, ó sì bá a, ó dúró ti ìbákasẹ wọ̀n-ọn-nì ní ẹ̀bá ìsun omi.
31 I rzekł do niego: Wnijdź błogosławiony Pański; przecz byś stał na dworze, jużem ja nagotował dom, i miejsce wielbłądom?
Ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Wá, ìwọ ẹni ìbùkún Olúwa, èéṣe tí o dúró sí ìta níhìn-ín? Mo ti pèsè ààyè sílẹ̀ fún ọ àti ààyè fún àwọn ìbákasẹ rẹ.”
32 Tedy wszedł mąż on w dom; a Laban rozsiodłał wielbłądy, i dał plew i pastwy wielbłądom, i wody dla umycia nóg jego, i nóg mężów onych, którzy z nim byli.
Ọkùnrin náà sì bá Labani lọ ilé, ó sì tú ẹrù orí ìbákasẹ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fún wọn ni koríko àti oúnjẹ. Ó sì bu omi fún ọkùnrin náà àti àwọn arákùnrin rẹ̀ láti wẹ ẹsẹ̀ wọn.
33 I położył przedeń, coby jadł; ale on rzekł: Nie będę jadł, aż pierwej odprawię rzecz swoję. Tedy rzekł Laban: Mówże.
Wọ́n sì gbé oúnjẹ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n, ó wí pé, “Èmi kò ní jẹun àyàfi bí mo bá sọ ohun tí mo ní í sọ.” Labani sì wí pé, “Kò burú, sọ ọ́.”
34 I rzekł: Jam jest sługa Abrahamów;
Nítorí náà, ó wí pé, “Ìránṣẹ́ Abrahamu ni èmi.
35 A Pan ubłogosławił pana mego bardzo, i stał się możnym; bo mu nadał owiec, i wołów, i srebra, i złota, i sług, i służebnic, i wielbłądów, i osłów.
Olúwa sì ti bùkún olúwa mi gidigidi. Ó sì ti di ọlọ́rọ̀, Ó sì ti fún un ní àgùntàn, màlúù, àti fàdákà àti wúrà, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin àti ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
36 A urodziła Sara, żona pana mego syna panu memu, w starości jego, któremu dał wszystko, co ma.
Sara aya olúwa mi sì ti bí ọmọkùnrin kan fún un, ní ìgbà ogbó rẹ̀, olúwa mi sì ti fún ọmọ náà ní ohun gbogbo tí ó ní.
37 I poprzysiągł mię pan mój, mówiąc: Nie weźmiesz żony synowi memu z córek Chananejskich, w których ziemi ja mieszkam;
Olúwa mi sì ti mú mi búra wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani, ní ilẹ̀ ibi tí èmi ń gbé,
38 Ale do domu ojca mego pójdziesz i do rodziny mojej; a weźmiesz stamtąd żonę synowi mojemu.
ṣùgbọ́n lọ sí ìdílé baba mi láàrín àwọn ìbátan mi kí o sì fẹ́ aya fún ọmọ mi.’
39 I rzekłem do pana mego: Nie pójdzie snać ta niewiasta ze mną.
“Mo sì bí olúwa mi léèrè pé, ‘Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà kò bá fẹ́ bá mi wá ń kọ́?’
40 Tedy mi odpowiedział: Pan, przed któregom ja obliczem chodził, pośle Anioła swego z tobą, i poszczęści drogę twoję; a weźmiesz żonę synowi memu z rodziny mojej, i z domu ojca mego.
“Ó sì dáhùn wí pé, ‘Olúwa, níwájú ẹni tí èmi ń rìn yóò rán Angẹli rẹ̀ ṣáájú rẹ yóò sì jẹ́ kí o ṣe àṣeyọrí ní ìrìnàjò rẹ, kí ìwọ kí ó ba le fẹ́ aya fún ọmọ mi, láàrín àwọn ìbátan mi, àti láàrín àwọn ìdílé baba mi.
41 Tedy wolen będziesz od poprzysiężenia mego, gdy przyjdziesz do rodziny mojej; ale jeźlićby jej nie dano, wolen będziesz od poprzysiężenia mego.
Nígbà tí ìwọ bá lọ sí ọ̀dọ̀ ìdílé baba mi (gẹ́gẹ́ bí mo tí wí), nígbà náà ni ìwọ tó bọ́ nínú ìbúra yìí.’
42 Przyszedłem tedy dziś do studni, i rzekłem Panie, Boże pana mego Abrahama, jeźliż ty teraz szczęścisz drogę moję, którę ja idę:
“Nígbà tí mo dé ibi ìsun omi lónìí, mo wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, bí ìwọ bá fẹ́, jọ̀wọ́ jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lórí ohun tí mo bá wá yìí.
43 Oto, ja stoję u studni wody; niechajże panienka, która wynijdzie czerpać wodę, a gdybym jej rzekł: Daj mi proszę napić się trochę wody z wiadra twego;
Wò ó, mo dúró ní ẹ̀bá ìsun omi yìí, kí ó ṣe pé, nígbà tí wúńdíá kan bá jáde wá pọn omi, tí èmi sì wí fún un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ìwọ̀nba omi díẹ̀ mu nínú ládugbó rẹ,”
44 A ona by rzekła do mnie: I ty pij, naczerpię też i wielbłądom twoim: ta będzie żoną, którą zgotował Pan synowi pana mego.
tí ó bá sì wí fún mi pé, “Mu ún, èmi yóò sì tún pọn omi fún àwọn ìbákasẹ rẹ pẹ̀lú,” jẹ́ kí ẹni náà jẹ́ ẹni tí Olúwa yàn fún ọmọ Abrahamu, olúwa mi.’
45 Niżelim ja tedy przestał mówić w sercu swem, oto, Rebeka wychodziła, niosąc wiadro swe na ramieniu swem, i przyszła do studni, a czerpała; którejm rzekł: Daj mi pić proszę.
“Kí n sì tó gbàdúrà tán nínú ọkàn mi, Rebeka jáde wá pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀, ó sì lọ sí ibi ìsun omi ó sì pọn omi. Mo sì wí fun un pé, ‘Jọ̀wọ́ fún mi ni omi mu.’
46 Ona tedy prędko złożywszy wiadro z siebie, rzekła: Pij, owszem i wielbłądy twoje napoję. I piłem; napoiła też i wielbłądy.
“Kíákíá ni ó sọ ìkòkò rẹ̀ kalẹ̀ láti èjìká rẹ̀, ó sì wí fún mi pé, ‘Mu ún, èmi yóò sì tún fún àwọn ìbákasẹ rẹ mu pẹ̀lú.’ Mo sì mu, ó sì tún fún àwọn ìbákasẹ mi mu pẹ̀lú.
47 I pytałem jej, mówiąc: Czyjaś ty córka? i odpowiedziała: Jestem córka Batuela, syna Nachorowego, którego mu urodziła Melcha, tedym włożył nausznice na twarz jej, i manele na ręce jej.
“Mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Ọmọ ta ní ìwọ í ṣe?’ “Ó sì wí fún mi pé, ‘Ọmọbìnrin Betueli tí í ṣe ọmọ Nahori ni òun, Milka sì ni ìyá òun.’ “Nígbà náà ni mo fi òrùka náà bọ imú rẹ̀, mo sì fi ẹ̀gbà ọwọ́ náà si ní ọwọ́.
48 Zatem pokłoniwszy się, dałem chwałę Panu, i błogosławiłem Panu, Bogu pana mego Abrahama, który mię prowadził drogą prawą, abym wziął córkę brata pana mego, synowi jego
Èmi sì tẹríba, mo sì wólẹ̀ fún Olúwa, mó sì fi ìbùkún fún Ọlọ́run Abrahamu olúwa mi, ẹni tí ó mú mi tọ ọ̀nà títọ́ láti rí ọmọ ọmọ arákùnrin olúwa mi mú wá fún ọmọ rẹ̀.
49 Przetoż teraz, jeźli chcecie uczynić miłosierdzie i prawdę z panem moim, oznajmijcie mi: a jeźli nie, powiedzcie mi też, żebym się obrócił na prawo albo na lewo.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí bí ẹ̀yin yóò bá fi inú rere àti òtítọ́ bá olúwa mi lò, ẹ sọ fún mi, bí bẹ́ẹ̀ sì kọ́, ẹ sọ fún mi, kí ń le è mọ ọ̀nà tí èmi yóò yà sí.”
50 Tedy odpowiedział Laban i Batuel, mówiąc: Od Pana ta rzecz wyszła; my tobie w niczem przeczyć nie możemy.
Labani àti Betueli sì dáhùn pé, “Lọ́dọ̀ Olúwa ni èyí ti wá, nítorí náà àwa kò le sọ rere tàbí búburú fún ọ.
51 Oto Rebeka przed tobą; weźmij ją, a idź; a niech będzie żoną syna pana twego, jako rzekł Pan.
Rebeka nìyí, mú un kí ó máa lọ, kí ó sì di aya ọmọ olúwa à rẹ, bí Olúwa ti fẹ́.”
52 I stało się, gdy usłyszał sługa Abrahamów słowa ich pokłonił się aż do ziemi Panu.
Nígbà tí ọmọ ọ̀dọ̀ Abrahamu gbọ́ ohun tí wọ́n wí, ó wólẹ̀ níwájú Olúwa.
53 Zatem wyjął sługa on naczynia srebrne, i naczynia złote, i szaty, a oddał je Rebece; dał też upominki drogie bratu jej, i matce jej.
Nígbà náà ni ó kó ohun èlò wúrà àti fàdákà jáde àti aṣọ, ó sì fi wọ́n fún Rebeka, ó fún arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ ní ẹ̀bùn olówó iyebíye pẹ̀lú.
54 Jedli tedy i pili, on i mężowie, którzy z nim byli, i zostali tam na noc; a rano wstawszy, rzekł: Puśćcie mię do pana mego.
Lẹ́yìn náà ni òun àti àwọn ọkùnrin tí ó bá a wá tó jẹ, tí wọ́n sì mu, tí wọn sì sùn níbẹ̀ ní òru ọjọ́ náà. Bí wọ́n ti dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó wí pé, “Ẹ rán mi padà lọ sí ọ̀dọ̀ olúwa mi.”
55 I rzekł brat jej, i matka jej: Niechaj pomieszka z nami dzieweczka dzień, albo dziesięć; potem pójdziesz.
Ṣùgbọ́n arákùnrin Rebeka àti ìyá rẹ̀ fèsì pé, “A fẹ́ kí Rebeka wà pẹ̀lú wa fún nǹkan bí ọjọ́ mẹ́wàá sí i, lẹ́yìn èyí, ìwọ le máa mu lọ.”
56 A on rzekł do nich: Nie zatrzymywajcie mię, gdyż Pan poszczęścił drogę moję, puśćcie mię, abym jechał do pana mego.
Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá mi dúró, Olúwa sá à ti ṣe ọ̀nà mi ní rere. Ẹ rán mi lọ, kí èmi kí ó le è tọ olúwa à mi lọ.”
57 Zatem rzekli: Zawołajmy dzieweczki, a spytajmy, co na to rzecze.
Nígbà náà ni wọ́n sọ pé, “Jẹ́ kí a pe ọmọ náà gan an kí a sì bi í.”
58 Tedy zawołali Rebeki, i mówili do niej: Chceszże jechać z tym człowiekiem? A ona odpowiedziała: Pojadę.
Wọ́n sì pe Rebeka wọ́n sì bi í, wí pé, “Ṣe ìwọ yóò bá ọkùnrin yìí lọ.” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi yóò lọ.”
59 I puścili Rebekę siostrę swoję, z mamką jej, i sługę Abrahamowego, z mężami jego.
Wọ́n sì gbà kí Rebeka àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Abrahamu àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ máa lọ.
60 Tedy błogosławili Rebece, mówiąc jej: Siostraś nasza, rozmnóż się w tysiąc tysięcy, a niech posiądzie nasienie twoje bramy nieprzyjaciół swych.
Wọ́n sì súre fún Rebeka, wọn sì wí fun un pé, “Ìwọ ni arábìnrin wa ìwọ yóò di ìyá ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹ kí ó ni ẹnu ibodè ọ̀tá wọn.”
61 Tedy wstawszy Rebeka z dzieweczkami swemi, i wsiadłszy na wielbłądy jechały za onym mężem; i wziął sługa on Rebekę, i odjechał.
Nígbà náà ni Rebeka àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rebeka, ó sì bá tirẹ̀ lọ.
62 A Izaak wracał się z przechadzki od studni, którą zowią Żywiącego i Widzącego mię; bo mieszkał w ziemi południowej.
Isaaki sì ń ti ọ̀nà kànga Lahai-Roi bọ, nítorí ìhà gúúsù ni ó ń gbé.
63 A wyszedł był Izaak, dla modlitwy na pole pod wieczór, i podniósłszy oczy swe, ujrzał wielbłądy przychodzące.
Isaaki sì jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àṣàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ìbákasẹ tí ń bọ̀ wá.
64 Podniosła też i Rebeka oczy swe, i ujrzała Izaaka, i zsiadła z wielbłąda;
Rebeka pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Isaaki. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ìbákasẹ,
65 Bo rzekła do sługi: Cóż on za mąż, który idzie przez pole przeciwko nam? I odpowiedział sługa: Ten jest pan mój. A ona wziąwszy rańtuch nakryła się.
ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?” Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rebeka mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.
66 I powiedział on sługa Izaakowi wszystko, co sprawił.
Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Isaaki ohun gbogbo tí ó ti ṣe.
67 I wprowadził ją Izaak do namiotu Sary, matki swojej; i wziął Rebekę, i była mu żoną, i miłował ją. I ucieszył się Izaak po śmierci matki swojej.
Nígbà náà ni Isaaki mú Rebeka wọ inú àgọ́ ìyá rẹ̀, Sara, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Isaaki lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.

< Rodzaju 24 >