< Ezdrasza 8 >

1 A cić są przedniejsi z domów swych ojcowskich, i ród tych, którzy wyszli zemną z Babilonu za królowania króla Artakserksesa:
Wọ̀nyí ni àwọn olórí ìdílé àti àwọn tí ó fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn tì wọn gòkè pẹ̀lú mi láti Babeli ní àkókò ìjọba Artasasta ọba:
2 Z synów Fineaszowych Gierson; z synów Itamarowych Danijel; z synów Dawidowych Hattus;
nínú àwọn ọmọ Finehasi: Gerṣomu; nínú àwọn ọmọ Itamari: Daniẹli; nínú àwọn ọmọ Dafidi: Hattusi,
3 Z synów Sechanijaszowych, który był z synów Faresowych, Zacharyjasz, a z nim poczet mężów sto i pięćdziesiąt;
nínú àwọn ọmọ Ṣekaniah; nínú àwọn ọmọ Paroṣi: Sekariah, àti pé àádọ́jọ ọkùnrin fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú rẹ;
4 Z synów Pachatmoabowych Elijeoenaj, syn Zerachyjaszowy, a z nim dwieście mężów;
nínú àwọn ọmọ Pahati-Moabu: Elihoenai ọmọ Serahiah àti àwọn igba ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
5 Z synów Sechanijaszowych syn Jahazyjelowy, a z nim trzy sta mężów;
nínú àwọn ọmọ Sattu: Ṣekaniah ọmọ Jahasieli àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
6 A z synów Adynowych Ebed, syn Jonatana, a z nim pięćdziesiąt mężów;
nínú àwọn ọmọ Adini: Ebedi ọmọ Jonatani, àti àádọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
7 A z synów Elamowych Isajasz, syn Atalijasza, a z nim siedmdziesiąt mężów;
nínú àwọn ọmọ Elamu: Jeṣaiah ọmọ Ataliah àwọn àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
8 A z synów Sefatyjaszowych Zabadyjasz, syn Michaelowy, a z nim ośmdziesiąt mężów;
nínú àwọn ọmọ Ṣefatia: Sebadiah ọmọ Mikaeli, àti ọgọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
9 Z synów Joabowych Obadyjasz, syn Jechyjelowy, a z nim dwieście i ośmnaście mężów;
nínú àwọn ọmọ Joabu: Obadiah ọmọ Jehieli àti ogún ó lé nígba ó dín méjì ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
10 A z synów Selomitowych, syn Josyfijaszowy, a z nim sto i sześćdziesiąt mężów;
nínú àwọn ọmọ Bani: Ṣelomiti ọmọ Josafiah, àti ọgọ́jọ ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
11 A z synów Bebajowych Zacharyjasz, syn Bebajowy, a z nim dwadzieścia i ośm mężów;
nínú àwọn ọmọ Bebai: Sekariah ọmọ Bebai àti ọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n pẹ̀lú rẹ̀;
12 A z synów Azgadowych Johanan, syn Hakatanowy, a z nim sto i dziesięć mężów;
nínú àwọn ọmọ Asgadi: Johanani ọmọ Hakatani, àti àádọ́fà ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
13 A z synów Adonikamowych najostateczniejszych, których te są imiona: Elifelet, Jehijel, i Semejasz, a z nimi sześdziesiąt mężów,
nínú àwọn ọmọ Adonikami: àwọn ti ó gbẹ̀yìn, tì orúkọ wọn ń jẹ́ Elifaleti, Jeieli àti Ṣemaiah, àti ọgọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú wọn;
14 A z synów Bigwajowych Utaj i Zabud, a z nimi siedmdziesiąt mężów;
nínú àwọn ọmọ Bigfai: Uttai àti Sakkuri, àti àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú wọn.
15 A tak zgromadziłem ich do rzeki, która wpada do Achawy, i leżeliśmy tam obozem przez trzy dni: potem przeglądałem lud i kapłanów, a z synów Lewiego nie znalazłem tam żadnego.
Èmi kó wọn jọ pọ̀ si etí odò ti ń sàn lọ sí Ahafa, a pàgọ́ síbẹ̀ fún odidi ọjọ́ mẹ́ta, nígbà ti mo wo àárín àwọn ènìyàn àti àárín àwọn àlùfáà, ń kò rí ọmọ Lefi kankan níbẹ̀.
16 Przetoż posłałem Elijezera, Aryjela, Semejasza, i Elnatana, i Jaryba, i Elnatana i Natana, i Zacharyjasza, i Mesullama, przedniejszych, i Jojaryba, i Elnatana, mężów uczonych;
Nígbà náà ni mo pe Elieseri, Arieli, Ṣemaiah, Elnatani, Jaribi, Elnatani, Natani, Sekariah, àti Meṣullamu, tí wọ́n jẹ́ olórí, àti Joiaribu àti Elnatani tí wọ́n jẹ́ onímọ̀ ìjìnlẹ̀,
17 I rozkazałem im do Iddona, przełożonego nad miejscem Kasyfii, i włożyłem w usta ich słowa, które mieli mówić do Iddona, Achywa i Netynejczyków na miejscu Kasyfii, aby nam przywiedli sług do domu Boga naszego.
mo sì rán wọn tí àwọn ti àṣẹ sí ọ̀dọ̀ Iddo, tí ó jẹ́ olórí ní ibi ti a ń pè ni Kasifia, mo sì sọ fún wọn ohun tí wọn yóò wí fun Iddo àti àwọn Lefi arákùnrin rẹ̀, tí wọ́n jẹ́ òṣìṣẹ́ tẹmpili ní Kasifia pé, kí wọn mú àwọn ìránṣẹ́ wá sí ọ̀dọ̀ wa fún ilé Ọlọ́run wa.
18 I przywiedli nam według ręki Boga naszego łaskawej nad nami, męża nauczonego z synów Maheli, syna Lewiego, syna Izraelowego, i Serebijasza, i synów jego, i braci jego ośmnaście;
Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run wa wà lára wa, wọ́n sì mú Ṣerebiah wá fún wa, ẹni tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ìran Mahili, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli, àti àwọn ọmọ Ṣerebiah àti àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n jẹ́ ọkùnrin méjìdínlógún.
19 I Hasabijasza, a z nim Jesajasza z synów Merarego, braci jego, i synów ich dwadzieścia;
Àti Haṣabiah, pẹ̀lú Jeṣaiah láti ìran Merari, pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ọmọ wọ́n jẹ́ ogún ọkùnrin.
20 Nadto z Netynejczyków, których był postanowił Dawid i przedniejsi ku posłudze Lewitów, Netynejczyków dwieście i dwadzieścia; ci wszyscy z imienia mianowani byli.
Wọ́n sì tún mú ogún lé nígba àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili wá—àwọn ènìyàn tí Dafidi àti àwọn ìjòyè rẹ̀ gbé kalẹ̀ láti ran àwọn ọmọ Lefi lọ́wọ́. Gbogbo wọn ni a ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
21 Tedym tam zapowiedział post u rzeki Achawy, abyśmy się dręczyli przed Bogiem naszym, a szukali od niego drogi prostej sobie, i dziatkom naszym, i wszystkiej majętności naszej.
Níbẹ̀, ní ẹ̀bá odò Ahafa, mo kéde àwẹ̀, kí a ba à le rẹ ara wa sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run, kí a sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ fún ìrìnàjò àìléwu fún wa àti àwọn ọmọ wa àti fún gbogbo ohun ìní wa.
22 Bom się wstydził prosić u króla o jaki poczet jezdnych, aby nam byli na pomocy przeciwko nieprzyjaciołom w drodze; bośmy byli powiedzieli królowi, mówiąc: Ręka Boga naszego jest nad wszystkimi, którzy go szukają uprzejmie, ale moc jego i popędliw ość jego przeciwko wszystkim, którzy go opuszczają.
Mo tijú láti béèrè lọ́wọ́ ọba fún àwọn jagunjagun orí ilẹ̀, àti ti orí ẹṣin láti dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá ní ọ̀nà wa, nítorí àti sọ fún ọba pé, “Ọwọ́ àánú Ọlọ́run wà ní ara gbogbo ẹni tí ó gbé ojú sókè sí i, ṣùgbọ́n ìbínú ńlá rẹ wà lórí ẹni tó kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
23 A gdyśmy pościli, i prosiliśmy o to Boga naszego, wysłuchał nas.
Bẹ́ẹ̀ ni a sì gbààwẹ̀, a sì bẹ̀bẹ̀ fún èyí lọ́dọ̀ Ọlọ́run wa, òun sì gbọ́ àdúrà wa.
24 Tedym odłączył z przedniejszych kapłanów dwanaście: Serebijasza, Hasabijasza, a z nimi braci ich dziesięć;
Nígbà náà ni mo ya àwọn àlùfáà tó jẹ́ aṣáájú méjìlá sọ́tọ̀, pẹ̀lú Ṣerebiah, Haṣabiah àti mẹ́wàá lára àwọn arákùnrin wọn,
25 I odważyłem im srebro, i złoto, i naczynia na ofiarę podnoszenia do domu Boga naszego, które ofiarowali król i rada jego, i książęta jego, i wszystek lud Izraelski, ile się go znalazło.
mo sì fi òsùwọ̀n wọn ọrẹ fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò tí ọba, àti ti àwọn ìgbìmọ̀, àti ti àwọn ìjòyè, àti ti gbogbo ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀, tí wọ́n gbe sílẹ̀ fún ilé Ọlọ́run wa.
26 Odważyłem, mówię do rąk ich srebra talentów sześćset i pięćdziesiąt, a naczynia srebrnego sto talentów, przytem złota sto talentów.
Mo fi òsùwọ̀n wọn ẹgbẹ̀ta lé láàádọ́ta tálẹ́ǹtì fàdákà, àti ohun èlò fàdákà tí ó wọn ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì, ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì wúrà,
27 Czasz też złotych dwadzieścia, ważących po tysiąc łótów, a dwa naczynia z mosiądzu wybornego, tak piękne jako złoto.
ogún ago wúrà tí iye rẹ̀ tó ẹgbẹ̀rún dariki, àti ohun èlò idẹ dáradára méjì ti ó ni iye lórí bí i wúrà.
28 Potemem rzekł do nich: Wyście poświęceni Panu, i naczynia także poświęcone, a to srebro i to złoto dobrowolnie ofiarowane jest Panu, Bogu ojców waszych.
Mo wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin àti àwọn ohun èlò wọ̀nyí ni a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa. Fàdákà àti wúrà sì jẹ́ ọrẹ àtinúwá sí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín.
29 Pilnujcież a strzeżcie, aż to odważycie przed kapłanami przedniejszymi, i Lewitami, i książętami z domów ojcowskich w Izraelu w Jeruzalemie, w gmachach domu Pańskiego.
Ẹ máa tọ́jú wọn dáradára títí ẹ̀yin yóò fi fi òsùwọ̀n wọ̀n wọ́n jáde kúrò ni ilé Olúwa ni Jerusalẹmu ní iwájú àwọn aṣáájú, àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti ní iwájú olórí ìdílé gbogbo ni Israẹli.”
30 A tak wzięli kapłani i Lewitowie wagę onego srebra, i złota, i naczynia, aby je odnieśli do Jeruzalemu, do domu Boga naszego.
Nígbà náà ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi gba fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ́ tí a ti wọ̀n jáde fún kíkó lọ sí ilé Ọlọ́run wa ní Jerusalẹmu.
31 Zatem ruszyliśmy się od rzeki Achawy dwunastego dnia, miesiąca pierwszego, abyśmy szli do Jeruzalemu; a ręka Boga naszego była nad nami, i wyrwała nas z ręki nieprzyjaciela i czyhającego na nas w drodze.
Ní ọjọ́ kejìlá oṣù kìn-ín-ní ni a gbéra kúrò ní ẹ̀bá odò Ahafa láti lọ sí Jerusalẹmu. Ọwọ́ Ọlọ́run wa wà lára wa, ó sì dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá àti àwọn adigunjalè ní ọ̀nà wa.
32 I przyszliśmy do Jeruzalemu, i zamieszkaliśmy tam przez trzy dni.
Bẹ́ẹ̀ ni a gúnlẹ̀ sí Jerusalẹmu, níbi tí a ti sinmi fún ọjọ́ mẹ́ta.
33 A dnia czwartego odważono srebro, i złoto, i naczynie ono w domu Boga naszego do ręki Meremota, syna Uryjasza kapłana, z którym był Eleazar, syn Fineesowy; z nimi też byli Josabad, syn Jesuego, i Noadyjasz, syn Binnujego, Lewitowie;
Ní ọjọ́ kẹrin, a wọn ohun èlò fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ lé àlùfáà Meremoti ọmọ Uriah lọ́wọ́, láti inú ilé Ọlọ́run wa, Eleasari ọmọ Finehasi wà pẹ̀lú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi; Josabadi ọmọ Jeṣua àti Noadiah ọmọ Binnui wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
34 Pod liczbą i wagą wszystko, i zapisano wagę tego wszystkiego onegoż czasu.
Gbogbo nǹkan ni a kà, tí a sì wọ̀n, gbogbo iye ìwọ̀n ni a sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú ìwé ní ìgbà náà.
35 Wróciwszy się tedy z niewoli ci, którzy byli w pojmaniu, ofiarowali Bogu Izraelskiemu cielców dwanaście za wszystkiego Izraela, baranów dziewięćdziesiąt i sześć, baranków siedmdziesiąt i siedm, kozłów za grzech dwanaście, to wszystko na całopalenie Panu.
Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn tí ó ti padà láti ilẹ̀ àjèjì rú ẹbọ sísun sí Ọlọ́run Israẹli: akọ màlúù méjìlá fún gbogbo Israẹli, àgbò mẹ́rìndínlọ́gọ́rùn-ún, ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́tàdínlọ́gọ́rin, àti òbúkọ méjìlá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Gbogbo èyí jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa.
36 I oddali wyroki królewskie starostom królewskim, i książętom za rzeką, a ci byli pomocą ludowi i domowi Bożemu.
Wọ́n sì jíṣẹ́ àṣẹ ọba fún àwọn ìjòyè àti àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn ènìyàn àti ilé Ọlọ́run.

< Ezdrasza 8 >