< Ezechiela 25 >

1 I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Synu człowieczy! obróć twarz twoję przeciwko synom Ammonowym, a prorokuj przeciwko nim.
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
3 I rzecz synom Ammonowym: Słuchajcie słowa panującego Pana. Tak mówi panujący Pan: Przeto, żeś wykrzykał mówiąc: Hej, hej! nad świątnicą moją, gdy była splugawiona, i nad ziemią Izraelską, i gdy była spustoszona, i nad domem Judzkim, i gdy szedł w niewolę;
Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
4 Przetoż oto Ja cię też podam narodom wschodnim w dziedzictwo i pobudują pałace swoje w tobie, a wystawią mieszkanie swoje w tobie, one będą jeść urodzaje twoje, oni też będą pić mleko twoje.
kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
5 I dam Rabbę na mieszkanie wielbłądom, a miasta synów Ammonowych na legowisko trzodom; i dowiecie się, żem Ja Pan.
Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
6 Bo tak mówi panujacy Pan: Przeto, iżeś klaskał ręką, a tąpał nogą, i weseliłeś się z serca, żeś cale spustoszył ziemię Izraelską:
Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
7 Przetoż oto Ja wyciągnę rękę swą przeciwko tobie, a dam cię w rozchwycenie narodom, i wytnę cię z narodów, a wytracę cię z ziem, i wygładzę cię, a dowiesz się, żem Ja Pan.
nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
8 Tak mówi panujący Pan: Dlatego, że Moab i Seir mówił: Oto dom Judzki podobny jest wszystkim innym narodom.
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
9 Dlatego oto Ja otworzę stronę Moabczyków od miast, od miast mówię ich, i od granic ich, ozdobę ziemi Betiesymot, Baalmeon, i Karyjataim,
nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
10 Narodom wschodnim z ziemią synów Ammonowych; bom ją dał w dziedzictwo, aby nie było pamiątki synów Ammonowych między narodami.
Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
11 A tak nad Moabem sądy wykonam, iż poznają, żem Ja Pan.
Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
12 Tak mówi panujący Pan: Przetoż, iż się Edomczycy srodze mścili nad domem Judzkim, i przywiedli na się winę wielką, mszcząc się nad nimi;
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
13 Przetoż tak mówi panujący Pan: Wyciągnę też rękę moję na ziemię Edomczyków, a wytrcę z niej ludzi i bydło, i uczynię ją pustynią; od Teman aż do Dedan od miecza polegną.
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
14 A tak wykonam pomstę moję nad Edomczykami przez ręce ludu mojego Izraelskiego, a obejdą się z Edomczykami według popędliwości mojej, i według gniewu mego; i poznają pomstę moję, mówi panujacy Pan.
Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 Tak mówi panujący Pan: Przeto, iż się Filistyńczycy mścili, i pomstę wykonywali, pustosząc ich z serca, a do zginienia przywodząc z nieprzyjaźni starodawnej;
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
16 Dlatego tak mówi panujący Pan: Oto Ja wyciągnę rękę moję na Filistyńczyków, i wykorzenię Cheretejczyków, i wytracę ostatek krainy pomorskiej.
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
17 A tak uczynię nad nimi pomsty wielkie, karząc ich w zapalczywości; i dowiedzą się, żem Ja Pan, gdy wykonam pomstę moję nad nimi.
Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”

< Ezechiela 25 >