< Ezdrasza 9 >

1 A gdy się to odprawiło, przystąpili do mnie książęta, mówiąc: Nie odłączył się lud Izraelski, i kapłani, i Lewitowie od narodów tych ziem; ale czynią według obrzydliwości Chananejczyków, Hetejczyków, Ferezejczyków, Jebuzejczyków, Ammonitczyków, Moabczyków, Egipczyków, i Amorejczyków.
Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí tán, àwọn olórí tọ̀ mí wá, wọ́n sì wí pé, “Àwọn ènìyàn Israẹli, tí ó fi mọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, kò tì í ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn agbègbè tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra bí i ti àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, àwọn ará Peresi, àwọn ará Jebusi, àwọn ará Ammoni, àwọn ará Moabu, àwọn ará Ejibiti àti ti àwọn ará Amori.
2 Albowiem pojęli córki ich sobie i synom swym, a pomięszało się nasienie święte z narodami tych ziem, a ręka książąt i zwierzchności pierwsza była w tem przestępstwie.
Wọ́n ti fẹ́ lára àwọn ọmọbìnrin wọn fún ara wọn àti fún àwọn ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí aya, wọ́n ti da irú-ọmọ ìran mímọ́ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn ti ó wà ní àyíká wọn. Àwọn olórí àti àwọn ìjòyè ta àwọn ènìyàn tókù yọ nínú híhu ìwà àìṣòótọ́.”
3 Co gdym usłyszał, rozdarłem suknię moję i płaszcz mój, a rwałem włosy na głowie mojej, i na brodzie mojej, i siedziałem, zdumiawszy się.
Nígbà tí mo gbọ́ èyí, mo fa àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi ya, mo tu irun orí àti irùngbọ̀n mi, mo sì jókòó ní ìjayà.
4 I zgromadzili się do mnie wszyscy, którzy drżą przed słowem Boga Izraelskiego dla przestępstwa tych, którzy przyszli z niewoli, a jam siedział, zdumiawszy się, aż do ofiary wieczornej.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn tí ó wárìrì sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Israẹli kó ara wọn jọ yí mi ká nítorí àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn yìí. Èmi sì jókòó níbẹ̀ ní ìjayà títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́.
5 Ale pod czas ofiary wieczornej wstałem z utrapienia mego, mając rozdartą suknię moję i płaszcz mój, a poklęknąwszy na kolana swe, wyciągnąłem ręce swe ku Panu, Bogu memu,
Ní ìgbà tí ó di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, mo dìde kúrò nínú ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn mi, pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi yíya ní ọrùn mi, mo kúnlẹ̀ lórí eékún mi méjèèjì, mo sì tẹ́ ọwọ́ mi méjèèjì sí Olúwa Ọlọ́run mi.
6 I rzekłem: Boże mój! wstydci mię, i sromam się podnieść, Boże mój! oblicza mego do ciebie; albowiem nieprawości nasze rozmnożyły się nad głową, a grzechy nasze urosły aż ku niebu.
Mo sì gbàdúrà: “Ojú tì mí gidigidi, tí n kò fi lè gbé ojú mi sókè sí ọ̀dọ̀ rẹ, Ọlọ́run mi, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá di púpọ̀ ní orí wa, ẹ̀bi wa sì ga kan àwọn ọ̀run.
7 Ode dni ojców naszych byliśmy w wielkim grzechu aż do dnia tego, a przez nieprawości nasze wydaniśmy, królowie nasi i kapłani nasi, w ręce królów ziemskich pod miecz, w niewolę, i na łup, i na zawstydzenie twarzy naszej, jako się to dziś dzieje.
Láti ọjọ́ àwọn baba wá ni ẹ̀bi wa ti pọ̀ jọjọ títí di ìsinsin yìí. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa, àwa àti àwọn ọba wa àti àwọn àlùfáà wa ni a ti sọ di ẹni idà, ẹni ìgbèkùn, ìkógun àti ẹni ẹ̀sín lọ́wọ́ àwọn àjèjì ọba, bí ó ti rí lónìí.
8 Ale teraz, jakoby w prędkiem okamgnieniu, stała się nam łaska od Pana, Boga naszego, że nam zostawił ostatki, i dał nam mieszkanie na miejscu świętem swojem, aby oświecił oczy nasze Bóg nasz, a dał nam trochę wytchnienia z niewoli naszej.
“Ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí, fún ìgbà díẹ̀, ni a ti fi oore-ọ̀fẹ́ fún wa láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa wá láti sálà, àti láti fi èèkàn fún wa ni ibi mímọ́ rẹ̀, nítorí kí Ọlọ́run kí ó lè mú ojú wa mọ́lẹ̀, kí ó sì tún wa gbé dìde díẹ̀ kúrò nínú ìgbèkùn wa.
9 Bo chociaśmy byli niewolnikami, przecież w niewoli naszej nie opuścił nas Bóg nasz, ale skłonił ku nam miłosierdzie przed królmi Perskimi, dawszy nam wytchnienie, abyśmy wystawili dom Boga naszego, i naprawili spustoszenia jego; nawet dał nam ogrodzenie w Judztwie i w Jeruzalemie.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwa jẹ́ ẹrú, Ọlọ́run wa kò fi wa sílẹ̀ nínú ìgbèkùn wa. Ó ti fi àánú hàn fún wa ni iwájú àwọn ọba Persia: Ó ti fún wa ní ìgbé ayé tuntun láti tún odi ilé Ọlọ́run wa mọ, kí a sì tún àwókù rẹ̀ ṣe, ó sì fi odi ààbò fún wa ní Juda àti ní Jerusalẹmu.
10 Przetoż cóż teraz rzeczemy, o Boże nasz! po tem? ponieważeśmy opuścili rozkazania twoje,
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, kí ni àwa yóò wí lẹ́yìn èyí? Nítorí tí àwa kọ àṣẹ rẹ sílẹ̀
11 Któreś ty przykazał przez sług twoich proroków, mówiąc: Ziemia, do której wnijdziecie, abyście ją posiedli, jest ziemia nieczysta przez nieczystotę ludu tych ziem, dla obrzydłości ich, któremi ją napełnili od końca do końca nieczystością swoją.
èyí tí ìwọ ti pa fún wa láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, nígbà ti ìwọ wí pé, ‘Ilẹ̀ náà ti ẹ̀yin ń wọ̀ lọ láti gbà n nì jẹ́ ilẹ̀ aláìmọ́ tó kún fún ẹ̀gbin àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, nípa ṣíṣe ohun ìríra àti híhu ìwà èérí ti kún ún láti ìkángun kan dé èkejì.
12 A przetoż nie dawajcie córek waszych synom ich, ani bierzcie synom waszym córek ich, i nie szukajcie pokoju ich, i dobrego ich aż na wieki, abyście byli umocnieni, a pożywali dóbr tej ziemi, i podali ją w dziedzictwo synom waszym aż na wieki.
Nítorí náà, ẹ má ṣe fi àwọn ọmọbìnrin yín fún àwọn ọmọkùnrin wọn ní ìyàwó tàbí kí ẹ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó. Ẹ má ṣe dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn nígbàkígbà kí ẹ̀yin kí ó sì le lágbára, kí ẹ sì le máa jẹ ire ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le fi í sílẹ̀ fún àwọn ọmọ yín gẹ́gẹ́ bí ogún ayérayé.’
13 A po tem wszystkiem, co przyszło na nas dla spraw naszych złych i dla grzechu naszego wielkiego, ponieważeś ty, Boże nasz! zawściągnął karania, abyśmy nie byli potłumieni dla nieprawości naszej, aleś nam dał wybawienie takowe;
“Ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa jẹ́ àyọríṣí iṣẹ́ búburú wa àti ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ńlá wa, síbẹ̀, Ọlọ́run wa, ìjìyà ti ìwọ fún wa kéré si ìjìyà tí ó yẹ fún ẹ̀ṣẹ̀ ti a dá, ìwọ sì fún wa ní àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù bí èyí.
14 Izali się obrócimy ku zgwałceniu przykazań twoich, powinowacąc się z tymi narodami obrzydłymi? izalibyś się surowie nie gniewał na nas, abyś nas wyniszczył, aby nikt nie został i nie uszedł?
Ǹjẹ́ ó yẹ kí àwa tún yẹ̀ kúrò nínú àṣẹ rẹ, kí a sì máa ṣe ìgbéyàwó papọ̀ pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọn ti ṣe onírúurú ohun ìríra báyìí? Ṣe ìwọ kò ní bínú sí wa láti pa wá run tí kì yóò sẹ́ ku ẹnikẹ́ni tí yóò là?
15 O Panie, Boże Izraelski! sprawiedliwyś ty; bośmy pozostałe ostatki, jako się to dziś pokazuje. Otośmy my przed obliczem twojem w przewinieniu naszeem, choć się nie godzi stawiać przed oblicze twoje dla tego.
Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ìwọ jẹ́ olódodo! Àwa ìgbèkùn tí ó ṣẹ́kù bí ó ti rí lónìí. Àwa dúró níwájú rẹ nínú ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé nítorí èyí ẹnikẹ́ni nínú wa kò lè dúró níwájú rẹ”.

< Ezdrasza 9 >